< Judges 9 >
1 Ní ọjọ́ kan Abimeleki ọmọ Jerubbaali lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin ìyá rẹ̀ ní Ṣekemu ó sì bá wọn sọ̀rọ̀ àti gbogbo àwọn ìbátan ìyá rẹ̀ wí pé,
Jerubáalov sin Abiméleh je šel do Sihema, do bratov svoje matere in se z njimi posvetoval in z vso družino hiše očeta svoje matere, rekoč:
2 “Ẹ bi gbogbo àwọn ará Ṣekemu léèrè, ‘Èwo ló sàn fún un yín, ṣé kí gbogbo àwọn àádọ́rin ọmọ Jerubbaali jẹ ọba lórí yín ni tàbí kí ẹnìkan ṣoṣo ṣe àkóso yín?’ Ṣùgbọ́n ẹ rántí pé ẹran-ara yín àti ẹ̀jẹ̀ yín ni èmi ń ṣe.”
»Govorite, prosim vas, na ušesa vsem sihemskim gospodarjem: ›Ali je za vas bolje, da vsi Jerubáalovi sinovi, katerih je sedemdeset oseb, kraljujejo nad vami ali da nad vami kraljuje eden? Spomnite se tudi, da sem jaz vaša kost in vaše meso.‹«
3 Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ sọ èyí ní etí àwọn ará Ṣekemu, ọkàn wọn fà sí àti tẹ̀lé Abimeleki torí, wọ́n sọ wí pé, “Arákùnrin wa ní í ṣe.”
Bratje njegove matere so vse te besede o njem govorili v ušesa vseh sihemskih gospodarjev in njihova srca nagnili, da sledijo Abimélehu, kajti rekli so: »On je naš brat.«
4 Wọ́n fún un ní àádọ́rin ṣékélì fàdákà láti ilé òrìṣà Baali-Beriti, Abimeleki fi owó náà gba àwọn jàǹdùkú àti aláìníláárí ènìyàn tí wọ́n sì di olùtẹ̀lé rẹ̀.
Iz hiše Baal-berita so mu dali sedemdeset koščkov srebra, s katerimi je Abiméleh najel prazno-glave in nepomembne osebe, ki so mu sledili.
5 Ó kó wọn lọ sí ilé baba rẹ̀ ní Ofira, níbẹ̀ ní orí òkúta kan ṣoṣo ni ó ti pa àádọ́rin nínú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn Jerubbaali, ṣùgbọ́n Jotamu, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ Jerubbaali, bọ́ yọ nítorí pé ó sá pamọ́.
Odšel je v hišo svojega očeta pri Ofri in na enem kamnu usmrtil svoje brate, Jerubáalove sinove, ki jih je bilo sedemdeset oseb. Kljub temu pa je ostal najmlajši Jerubáalov sin Jotám, kajti ta se je skril.
6 Gbogbo àwọn ará Ṣekemu àti àwọn ará Beti-Milo pàdé pọ̀ ní ẹ̀bá igi óákù ní ibi òpó ní Ṣekemu láti fi Abimeleki jẹ ọba.
Vsi sihemski gospodarji so se zbrali skupaj in vsa Milójeva hiša in odšli ter Abiméleha postavili za kralja pri ravninskem stebru, ki je bil v Sihemu.
7 Nígbà tí wọ́n sọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ yìí fún Jotamu, ó gun orí ṣóńṣó òkè Gerisimu lọ, ó sì ké lóhùn rara pé, “Ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin àgbàgbà Ṣekemu, kí Ọlọ́run le tẹ́tí sí yín.
Ko so to povedali Jotámu, je ta odšel in se postavil na vrhu gore Garizím, povzdignil svoj glas, zavpil in jim rekel: »Prisluhnite mi, vi sihemski gospodarji, da bo Bog lahko prisluhnil vam.
8 Ní ọjọ́ kan àwọn igi jáde lọ láti fi òróró yan ọba fún ara wọn. Wọ́n pe igi Olifi pé, ‘Wá ṣe ọba wa.’
Drevesa so šla naprej ob času, da mazilijo kralja nad seboj in rekla so oljki: ›Kraljuj nad nami.‹
9 “Ṣùgbọ́n igi Olifi dá wọn lóhùn pé, ‘Èmi yóò ha fi òróró mi sílẹ̀ èyí tí a ń lò láti fi ọ̀wọ̀ fún àwọn ọlọ́run àti ènìyàn kí èmi sì wá ṣe olórí àwọn igi?’
Toda oljka jim je rekla: ›Mar naj zapustim svojo mastnost, s katero po meni častijo Boga in človeka in grem, da bi bila povišana nad drevesa?‹
10 “Àwọn igi sọ fún igi ọ̀pọ̀tọ́ pé, ‘Wá jẹ ọba ní orí wa.’
Drevesa so rekla figovemu drevesu: ›Ti pridi in kraljuj nad nami.‹
11 “Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀tọ́ dá wọn lóhùn pé, ‘Kí èmi fi èso mi tí ó dára tí ó sì dùn sílẹ̀ láti wá ṣe olórí àwọn igi?’
Toda figovo drevo jim je reklo: ›Mar naj zapustim svojo sladkost in svoj dober sad in grem, da bi bilo povišano nad drevesa?‹
12 “Àwọn igi sì tún sọ fún àjàrà pé, ‘Wá, kí o ṣe ọba wa.’
Potem so drevesa rekla trti: ›Ti pridi in kraljuj nad nami.‹
13 “Ṣùgbọ́n àjàrà dáhùn pé, ‘Ṣé kí èmi dẹ́kun àti máa so èso wáìnì mi èyí tí ó ń mú inú Ọlọ́run àti àwọn ènìyàn dùn láti máa ṣe olórí àwọn igi?’
Trta pa jim je rekla: ›Mar naj zapustim svoje vino, ki razveseljuje Boga in človeka in grem, da naj bi bila povišana nad drevesa?‹
14 “Ní ìparí gbogbo àwọn igi lọ bá igi ẹ̀gún wọ́n sì sọ fún un pé, ‘Wá kí ó ṣe ọba wa.’
Potem so vsa drevesa rekla trnovemu grmu: ›Ti pridi in kraljuj nad nami.‹
15 “Igi ẹ̀gún dá àwọn igi lóhùn pé, ‘Bí olóòtítọ́ ni ẹ bá fẹ́ yàn mí ní ọba yín. Ẹ sá àsálà sí abẹ́ ibòòji mi; ṣùgbọ́n tí kì í bá ṣe bẹ́ẹ̀ jẹ́ kí iná jáde láti inú igi ẹ̀gún kí ó sì jó àwọn igi kedari àti ti Lebanoni run!’
Trnov grm je rekel drevesom: ›Če me resnično mazilite za kralja nad seboj, potem pridite in svoje zaupanje položite v mojo senco, in če ne, naj ogenj pride iz trnovega grma in použije libanonske cedre.‹
16 “Báyìí tí ó bá jẹ́ pé ẹ̀yin ṣe ohun tí ó ní ọlá àti pẹ̀lú ẹ̀mí òtítọ́ ní fífi Abimeleki jẹ ọba, tí ó bá ṣe pé ohun tí ó tọ́ ni ẹ ṣe sí Jerubbaali àti ìdílé rẹ̀, bí ẹ bá san ẹ̀san tó yẹ fún un.
Zdaj torej, če ste storili resnično in iskreno v tem, da ste si postavili Abiméleha za kralja in če ste dobro postopali z Jerubáalom in njegovo hišo in mu storili glede na ravnanje njegovih rok
17 Nítorí pé baba mi jà nítorí yín, ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu láti gbà yín sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Midiani;
(kajti moj oče se je bojeval za vas in v ospredju tvegal svoje življenje in vas osvobodil iz roke Midjáncev
18 ṣùgbọ́n lónìí ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí ilé baba mi, ní orí òkúta kan ṣoṣo ni ẹ ti pa àwọn àádọ́rin ọmọ rẹ̀, ẹ̀yin sì ti fi Abimeleki ọmọ ẹrúbìnrin rẹ̀ jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn Ṣekemu nítorí tí ó jẹ́ arákùnrin yín.
in ste ta dan vstali zoper hišo mojega očeta in umorili njegove sinove, sedemdeset oseb na enem kamnu in postavili Abiméleha, sina njegove dekle, za kralja nad sihemskimi gospodarji, ker je vaš brat).
19 Bí ohun tí ẹ ṣe sí Jerubbaali àti ìdílé rẹ̀ bá jẹ́ ohun tí ó yẹ, tí ẹ sì ṣe òtítọ́ inú sí i, kí ẹ ní ayọ̀ nínú Abimeleki kí òun náà sì ní ayọ̀ nínú yín.
Če ste torej ta dan resnično in iskreno postopali z Jerubáalom in njegovo hišo, potem se veselite z Abimélehom in naj se tudi on veseli z vami.
20 Ṣùgbọ́n tí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀ jẹ́ kí iná jó jáde wá láti ọ̀dọ̀ Abimeleki kí ó sì jó yín run. Ẹ̀yin ará Ṣekemu àti ará Beti-Milo, kí iná pẹ̀lú jáde láti ọ̀dọ̀ yín wá ẹ̀yin ará Ṣekemu àti ará Beti-Milo kí ó sì jó Abimeleki run.”
Toda če ne, naj ogenj pride od Abiméleha in pogoltne sihemske gospodarje in Milójevo hišo. In ogenj naj pride od sihemskih gospodarjev in od Milójeve hiše in požre Abiméleha.
21 Lẹ́yìn tí Jotamu ti sọ èyí tan, ó sá àsálà lọ sí Beeri, ó sì gbé níbẹ̀ nítorí ó bẹ̀rù arákùnrin rẹ̀ Abimeleki.
Jotám je stekel proč, pobegnil in odšel v Beêr in tam prebival zaradi strahu pred svojim bratom Abimélehom.
22 Lẹ́yìn tí Abimeleki ti ṣe àkóso Israẹli fún ọdún mẹ́ta,
Ko je Abiméleh tri leta kraljeval nad Izraelom,
23 Ọlọ́run rán ẹ̀mí búburú sáàárín Abimeleki àti àwọn ará Ṣekemu, àwọn ẹni tí ó hu ìwà ọ̀tẹ̀.
je potem Bog med Abiméleha in sihemske gospodarje poslal zlega duha in sihemski gospodarji so zahrbtno postopali z Abimélehom,
24 Ọlọ́run ṣe èyí láti gbẹ̀san àwọn ìwà búburú, àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ àwọn àádọ́rin ọmọ Jerubbaali lára Abimeleki arákùnrin wọn àti lára àwọn ènìyàn Ṣekemu, ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́ láti pa àwọn arákùnrin rẹ̀.
da bi ta krutost, storjena sedemdesetim Jerubáalovim sinovom lahko prišla in bi bila njihova kri položena na njihovega brata Abiméleha, ki jih je umoril in na sihemske gospodarje, ki so mu pomagali pri morjenju njegovih bratov.
25 Nítorí ìkórìíra tí wọ́n ni sí àwọn olórí, ni Ṣekemu dẹ àwọn ènìyàn sí àwọn orí òkè láti máa dá àwọn ènìyàn tó ń kọjá lọ́nà, kí wọn sì máa jà wọ́n lólè, àwọn kan ló sọ èyí fún Abimeleki.
Sihemski gospodarji so zanj postavili prežavce v zasedi na vrhu gora in ti so oropali vse, ki so mimo njih prišli po tej poti, in to je bilo povedano Abimélehu.
26 Gaali ọmọ Ebedi àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wá sí Ṣekemu, àwọn ará Ṣekemu sì gbẹ́kẹ̀lé wọn, wọ́n sì fi inú tán wọn.
Ebedov sin Gáal je prišel s svojimi brati in odšel preko v Sihem in sihemski gospodarji so svoje zaupanje položili vanj.
27 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde lọ sí oko, wọ́n sì ṣa èso àjàrà wọn jọ, wọ́n fún èso àjàrà náà, wọ́n sì ṣe àjọ̀dún nínú ilé òrìṣà wọn. Nígbà tí wọ́n ń jẹ tí wọ́n ń mu wọ́n fi Abimeleki ré.
Odšli so ven na polja in obrali svoje vinograde in tlačili grozdje in se veselili in odšli v hišo svojega boga, jedli, pili in preklinjali Abiméleha.
28 Gaali ọmọ Ebedi dáhùn pé, “Ta ni Abimeleki tàbí ta ni Ṣekemu tí àwa ó fi sìn ín? Ọmọ Jerubbaali kọ́ ní ṣe tàbí Sebulu kọ́ ní igbákejì rẹ̀? Ẹ má sin àwọn ará Hamori baba àwọn ará Ṣekemu, èéṣe tí a ó fi sin Abimeleki?
Ebedov sin Gáal je rekel: »Kdo je Abiméleh in kdo je Sihem, da bi mu služili? Mar ni on Jerubáalov sin? In Zebúl njegov častnik? Služite možem Sihemovega očeta Hamórja, kajti zakaj bi mi služili njemu?
29 Ìbá se pé àwọn ènìyàn yìí wà ní abẹ́ ìṣàkóso mi ni! Èmi ìbá bọ́ àjàgà rẹ̀ kúrò ní ọrùn yín. Èmi yóò wí fún Abimeleki pé, ‘Kó gbogbo àwọn ogun rẹ jáde láti jà.’”
Bog daj, da bi bilo to ljudstvo pod mojo roko! Potem bi odstranil Abiméleha.« In Abimélehu je rekel: »Okrepi svojo vojsko in pridi ven.«
30 Nígbà tí Sebulu, alákòóso ìlú náà gbọ́ ohun tí Gaali ọmọ Ebedi sọ, inú bí i gidigidi.
Ko je Zebúl, vladar mesta, slišal besede Ebedovega sina Gáala, je bila njegova jeza vžgana.
31 Ó ránṣẹ́ sí Abimeleki pé, “Gaali ọmọ Ebedi àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wá láti máa gbé ní Ṣekemu ṣùgbọ́n, wọ́n ń rú àwọn ènìyàn sókè láti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.
Na skrivnem je poslal poslance k Abimélehu, rekoč: »Glej, Ebedov sin Gáal in njegovi bratje so prišli v Sihem in glej, zoper tebe utrjujejo mesto.
32 Wá ní òru kí ìwọ àti àwọn ogun rẹ sá pamọ́ dè wọ́n nínú igbó.
Zdaj se torej dvigni ponoči ti in ljudstvo, ki je s teboj in na polju prežite v zasedi
33 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù bí oòrùn ti ń yọ ìwọ yóò wọ inú ìlú náà lọ láti bá a jà. Yóò sì ṣe nígbà tí Gaali àti àwọn ogun rẹ̀ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ bá jáde sí ọ láti bá ọ jà, ìwọ yóò ṣe ohunkóhun tí o bá fẹ́ sí wọn.”
in zgodilo se bo, da zjutraj, takoj ko bo sonce vzšlo, da boš zgodaj vstal in se nameril na mesto. In glej, ko bodo on in ljudstvo, ki je z njim, prišli ven zoper tebe, potem jim boš lahko storil kakor boš našel priložnost.«
34 Abimeleki àti gbogbo àwọn ogun rẹ̀ sì jáde ní òru, wọ́n sì sá pamọ́ sí ọ̀nà mẹ́rin yí Ṣekemu ká.
Abiméleh je ponoči vstal in vse ljudstvo, ki je bilo z njim in so v štirih skupinah prežali zoper Sihem.
35 Gaali ọmọ Ebedi jáde síta, ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ibodè ìlú náà ní àkókò tí Abimeleki àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jáde kúrò níbi tí wọn sá pamọ́ sí.
Ebedov sin Gáal je odšel ven in stal v vhodu velikih vrat mesta. Abiméleh in ljudstvo, ki je bilo z njim, pa je vstalo od prežanja.
36 Nígbà tí Gaali rí àwọn ènìyàn náà, ó sọ fún Sebulu pé, “Wò ó, àwọn ènìyàn ń ti orí òkè sọ̀kalẹ̀ wá!” Sebulu sì wí fún un pé, “Òjìji òkè wọ̀n-ọn-nì ni ìwọ rí bi ẹni pé ènìyàn.”
Ko je Gáal zagledal ljudstvo, je rekel Zebúlu: »Glej, tam prihaja ljudstvo dol iz vrha gorovja.« Zebúl mu je rekel: »Senco gorovja vidiš, kakor bi bili možje.«
37 Gaali ké ó ní, “Wòkè, àwọn ènìyàn ń tọ̀ wá bọ̀ láti agbede-méjì ilẹ̀ wá àti ẹ̀gbẹ́ kan sì ń ti ọ̀nà igi óákù Meonenimu wá.”
Gáal je ponovno spregovoril in rekel: »Vidiš, tam prihaja dol ljudstvo po sredi dežele in druga skupina prihaja vzdolž ravnine Maonim.«
38 Nígbà náà ni Sebulu dá a lóhùn pé, “Níbo ni ẹnu tí ó ń ṣe ni wà báyìí. Ṣe bí o wí pé, ‘Ta ni Abimeleki tí àwa ó fi máa sìn ín?’ Àwọn ẹni tí ó gàn án kọ́ nìyí? Jáde lọ kí o sì bá wọn jà!”
Potem mu je Zebúl rekel: »Kje so sedaj tvoja usta, s katerimi praviš: ›Kdo je Abiméleh, da bi mu služili?‹ Mar ni to ljudstvo, ki si ga preziral? Pojdi sedaj ven, prosim te in se bori z njimi.«
39 Gaali sì síwájú àwọn ogun ará Ṣekemu lọ kọjú Abimeleki láti bá wọn jagun.
Gáal je odšel ven pred sihemskimi gospodarji in se boril z Abimélehom.
40 Abimeleki sì lé e, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun ṣubú wọ́n sì gbọgbẹ́ bí wọ́n ṣe ń sálọ, títí dé ẹnu-ọ̀nà ibùdó ìlú náà.
Abiméleh ga je pregnal in ta je pobegnil pred njim in mnogi so bili zrušeni in ranjeni, celó do vhoda velikih vrat.
41 Abimeleki dúró sí Aruma, nígbà tí Sebulu lé Gaali àti àwọn arákùnrin rẹ̀ kúrò ni Ṣekemu, kò sì jẹ́ kí wọ́n gbé Ṣekemu mọ́.
Abiméleh je prebival pri Arúmi, Zebúl pa je vrgel ven Gáala in njegove brate, da ne bi prebivali v Sihemu.
42 Ní ọjọ́ kejì àwọn ará Ṣekemu sì jà lọ́ sí oko, ẹnìkan ló ṣe òfófó rẹ̀ fún Abimeleki.
Naslednji dan se je pripetilo, da je ljudstvo odšlo ven na polje in povedali so Abimélehu.
43 Ó kó àwọn ènìyàn rẹ̀, ó pín wọn sí ẹgbẹ́ mẹ́ta ó sì sá pamọ́ sí inú oko. Nígbà tí ó sì rí tí àwọn ènìyàn náà ń jáde kúrò nínú ìlú, ó dìde ó gbóguntì wọ́n.
Ta je vzel ljudstvo in jih razdelil v tri skupine. Na polju so prežali v zasedi in glej, ljudstvo je prišlo ven iz mesta. Vstal je zoper njih in jih udaril.
44 Abimeleki àti àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sáré síwájú, wọ́n gba ẹnu ibodè ìlú náà, wọ́n sì dúró níbẹ̀. Àwọn ẹgbẹ́ méjì tókù sì sáré sí àwọn tó wà ní oko wọ́n sì gbóguntì wọ́n.
Abiméleh in skupina, ki je bila z njim, je pohitela naprej in stala na vhodu velikih vrat mesta in dve drugi skupini sta stekli nad vse ljudstvo, ki je bilo na poljih in jih usmrtili.
45 Ní gbogbo ọjọ́ náà ni Abimeleki fi bá àwọn ará ìlú náà jà, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa àwọn ènìyàn ìlú náà ó wó ìlú náà palẹ̀ pátápátá ó sì fọ́n iyọ̀ sí i.
Abiméleh se je ves tisti dan boril zoper mesto, zavzel mesto, usmrtil ljudstvo, ki je bilo v njem, premagal mesto in ga potresel s soljo.
46 Àwọn ènìyàn ilé ìṣọ́ Ṣekemu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, wọ́n sálọ fún ààbò sí inú ilé ìṣọ́ òrìṣà El-Beriti.
Ko so vsi gospodarji sihemskega stolpa to slišali, so vstopili v trdnjavo hiše boga Berita.
47 Nígbà tí wọ́n sọ fún Abimeleki pé gbogbo àwọn ènìyàn ilé ìṣọ́ Ṣekemu kó ara wọn jọ pọ̀.
To je bilo povedano Abimélehu, da so bili vsi gospodarji sihemskega stolpa zbrani skupaj.
48 Abimeleki àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ gun òkè Salmoni lọ. Ó gé àwọn ẹ̀ka díẹ̀ pẹ̀lú àáké, ó gbé àwọn ẹ̀ka wọ̀nyí sí èjìká rẹ̀. Ó sọ fún àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ pé, “Ẹ ṣe ohun tí ẹ rí tí mo ń ṣe yìí ní kíákíá.”
Abiméleh se je povzpel na goro Calmón, on in vse ljudstvo, ki je bilo z njim in Abiméleh je v svojo roko vzel sekiro, odsekal vejo iz dreves, jo vzel in jo položil na svojo ramo in rekel ljudstvu, ki je bilo z njim: »Kar ste videli storiti mene, pohitite in storite, kakor sem storil jaz.«
49 Báyìí gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ gé àwọn ẹ̀ka igi wọn tẹ̀lé Abimeleki. Wọ́n kó wọn ti ilé ìṣọ́ agbára níbi tí àwọn ènìyàn sá pamọ́ sí wọ́n sì fi iná sí i, tóbẹ́ẹ̀ tí gbogbo àwọn ọkùnrin ilé ìṣọ́ Ṣekemu fi kú pẹ̀lú. Gbogbo àwọn ènìyàn náà tí ó tó ẹgbẹ̀rún ènìyàn lọ́kùnrin àti lóbìnrin sì kú.
Podobno je vse ljudstvo odsekalo vsak svojo vejo, sledilo Abimélehu, jih položili k trdnjavi in zažgali trdnjavo nad njimi. Tako da so umrli tudi vsi ljudje iz sihemskega stolpa, okoli tisoč mož in žena.
50 Abimeleki tún lọ sí Tebesi, ó yí ìlú náà ká pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun, ó sì ṣẹ́gun rẹ̀.
Potem je Abiméleh odšel v Tebéc, se utaboril zoper Tebéc in ga zavzel.
51 Ilé ìṣọ́ kan tí ó ní agbára sì wà nínú ìlú náà. Gbogbo àwọn ènìyàn ìlú náà ọkùnrin àti obìnrin sá sínú ilé ìṣọ́ náà. Wọ́n ti ara wọn mọ́ ibẹ̀ wọ́n sì sálọ sí inú àjà ilé ìṣọ́ náà.
Toda tam, znotraj mesta, je bil močan stolp in tja so pobegnili vsi možje in žene in vsi iz mesta in ga za seboj zaprli in se spravili na vrh stolpa.
52 Abimeleki lọ sí ìsàlẹ̀ ilé ìṣọ́ náà, ó sì ń bá a jà. Ṣùgbọ́n bí ó ti súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé ìṣọ́ náà láti dáná sun ún,
Abiméleh je prišel k stolpu, se boril zoper njega in se približal vratom stolpa, da bi ga zažgal z ognjem.
53 obìnrin kan sọ ọmọ ọlọ lu Abimeleki lórí, ó sì fọ́ ọ ní agbárí.
Neka ženska je kos mlinskega kamna vrgla na Abimélehovo glavo in razbila njegovo lobanjo.
54 Ní ojú kan náà ni ó pe ẹni tí ó ru àpáta rẹ̀ pé, “Yára yọ idà rẹ kí o sì pa mí, kí wọn má ba à sọ pé, ‘Obìnrin ni ó pa á.’” Ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì fi ọ̀kọ̀ gún un, ó sì kú.
Potem je naglo zaklical k mladeniču, svojemu nosilcu bojne opreme in mu rekel: »Izvleci svoj meč in me usmrti, da ne bodo ljudje o meni rekli: ›Ubila ga je ženska.‹« In njegov mladenič ga je prebodel in ta je umrl.
55 Nígbà tí àwọn ará Israẹli rí i pé Abimeleki kú, olúkúlùkù wọn padà sí ilé rẹ̀.
Ko so možje iz Izraela videli, da je bil Abiméleh mrtev, so odšli vsak mož na svoj kraj.
56 Báyìí ni Ọlọ́run san ẹ̀san ìwà búburú ti Abimeleki hù sí baba rẹ̀ ní ti pípa tí ó pa, àwọn àádọ́rin arákùnrin rẹ̀.
Tako je Bog povrnil Abimélehovo zlobnost, ki jo je storil svojemu očetu z umorom svojih sedemdesetih bratov
57 Ọlọ́run jẹ́ kí ìwà búburú àwọn ará Ṣekemu pẹ̀lú padà sí orí wọn. Ègún Jotamu ọmọ Jerubbaali pàápàá wá sí orí wọn.
in vse zlo sihemskih ljudi je Bog povrnil na njihove glave in nadnje je prišlo prekletstvo Jerubáalovega sina Jotáma.