< Judges 8 >

1 Àwọn àgbàgbà ẹ̀yà Efraimu sì bínú gidigidi sí Gideoni wọ́n bi í léèrè pé, kí ló dé tí o fi ṣe irú èyí sí wa? Èéṣe tí ìwọ kò fi pè wá nígbà tí ìwọ kọ́kọ́ jáde lọ láti bá àwọn ará Midiani jagun? Ohùn ìbínú ni wọ́n fi bá a sọ̀rọ̀.
Un Efraīma vīri sacīja uz viņu: kas tas ir, ko tu mums esi darījis, ka tu mūs neesi aicinājis pret Midijaniešiem karot? Un tie ar viņu stipri bārās.
2 Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Àṣeyọrí wo ni mo ti ṣe tí ó tó fiwé tiyín? Àṣàkù àjàrà Efraimu kò ha dára ju gbogbo ìkórè àjàrà Abieseri lọ bí?
Tad viņš uz tiem sacīja: vai tad es ko esmu darījis, kā jūs? Vai Efraīma salasas nav labākas nekā Abiēzera savākums.
3 Ọlọ́run ti fi Orebu àti Seebu àwọn olórí àwọn ará Midiani lé yín lọ́wọ́. Kí ni ohun tí Mose ṣe tí ó tó fiwé e yín tàbí tí ó tó àṣeyọrí i yín?” Nígbà tí ó wí èyí ríru ìbínú wọn rọlẹ̀.
Dievs Midijana valdniekus Orebu un Zeēbu nodevis jūsu rokās, - vai tad es ko varēju darīt kā jūs? Tad viņu dusmas pret to aprima, tam šo vārdu runājot.
4 Gideoni àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ̀síwájú láti lépa àwọn ọ̀tá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ̀ wọ́n, wọ́n dé Jordani wọ́n sì kọjá sí òdìkejì.
Un Gideons nāca pie Jardānes, un gāja pāri ar tiem trīssimt vīriem, kas pie viņa bija, piekusuši no pakaļ dzīšanās.
5 Ó wí fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Ẹ fún àwọn ọmọ-ogun mi ní oúnjẹ díẹ̀, nítorí ó ti rẹ̀ wọ́n, èmi sì ń lépa Seba àti Salmunna àwọn ọba Midiani.”
Un viņš sacīja uz Sukotas vīriem: dodiet jel kādus maizes klaipus tiem ļaudīm, kas man līdz, jo tie piekusuši; un es dzenos pakaļ Zebum un Calmunum, Midijana ķēniņiem.
6 Ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Sukkoti fèsì pé ṣé ọwọ́ rẹ ti tẹ Seba àti Salmunna náà ni? Èéṣe tí àwa yóò ṣe fún àwọn ológun rẹ ní oúnjẹ?
Tad Sukotas virsnieki sacīja: vai tad Zebus un Calmunus dūre jau ir tavā rokā, ka mums tavam karaspēkam būs maizes dot?
7 Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Ó dára, nígbà tí Olúwa bá fi Seba àti Salmunna lé mi lọ́wọ́ tán èmi yóò fi ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún òṣùṣú ya ẹran-ara yín.”
Tad Gideons sacīja: nu tad, ja Tas Kungs Zebu un Calmunu dos manā rokā, tad es jūsu miesas kapāšu ar tuksneša ērkšķiem un ar dadžiem.
8 Láti ibẹ̀, ó lọ sí Penieli ó sì bẹ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ṣùgbọ́n àwọn náà dá a lóhùn bí àwọn ará Sukkoti ti dá a lóhùn.
Un viņš gāja no turienes uz Pnuēli un runāja uz tiem tāpat; tad Pnuēles vīri viņam atbildēja, kā Sukotas vīri bija atbildējuši.
9 Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ọkùnrin Penieli pé, “Nígbà tí mo bá ṣẹ́gun tí mo sì padà dé ní àlàáfíà, èmi yóò wó ilé ìṣọ́ yìí.”
Un viņš arī ar Pnuēles vīriem runāja sacīdams: kad es ar mieru griezīšos atpakaļ, tad es šo torni noārdīšu.
10 Ní àsìkò náà Seba àti Salmunna wà ní Karkori pẹ̀lú ọmọ-ogun wọn tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọkùnrin, àwọn wọ̀nyí ni ó ṣẹ́kù nínú gbogbo ogun àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn, nítorí ọ̀kẹ́ mẹ́fà ọkùnrin tí ó fi idà jà ti kú ní ojú ogun.
Bet Zebus un Calmunus bija Karkorā, un viņu karaspēki pie viņiem, kādi piecpadsmit tūkstoši, kas vien bija atlikuši no visa austruma bērnu spēka, jo simts un divdesmit tūkstoš vīri, zobena nesēji, bija gājuši bojā.
11 Gideoni gba ọ̀nà tí àwọn darandaran máa ń rìn ní apá ìhà ìlà-oòrùn Noba àti Jogbeha ó sì kọjú ogun sí àwọn ọmọ-ogun náà nítorí wọ́n ti túra sílẹ̀.
Un Gideons gāja pa telts ļaužu ceļu pret rītiem no Nobas un Jagbeas, un sakāva to karaspēku, jo tas karaspēks tur gulēja it droši.
12 Seba àti Salmunna, àwọn ọba Midiani méjèèjì sá, ṣùgbọ́n Gideoni lépa wọn ó sì mú wọn, ó run gbogbo ogun wọn.
Un Zebus un Calmunus bēga, bet viņš tiem dzinās pakaļ un sagūstīja tos divus Midijaniešu ķēniņus, Zebu un Calmunu, un izbiedēja visu to karaspēku.
13 Gideoni ọmọ Joaṣi gba ọ̀nà ìgòkè Heresi padà sẹ́yìn láti ojú ogun.
Tad Gideons, Joasa dēls, griezās atpakaļ no kaušanās, pirms saule uzlēca.
14 Ó mú ọ̀dọ́mọkùnrin kan ará Sukkoti, ó sì béèrè àwọn ìbéèrè ní ọwọ́ rẹ̀, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì kọ orúkọ àwọn ìjòyè Sukkoti mẹ́tàdínlọ́gọ́rin fún un tí wọ́n jẹ́ àgbàgbà ìlú náà.
Un viņš sagūstīja vienu puisi no Sukotas vīriem un to vaicāja; un tas viņam uzrakstīja Sukotas virsniekus un viņas vecajus, septiņdesmit un septiņus vīrus.
15 Nígbà náà ni Gideoni wá ó sọ fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Seba àti Salmunna nìwọ̀nyí nípa àwọn tí ẹ̀yin fi mí ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ẹ wí pé, ‘Ṣé ó ti ṣẹ́gun Seba àti Salmunna? Èéṣe tí àwa ó fi fún àwọn ọmọ-ogun rẹ tí ó ti rẹ̀ ní oúnjẹ?’”
Tad viņš nāca pie tiem Sukotas vīriem un sacīja: redz še ir Zebus un Calmunus, kādēļ jūs mani esat apsmējuši sacīdami: vai tad Zebus un Calmunus dūre jau ir tavā rokā, ka mums taviem piekusušiem vīriem būs maizes dot?
16 Ó mú àwọn àgbàgbà ìlú náà, ó sì fi kọ́ àwọn Sukkoti lọ́gbọ́n nípa jíjẹ wọ́n ní yà pẹ̀lú àwọn ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún ọ̀gàn.
Un viņš ņēma tās pilsētas vecajus un tuksneša ērkšķus un dadžus un pārmācīja Sukotas vīrus.
17 Ó wó ilé ìṣọ́ Penieli, ó sì pa àwọn ọkùnrin ìlú náà.
Un Pnuēles torni viņš noārdīja un nokāva tās pilsētas ļaudis.
18 Gideoni bi Seba àti Salmunna pé, “Irú ọkùnrin tí ẹ pa ní Tabori, báwo ni wọ́n ṣe rí?” “Àwọn ọkùnrin náà dàbí rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dàbí ọmọ ọba,” ní ìdáhùn wọn.
Un viņš sacīja uz Zebu un Calmunu: kas tie bija par vīriem, ko jūs Tāborā nokāvāt? Un tie sacīja: tie bija tādi kā tu, visi tādā vaigā, kā ķēniņa bērni.
19 Gideoni dáhùn pé, “Arákùnrin mi ni wọ́n, àwọn ọmọ ìyá mi. Mo fi Olúwa búra, bí ó bá ṣe pé ẹ dá ẹ̀mí wọn sí, èmi náà ò nípa yín.”
Un viņš sacīja: tie bija mani brāļi, manas mātes dēli; tik tiešām kā Tas Kungs dzīvo, ja jūs tos būtu atstājuši dzīvus, es jūs nenokautu.
20 Ó yí padà sí Jeteri, ọmọ rẹ̀ tí ó dàgbà jùlọ, ó wí fún un pé, “Pa wọ́n!” Ṣùgbọ́n Jeteri kò fa idà rẹ̀ yọ láti pa wọ́n nítorí ó jẹ́ ọ̀dọ́mọdé ẹ̀rù sì bà á láti pa wọ́n.
Un viņš sacīja uz Jeteru, savu pirmdzimto: celies, nokauj tos. Bet tas zēns neizvilka savu zobenu, jo viņš bijās, tāpēc ka vēl bija jauns.
21 Seba àti Salmunna dá Gideoni lóhùn pé, “Wá pa wá fún raàrẹ, ‘Nítorí bí ènìyàn bá ti rí bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóò rí.’” Gideoni bọ́ síwájú ó sì pa wọ́n, ó sì mú ohun ọ̀ṣọ́ tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
Tad Zebus un Calmunus sacīja: celies pats un sit mūs, jo kāds vīrs, tāds spēks. Tad Gideons cēlās un nokāva Zebu un Calmunu un paņēma tās sprādzes, kas bija ap viņu kamieļu kakliem.
22 Àwọn ará Israẹli wí fún Gideoni pé, “Jọba lórí wa—ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ pẹ̀lú, nítorí tí ìwọ ti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ará Midiani.”
Un Israēla vīri sacīja uz Gideonu: valdi pār mums, tu un tavs dēls un tava dēla dēls, tāpēc ka tu mūs esi atpestījis no Midijana rokas.
23 Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Èmi kì yóò jẹ ọba lórí yín, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ mi kì yóò jẹ ọba lórí yín. Olúwa ni yóò jẹ ọba lórí yín.”
Bet Gideons uz tiem sacīja: es negribu pār jums valdīt, nedz mans dēls pār jums valdīs; Tas Kungs pār jums valdīs.
24 Gideoni sì wí pé, “Mo ní ẹ̀bẹ̀ kan tí mo fẹ́ bẹ̀ yín kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín fún mi ní yẹtí kọ̀ọ̀kan láti inú ohun ti ó kàn yín láti inú ìkógun.” (Àṣà àwọn ará Iṣmaeli ni láti máa fi yẹtí wúrà sétí.)
Un Gideons uz tiem sacīja: es no jums ko prasīšu: dodiet man ikviens vienu ausu sprādzi no sava laupījuma. Jo tiem bija zelta ausu sprādzes, tāpēc ka tie bija Ismaēlieši.
25 Wọ́n dáhùn pé, “Tayọ̀tayọ̀ ni àwa yóò fi wọ́n sílẹ̀.” Wọ́n tẹ́ aṣọ kan sílẹ̀ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan sì ń sọ yẹtí kọ̀ọ̀kan tí ó kàn wọ́n láti ibi ìkógun síbẹ̀.
Un tie sacīja: mēs dosim. Un tie izklāja drēbi un meta uz to ikkatrs vienu ausu sprādzi no sava laupījuma.
26 Ìwọ̀n òrùka wúrà tí ó béèrè fún tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ìwọ̀n ṣékélì, láìka àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àti ohun sísorọ̀ tí ó wà lára ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn àti aṣọ elése àlùkò tí àwọn ọba Midiani ń wọ̀ tàbí àwọn ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
Un to zelta ausu sprādžu svars, ko viņš bija prasījis, bija tūkstoš un septiņi simti zelta sēķeļi, bez tām sprādzēm un ķēdēm un tām purpura drēbēm, kas Midijaniešu ķēniņiem bija mugurā, un bez tām kakla saitēm, kas bija pie viņu kamieļu kakliem.
27 Gideoni fi àwọn wúrà náà ṣe efodu èyí tí ó gbé kalẹ̀ ní Ofira ìlú rẹ̀. Àwọn ọmọ Israẹli sì sọ ara wọn di àgbèrè nípa sínsin-ín ní ibẹ̀. Ó sì di ìdẹ̀kùn fún Gideoni àti ìdílé rẹ̀.
Un Gideons no tā taisīja efodu, un to nolika Ovrā, savā pilsētā, un viss Israēls tur tam maukoja pakaļ, un tas Gideonam un viņa namam palika par slazda valgu. -
28 Báyìí ni a ṣe tẹrí àwọn ará Midiani ba níwájú àwọn ọmọ Israẹli bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tún gbé orí mọ́. Ní ọjọ́ Gideoni, Israẹli wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún.
Tā Midijanieši tapa pazemoti priekš Israēla bērniem un nepacēla vairs savu galvu. Un zemei bija miers četrdesmit gadus, kamēr Gideons dzīvoja.
29 Jerubbaali ọmọ Joaṣi padà lọ láti máa gbé ní ìlú rẹ̀.
Un JerubBaāls, Joasa dēls, nogāja un dzīvoja savā namā.
30 Àádọ́rin ọmọ ni Gideoni bí, nítorí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìyàwó.
Un Gideonam bija septiņdesmit dēli, kas no viņa gurniem nākuši, jo viņam bija daudz sievas;
31 Àlè rẹ̀, tó ń gbé ní Ṣekemu, pàápàá bí ọmọkùnrin kan fún un tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Abimeleki.
Un viņa liekā sieva, kas bija Šehemē, arīdzan viņam dzemdēja dēlu, un viņš tam vārdu nosauca Abimeleks.
32 Gideoni ọmọ Joaṣi kú ní ògbólógbòó ọjọ́ rẹ̀, ó sì pọ̀ ní ọjọ́ orí, wọ́n sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀ ní Ofira ti àwọn ará Abieseri.
Un Gideons, Joasa dēls, nomira labā vecumā un tapa aprakts sava tēva Joasa kapā, Abiēzeriešu Ovrā.
33 Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gideoni ni àwọn ará Israẹli ṣe àgbèrè tọ Baali lẹ́yìn, wọ́n fi Baali-Beriti ṣe òrìṣà wọn.
Un kad Gideons bija nomiris, tad Israēla bērni nogriezās un maukoja Baāliem pakaļ un iecēla to BaālBeritu sev par dievu.
34 Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.
Un Israēla bērni nepieminēja To Kungu, savu Dievu, kas tos bija izglābis no visu ienaidnieku rokas visapkārt.
35 Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jerubbaali (èyí ni Gideoni) fún gbogbo oore tí ó ṣe fún wọn.
Un tie nedarīja žēlastību pie JerubBaāla, tas ir Gideona, nama, pēc visa tā labuma, ko viņš bija darījis pie Israēla.

< Judges 8 >