< Lamentations 1 >

1 Báwo ni ìlú ṣe jókòó nìkan, nígbà kan tí ó sì kún fún ènìyàn! Ó ti fìgbà kan jẹ́ ìlú olókìkí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó wà ní ipò opó, ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọbabìnrin láàrín ìlú ni ó padà di ẹrú.
Ach, jak samotnie siedzi miasto niegdyś tak pełne ludzi! Stało się jak wdowa! [Niegdyś] wielka wśród narodów i księżniczka wśród prowincji, [teraz] stała się podwładną.
2 Ọ̀gànjọ́ òru ni ó fi máa ń sọkún kíkorò pẹ̀lú omijé ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ tí ó dúró sí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀. Nínú gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ọ̀kan nínú wọn láti rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún. Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti jọ̀wọ́ rẹ̀ wọ́n ti di alátakò rẹ̀.
Nieustannie płacze w nocy, a na jej policzkach łzy. Nie ma nikogo, kto by ją pocieszył pośród wszystkich jej kochanków. Wszyscy jej przyjaciele zdradzili ją i stali się jej wrogami.
3 Lẹ́yìn ìjìyà àti ìpọ́njú nínú oko ẹrú, Juda lọ sí àjò Ó tẹ̀dó láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n kò rí ibi ìsinmi. Àwọn tí ó ń tẹ̀lé ká á mọ́ ibi tí kò ti le sá àsálà.
Juda poszedł na wygnanie z powodu ucisku i wielkiej niewoli, mieszka między poganami i nie znajduje odpoczynku. Wszyscy jego prześladowcy dopadli go pośród ucisków.
4 Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ Sioni ń ṣọ̀fọ̀, nítorí ẹnìkan kò wá sí àjọ̀dún tí a yàn. Gbogbo ẹnu-bodè rẹ̀ dahoro, àwọn àlùfáà rẹ̀ kẹ́dùn, àwọn wúńdíá rẹ̀ sì ń káàánú, òun gan an wà ní ọkàn kíkorò.
Drogi Syjonu płaczą, bo nikt nie przychodzi na uroczyste święta. Wszystkie jego bramy opustoszały, jego kapłani wzdychają, jego dziewice są smutne, a on sam jest pełny goryczy.
5 Àwọn aninilára rẹ̀ gbogbo di olúwa rẹ̀, nǹkan sì rọrùn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀, Olúwa ti fún un ní ìjìyà tó tọ́ nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Àwọn ẹ̀ṣọ́ wẹ́wẹ́ rẹ̀ lọ sí oko ẹrú, ìgbèkùn níwájú àwọn ọ̀tá.
Jego wrogowie są zwierzchnikami, jego przeciwnikom szczęśliwie się powodzi. PAN bowiem trapił go z powodu mnóstwa jego występków. Jego dzieci poszły do niewoli przed ciemięzcą.
6 Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé kúrò lọ́dọ̀ ọmọbìnrin Sioni. Àwọn ìjòyè rẹ̀ dàbí i àgbọ̀nrín tí kò rí ewé tútù jẹ; nínú àárẹ̀ wọ́n sáré níwájú ẹni tí ó ń lé wọn.
A tak odjęte zostało od córki Syjonu całe jej dostojeństwo. Jej książęta stali się jak jelenie, które nie znajdują pastwiska, i uchodzą bez siły przed tym, który je ściga.
7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ ni Jerusalẹmu rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀ tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́. Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá, kò sì ṣí olùrànlọ́wọ́ fún un. Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ó wọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.
W dniach swego utrapienia i [swej] niedoli Jerozolima wspomina wszystkie swoje kosztowności, jakie miała za dawnych dni, gdy jej lud wpadł w ręce wroga, a nikt jej nie pomógł; nieprzyjaciele, widząc ją, naśmiewali się z jej szabatów.
8 Jerusalẹmu sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀ ó sì ti di aláìmọ́. Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀, nítorí wọ́n ti rí ìhòhò rẹ̀; ó kérora fúnra rẹ̀, ó sì lọ kúrò.
Jerozolima ciężko zgrzeszyła, dlatego została odłączona jako nieczysta. Wszyscy, którzy ją szanowali, gardzą nią, gdyż widzą jej nagość, a ona wzdycha i odwraca się plecami.
9 Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀. Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu; olùtùnú kò sì ṣí fún un. “Wo ìpọ́njú mi, Olúwa, nítorí àwọn ọ̀tá ti borí.”
Jej nieczystość jest na brzegach jej szat, nie pamięta swego końca; dlatego wielce ją poniżono i nikt jej nie pociesza. Spójrz, PANIE, na moje utrapienie, bo wróg się wywyższył.
10 Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ lé gbogbo ìní rẹ; o rí pé àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ— àwọn tí o ti kọ̀sílẹ̀ láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.
Wróg wyciągnął swoją rękę po wszystkie jej kosztowności. Patrzy, jak poganie, którym zakazałeś wchodzić do twego zgromadzenia, wchodzą do jej świątyni.
11 Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérora bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ; wọ́n fi ohun ìní wọn ṣe pàṣípàrọ̀ oúnjẹ láti mú wọn wà láààyè. “Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó, nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”
Cały jej lud wzdycha i szuka chleba, daje swoje kosztowności za pokarm, aby posilić duszę. Spójrz, PANIE, i zobacz, że zostałam znieważona.
12 “Kò ha jẹ́ nǹkan kan sí i yín? Gbogbo ẹ̀yin tí ń rékọjá. Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyà tí a fi fún mi, ti Olúwa mú wá fún mi ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.
Czy nic was to nie obchodzi, wszyscy, którzy przechodzicie obok? Spójrzcie i zobaczcie, czy jest boleść podobna do mojej boleści, jaką mi zadano, którą dotknął mnie PAN w dniu swojego zapalczywego gniewu.
13 “Ó rán iná láti òkè sọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi. Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi, ó sì yí mi padà. Ó ti pa mí lára mó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.
Z wysoka zesłał ogień na moje kości, który je pokonał. Rozciągnął sieć na moje nogi i zawrócił mnie, wydał mnie na spustoszenie i przez cały dzień omdlewam.
14 “Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di sísopọ̀ sí àjàgà; ọwọ́ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀. Wọ́n ti yí ọrùn mi ká Olúwa sì ti dín agbára mi kù. Ó sì ti fi mí lé àwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.
Jarzmo moich nieprawości jest związane jego ręką, splotły się i weszły na moją szyję, a [to] poraziło moją siłę. Pan wydał mnie w ręce [wrogów] i nie mogę powstać.
15 “Olúwa kọ àwọn akọni mi sílẹ̀, ó rán àwọn ológun lòdì sí mi kí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run. Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́ àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Juda.
Pan podeptał wszystkich moich mocarzy, [którzy są] pośród mnie, zwołał przeciwko mnie gromadę, aby zmiażdżyć moich młodzieńców. Pan, jak w tłoczni, podeptał dziewicę, córkę Judy.
16 “Ìdí nìyí tí mo fi ń sọkún tí omijé sì ń dà lójú mi. Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sí mi, kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà. Àwọn ọmọ mi di aláìní nítorí ọ̀tá ti borí.”
Dlatego ja płaczę; z oczu, z moich oczu, ciekną wody, gdyż daleko jest ode mnie pocieszyciel, który by pokrzepił moją duszę; moi synowie są wytraceni, bo wróg zwyciężył.
17 Sioni na ọwọ́ jáde, ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un. Olúwa ti pàṣẹ fún Jakọbu pé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀tá fún un Jerusalẹmu ti di ohun aláìmọ́ láàrín wọn.
Syjon wyciąga swoje ręce, nie ma nikogo, kto by go pocieszył. PAN pobudził dokoła Jakuba jego wrogów; Jerozolima jest wśród nich [jak kobieta] oddalona z powodu [jej] nieczystości.
18 “Olóòtítọ́ ni Olúwa, ṣùgbọ́n mo ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀. Ẹ gbọ́, gbogbo ènìyàn; ẹ wò mí wò ìyà mi. Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi ni a ti kó lọ sí ìgbèkùn.
PAN jest sprawiedliwy, bo zbuntowałam się przeciwko jego słowu. Słuchajcie, proszę, wszyscy ludzie, i zobaczcie moje boleści. Moje dziewice i moi młodzieńcy poszli do niewoli.
19 “Mo pe àwọn ọ̀rẹ́ mi ṣùgbọ́n wọ́n dà mí. Àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà mi ṣègbé sínú ìlú nígbà tí wọ́n ń wá oúnjẹ tí yóò mú wọn wà láààyè.
Wołałam do moich kochanków, lecz oni mnie zdradzili. Moi kapłani i starcy zginęli w mieście, kiedy szukali pokarmu dla siebie, aby posilić swoją duszę.
20 “Olúwa, wò ó, bí mo ti wà nínú ìnira! Tí mo sì ń jẹ̀rora nínú mi, ìdààmú dé bá ọkàn mi nítorí pé a ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi gidigidi. Ní gbangba ni idà ń parun; ikú wà nínú ilé pẹ̀lú.
Spójrz, PANIE, bo jestem utrapiona, moje wnętrzności drżą, moje serce przewraca się we mnie, gdyż uparcie się buntowałam. Na dworze miecz osieroca, [a] w domu nie ma nic oprócz śmierci.
21 “Àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìrora mi, ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún mi. Àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ ìparun mi; wọ́n yọ̀ sí ohun tí o ṣe. Kí o mú ọjọ́ tí o ti kéde, kí wọ́n le dàbí tèmi.
Słyszą, że wzdycham, [ale] nie ma nikogo, kto by mnie pocieszył; wszyscy moi wrogowie słyszeli o moim nieszczęściu i cieszą się, że to uczyniłeś. Sprowadzasz dzień, który zapowiedziałeś, a staną się podobni do mnie.
22 “Jẹ́ kí ìwà ìkà wọn wá síwájú rẹ; jẹ wọ́n ní yà bí o ṣe jẹ mí ní yà nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi. Ìrora mi pọ̀ ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”
Niech cała ich niegodziwość przyjdzie przed ciebie; uczyń im tak, jak mnie uczyniłeś z powodu wszystkich moich przestępstw. Wiele bowiem jest moich westchnień, a moje serce omdlewa.

< Lamentations 1 >