< Judges 8 >

1 Àwọn àgbàgbà ẹ̀yà Efraimu sì bínú gidigidi sí Gideoni wọ́n bi í léèrè pé, kí ló dé tí o fi ṣe irú èyí sí wa? Èéṣe tí ìwọ kò fi pè wá nígbà tí ìwọ kọ́kọ́ jáde lọ láti bá àwọn ará Midiani jagun? Ohùn ìbínú ni wọ́n fi bá a sọ̀rọ̀.
Efrayimoğulları Gidyon'a, “Midyanlılar'la savaşmaya gittiğinde bizi çağırmadın; bize neden böyle davrandın?” diyerek onu sert bir dille eleştirdiler.
2 Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Àṣeyọrí wo ni mo ti ṣe tí ó tó fiwé tiyín? Àṣàkù àjàrà Efraimu kò ha dára ju gbogbo ìkórè àjàrà Abieseri lọ bí?
Gidyon, “Sizin yaptığınızın yanında benim yaptığım ne ki?” diye karşılık verdi, “Efrayim'in bağbozumundan artakalan üzümler, Aviezer'in bütün bağbozumu ürününden daha iyi değil mi?
3 Ọlọ́run ti fi Orebu àti Seebu àwọn olórí àwọn ará Midiani lé yín lọ́wọ́. Kí ni ohun tí Mose ṣe tí ó tó fiwé e yín tàbí tí ó tó àṣeyọrí i yín?” Nígbà tí ó wí èyí ríru ìbínú wọn rọlẹ̀.
Tanrı Midyan önderlerini, Orev'i ve Zeev'i elinize teslim etti. Sizin yaptıklarınıza kıyasla ben ne yapabildim ki?” Gidyon'un bu sözleri onların öfkesini yatıştırdı.
4 Gideoni àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ̀síwájú láti lépa àwọn ọ̀tá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ̀ wọ́n, wọ́n dé Jordani wọ́n sì kọjá sí òdìkejì.
Gidyon bitkin olmalarına karşın Midyanlılar'ı kovalamayı sürdüren üç yüz adamıyla Şeria Irmağı'na ulaşıp karşıya geçti.
5 Ó wí fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Ẹ fún àwọn ọmọ-ogun mi ní oúnjẹ díẹ̀, nítorí ó ti rẹ̀ wọ́n, èmi sì ń lépa Seba àti Salmunna àwọn ọba Midiani.”
Sukkot'a vardıklarında kent halkına, “Lütfen ardımdaki adamlara ekmek verin, bitkin haldeler” dedi, “Ben Midyan kralları Zevah ve Salmunna'yı kovalıyorum.”
6 Ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Sukkoti fèsì pé ṣé ọwọ́ rẹ ti tẹ Seba àti Salmunna náà ni? Èéṣe tí àwa yóò ṣe fún àwọn ológun rẹ ní oúnjẹ?
Sukkot önderleri, “Zevah ile Salmunna'yı tutsak aldın mı ki, orduna ekmek verelim?” dediler.
7 Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Ó dára, nígbà tí Olúwa bá fi Seba àti Salmunna lé mi lọ́wọ́ tán èmi yóò fi ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún òṣùṣú ya ẹran-ara yín.”
Gidyon, “Öyle olsun!” diye karşılık verdi, “RAB Zevah ile Salmunna'yı elime teslim edince, bedenlerinizi çöl dikenleriyle, çalılarla yaracağım.”
8 Láti ibẹ̀, ó lọ sí Penieli ó sì bẹ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ṣùgbọ́n àwọn náà dá a lóhùn bí àwọn ará Sukkoti ti dá a lóhùn.
Gidyon oradan Penuel'e gitti ve oranın halkından da aynı şeyi istedi. Penuel halkı da Sukkot halkının verdiği yanıtın aynısını verdi.
9 Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ọkùnrin Penieli pé, “Nígbà tí mo bá ṣẹ́gun tí mo sì padà dé ní àlàáfíà, èmi yóò wó ilé ìṣọ́ yìí.”
Gidyon onlara, “Esenlik içinde döndüğüm zaman bu kuleyi yıkacağım” dedi.
10 Ní àsìkò náà Seba àti Salmunna wà ní Karkori pẹ̀lú ọmọ-ogun wọn tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọkùnrin, àwọn wọ̀nyí ni ó ṣẹ́kù nínú gbogbo ogun àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn, nítorí ọ̀kẹ́ mẹ́fà ọkùnrin tí ó fi idà jà ti kú ní ojú ogun.
Zevah ile Salmunna doğulu halkların ordularından artakalan yaklaşık on beş bin kişilik bir orduyla birlikte Karkor'daydılar. Eli kılıç tutan yüz yirmi bin savaşçı ölmüştü.
11 Gideoni gba ọ̀nà tí àwọn darandaran máa ń rìn ní apá ìhà ìlà-oòrùn Noba àti Jogbeha ó sì kọjú ogun sí àwọn ọmọ-ogun náà nítorí wọ́n ti túra sílẹ̀.
Gidyon Novah ve Yogboha'nın doğusundan, göçebelerin yolundan geçerek düşman ordugahına saldırdı. Adamlar hazırlıksız yakalandılar.
12 Seba àti Salmunna, àwọn ọba Midiani méjèèjì sá, ṣùgbọ́n Gideoni lépa wọn ó sì mú wọn, ó run gbogbo ogun wọn.
Zevah ile Salmunna kaçtıysa da Gidyon peşlerine düştü. Bu iki Midyan kralını, Zevah ile Salmunna'yı yakalayıp bütün ordularını bozguna uğrattı.
13 Gideoni ọmọ Joaṣi gba ọ̀nà ìgòkè Heresi padà sẹ́yìn láti ojú ogun.
Yoaş oğlu Gidyon Heres Geçidi yoluyla savaştan döndü.
14 Ó mú ọ̀dọ́mọkùnrin kan ará Sukkoti, ó sì béèrè àwọn ìbéèrè ní ọwọ́ rẹ̀, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì kọ orúkọ àwọn ìjòyè Sukkoti mẹ́tàdínlọ́gọ́rin fún un tí wọ́n jẹ́ àgbàgbà ìlú náà.
Yolda Sukkot'tan genç bir adamı yakalayıp sorguya çekti. Adam Sukkot önderleriyle ileri gelenlerinin adlarını, toplam yetmiş yedi kişinin adını yazıp Gidyon'a verdi.
15 Nígbà náà ni Gideoni wá ó sọ fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Seba àti Salmunna nìwọ̀nyí nípa àwọn tí ẹ̀yin fi mí ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ẹ wí pé, ‘Ṣé ó ti ṣẹ́gun Seba àti Salmunna? Èéṣe tí àwa ó fi fún àwọn ọmọ-ogun rẹ tí ó ti rẹ̀ ní oúnjẹ?’”
Gidyon Sukkot'a gidip halka şöyle dedi: “‘Zevah ile Salmunna'yı tutsak aldın mı ki bitkin adamlarına ekmek verelim’ diyerek beni aşağıladınız. İşte Zevah ile Salmunna!”
16 Ó mú àwọn àgbàgbà ìlú náà, ó sì fi kọ́ àwọn Sukkoti lọ́gbọ́n nípa jíjẹ wọ́n ní yà pẹ̀lú àwọn ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún ọ̀gàn.
Sonra kentin ileri gelenlerini topladı; Sukkot halkını çöl dikenleriyle, çalılarla döverek cezalandırdı.
17 Ó wó ilé ìṣọ́ Penieli, ó sì pa àwọn ọkùnrin ìlú náà.
Ardından Penuel Kulesi'ni yıkıp kent halkını kılıçtan geçirdi.
18 Gideoni bi Seba àti Salmunna pé, “Irú ọkùnrin tí ẹ pa ní Tabori, báwo ni wọ́n ṣe rí?” “Àwọn ọkùnrin náà dàbí rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dàbí ọmọ ọba,” ní ìdáhùn wọn.
Sonra Zevah ile Salmunna'ya, “Tavor'da öldürdükleriniz nasıl adamlardı?” diye sordu. “Tıpkı senin gibiydiler, hepsi kral oğullarına benziyordu” yanıtını verdiler.
19 Gideoni dáhùn pé, “Arákùnrin mi ni wọ́n, àwọn ọmọ ìyá mi. Mo fi Olúwa búra, bí ó bá ṣe pé ẹ dá ẹ̀mí wọn sí, èmi náà ò nípa yín.”
Gidyon, “Onlar kardeşlerimdi, öz annemin oğullarıydı” dedi, “Yaşayan RAB'bin adıyla ant içerim ki, onları sağ bıraksaydınız sizi öldürmezdim.”
20 Ó yí padà sí Jeteri, ọmọ rẹ̀ tí ó dàgbà jùlọ, ó wí fún un pé, “Pa wọ́n!” Ṣùgbọ́n Jeteri kò fa idà rẹ̀ yọ láti pa wọ́n nítorí ó jẹ́ ọ̀dọ́mọdé ẹ̀rù sì bà á láti pa wọ́n.
Sonra büyük oğlu Yeter'e, “Haydi, öldür onları” dedi. Ne var ki, henüz genç olan Yeter korktu, kılıcını çekmedi.
21 Seba àti Salmunna dá Gideoni lóhùn pé, “Wá pa wá fún raàrẹ, ‘Nítorí bí ènìyàn bá ti rí bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóò rí.’” Gideoni bọ́ síwájú ó sì pa wọ́n, ó sì mú ohun ọ̀ṣọ́ tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
Bunun üzerine Zevah ile Salmunna Gidyon'a, “Sen öldür bizi” dediler, “Erkeğin işini ancak erkek yapar.” Böylece Gidyon varıp Zevah ile Salmunna'yı öldürdü. Develerinin boyunlarındaki hilal biçimi süsleri de aldı.
22 Àwọn ará Israẹli wí fún Gideoni pé, “Jọba lórí wa—ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ pẹ̀lú, nítorí tí ìwọ ti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ará Midiani.”
İsrailliler Gidyon'a, “Sen, oğlun ve torunun bize önderlik edin” dediler. “Çünkü bizi Midyanlılar'ın elinden sen kurtardın.”
23 Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Èmi kì yóò jẹ ọba lórí yín, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ mi kì yóò jẹ ọba lórí yín. Olúwa ni yóò jẹ ọba lórí yín.”
Ama Gidyon, “Ben size önderlik etmem, oğlum da etmez” diye karşılık verdi, “Size RAB önderlik edecek.”
24 Gideoni sì wí pé, “Mo ní ẹ̀bẹ̀ kan tí mo fẹ́ bẹ̀ yín kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín fún mi ní yẹtí kọ̀ọ̀kan láti inú ohun ti ó kàn yín láti inú ìkógun.” (Àṣà àwọn ará Iṣmaeli ni láti máa fi yẹtí wúrà sétí.)
Sonra, “Yalnız sizden bir dileğim var” diye sözünü sürdürdü, “Ele geçirdiğiniz ganimetin içindeki küpeleri bana verin.” –İsmaililer altın küpeler takarlardı.–
25 Wọ́n dáhùn pé, “Tayọ̀tayọ̀ ni àwa yóò fi wọ́n sílẹ̀.” Wọ́n tẹ́ aṣọ kan sílẹ̀ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan sì ń sọ yẹtí kọ̀ọ̀kan tí ó kàn wọ́n láti ibi ìkógun síbẹ̀.
İsrailliler, “Seve seve veririz” diyerek yere bir üstlük serdiler. Herkes ele geçirdiği küpeleri üstlüğün üzerine attı.
26 Ìwọ̀n òrùka wúrà tí ó béèrè fún tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ìwọ̀n ṣékélì, láìka àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àti ohun sísorọ̀ tí ó wà lára ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn àti aṣọ elése àlùkò tí àwọn ọba Midiani ń wọ̀ tàbí àwọn ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
Hilaller, kolyeler, Midyan krallarının giydiği mor giysiler ve develerin boyunlarından alınan zincirler dışında, Gidyon'un aldığı altın küpelerin ağırlığı bin yedi yüz şekel tuttu.
27 Gideoni fi àwọn wúrà náà ṣe efodu èyí tí ó gbé kalẹ̀ ní Ofira ìlú rẹ̀. Àwọn ọmọ Israẹli sì sọ ara wọn di àgbèrè nípa sínsin-ín ní ibẹ̀. Ó sì di ìdẹ̀kùn fún Gideoni àti ìdílé rẹ̀.
Gidyon bu altından bir efod yaparak onu kendi kenti olan Ofra'ya yerleştirdi. Bütün İsrailliler bu put yüzünden RAB'be vefasızlık ettiler. Böylece efod Gidyon ile ailesi için bir tuzak oldu.
28 Báyìí ni a ṣe tẹrí àwọn ará Midiani ba níwájú àwọn ọmọ Israẹli bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tún gbé orí mọ́. Ní ọjọ́ Gideoni, Israẹli wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún.
İsrailliler'e yenilen Midyanlılar bir daha toparlanamadılar. Ülke Gidyon zamanında kırk yıl barış içinde yaşadı.
29 Jerubbaali ọmọ Joaṣi padà lọ láti máa gbé ní ìlú rẹ̀.
Yoaş oğlu Yerubbaal dönüp kendi evinde yaşamını sürdürdü.
30 Àádọ́rin ọmọ ni Gideoni bí, nítorí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìyàwó.
Çok sayıda kadınla evlendi ve yetmiş oğlu oldu.
31 Àlè rẹ̀, tó ń gbé ní Ṣekemu, pàápàá bí ọmọkùnrin kan fún un tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Abimeleki.
Ayrıca Şekem'de bir cariyesi vardı. Bundan da bir oğlu oldu, adını Avimelek koydu.
32 Gideoni ọmọ Joaṣi kú ní ògbólógbòó ọjọ́ rẹ̀, ó sì pọ̀ ní ọjọ́ orí, wọ́n sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀ ní Ofira ti àwọn ará Abieseri.
Yoaş oğlu Gidyon iyice yaşlanıp öldü. Aviezerliler'e ait Ofra Kenti'nde, babası Yoaş'ın mezarına gömüldü.
33 Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gideoni ni àwọn ará Israẹli ṣe àgbèrè tọ Baali lẹ́yìn, wọ́n fi Baali-Beriti ṣe òrìṣà wọn.
Gidyon ölünce İsrailliler yine RAB'be vefasızlık ettiler. Baallar'a taptılar. Baal-Berit'i ilah edinerek
34 Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.
kendilerini çevrelerindeki düşmanlarının elinden kurtaran Tanrıları RAB'bi unuttular.
35 Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jerubbaali (èyí ni Gideoni) fún gbogbo oore tí ó ṣe fún wọn.
İsrail'e büyük iyilikler yapan Yerubbaal'ın –Gidyon'un– ev halkına vefasızlık ettiler.

< Judges 8 >