< Judges 8 >

1 Àwọn àgbàgbà ẹ̀yà Efraimu sì bínú gidigidi sí Gideoni wọ́n bi í léèrè pé, kí ló dé tí o fi ṣe irú èyí sí wa? Èéṣe tí ìwọ kò fi pè wá nígbà tí ìwọ kọ́kọ́ jáde lọ láti bá àwọn ará Midiani jagun? Ohùn ìbínú ni wọ́n fi bá a sọ̀rọ̀.
I rzekli do niego mężowie z Efraim: Przeczżeś to nam uczynił, iżeś nas nie wezwał, gdyś szedł walczyć przeciwko Madyjanitom? i swarzyli się z nim srodze.
2 Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Àṣeyọrí wo ni mo ti ṣe tí ó tó fiwé tiyín? Àṣàkù àjàrà Efraimu kò ha dára ju gbogbo ìkórè àjàrà Abieseri lọ bí?
A on rzekł: Cóżem ja takiego uczynił, jako wy? izali nie lepsze jest poślednie zbieranie wina Efraimowe, niż pierwsze zbieranie Abieserowe?
3 Ọlọ́run ti fi Orebu àti Seebu àwọn olórí àwọn ará Midiani lé yín lọ́wọ́. Kí ni ohun tí Mose ṣe tí ó tó fiwé e yín tàbí tí ó tó àṣeyọrí i yín?” Nígbà tí ó wí èyí ríru ìbínú wọn rọlẹ̀.
W rękę waszą podał Bóg książęta Madyjańskie, Oreba i Zeba; i cóżem mógł takiego uczynić, jako wy? Tedy się uśmierzył duch ich przeciw niemu, gdy mówił te słowa.
4 Gideoni àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ̀síwájú láti lépa àwọn ọ̀tá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ̀ wọ́n, wọ́n dé Jordani wọ́n sì kọjá sí òdìkejì.
A gdy przyszedł Giedeon do Jordanu, przeprawił się przezeń sam, i trzy sta mężów, którzy z nim byli spracowani w pogoni.
5 Ó wí fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Ẹ fún àwọn ọmọ-ogun mi ní oúnjẹ díẹ̀, nítorí ó ti rẹ̀ wọ́n, èmi sì ń lépa Seba àti Salmunna àwọn ọba Midiani.”
I rzekł do mieszczan w Sokot: Dajcie proszę po bochenku chleba ludowi, który idzie za mną, bo są spracowani, a ja będę gonił Zebeę i Salmana, króle Madyjańskie.
6 Ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Sukkoti fèsì pé ṣé ọwọ́ rẹ ti tẹ Seba àti Salmunna náà ni? Èéṣe tí àwa yóò ṣe fún àwọn ológun rẹ ní oúnjẹ?
Ale mu rzekli przedniejsi z Sokot: Izali już moc Zeby i Salmana jest w rękach twoich, żebyśmy dać mieli wojsku twemu chleba?
7 Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Ó dára, nígbà tí Olúwa bá fi Seba àti Salmunna lé mi lọ́wọ́ tán èmi yóò fi ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún òṣùṣú ya ẹran-ara yín.”
Którym rzekł Giedeon: Więc kiedy poda Pan Zebeę i Salmana w rękę moję, tedy będę młócił ciała wasze cierniem z tej puszczy i ostem.
8 Láti ibẹ̀, ó lọ sí Penieli ó sì bẹ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ṣùgbọ́n àwọn náà dá a lóhùn bí àwọn ará Sukkoti ti dá a lóhùn.
Szedł zasię stamtąd do Fanuel, i mówił także do nich; ale mu odpowiedzieli mężowie z Fanuel, jako odpowiedzieli mężowie w Sokot.
9 Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ọkùnrin Penieli pé, “Nígbà tí mo bá ṣẹ́gun tí mo sì padà dé ní àlàáfíà, èmi yóò wó ilé ìṣọ́ yìí.”
Tedy też powiedział mężom z Fanuel, mówiąc: Gdy się wrócę w pokoju, rozwalę tę wieżę.
10 Ní àsìkò náà Seba àti Salmunna wà ní Karkori pẹ̀lú ọmọ-ogun wọn tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọkùnrin, àwọn wọ̀nyí ni ó ṣẹ́kù nínú gbogbo ogun àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn, nítorí ọ̀kẹ́ mẹ́fà ọkùnrin tí ó fi idà jà ti kú ní ojú ogun.
Ale Zebee i Salmana byli w Karkor, i wojska ich z nimi około piętnastu tysięcy, wszyscy, którzy byli pozostali ze wszystkiego wojska z ludzi od wschodu słońca; a pobitych było sto i dwadzieścia tysięcy mężów walecznych.
11 Gideoni gba ọ̀nà tí àwọn darandaran máa ń rìn ní apá ìhà ìlà-oòrùn Noba àti Jogbeha ó sì kọjú ogun sí àwọn ọmọ-ogun náà nítorí wọ́n ti túra sílẹ̀.
Tedy ciągnął Giedeon drogą tych, co mieszkali w namiociech, od wschodu słońca Nobe i Jegbaa, i uderzył na obóz, (a obóz się był ubezpieczył, )
12 Seba àti Salmunna, àwọn ọba Midiani méjèèjì sá, ṣùgbọ́n Gideoni lépa wọn ó sì mú wọn, ó run gbogbo ogun wọn.
A uciekli Zebee i Salmana, i gonił je, i pojmał onych dwóch królów Madyjańskich, Zebeę i Salmana, i wszystko wojsko ich strwożył.
13 Gideoni ọmọ Joaṣi gba ọ̀nà ìgòkè Heresi padà sẹ́yìn láti ojú ogun.
Potem się wrócił Giedeon, syn Joasów, z bitwy, niż weszło słońce;
14 Ó mú ọ̀dọ́mọkùnrin kan ará Sukkoti, ó sì béèrè àwọn ìbéèrè ní ọwọ́ rẹ̀, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì kọ orúkọ àwọn ìjòyè Sukkoti mẹ́tàdínlọ́gọ́rin fún un tí wọ́n jẹ́ àgbàgbà ìlú náà.
A pojmawszy młodzieńca z mężów Sokot, wypytał go, który spisał mu przedniejszych w Sokot i starszych jego, siedemdziesiąt i siedem mężów.
15 Nígbà náà ni Gideoni wá ó sọ fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Seba àti Salmunna nìwọ̀nyí nípa àwọn tí ẹ̀yin fi mí ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ẹ wí pé, ‘Ṣé ó ti ṣẹ́gun Seba àti Salmunna? Èéṣe tí àwa ó fi fún àwọn ọmọ-ogun rẹ tí ó ti rẹ̀ ní oúnjẹ?’”
A przyszedłszy do mężów Sokot, rzekł: Otóż Zebeę i Salmana, którymiście mi urągali, mówiąc: Izali moc Zeby i Salmana jest w rękach twoich, abyśmy mieli dać mężom twoim spracowanym chleba?
16 Ó mú àwọn àgbàgbà ìlú náà, ó sì fi kọ́ àwọn Sukkoti lọ́gbọ́n nípa jíjẹ wọ́n ní yà pẹ̀lú àwọn ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún ọ̀gàn.
Przetoż wziąwszy starsze miasta onego, i ciernia z onej pustyni i ostu, dał na nich przykład innym mężom Sokot.
17 Ó wó ilé ìṣọ́ Penieli, ó sì pa àwọn ọkùnrin ìlú náà.
Wieżę też Fanuel rozwalił, i pobił męże miasta.
18 Gideoni bi Seba àti Salmunna pé, “Irú ọkùnrin tí ẹ pa ní Tabori, báwo ni wọ́n ṣe rí?” “Àwọn ọkùnrin náà dàbí rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dàbí ọmọ ọba,” ní ìdáhùn wọn.
Rzekł potem do Zeby i do Salmana: Co zacz byli mężowie oni, któreście pobili w Tabor? A oni odpowiedzieli: Takowi byli jakoś ty; każdy z nich na wejrzeniu był, jako syn królewski.
19 Gideoni dáhùn pé, “Arákùnrin mi ni wọ́n, àwọn ọmọ ìyá mi. Mo fi Olúwa búra, bí ó bá ṣe pé ẹ dá ẹ̀mí wọn sí, èmi náà ò nípa yín.”
I rzekł: Braciać to moi, synowie matki mojej byli; żywie Pan, byście je byli żywo zachowali, nie pobiłbym was.
20 Ó yí padà sí Jeteri, ọmọ rẹ̀ tí ó dàgbà jùlọ, ó wí fún un pé, “Pa wọ́n!” Ṣùgbọ́n Jeteri kò fa idà rẹ̀ yọ láti pa wọ́n nítorí ó jẹ́ ọ̀dọ́mọdé ẹ̀rù sì bà á láti pa wọ́n.
I rzekł do Jetra, pierworodnego swego: Wstań, a pobij je. Ale nie dobył młodzieńczyk miecza swego, przeto iż się bał; bo jeszcze był pacholęciem.
21 Seba àti Salmunna dá Gideoni lóhùn pé, “Wá pa wá fún raàrẹ, ‘Nítorí bí ènìyàn bá ti rí bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóò rí.’” Gideoni bọ́ síwájú ó sì pa wọ́n, ó sì mú ohun ọ̀ṣọ́ tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
Tedy rzekli Zebee i Salmana: Wstań ty, a rzuć się na nas; bo jaki mąż, taka siła jego. A tak wstawszy Giedeon, zabił Zebeę i Salmana, i pobrał klejnoty, które były na szyjach wielbłądów ich.
22 Àwọn ará Israẹli wí fún Gideoni pé, “Jọba lórí wa—ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ pẹ̀lú, nítorí tí ìwọ ti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ará Midiani.”
I rzekli Izraelczycy do Giedeona: Panuj nad nami, i ty, i syn twój, i syn syna twego; boś nas wybawił z ręki Madyjańczyków.
23 Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Èmi kì yóò jẹ ọba lórí yín, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ mi kì yóò jẹ ọba lórí yín. Olúwa ni yóò jẹ ọba lórí yín.”
Na to odpowiedział im Giedeon: Nie będę ja panował nad wami, ani będzie panował syn mój nad wami; Pan panować będzie nad wami.
24 Gideoni sì wí pé, “Mo ní ẹ̀bẹ̀ kan tí mo fẹ́ bẹ̀ yín kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín fún mi ní yẹtí kọ̀ọ̀kan láti inú ohun ti ó kàn yín láti inú ìkógun.” (Àṣà àwọn ará Iṣmaeli ni láti máa fi yẹtí wúrà sétí.)
Nadto rzekł do nich Giedeon: Będę was prosił o jednę rzecz, aby mi każdy z was dał nausznicę z łupu swego; (bo nausznice złote mieli, będąc Ismaelczykami.)
25 Wọ́n dáhùn pé, “Tayọ̀tayọ̀ ni àwa yóò fi wọ́n sílẹ̀.” Wọ́n tẹ́ aṣọ kan sílẹ̀ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan sì ń sọ yẹtí kọ̀ọ̀kan tí ó kàn wọ́n láti ibi ìkógun síbẹ̀.
I rzekli: Radzić damy; i rozpostarłszy szatę rzucali na nię każdy nausznicę z łupów swoich.
26 Ìwọ̀n òrùka wúrà tí ó béèrè fún tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ìwọ̀n ṣékélì, láìka àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àti ohun sísorọ̀ tí ó wà lára ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn àti aṣọ elése àlùkò tí àwọn ọba Midiani ń wọ̀ tàbí àwọn ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
I była waga nausznic onych złotych, które sobie uprosił, tysiąc i siedemset syklów złota, oprócz klejnotów i zawieszenia i szat szarłatowych, które były na królach Madyjańskich, i oprócz łańcuchów, które były na szyjach wielbłądów ich.
27 Gideoni fi àwọn wúrà náà ṣe efodu èyí tí ó gbé kalẹ̀ ní Ofira ìlú rẹ̀. Àwọn ọmọ Israẹli sì sọ ara wọn di àgbèrè nípa sínsin-ín ní ibẹ̀. Ó sì di ìdẹ̀kùn fún Gideoni àti ìdílé rẹ̀.
I sprawił z tego Giedeon Efod, a położył go w mieście swem w Efra; i scudzołożył się tam wszystek Izrael, chodząc za nim, a było to Giedeonowi i domowi jego sidłem.
28 Báyìí ni a ṣe tẹrí àwọn ará Midiani ba níwájú àwọn ọmọ Israẹli bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tún gbé orí mọ́. Ní ọjọ́ Gideoni, Israẹli wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún.
A tak byli poniżeni Madyjańczycy przed synami Izraelskimi, i nie podnieśli więcej głowy swojej; i była w pokoju ziemia przez czterdzieści lat za dni Giedeona.
29 Jerubbaali ọmọ Joaṣi padà lọ láti máa gbé ní ìlú rẹ̀.
Wrócił się tedy Jerobaal, syn Joasów, i mieszkał w domu swoim.
30 Àádọ́rin ọmọ ni Gideoni bí, nítorí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìyàwó.
A miał Giedeon siedmdziesiąt synów, którzy poszli z biódr jego; albowiem miał wiele żon.
31 Àlè rẹ̀, tó ń gbé ní Ṣekemu, pàápàá bí ọmọkùnrin kan fún un tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Abimeleki.
Miał też założnicę, która była z Sychem, a ta mu urodziła syna, i dała mu imię Abimelech.
32 Gideoni ọmọ Joaṣi kú ní ògbólógbòó ọjọ́ rẹ̀, ó sì pọ̀ ní ọjọ́ orí, wọ́n sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀ ní Ofira ti àwọn ará Abieseri.
Umarł potem Giedeon, syn Joasów, w starości dobrej, a pogrzebion jest w grobie Joasa, ojca swego w Efra, które jest ojca Esrowego.
33 Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gideoni ni àwọn ará Israẹli ṣe àgbèrè tọ Baali lẹ́yìn, wọ́n fi Baali-Beriti ṣe òrìṣà wọn.
A gdy umarł Giedeon, odwrócili się synowie Izraelscy, i scudzołożyli się, idąc za Baalem, i postawili sobie Baalberyt za boga.
34 Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.
I nie pamiętali synowie Izraelscy na Pana, Boga swego, który je wyrwał z rąk wszystkich nieprzyjaciół ich okolicznych;
35 Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jerubbaali (èyí ni Gideoni) fún gbogbo oore tí ó ṣe fún wọn.
I nie uczynili miłosierdzia z domem Jerobaala Giedeona według wszystkich dobrodziejstw, które on był uczynił Izraelowi.

< Judges 8 >