< Judges 8 >

1 Àwọn àgbàgbà ẹ̀yà Efraimu sì bínú gidigidi sí Gideoni wọ́n bi í léèrè pé, kí ló dé tí o fi ṣe irú èyí sí wa? Èéṣe tí ìwọ kò fi pè wá nígbà tí ìwọ kọ́kọ́ jáde lọ láti bá àwọn ará Midiani jagun? Ohùn ìbínú ni wọ́n fi bá a sọ̀rọ̀.
And the men of Effraym seiden to hym, What is this thing, which thou woldist do, that thou clepidist not vs, whanne thou yedist to batel ayens Madian? And thei chidden strongli, and almest diden violence.
2 Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Àṣeyọrí wo ni mo ti ṣe tí ó tó fiwé tiyín? Àṣàkù àjàrà Efraimu kò ha dára ju gbogbo ìkórè àjàrà Abieseri lọ bí?
To whiche he answeride, `What sotheli siche thing myyte Y do, what maner thing ye diden? Whethir a reisyn of Effraym is not betere than the vindagis of Abiezer?
3 Ọlọ́run ti fi Orebu àti Seebu àwọn olórí àwọn ará Midiani lé yín lọ́wọ́. Kí ni ohun tí Mose ṣe tí ó tó fiwé e yín tàbí tí ó tó àṣeyọrí i yín?” Nígbà tí ó wí èyí ríru ìbínú wọn rọlẹ̀.
And the Lord bitook in to youre hondis the princes of Madian, Oreb and Zeb. What sich thing myyte Y do, what maner thing ye diden? And whanne he hadde spoke this thing, the spirit of hem restide, bi which thei bolneden ayens hym.
4 Gideoni àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ̀síwájú láti lépa àwọn ọ̀tá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ̀ wọ́n, wọ́n dé Jordani wọ́n sì kọjá sí òdìkejì.
And whanne Gedeon hadde come to Jordan, he passide it with thre hundrid men, that weren with hym; and for weerynesse thei myyten not pursue hem that fledden.
5 Ó wí fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Ẹ fún àwọn ọmọ-ogun mi ní oúnjẹ díẹ̀, nítorí ó ti rẹ̀ wọ́n, èmi sì ń lépa Seba àti Salmunna àwọn ọba Midiani.”
And he seide to the men of Socoth, Y biseche, yyue ye looues to the puple, which is with me; for thei failiden greetli, that we moun pursue Zebee and Salmana, kyngis of Madian.
6 Ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Sukkoti fèsì pé ṣé ọwọ́ rẹ ti tẹ Seba àti Salmunna náà ni? Èéṣe tí àwa yóò ṣe fún àwọn ológun rẹ ní oúnjẹ?
The princes of Socoth answeriden in scorne, In hap the pawmes of the hondis of Zebee and of Salmana ben in thin hond, and therfor thou axist, that we yyue looues to thin oost.
7 Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Ó dára, nígbà tí Olúwa bá fi Seba àti Salmunna lé mi lọ́wọ́ tán èmi yóò fi ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún òṣùṣú ya ẹran-ara yín.”
To whiche he seide, Therfor, whanne the Lord schal bitake Zebee and Salmana in to myn hondis, and whanne Y schal turne ayen ouercomere in pees, Y schal to-reende youre fleischis with the thornes and breris of deseert.
8 Láti ibẹ̀, ó lọ sí Penieli ó sì bẹ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ṣùgbọ́n àwọn náà dá a lóhùn bí àwọn ará Sukkoti ti dá a lóhùn.
And he stiede fro thennus, and cam in to Phanuel; and he spak lijk thingis to men of that place, to whom also thei answeriden, as the men of Socoth hadden answerid.
9 Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ọkùnrin Penieli pé, “Nígbà tí mo bá ṣẹ́gun tí mo sì padà dé ní àlàáfíà, èmi yóò wó ilé ìṣọ́ yìí.”
And so he seide to hem, Whanne Y schal turne ayen ouercomere in pees, Y schal distrie this tour.
10 Ní àsìkò náà Seba àti Salmunna wà ní Karkori pẹ̀lú ọmọ-ogun wọn tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọkùnrin, àwọn wọ̀nyí ni ó ṣẹ́kù nínú gbogbo ogun àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn, nítorí ọ̀kẹ́ mẹ́fà ọkùnrin tí ó fi idà jà ti kú ní ojú ogun.
Forsothe Zebee and Salmana restiden with al her oost; for fiftene thousynde men leften of alle the cumpenyes of the `puplis of the eest, whanne an hundrid and twenti thousynde of `fiyteris and of men drawynge out swerd weren slayn.
11 Gideoni gba ọ̀nà tí àwọn darandaran máa ń rìn ní apá ìhà ìlà-oòrùn Noba àti Jogbeha ó sì kọjú ogun sí àwọn ọmọ-ogun náà nítorí wọ́n ti túra sílẹ̀.
And Gedeon stiede bi the weye of hem that dwelliden in tabernaclis at the eest coost of Nobe and of Lethoa, and smoot the `tentis of enemyes, that weren sikur, and supposiden not ony thing of aduersite.
12 Seba àti Salmunna, àwọn ọba Midiani méjèèjì sá, ṣùgbọ́n Gideoni lépa wọn ó sì mú wọn, ó run gbogbo ogun wọn.
And Zebee and Salmana fledden, whiche Gedeon pursuede and took, whanne al `the oost of hem was disturblid.
13 Gideoni ọmọ Joaṣi gba ọ̀nà ìgòkè Heresi padà sẹ́yìn láti ojú ogun.
And he turnede ayen fro batel bifor the `risyng of the sunne,
14 Ó mú ọ̀dọ́mọkùnrin kan ará Sukkoti, ó sì béèrè àwọn ìbéèrè ní ọwọ́ rẹ̀, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì kọ orúkọ àwọn ìjòyè Sukkoti mẹ́tàdínlọ́gọ́rin fún un tí wọ́n jẹ́ àgbàgbà ìlú náà.
and took a child of the men of Socoth; and he axide hym the names of the princes and eldere men of Socoth; and he descryuede seuene and seuenti men in noumbre.
15 Nígbà náà ni Gideoni wá ó sọ fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Seba àti Salmunna nìwọ̀nyí nípa àwọn tí ẹ̀yin fi mí ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ẹ wí pé, ‘Ṣé ó ti ṣẹ́gun Seba àti Salmunna? Èéṣe tí àwa ó fi fún àwọn ọmọ-ogun rẹ tí ó ti rẹ̀ ní oúnjẹ?’”
And he cam to Socoth, and seide to hem, Lo Zebee and Salmana! of whiche ye vpbreideden me, and seiden, In hap the hondis of Zebee and of Salmana ben in thin hondis, and therfor thou axist, that we yyue looues to men, that ben weeri and failiden.
16 Ó mú àwọn àgbàgbà ìlú náà, ó sì fi kọ́ àwọn Sukkoti lọ́gbọ́n nípa jíjẹ wọ́n ní yà pẹ̀lú àwọn ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún ọ̀gàn.
Therfor Gedeon took the eldere men of the citee, and thornes and breris of deseert, and he to-rente with tho, and al to-brak the men of Socoth; also he destriede the tour of Phanuel,
17 Ó wó ilé ìṣọ́ Penieli, ó sì pa àwọn ọkùnrin ìlú náà.
whanne the dwelleris of the citee weren slayn.
18 Gideoni bi Seba àti Salmunna pé, “Irú ọkùnrin tí ẹ pa ní Tabori, báwo ni wọ́n ṣe rí?” “Àwọn ọkùnrin náà dàbí rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dàbí ọmọ ọba,” ní ìdáhùn wọn.
And he seide to Zebee and Salmana, What maner men weren thei, whiche ye killiden in Thabor? Whiche answeriden, Thei weren lijk thee, and oon of hem was as the sone of a kyng.
19 Gideoni dáhùn pé, “Arákùnrin mi ni wọ́n, àwọn ọmọ ìyá mi. Mo fi Olúwa búra, bí ó bá ṣe pé ẹ dá ẹ̀mí wọn sí, èmi náà ò nípa yín.”
To whiche he seide, Thei weren my britheren, the sones of my modir; the Lord lyueth, if ye hadden saued hem, Y `nolde sle you.
20 Ó yí padà sí Jeteri, ọmọ rẹ̀ tí ó dàgbà jùlọ, ó wí fún un pé, “Pa wọ́n!” Ṣùgbọ́n Jeteri kò fa idà rẹ̀ yọ láti pa wọ́n nítorí ó jẹ́ ọ̀dọ́mọdé ẹ̀rù sì bà á láti pa wọ́n.
And he seide to Jepther, his firste gendrid sone, Rise thou, and sle hem. Which drow not swerd; for he dredde, for he was yit a child.
21 Seba àti Salmunna dá Gideoni lóhùn pé, “Wá pa wá fún raàrẹ, ‘Nítorí bí ènìyàn bá ti rí bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóò rí.’” Gideoni bọ́ síwájú ó sì pa wọ́n, ó sì mú ohun ọ̀ṣọ́ tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
And Zebee and Salmana seiden, Ryse thou, and falle on vs; for thou art bi the age and strengthe of man. Gedeon roos, and killide Zebee and Salmana, and took the ournementis, and bellis, with whiche the neckis of kyngis camels ben wont to be maad fair.
22 Àwọn ará Israẹli wí fún Gideoni pé, “Jọba lórí wa—ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ pẹ̀lú, nítorí tí ìwọ ti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ará Midiani.”
And alle the men of Israel seiden to Gedeon, Be thou lord of vs, thou, and thi sone, and the sone of thi sone; for thou deliueridist vs fro the hond of Madian.
23 Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Èmi kì yóò jẹ ọba lórí yín, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ mi kì yóò jẹ ọba lórí yín. Olúwa ni yóò jẹ ọba lórí yín.”
To whiche he seide, Y schal not be lord of you, nethir my sone schal be lord on you, but the Lord schal be lord.
24 Gideoni sì wí pé, “Mo ní ẹ̀bẹ̀ kan tí mo fẹ́ bẹ̀ yín kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín fún mi ní yẹtí kọ̀ọ̀kan láti inú ohun ti ó kàn yín láti inú ìkógun.” (Àṣà àwọn ará Iṣmaeli ni láti máa fi yẹtí wúrà sétí.)
And he seide to hem, Y axe oon axyng of you, yyue ye to me the eere ryngis of youre prey; for Ismaelitis weren wont to haue goldun eere ryngis.
25 Wọ́n dáhùn pé, “Tayọ̀tayọ̀ ni àwa yóò fi wọ́n sílẹ̀.” Wọ́n tẹ́ aṣọ kan sílẹ̀ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan sì ń sọ yẹtí kọ̀ọ̀kan tí ó kàn wọ́n láti ibi ìkógun síbẹ̀.
Whiche answeriden, We schulen yyue moost gladli. And thei spredden forth a mentil on the erthe, and castiden forth therynne `eere ryngis of the prey;
26 Ìwọ̀n òrùka wúrà tí ó béèrè fún tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ìwọ̀n ṣékélì, láìka àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àti ohun sísorọ̀ tí ó wà lára ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn àti aṣọ elése àlùkò tí àwọn ọba Midiani ń wọ̀ tàbí àwọn ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
and the weiyte of `eere ryngis axid was a thousynde and seuene hundrid siclis of gold, with out ournementis and brochis and cloth of purpur, whiche the kyngis of Madian weren wont to vse, and outakun goldun bies of camels.
27 Gideoni fi àwọn wúrà náà ṣe efodu èyí tí ó gbé kalẹ̀ ní Ofira ìlú rẹ̀. Àwọn ọmọ Israẹli sì sọ ara wọn di àgbèrè nípa sínsin-ín ní ibẹ̀. Ó sì di ìdẹ̀kùn fún Gideoni àti ìdílé rẹ̀.
And Gedeon made therof ephot, that is, a preestis cloth, `and propir cloth of the hiyeste preest, and he puttide it in his citee Ephra; and al Israel diden fornycacioun, `that is ydolatrye, ther ynne; and it was maad to Gedeon and to al his hows in to fallyng.
28 Báyìí ni a ṣe tẹrí àwọn ará Midiani ba níwájú àwọn ọmọ Israẹli bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tún gbé orí mọ́. Ní ọjọ́ Gideoni, Israẹli wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún.
Forsothe Madian was maad low bifor the sones of Israel, and thei myyten no more reise nollis; but the lond restide fourti yeer, in whiche Gedeon was souereyn.
29 Jerubbaali ọmọ Joaṣi padà lọ láti máa gbé ní ìlú rẹ̀.
And so Jerobaal, sone of Joas, yede, and dwellide in his hows;
30 Àádọ́rin ọmọ ni Gideoni bí, nítorí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìyàwó.
and he hadde seuenti sones, that yeden out of his thiy, for he hadde many wyues.
31 Àlè rẹ̀, tó ń gbé ní Ṣekemu, pàápàá bí ọmọkùnrin kan fún un tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Abimeleki.
Forsothe a concubyn, `that is, secoundarie wijf, of hym, whom he hadde in Sichem, gendride to hym a sone, Abymelech bi name.
32 Gideoni ọmọ Joaṣi kú ní ògbólógbòó ọjọ́ rẹ̀, ó sì pọ̀ ní ọjọ́ orí, wọ́n sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀ ní Ofira ti àwọn ará Abieseri.
And Gedeon, sone of Joas, diede in good elde, and was biried in the sepulcre of Joas, his fadir, in Ephra, of the meynee of Ezri.
33 Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gideoni ni àwọn ará Israẹli ṣe àgbèrè tọ Baali lẹ́yìn, wọ́n fi Baali-Beriti ṣe òrìṣà wọn.
Forsothe aftir that Gedeon was deed, the sones of Israel turneden awey `fro Goddis religioun, and diden fornycacioun, `that is, idolatrie, with Baalym; and thei smytiden boond of pees with Baal, that he schulde be to hem in to God,
34 Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.
nether thei hadden mynde of her Lord God, that delyuerede hem fro the hond of alle her enemyes `bi cumpas;
35 Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jerubbaali (èyí ni Gideoni) fún gbogbo oore tí ó ṣe fún wọn.
nether thei diden merci with the hous of Gerobaal Gedeon, bi alle the goodis whiche he `hadde do to Israel.

< Judges 8 >