< Lamentations 2 >

1 Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Sioni pẹ̀lú àwọsánmọ̀ ìbínú rẹ̀! Ó sọ ògo Israẹli kalẹ̀, láti ọ̀run sí ayé; kò rántí àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀ ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.
Comment, dans sa colère, l'Éternel a couvert d'un nuage la fille de Sion? Il a fait descendre du ciel à la terre la beauté d'Israël, et ne s'est pas souvenu de son marchepied au jour de sa colère.
2 Láìní àánú ni Olúwa gbé ibùgbé Jakọbu mì; nínú ìrunú rẹ̀, ni ó wó ibi gíga ọmọbìnrin Juda lulẹ̀. Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ-aládé ọkùnrin lọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.
Le Seigneur a englouti toutes les habitations de Jacob. sans pitié. Il a renversé dans sa colère les forteresses de la fille de Juda. Il les a fait descendre jusqu'au sol. Il a profané le royaume et ses princes.
3 Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó ké gbogbo ìwo Israẹli. Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrò nígbà tí àwọn ọ̀tá dé. Ó run ní Jakọbu bí ọ̀wọ́-iná ní àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Sioni.
Il a coupé toute la corne d'Israël dans une colère ardente. Il a retiré sa main droite de devant l'ennemi. Il a brûlé Jacob comme un feu ardent, qui dévore tout autour.
4 Ó na ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá; ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múra. Bí ti ọ̀tá tí ó ti parun ó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí iná sórí àgọ́ ọmọbìnrin Sioni.
Il a bandé son arc comme un ennemi. Il s'est tenu avec sa main droite comme un adversaire. Il a tué tout ce qui était agréable à l'œil. Dans la tente de la fille de Sion, il a déversé sa colère comme un feu.
5 Olúwa dàbí ọ̀tá; ó gbé Israẹli mì. Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mì ó pa ibi gíga rẹ̀ run. Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀ fún àwọn ọmọbìnrin Juda.
Le Seigneur est devenu comme un ennemi. Il a englouti Israël. Il a englouti tous ses palais. Il a détruit ses forteresses. Il a multiplié les deuils et les lamentations dans la fille de Juda.
6 Ó mú ìparun bá ibi mímọ́, ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run. Olúwa ti mú Sioni gbàgbé àjọ̀dún tí a yàn àti ọ̀sẹ̀ tí ó yàn; nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó run ọba àti olórí àlùfáà.
Il a violemment enlevé son tabernacle, comme si c'était un jardin. Il a détruit son lieu de rassemblement. Yahvé a fait en sorte que l'assemblée solennelle et le sabbat soient oubliés en Sion. Dans l'indignation de sa colère, il a méprisé le roi et le prêtre.
7 Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀ ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀. Ó sì fi lé ọ̀tá lọ́wọ́ àwọn odi ààfin rẹ̀; wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àpèjẹ tí a yàn.
L'Éternel a rejeté son autel. Il a abhorré son sanctuaire. Il a livré les murs de ses palais aux mains de l'ennemi. Ils ont fait du bruit dans la maison de Yahvé, comme au jour d'une assemblée solennelle.
8 Olúwa pinnu láti fa ògiri tí ó yí ọmọbìnrin Sioni ya. Ó gbé wọn sórí òsùwọ̀n, kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn. Ó mú kí ilé ìṣọ́ àti odi rẹ̀ ṣọ̀fọ̀ wọ́n ṣòfò papọ̀.
Yahvé a décidé de détruire la muraille de la fille de Sion. Il a étiré la ligne. Il n'a pas retiré sa main de la destruction; Il a fait pleurer les remparts et les murs. Ils se languissent ensemble.
9 Ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀; òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́. Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, kò sí òfin mọ́, àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí ìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.
Ses portes se sont enfoncées dans le sol. Il a détruit et brisé ses barreaux. Son roi et ses princes sont parmi les nations où la loi n'existe pas. Oui, ses prophètes ne trouvent aucune vision de Yahvé.
10 Àwọn àgbàgbà ọmọbìnrin Sioni jókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́; wọ́n da eruku sí orí wọn wọ́n sì wọ aṣọ àkísà. Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jerusalẹmu ti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.
Les anciens de la fille de Sion sont assis à terre. Ils gardent le silence. Ils ont jeté de la poussière sur leurs têtes. Ils se sont vêtus de sacs. Les vierges de Jérusalem baissent la tête vers le sol.
11 Ojú mi kọ̀ láti sọkún, mo ń jẹ ìrora nínú mi, mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀ nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run, nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kú ní òpópó ìlú.
Mes yeux sont pleins de larmes. Mon cœur est troublé. Ma bile est versée sur la terre, à cause de la destruction de la fille de mon peuple, parce que les jeunes enfants et les nourrissons se pâment dans les rues de la ville.
12 Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn, “Níbo ni ọkà àti wáìnì wà?” Wò ó bí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣe ní àwọn òpópónà ìlú, bí ayé wọn ṣe ń ṣòfò láti ọwọ́ ìyá wọn.
Ils demandent à leurs mères, « Où sont le blé et le vin? » quand ils s'évanouissent comme des blessés dans les rues de la ville, quand leur âme est versée dans le sein de leur mère.
13 Kí ni mo le sọ fún ọ? Pẹ̀lú kí ni mo lè fi ọ́ wé, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu? Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé, kí n lè tù ọ́ nínú, ìwọ wúńdíá obìnrin Sioni? Ọgbẹ́ rẹ jì bí Òkun. Ta ni yóò wò ọ́ sàn?
Que vous dirai-je? Que te ressemblerai-je, fille de Jérusalem? Que dois-je comparer à vous, pour que je puisse te réconforter, vierge fille de Sion? Car ta brèche est aussi grande que la mer. Qui peut vous guérir?
14 Ìran àwọn wòlíì rẹ jẹ́ kìkì ẹ̀tàn láìní ìwọ̀n; wọn kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàn tí yóò mú ìgbèkùn kúrò fún ọ. Àwọn òrìṣà tí wọ́n fún ọ jẹ́ èké àti ìmúniṣìnà.
Vos prophètes ont eu pour vous des visions fausses et insensées. Ils n'ont pas découvert votre iniquité, pour inverser votre captivité, mais ont vu pour vous de fausses révélations et des causes de bannissement.
15 Àwọn tí ó gba ọ̀nà ọ̀dọ̀ rẹ pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí; wọ́n kẹ́gàn wọ́n ju orí wọn sí ọmọbìnrin Jerusalẹmu: “Èyí ha ni ìlú tí à ń pè ní àṣepé ẹwà, ìdùnnú gbogbo ayé?”
Tous les passants te frappent dans les mains. Ils sifflent et remuent la tête contre la fille de Jérusalem, en disant, « Est-ce la ville que les hommes appelaient 'La perfection de la beauté', la joie de toute la terre'? »
16 Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ la ẹnu wọn gbòòrò sí ọ; wọ́n kẹ́gàn, wọ́n sì payínkeke wọ́n wí pé, “A ti gbé e mì tán. Èyí ni ọjọ́ tí a ti ń retí; tí a sì wá láti rí.”
Tous tes ennemis ont ouvert la bouche contre toi. Ils sifflent et grincent des dents. Ils disent: « Nous l'avons engloutie ». C'est certainement le jour que nous attendions. Nous l'avons trouvé. Nous l'avons vu. »
17 Olúwa ti ṣe ohun tí ó pinnu; ó ti mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ, tí ó sì pàṣẹ ní ọjọ́ pípẹ́. Ó ti ṣí ọ ní ipò láì láàánú, ó fún ọ̀tá ní ìṣẹ́gun lórí rẹ, ó ti gbé ìwo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ga.
L'Éternel a accompli ce qu'il avait prévu. Il a accompli sa parole qu'il a commandée dans les temps anciens. Il s'est jeté à terre, et n'a pas eu pitié. Il a fait en sorte que l'ennemi se réjouisse à votre sujet. Il a exalté la corne de tes adversaires.
18 Ọkàn àwọn ènìyàn kígbe jáde sí Olúwa. Odi ọmọbìnrin Sioni, jẹ́ kí ẹkún rẹ̀ sàn bí odò ní ọ̀sán àti òru; má ṣe fi ara rẹ fún ìtura, ojú rẹ fún ìsinmi.
Leur cœur a crié à l'Éternel. O mur de la fille de Sion, laisse les larmes couler comme une rivière jour et nuit. Ne vous donnez aucun répit. Ne laissez pas vos yeux se reposer.
19 Dìde, kígbe sókè ní àṣálẹ́, bí ìṣọ́ òru ti bẹ̀rẹ̀ tú ọkàn rẹ̀ jáde bí omi níwájú Olúwa. Gbé ọwọ́ yín sókè sí i nítorí ẹ̀mí àwọn èwe rẹ̀ tí ó ń kú lọ nítorí ebi ní gbogbo oríta òpópó.
Lève-toi, crie dans la nuit, au début des montres! Répands ton cœur comme de l'eau devant la face du Seigneur. Levez vos mains vers lui pour la vie de vos jeunes enfants, qui s'évanouissent de faim au bout de chaque rue.
20 “Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó. Ta ni ìwọ ti fìyà jẹ bí èyí. Ǹjẹ́ àwọn obìnrin yóò ha jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ tí wọn ń ṣe ìtọ́jú fún? Ǹjẹ́ kí a pa olórí àlùfáà àti àwọn wòlíì ní ibi mímọ́ Olúwa?
« Regarde, Yahvé, et vois à qui tu as fait cela! Les femmes devraient-elles manger leur progéniture, les enfants qu'ils tenaient et faisaient rebondir sur leurs genoux? Le prêtre et le prophète doivent-ils être tués dans le sanctuaire du Seigneur?
21 “Ọmọdé àti àgbà ń sùn papọ̀ sínú eruku àwọn òpópó; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi ti ṣègbé nípa idà. Ìwọ pa wọ́n run ní ọjọ́ ìbínú rẹ, Ìwọ pa wọ́n láìní àánú.
« Le jeune et le vieillard sont couchés par terre dans les rues. Mes vierges et mes jeunes hommes sont tombés par l'épée. Tu les as tués au jour de ta colère. Vous avez massacré, et pas plaint.
22 “Bí ó ti ṣe ní ọjọ́ àsè, bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe fi ẹ̀rù sí ẹ̀gbẹ́ mi. Ní ọjọ́ ìbínú Olúwa kò sí ẹni tí ó sálà tí ó sì yè; àwọn tí mo ti tọ́jú tí mo sì fẹ́ràn, ni ọ̀tá mi parun.”
« Tu as appelé, comme au jour d'une assemblée solennelle, mes terreurs de toutes parts. Il n'y eut personne qui échappa ou resta au jour de la colère de Yahvé. Mon ennemi a consumé ceux dont j'ai pris soin et que j'ai élevés.

< Lamentations 2 >