< Judges 1 >

1 Lẹ́yìn ikú Joṣua, ni orílẹ̀-èdè Israẹli béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Èwo nínú ẹ̀yà wa ni yóò kọ́kọ́ gòkè lọ bá àwọn ará Kenaani jagun fún wa?”
Torej po Józuetovi smrti se je pripetilo, da so Izraelovi otroci vprašali Gospoda, rekoč: »Kdo bo za nas najprej šel gor zoper Kánaance, da se bori zoper njih?«
2 Olúwa sì dáhùn pé, “Juda ni yóò lọ; nítorí pé èmi ti fi ilẹ̀ náà lé e lọ́wọ́.”
Gospod je rekel: »Juda bo šel gor. Glejte, deželo sem izročil v njegovo roko.«
3 Nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Juda béèrè ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Simeoni arákùnrin wọn pé, “Ẹ wá bá wa gòkè lọ sí ilẹ̀ tí a ti fi fún wa, láti bá àwọn ará Kenaani jà kí a sì lé wọn kúrò, àwa pẹ̀lú yóò sì bá a yín lọ sí ilẹ̀ tiyín bákan náà láti ràn yín lọ́wọ́.” Àwọn ọmọ-ogun Simeoni sì bá àwọn ọmọ-ogun Juda lọ.
Juda je svojemu bratu Simeonu rekel: »Pridi gor z menoj v moj žreb, da se bova lahko borila zoper Kánaance in prav tako bom tudi jaz šel s teboj v tvoj žreb.« Tako je Simeon odšel z njim.
4 Nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Juda sì kọlu wọ́n, Olúwa sì fi àwọn ará Kenaani àti àwọn ará Peresi lé wọn lọ́wọ́, wọ́n sì pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ní Beseki.
Juda je odšel gor in Gospod je Kánaance in Perizéjce izročil v njuno roko in izmed njih sta v Bezeku usmrtila deset tisoč mož.
5 Ní Beseki ni wọ́n ti rí Adoni-Beseki, wọ́n sì bá a jagun, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn ará Kenaani àti Peresi.
V Bezeku sta našla Adoní Bezeka in se borila zoper njega ter usmrtila Kánaance in Perizéjce.
6 Ọba Adoni-Beseki sá àsálà, ṣùgbọ́n ogun Israẹli lépa rẹ̀ wọ́n sì bá a, wọ́n sì gé àwọn àtàǹpàkò ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀.
Toda Adoní Bezek je pobegnil in sledila sta za njim, ga ujela ter odsekala njegova palca in velika prsta na njegovih stopalih.
7 Nígbà náà ni Adoni-Beseki wí pé, “Àádọ́rin ọba ni èmi ti gé àtàǹpàkò wọn tí wọ́n sì ń ṣa èérún oúnjẹ jẹ lábẹ́ tábìlì mi. Báyìí Ọlọ́run ti san án fún mi gẹ́gẹ́ bí ohun tí mo ṣe sí wọn.” Wọ́n sì mú un wá sí Jerusalẹmu, ó sì kú síbẹ̀.
Adoní Bezek je rekel: »Sedemdeset kraljev, ki imajo odsekane svoje palce in svoje palce na stopalih, je svojo hrano pobiralo pod mojo mizo. Kakor sem jaz storil, tako mi je Bog poplačal.« In odvedla sta ga v Jeruzalem in tam je umrl.
8 Àwọn ológun Juda sì ṣẹ́gun Jerusalẹmu, wọ́n sì kó o, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú, wọ́n sì dáná sun ìlú náà.
Torej Judovi otroci so se borili zoper Jeruzalem, ga zavzeli, udarili z ostrino meča in zažgali mesto.
9 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni àwọn ogun Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti bá àwọn ará Kenaani tí ń gbé ní àwọn ìlú orí òkè ní gúúsù àti ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ òkè lápá ìwọ̀-oòrùn Juda jagun.
Potem so Judovi otroci odšli dol, da se borijo zoper Kánaance, ki prebivajo na gori, na jugu in v dolini.
10 Ogun Juda sì tún ṣígun tọ ará Kenaani tí ń gbé Hebroni (tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Kiriati-Arba) ó sì ṣẹ́gun Ṣeṣai, Ahimani àti Talmai.
Juda je odšel zoper Kánaance, ki prebivajo v Hebrónu (torej ime Hebróna je bilo prej Kirját Arba) in usmrtili so Šešája, Ahimána in Talmája.
11 Láti ibẹ̀, wọ́n sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
Od tam je odšel zoper prebivalce Debírja. Ime Debírja pa je bilo prej Kirját Sefer.
12 Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
Kaléb je rekel: »Kdor udari Kirját Sefer in ga zavzame, njemu bom dal svojo hčer Ahso za ženo.«
13 Otnieli ọmọ Kenasi, àbúrò Kalebu sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
Zavzel ga je Kenázov sin Otniél, Kalébov mlajši brat in dal mu je svojo hčer Ahso za ženo.
14 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
Ko je prišla k njemu se je pripetilo, da ga je primorala, da prosi od svojega očeta polje in razjahala je svojega osla in Kaléb ji je rekel: »Kaj hočeš?«
15 Aksa sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
Rekla mu je: »Daj mi blagoslov, kajti dal si mi južno deželo; daj mi tudi vodne izvire.« In Kaléb ji je dal gornje izvire in spodnje izvire.
16 Àwọn ìran Keni tí wọ́n jẹ́ àna Mose bá àwọn ọmọ Juda gòkè láti ìlú ọ̀pẹ lọ sí aginjù Juda ní gúúsù Aradi; wọ́n sì lọ, orílẹ̀-èdè méjèèjì sì jùmọ̀ ń gbé pọ̀ láti ìgbà náà.
Otroci Kenéjca, Mojzesovega tasta, so z Judovimi otroki odšli gor iz mesta palmovih dreves v Judovo divjino, ki leži na jugu Aráda in odšli so ter prebivali med ljudstvom.
17 Ó sì ṣe, àwọn ológun Juda tẹ̀lé àwọn ológun Simeoni arákùnrin wọn, wọ́n sì lọ bá àwọn ará Kenaani tí ń gbé Sefati jagun, wọ́n sì run ìlú náà pátápátá, ní báyìí àwa yóò pe ìlú náà ní Horma (Horma èyí tí ń jẹ́ ìparun).
Juda je odšel s svojim bratom Simeonom in usmrtili so Kánaance, ki naseljujejo Cefát in ga popolnoma uničili. Ime mesta se je imenovalo Horma.
18 Àwọn ogun Juda sì ṣẹ́gun Gasa àti àwọn agbègbè rẹ̀, Aṣkeloni àti Ekroni pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó yí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ká.
Juda je zavzel tudi Gazo z njenimi pokrajinami, Aškelón z njegovimi pokrajinami in Ekrón z njegovimi pokrajinami.
19 Olúwa sì wà pẹ̀lú ẹ̀yà Juda, wọ́n gba ilẹ̀ òkè, ṣùgbọ́n wọn kò le lé àwọn ènìyàn tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí wọ́n ní kẹ̀kẹ́ ogun onírin.
Gospod je bil z Judom in napodil je prebivalce gore, toda ni mogel napoditi prebivalcev doline, ker so imeli železne vozove.
20 Gẹ́gẹ́ bí Mose ti ṣèlérí, wọ́n fún Kalebu ní Hebroni, ó sì lé àwọn tí ń gbé ibẹ̀ kúrò; àwọn náà ni ìran àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta.
Hebrón so dali Kalébu, kakor je rekel Mojzes, in od tam je izgnal tri Anákove sinove.
21 Àwọn ẹ̀yà Benjamini ni wọn kò le lé àwọn Jebusi tí wọ́n ń gbé Jerusalẹmu, nítorí náà wọ́n ń gbé àárín àwọn Israẹli títí di òní.
Benjaminovi otroci pa niso napodili Jebusejcev, ki so naseljevali Jeruzalem, temveč Jebusejci prebivajo z Benjaminovimi otroki v Jeruzalemu do današnjega dne.
22 Àwọn ẹ̀yà Josẹfu sì bá Beteli jagun, Olúwa síwájú pẹ̀lú wọn.
Jožefova hiša, tudi oni so se dvignili zoper Betel in Gospod je bil z njimi.
23 Nígbà tí ẹ̀yà Josẹfu rán àwọn ènìyàn láti lọ yọ́ Beteli wò (orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí ni Lusi).
Jožefova hiša je poslala, da razišče Betel. (Torej ime mesta je bilo prej Luz.)
24 Àwọn ayọ́lẹ̀wò náà rí ọkùnrin kan tí ń jáde láti inú ìlú náà wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Fi ọ̀nà àtiwọ ìlú yìí hàn wá, àwa ó sì dá ẹ̀mí rẹ sí, a ó sì ṣe àánú fún ọ.”
Ogledniki so videli moža priti iz mesta in mu rekli: »Pokaži nam, prosimo te, vhod v mesto, mi pa ti bomo izkazali usmiljenje.«
25 Ó sì fi ọ̀nà ìlú náà hàn wọ́n, wọ́n sì fi ojú idà kọlu ìlú náà, ṣùgbọ́n wọ́n dá ọkùnrin náà àti gbogbo ìdílé rẹ̀ si.
Ko jim je ta pokazal vhod v mesto, potem so mesto udarili z ostrino meča, toda spustili so moža in vso njegovo družino.
26 Ọkùnrin náà sí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Hiti, ó sì tẹ ìlú kan dó, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Lusi, èyí sì ni orúkọ rẹ̀ títí di òní.
Mož je odšel v deželo Hetejcev, zgradil mesto in njegovo ime imenoval Luz, kar je njegovo ime do današnjega dne.
27 Ṣùgbọ́n Manase kò lé àwọn ará Beti-Ṣeani àti ìlú rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jáde, tàbí àwọn ará Taanaki àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Dori àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Ibleamu àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Megido àti àwọn ìgbèríko tí ó yí i ká, torí pé àwọn ará Kenaani ti pinnu láti máa gbé ìlú náà.
Niti Manáse ni napodil prebivalcev Bet Šeána in njegovih mest, niti Taanáha in njegovih mest, niti prebivalcev Dora in njegovih mest, niti prebivalcev Jibleáma in njegovih mest, niti prebivalcev Megída in njenih mest, temveč so Kánaanci hoteli prebivati v tej deželi.
28 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli di alágbára, wọ́n mú àwọn ará Kenaani sìn bí i ẹrú, ṣùgbọ́n wọn kò fi agbára lé wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ náà.
Pripetilo se je, ko je bil Izrael močan, da so Kánaance podvrgli davku, niso pa jih popolnoma pognali ven.
29 Efraimu náà kò lé àwọn ará Kenaani tí ó ń gbé Geseri jáde, ṣùgbọ́n àwọn ará Kenaani sì ń gbé láàrín àwọn ẹ̀yà Efraimu.
Niti ni Efrájim napodil Kánaancev, ki prebivajo v Gezerju, temveč Kánaanci prebivajo med njimi v Gezerju.
30 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Sebuluni kò lé àwọn ará Kenaani tí ń gbé Kitironi jáde tàbí àwọn ará Nahalali, ṣùgbọ́n wọ́n sọ wọ́n di ẹrú. Wọ́n sì ń sin àwọn ará Sebuluni.
Niti ni Zábulon napodil prebivalcev Kitróna niti prebivalcev Nahalóla, temveč so Kánaanci prebivali med njimi in postali so davkoplačevalci.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Aṣeri kò lé àwọn tí ń gbé ní Akko tàbí ní Sidoni tàbí ní Ahlabu tàbí ní Aksibu tàbí ní Helba tàbí ní Afiki tàbí ní Rehobu.
Niti ni Aser napodil prebivalcev Aka, niti prebivalcev Sidóna, niti Ahalaba, niti Ahzíba, niti Helbe, niti Aféke, niti Rehóba,
32 Ṣùgbọ́n nítorí àwọn ará Aṣeri ń gbé láàrín àwọn ará Kenaani tí wọ́n ni ilẹ̀ náà.
temveč so Aserjevci prebivali med Kánaanci, prebivalci dežele, kajti niso jih pognali ven.
33 Àwọn ẹ̀yà Naftali pẹ̀lú kò lé àwọn ará Beti-Ṣemeṣi àti Beti-Anati jáde; ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Naftali náà ń gbé àárín àwọn ará Kenaani tí ó ti ní ilẹ̀ náà rí, ṣùgbọ́n àwọn tí ń gbé Beti-Ṣemeṣi àti Beti-Anati ń sìn ìsìn tipátipá.
Niti ni Neftáli napodil prebivalcev Bet Šemeša niti prebivalcev Bet Anáta, temveč je prebival med Kánaanci, prebivalci dežele. Kljub temu so jim prebivalci Bet Šemeša in Bet Anáta postali davkoplačevalci.
34 Àwọn ará Amori fi agbára dá àwọn ẹ̀yà Dani dúró sí àwọn ìlú orí òkè, wọn kò sì jẹ́ kí wọn sọ̀kalẹ̀ wá sí pẹ̀tẹ́lẹ̀.
Amoréjci pa so Danove otroke potisnili na goro, kajti niso jim hoteli pustiti, da pridejo dol k dolini,
35 Àwọn ará Amori ti pinnu láti dúró lórí òkè Heresi àti òkè Aijaloni àti ti Ṣaalbimu, ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yà Josẹfu di alágbára wọ́n borí Amori wọ́n sì mú wọn sìn.
temveč so Amoréjci hoteli prebivati na gori Heres v Ajalónu in v Šaalbímu. Vendar je roka Jožefove hiše prevladala, tako da so postali davkoplačevalci.
36 Ààlà àwọn ará Amori sì bẹ̀rẹ̀ láti ìgòkè Akrabbimu kọjá lọ sí Sela àti síwájú sí i.
Pokrajina Amoréjcev je bila od vzpona k Akrabímu, od skale in navzgor.

< Judges 1 >