< Lamentations 1 >

1 Báwo ni ìlú ṣe jókòó nìkan, nígbà kan tí ó sì kún fún ènìyàn! Ó ti fìgbà kan jẹ́ ìlú olókìkí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó wà ní ipò opó, ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọbabìnrin láàrín ìlú ni ó padà di ẹrú.
Cum șade singuratică cetatea, care era plină de popor! Cum a devenit ea ca o văduvă! Ea, care era mare printre națiuni și prințesă printre provincii, cum a ajuns să plătească tribut!
2 Ọ̀gànjọ́ òru ni ó fi máa ń sọkún kíkorò pẹ̀lú omijé ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ tí ó dúró sí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀. Nínú gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ọ̀kan nínú wọn láti rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún. Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti jọ̀wọ́ rẹ̀ wọ́n ti di alátakò rẹ̀.
Ea plânge amarnic noaptea și lacrimile ei îi sunt pe obraji; printre toți iubiții ei, nu are pe nimeni să o mângâie; toți prietenii ei s-au purtat cu perfidie cu ea, i-au devenit dușmani.
3 Lẹ́yìn ìjìyà àti ìpọ́njú nínú oko ẹrú, Juda lọ sí àjò Ó tẹ̀dó láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n kò rí ibi ìsinmi. Àwọn tí ó ń tẹ̀lé ká á mọ́ ibi tí kò ti le sá àsálà.
Iuda a mers în captivitate din cauza necazului și din cauza grelei servitudini; el locuiește printre păgâni, nu găsește odihnă; toți persecutorii lui l-au ajuns între strâmtori.
4 Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ Sioni ń ṣọ̀fọ̀, nítorí ẹnìkan kò wá sí àjọ̀dún tí a yàn. Gbogbo ẹnu-bodè rẹ̀ dahoro, àwọn àlùfáà rẹ̀ kẹ́dùn, àwọn wúńdíá rẹ̀ sì ń káàánú, òun gan an wà ní ọkàn kíkorò.
Căile Sionului jelesc, pentru că nimeni nu vine la sărbătorile solemne; toate porțile lui sunt pustiite; preoții lui suspină, fecioarele lui sunt chinuite și el este în amărăciune.
5 Àwọn aninilára rẹ̀ gbogbo di olúwa rẹ̀, nǹkan sì rọrùn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀, Olúwa ti fún un ní ìjìyà tó tọ́ nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Àwọn ẹ̀ṣọ́ wẹ́wẹ́ rẹ̀ lọ sí oko ẹrú, ìgbèkùn níwájú àwọn ọ̀tá.
Potrivnicii lui sunt cei dintâi, dușmanii lui prosperă, pentru că DOMNUL l-a chinuit din cauza mulțimii fărădelegilor lui; copiii lui au mers în captivitate înaintea dușmanului.
6 Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé kúrò lọ́dọ̀ ọmọbìnrin Sioni. Àwọn ìjòyè rẹ̀ dàbí i àgbọ̀nrín tí kò rí ewé tútù jẹ; nínú àárẹ̀ wọ́n sáré níwájú ẹni tí ó ń lé wọn.
Și de la fiica Sionului a plecat toată frumusețea ei; prinții ei au devenit ca cerbii care nu găsesc pășune, și au fugit fără putere înaintea urmăritorului.
7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ ni Jerusalẹmu rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀ tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́. Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá, kò sì ṣí olùrànlọ́wọ́ fún un. Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ó wọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.
Ierusalimul și-a amintit în zilele chinuirii lui și a nenorocirilor lui, de toate lucrurile lui plăcute, pe care le-a avut în zilele din vechime, când poporul lui a căzut în mâna dușmanului și nimeni nu l-a ajutat; potrivnicii l-au văzut și i-au batjocorit sabatele.
8 Jerusalẹmu sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀ ó sì ti di aláìmọ́. Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀, nítorí wọ́n ti rí ìhòhò rẹ̀; ó kérora fúnra rẹ̀, ó sì lọ kúrò.
Ierusalimul a păcătuit greu, de aceea el este îndepărtat; toți care l-au onorat îl disprețuiesc, pentru că i-au văzut goliciunea; da, el suspină și se întoarce cu spatele.
9 Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀. Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu; olùtùnú kò sì ṣí fún un. “Wo ìpọ́njú mi, Olúwa, nítorí àwọn ọ̀tá ti borí.”
Murdăria lui este în poalele lui; nu și-a amintit de sfârșitul lui; de aceea s-a coborât minunat; nu avea mângâietor. DOAMNE, privește nenorocirea mea, pentru că dușmanul s-a înălțat pe sine însuși.
10 Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ lé gbogbo ìní rẹ; o rí pé àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ— àwọn tí o ti kọ̀sílẹ̀ láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.
Potrivnicul și-a întins mâna peste toate lucrurile lui plăcute, pentru că el a văzut că păgânii au intrat în sanctuarul său, despre care tu ai poruncit ca ei să nu intre în adunarea ta.
11 Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérora bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ; wọ́n fi ohun ìní wọn ṣe pàṣípàrọ̀ oúnjẹ láti mú wọn wà láààyè. “Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó, nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”
Tot poporul lui suspină, ei caută pâine; și-au dat lucrurile lor plăcute pentru hrană, pentru a-și ușura sufletul; vezi, DOAMNE și ia aminte, pentru că eu am devenit nemernic.
12 “Kò ha jẹ́ nǹkan kan sí i yín? Gbogbo ẹ̀yin tí ń rékọjá. Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyà tí a fi fún mi, ti Olúwa mú wá fún mi ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.
Nu este aceasta nimic pentru voi, toți care treceți? Priviți și vedeți dacă este vreo întristare ca întristarea mea, care îmi este făcută, cu care DOMNUL m-a chinuit în ziua mâniei sale înverșunate.
13 “Ó rán iná láti òkè sọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi. Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi, ó sì yí mi padà. Ó ti pa mí lára mó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.
El a trimis, din înălțime, foc în oasele mele și acesta le-a învins; a întins o plasă picioarelor mele, m-a întors înapoi; m-a pustiit și [m]-a făcut de leșin toată ziua.
14 “Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di sísopọ̀ sí àjàgà; ọwọ́ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀. Wọ́n ti yí ọrùn mi ká Olúwa sì ti dín agbára mi kù. Ó sì ti fi mí lé àwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.
Jugul fărădelegilor mele este legat de mâna sa; ei sunt împletiți și s-au urcat pe gâtul meu; el a făcut puterea mea să cadă, DOMNUL m-a dat în mâinile lor, din care eu nu sunt în stare să mă ridic.
15 “Olúwa kọ àwọn akọni mi sílẹ̀, ó rán àwọn ológun lòdì sí mi kí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run. Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́ àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Juda.
DOMNUL a călcat în picioare pe toți vitejii mei în mijlocul meu; a chemat o adunare împotriva mea pentru a zdrobi pe tinerii mei; DOMNUL a călcat în picioare pe fecioară, pe fiica lui Iuda, ca într-un teasc.
16 “Ìdí nìyí tí mo fi ń sọkún tí omijé sì ń dà lójú mi. Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sí mi, kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà. Àwọn ọmọ mi di aláìní nítorí ọ̀tá ti borí.”
Pentru acestea plâng eu; ochiul meu, ochiul meu izvorăște lacrimi, pentru că mângâietorul, care ar trebui să îmi ușureze sufletul, este departe de mine; copiii mei sunt pustiiți pentru că dușmanul a învins.
17 Sioni na ọwọ́ jáde, ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un. Olúwa ti pàṣẹ fún Jakọbu pé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀tá fún un Jerusalẹmu ti di ohun aláìmọ́ láàrín wọn.
Sionul își întinde mâinile și nu este nimeni să o mângâie; DOMNUL a poruncit referitor la Iacob, ca potrivnicii lui să fie de jur împrejurul lui; Ierusalimul este, printre ei, ca o femeie în timpul menstruației.
18 “Olóòtítọ́ ni Olúwa, ṣùgbọ́n mo ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀. Ẹ gbọ́, gbogbo ènìyàn; ẹ wò mí wò ìyà mi. Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi ni a ti kó lọ sí ìgbèkùn.
DOMNUL este drept, pentru că eu m-am răzvrătit împotriva poruncii lui; auziți, vă rog, toate popoarele și priviți întristarea mea; fecioarele mele și tinerii mei au mers în captivitate.
19 “Mo pe àwọn ọ̀rẹ́ mi ṣùgbọ́n wọ́n dà mí. Àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà mi ṣègbé sínú ìlú nígbà tí wọ́n ń wá oúnjẹ tí yóò mú wọn wà láààyè.
Eu am chemat pe iubiții mei, dar ei m-au înșelat; preoții mei și bătrânii mei și-au dat duhul în cetate, în timp ce își căutau hrana pentru a-și ușura sufletele.
20 “Olúwa, wò ó, bí mo ti wà nínú ìnira! Tí mo sì ń jẹ̀rora nínú mi, ìdààmú dé bá ọkàn mi nítorí pé a ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi gidigidi. Ní gbangba ni idà ń parun; ikú wà nínú ilé pẹ̀lú.
Privește, DOAMNE, pentru că sunt în strâmtorare; adâncurile mele sunt tulburate; inima mea este întoarsă înăuntrul meu, pentru că eu m-am răzvrătit cumplit; afară, sabia mă văduvește, acasă este ca moartea.
21 “Àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìrora mi, ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún mi. Àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ ìparun mi; wọ́n yọ̀ sí ohun tí o ṣe. Kí o mú ọjọ́ tí o ti kéde, kí wọ́n le dàbí tèmi.
Ei m-au auzit că suspin; nu este nimeni să mă mângâie; toți dușmanii mei au auzit de tulburarea mea; ei se veselesc că ai făcut aceasta; tu vei aduce ziua pe care ai chemat-o și ei vor fi asemenea mie.
22 “Jẹ́ kí ìwà ìkà wọn wá síwájú rẹ; jẹ wọ́n ní yà bí o ṣe jẹ mí ní yà nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi. Ìrora mi pọ̀ ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”
Să ajungă înaintea ta toată stricăciunea lor; și fă-le precum mi-ai făcut mie pentru toate fărădelegile mele, pentru că suspinele mele sunt multe și inima mea este leșinată.

< Lamentations 1 >