< Judges 1 >
1 Lẹ́yìn ikú Joṣua, ni orílẹ̀-èdè Israẹli béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Èwo nínú ẹ̀yà wa ni yóò kọ́kọ́ gòkè lọ bá àwọn ará Kenaani jagun fún wa?”
Kwasekusithi emva kokufa kukaJoshuwa abantwana bakoIsrayeli babuza iNkosi besithi: Ngubani ozasenyukelela ukuyamelana lamaKhanani kuqala ukulwa emelene labo?
2 Olúwa sì dáhùn pé, “Juda ni yóò lọ; nítorí pé èmi ti fi ilẹ̀ náà lé e lọ́wọ́.”
INkosi yasisithi: UJuda uzakwenyuka; khangelani, ngilinikele ilizwe esandleni sakhe.
3 Nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Juda béèrè ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Simeoni arákùnrin wọn pé, “Ẹ wá bá wa gòkè lọ sí ilẹ̀ tí a ti fi fún wa, láti bá àwọn ará Kenaani jà kí a sì lé wọn kúrò, àwa pẹ̀lú yóò sì bá a yín lọ sí ilẹ̀ tiyín bákan náà láti ràn yín lọ́wọ́.” Àwọn ọmọ-ogun Simeoni sì bá àwọn ọmọ-ogun Juda lọ.
UJuda wasesithi kuSimeyoni umfowabo: Yenyuka lami enkathweni yami ukuze silwe simelene lamaKhanani; lami-ke ngizahamba lawe enkathweni yakho. USimeyoni wasehamba laye.
4 Nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Juda sì kọlu wọ́n, Olúwa sì fi àwọn ará Kenaani àti àwọn ará Peresi lé wọn lọ́wọ́, wọ́n sì pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ní Beseki.
UJuda wasesenyuka, njalo iNkosi yanikela amaKhanani lamaPerizi esandleni sabo; bawatshaya eBezeki, amadoda azinkulungwane ezilitshumi.
5 Ní Beseki ni wọ́n ti rí Adoni-Beseki, wọ́n sì bá a jagun, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn ará Kenaani àti Peresi.
Basebefica uAdoni-Bezeki eBezeki, balwa bemelene laye, bawatshaya amaKhanani lamaPerizi.
6 Ọba Adoni-Beseki sá àsálà, ṣùgbọ́n ogun Israẹli lépa rẹ̀ wọ́n sì bá a, wọ́n sì gé àwọn àtàǹpàkò ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀.
Kodwa uAdoni-Bezeki wabaleka, baxotshana laye, bambamba, baquma izithupha zezandla zakhe lamazwane akhe amakhulu.
7 Nígbà náà ni Adoni-Beseki wí pé, “Àádọ́rin ọba ni èmi ti gé àtàǹpàkò wọn tí wọ́n sì ń ṣa èérún oúnjẹ jẹ lábẹ́ tábìlì mi. Báyìí Ọlọ́run ti san án fún mi gẹ́gẹ́ bí ohun tí mo ṣe sí wọn.” Wọ́n sì mú un wá sí Jerusalẹmu, ó sì kú síbẹ̀.
UAdoni-Bezeki wasesithi: Amakhosi angamatshumi ayisikhombisa aqunywe izithupha zezandla zawo lezenyawo zawo ayedobha ngaphansi kwetafula lami. Njengokwenza kwami, ngokunjalo uNkulunkulu ungiphindisele. Basebemusa eJerusalema, wafela khona.
8 Àwọn ológun Juda sì ṣẹ́gun Jerusalẹmu, wọ́n sì kó o, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú, wọ́n sì dáná sun ìlú náà.
Abantwana bakoJuda balwa-ke bemelene leJerusalema, bayithumba, bayitshaya ngobukhali benkemba, lomuzi bawuthungela ngomlilo.
9 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni àwọn ogun Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti bá àwọn ará Kenaani tí ń gbé ní àwọn ìlú orí òkè ní gúúsù àti ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ òkè lápá ìwọ̀-oòrùn Juda jagun.
Emva kwalokho-ke abantwana bakoJuda behla ukuyakulwa bemelene lamaKhanani ayehlala entabeni leningizimu lesihotsheni.
10 Ogun Juda sì tún ṣígun tọ ará Kenaani tí ń gbé Hebroni (tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Kiriati-Arba) ó sì ṣẹ́gun Ṣeṣai, Ahimani àti Talmai.
UJuda wasehamba wamelana lamaKhanani ayehlala eHebroni; lebizo leHebroni kuqala kwakuyiKiriyathi-Arba; batshaya uSheshayi loAhimani loTalimayi.
11 Láti ibẹ̀, wọ́n sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
Basuka lapho baya bamelana labahlali beDebiri. Lebizo leDebiri kuqala kwakuyiKiriyathi-Seferi.
12 Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
UKalebi wasesithi: Ozatshaya iKiriyathi-Seferi, ayithumbe, ngizamnika uAkisa indodakazi yami ibe ngumkakhe.
13 Otnieli ọmọ Kenasi, àbúrò Kalebu sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
UOthiniyeli indodana kaKenazi umfowabo kaKalebi, owayemncane kulaye, waseyithumba; wasemnika uAkisa indodakazi yakhe ukuba ngumkakhe.
14 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
Kwasekusithi ekufikeni kwakhe wamkhuthaza ukuthi acele kuyise insimu; wasesehla kubabhemi, uKalebi wasesithi kuye: Ulani?
15 Aksa sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
Wasesithi kuye: Ngipha isibusiso. Njengoba ungiphe ilizwe leningizimu, ngipha njalo imithombo yamanzi. UKalebi wasemnika imithombo engaphezulu lemithombo engaphansi.
16 Àwọn ìran Keni tí wọ́n jẹ́ àna Mose bá àwọn ọmọ Juda gòkè láti ìlú ọ̀pẹ lọ sí aginjù Juda ní gúúsù Aradi; wọ́n sì lọ, orílẹ̀-èdè méjèèjì sì jùmọ̀ ń gbé pọ̀ láti ìgbà náà.
Abantwana bomKeni, uyisezala kaMozisi, basebesenyuka besuka emzini wamalala, belabantwana bakoJuda, baya enkangala yakoJuda, eseningizimu kweAradi; baya bahlala phakathi kwabantu.
17 Ó sì ṣe, àwọn ológun Juda tẹ̀lé àwọn ológun Simeoni arákùnrin wọn, wọ́n sì lọ bá àwọn ará Kenaani tí ń gbé Sefati jagun, wọ́n sì run ìlú náà pátápátá, ní báyìí àwa yóò pe ìlú náà ní Horma (Horma èyí tí ń jẹ́ ìparun).
UJuda wasehamba loSimeyoni umfowabo, bawatshaya amaKhanani ayehlala eZefathi, bayitshabalalisa. Ngakho ibizo lomuzi lathiwa yiHorma.
18 Àwọn ogun Juda sì ṣẹ́gun Gasa àti àwọn agbègbè rẹ̀, Aṣkeloni àti Ekroni pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó yí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ká.
UJuda wasethumba iGaza lomngcele wayo, leAshikeloni lomngcele wayo, leEkhironi lomngcele wayo.
19 Olúwa sì wà pẹ̀lú ẹ̀yà Juda, wọ́n gba ilẹ̀ òkè, ṣùgbọ́n wọn kò le lé àwọn ènìyàn tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí wọ́n ní kẹ̀kẹ́ ogun onírin.
INkosi yasisiba loJuda, wadla ilifa lezintaba, kodwa wayengelakubaxotsha elifeni abahlali besigodi, ngoba babelezinqola zensimbi.
20 Gẹ́gẹ́ bí Mose ti ṣèlérí, wọ́n fún Kalebu ní Hebroni, ó sì lé àwọn tí ń gbé ibẹ̀ kúrò; àwọn náà ni ìran àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta.
Basebenika uKalebi iHebroni, njengokutsho kukaMozisi; wasexotsha elifeni esuka lapho amadodana amathathu kaAnaki.
21 Àwọn ẹ̀yà Benjamini ni wọn kò le lé àwọn Jebusi tí wọ́n ń gbé Jerusalẹmu, nítorí náà wọ́n ń gbé àárín àwọn Israẹli títí di òní.
Kodwa abantwana bakoBhenjamini kabawaxotshanga elifeni amaJebusi ayehlala eJerusalema; ngakho amaJebusi ahlala labantwana bakoBhenjamini eJerusalema kuze kube lamuhla.
22 Àwọn ẹ̀yà Josẹfu sì bá Beteli jagun, Olúwa síwájú pẹ̀lú wọn.
Lendlu kaJosefa, labo benyukela eBhetheli; njalo iNkosi yayilabo.
23 Nígbà tí ẹ̀yà Josẹfu rán àwọn ènìyàn láti lọ yọ́ Beteli wò (orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí ni Lusi).
Indlu kaJosefa yasithuma inhloli eBhetheli; lebizo lomuzi kuqala laliyiLuzi.
24 Àwọn ayọ́lẹ̀wò náà rí ọkùnrin kan tí ń jáde láti inú ìlú náà wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Fi ọ̀nà àtiwọ ìlú yìí hàn wá, àwa ó sì dá ẹ̀mí rẹ sí, a ó sì ṣe àánú fún ọ.”
Abalindi basebebona umuntu ephuma emzini, bathi kuye: Akusitshengise indlela yokungena emzini, besesikwenzela umusa.
25 Ó sì fi ọ̀nà ìlú náà hàn wọ́n, wọ́n sì fi ojú idà kọlu ìlú náà, ṣùgbọ́n wọ́n dá ọkùnrin náà àti gbogbo ìdílé rẹ̀ si.
Esebatshengise indlela yokungena emzini, bawutshaya umuzi ngobukhali benkemba, kodwa lowomuntu losapho lwakhe lonke babayekela bahamba.
26 Ọkùnrin náà sí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Hiti, ó sì tẹ ìlú kan dó, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Lusi, èyí sì ni orúkọ rẹ̀ títí di òní.
Lowomuntu wasesiya elizweni lamaHethi, wakha umuzi, wabiza ibizo lawo ngokuthi yiLuzi; yilelo ibizo lawo kuze kube lamuhla.
27 Ṣùgbọ́n Manase kò lé àwọn ará Beti-Ṣeani àti ìlú rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jáde, tàbí àwọn ará Taanaki àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Dori àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Ibleamu àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Megido àti àwọn ìgbèríko tí ó yí i ká, torí pé àwọn ará Kenaani ti pinnu láti máa gbé ìlú náà.
UManase kaxotshanga-ke iBeti-Sheyani lemizana yayo, leThahanakhi lemizana yayo, labahlali beDori lemizana yayo, labahlali beIbileyamu lemizana yayo, labahlali beMegido lemizana yayo; kodwa amaKhanani afuna ukuhlala kulelolizwe.
28 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli di alágbára, wọ́n mú àwọn ará Kenaani sìn bí i ẹrú, ṣùgbọ́n wọn kò fi agbára lé wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ náà.
Kwasekusithi uIsrayeli eselamandla wawamisa amaKhanani kusibhalo, kodwa kawaxotshanga lokuwaxotsha elifeni.
29 Efraimu náà kò lé àwọn ará Kenaani tí ó ń gbé Geseri jáde, ṣùgbọ́n àwọn ará Kenaani sì ń gbé láàrín àwọn ẹ̀yà Efraimu.
UEfrayimi kawaxotshanga-ke elifeni amaKhanani ayehlala eGezeri, kodwa amaKhanani ahlala eGezeri phakathi kwabo.
30 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Sebuluni kò lé àwọn ará Kenaani tí ń gbé Kitironi jáde tàbí àwọn ará Nahalali, ṣùgbọ́n wọ́n sọ wọ́n di ẹrú. Wọ́n sì ń sin àwọn ará Sebuluni.
UZebuluni kabaxotshanga elifeni abahlali beKitroni labahlali beNahaloli, kodwa amaKhanani ahlala phakathi kwabo, aba yizibhalwa.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Aṣeri kò lé àwọn tí ń gbé ní Akko tàbí ní Sidoni tàbí ní Ahlabu tàbí ní Aksibu tàbí ní Helba tàbí ní Afiki tàbí ní Rehobu.
UAsheri kabaxotshanga elifeni abahlali beAko labahlali beSidoni leAhilabi leAkizibi leHeliba leAfiki leRehobi;
32 Ṣùgbọ́n nítorí àwọn ará Aṣeri ń gbé láàrín àwọn ará Kenaani tí wọ́n ni ilẹ̀ náà.
kodwa abakoAsheri bahlala phakathi kwamaKhanani abahlali belizwe, ngoba kabawaxotshanga elifeni.
33 Àwọn ẹ̀yà Naftali pẹ̀lú kò lé àwọn ará Beti-Ṣemeṣi àti Beti-Anati jáde; ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Naftali náà ń gbé àárín àwọn ará Kenaani tí ó ti ní ilẹ̀ náà rí, ṣùgbọ́n àwọn tí ń gbé Beti-Ṣemeṣi àti Beti-Anati ń sìn ìsìn tipátipá.
UNafithali kabaxotshanga elifeni abahlali beBeti-Shemeshi labahlali beBeti-Anathi, kodwa wahlala phakathi kwamaKhanani, abahlali belizwe; kodwa abahlali beBeti-Shemeshi labeBeti-Anathi baba yizibhalwa kubo.
34 Àwọn ará Amori fi agbára dá àwọn ẹ̀yà Dani dúró sí àwọn ìlú orí òkè, wọn kò sì jẹ́ kí wọn sọ̀kalẹ̀ wá sí pẹ̀tẹ́lẹ̀.
AmaAmori asebafuqela abantwana bakoDani entabeni, ngoba kawabavumelanga ukwehlela esigodini.
35 Àwọn ará Amori ti pinnu láti dúró lórí òkè Heresi àti òkè Aijaloni àti ti Ṣaalbimu, ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yà Josẹfu di alágbára wọ́n borí Amori wọ́n sì mú wọn sìn.
Kodwa amaAmori ayefuna ukuhlala entabeni yeHeresi eAjaloni leShahalibimi, kodwa isandla sendlu kaJosefa saba nzima, aba yizibhalwa.
36 Ààlà àwọn ará Amori sì bẹ̀rẹ̀ láti ìgòkè Akrabbimu kọjá lọ sí Sela àti síwájú sí i.
Umngcele wamaAmori wawusukela emqansweni weAkirabimi, uvela edwaleni usiya phezulu.