< Judges 8 >
1 Àwọn àgbàgbà ẹ̀yà Efraimu sì bínú gidigidi sí Gideoni wọ́n bi í léèrè pé, kí ló dé tí o fi ṣe irú èyí sí wa? Èéṣe tí ìwọ kò fi pè wá nígbà tí ìwọ kọ́kọ́ jáde lọ láti bá àwọn ará Midiani jagun? Ohùn ìbínú ni wọ́n fi bá a sọ̀rọ̀.
Тогава ефремците казаха на Гедеона: Какво ни стори ти, че не ни повика, когато отиде да воюваш против Мадиама? И караха се силно с него.
2 Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Àṣeyọrí wo ni mo ti ṣe tí ó tó fiwé tiyín? Àṣàkù àjàrà Efraimu kò ha dára ju gbogbo ìkórè àjàrà Abieseri lọ bí?
А той им рече: Що съм извършил аз сега в сравнение с вас? Ефремовият пабирък не е ли по-желателен от Авиезеровия гроздобер?
3 Ọlọ́run ti fi Orebu àti Seebu àwọn olórí àwọn ará Midiani lé yín lọ́wọ́. Kí ni ohun tí Mose ṣe tí ó tó fiwé e yín tàbí tí ó tó àṣeyọrí i yín?” Nígbà tí ó wí èyí ríru ìbínú wọn rọlẹ̀.
В нашите ръце Бог предаде мадиамските началници, Орива и Зива; и що съм могъл аз да извърша в сравнение с вас? Тогава гневът им се укроти към него, когато каза това.
4 Gideoni àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ̀síwájú láti lépa àwọn ọ̀tá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ̀ wọ́n, wọ́n dé Jordani wọ́n sì kọjá sí òdìkejì.
И като дойде Гедеон при Иордан, той премина с тристата мъже, които бяха с него, уморени, но пак преследвайки.
5 Ó wí fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Ẹ fún àwọn ọmọ-ogun mi ní oúnjẹ díẹ̀, nítorí ó ti rẹ̀ wọ́n, èmi sì ń lépa Seba àti Salmunna àwọn ọba Midiani.”
И рече на сокхотските жители: Дайте, моля, няколко хляба на людете, които вървят подир мене защото са изнемощели; а аз гоня мадиамските царе Зевей и Салман.
6 Ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Sukkoti fèsì pé ṣé ọwọ́ rẹ ti tẹ Seba àti Salmunna náà ni? Èéṣe tí àwa yóò ṣe fún àwọn ológun rẹ ní oúnjẹ?
А сокхотските първенци му казаха: Ръцете на Зевея и на Салмана в ръката ти ли са вече та да дадем хляб на войската ти?
7 Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Ó dára, nígbà tí Olúwa bá fi Seba àti Salmunna lé mi lọ́wọ́ tán èmi yóò fi ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún òṣùṣú ya ẹran-ara yín.”
А Гедеон рече: Затова, когато Господ предаде Зевея и Салмана в ръката ми, тогава аз ще разкъсам месата ви с пустинните тръни и с глоговете.
8 Láti ibẹ̀, ó lọ sí Penieli ó sì bẹ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ṣùgbọ́n àwọn náà dá a lóhùn bí àwọn ará Sukkoti ti dá a lóhùn.
От там отиде във Фануил и каза на жителите му същото; а фануилските мъже му отговориха, както бяха отговорили сокхотските мъже.
9 Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ọkùnrin Penieli pé, “Nígbà tí mo bá ṣẹ́gun tí mo sì padà dé ní àlàáfíà, èmi yóò wó ilé ìṣọ́ yìí.”
А той говори на фануилските мъже, казвайки: Когато се върна с мир, аз ще съборя тая кула.
10 Ní àsìkò náà Seba àti Salmunna wà ní Karkori pẹ̀lú ọmọ-ogun wọn tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọkùnrin, àwọn wọ̀nyí ni ó ṣẹ́kù nínú gbogbo ogun àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn, nítorí ọ̀kẹ́ mẹ́fà ọkùnrin tí ó fi idà jà ti kú ní ojú ogun.
А Зевей и Салман бяха в Каркор и войските им с тях, около петдесет хиляди души, всичките колкото бяха оцелели от цялата войска на източните жители; защото бяха паднали сто и двадесет хиляди мъже, които теглеха нож.
11 Gideoni gba ọ̀nà tí àwọn darandaran máa ń rìn ní apá ìhà ìlà-oòrùn Noba àti Jogbeha ó sì kọjú ogun sí àwọn ọmọ-ogun náà nítorí wọ́n ti túra sílẹ̀.
И Гедеон отиде през пътя на ония, които живееха в шатри на изток от Нова и на Иогвея, та порази множеството; защото множеството беше в безгрижност.
12 Seba àti Salmunna, àwọn ọba Midiani méjèèjì sá, ṣùgbọ́n Gideoni lépa wọn ó sì mú wọn, ó run gbogbo ogun wọn.
А Зевей и Салман побягнаха; но той ги гони, и хвана двамата мадиамски царе Зевея и Салмана, и разби цялото множество.
13 Gideoni ọmọ Joaṣi gba ọ̀nà ìgòkè Heresi padà sẹ́yìn láti ojú ogun.
Тогава Гедеон Иоасовият син се върна от войната през нагорнището на Херес.
14 Ó mú ọ̀dọ́mọkùnrin kan ará Sukkoti, ó sì béèrè àwọn ìbéèrè ní ọwọ́ rẹ̀, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì kọ orúkọ àwọn ìjòyè Sukkoti mẹ́tàdínlọ́gọ́rin fún un tí wọ́n jẹ́ àgbàgbà ìlú náà.
И като хвана един момък от сокхотските мъже, разпита го, и той му описа първенците на Сокхот и старейшините му, седемдесет и седем мъже.
15 Nígbà náà ni Gideoni wá ó sọ fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Seba àti Salmunna nìwọ̀nyí nípa àwọn tí ẹ̀yin fi mí ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ẹ wí pé, ‘Ṣé ó ti ṣẹ́gun Seba àti Salmunna? Èéṣe tí àwa ó fi fún àwọn ọmọ-ogun rẹ tí ó ti rẹ̀ ní oúnjẹ?’”
И Гедеон дойде при сокхотските мъже та рече: Ето Зевея и Салмана, за които ми се подиграхте като казахте: Ръцете на Зевея и на Салмана в ръката ти ли са вече та да дадем хляб на човеците ти, че били изнемощели?
16 Ó mú àwọn àgbàgbà ìlú náà, ó sì fi kọ́ àwọn Sukkoti lọ́gbọ́n nípa jíjẹ wọ́n ní yà pẹ̀lú àwọn ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún ọ̀gàn.
И взе градските старейшини, и пустинните тръни и глогове, та наказа с тях сокхотските мъже.
17 Ó wó ilé ìṣọ́ Penieli, ó sì pa àwọn ọkùnrin ìlú náà.
Също и събори кулата на Фануила и изби градските мъже.
18 Gideoni bi Seba àti Salmunna pé, “Irú ọkùnrin tí ẹ pa ní Tabori, báwo ni wọ́n ṣe rí?” “Àwọn ọkùnrin náà dàbí rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dàbí ọmọ ọba,” ní ìdáhùn wọn.
Тогава каза на Зевея и на Салмана: Какви бяха ония човеци, които убихте в Тавор? А те отговориха: Какъвто си ти, такива бяха и те; всеки приличаше на царски син.
19 Gideoni dáhùn pé, “Arákùnrin mi ni wọ́n, àwọn ọmọ ìyá mi. Mo fi Olúwa búra, bí ó bá ṣe pé ẹ dá ẹ̀mí wọn sí, èmi náà ò nípa yín.”
А той каза: Мои братя бяха, синовете на моята майка; заклевам се в живота на Господа, ако бяхте опазили живота им, аз не бих ви убил.
20 Ó yí padà sí Jeteri, ọmọ rẹ̀ tí ó dàgbà jùlọ, ó wí fún un pé, “Pa wọ́n!” Ṣùgbọ́n Jeteri kò fa idà rẹ̀ yọ láti pa wọ́n nítorí ó jẹ́ ọ̀dọ́mọdé ẹ̀rù sì bà á láti pa wọ́n.
И рече на първородния си, Етер: Стани, убий ги. Но младежът не изтегли меча си, защото се боеше, бидейки още млад.
21 Seba àti Salmunna dá Gideoni lóhùn pé, “Wá pa wá fún raàrẹ, ‘Nítorí bí ènìyàn bá ti rí bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóò rí.’” Gideoni bọ́ síwájú ó sì pa wọ́n, ó sì mú ohun ọ̀ṣọ́ tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
Тогава Зевей и Салмана казаха: Стани ти, та не нападни; защото според човека е и силата му. И тъй Гедеон стана та уби Зевея и Салмана, и взе полумесецообразните украшения, които бяха на вратовете на камилите им.
22 Àwọn ará Israẹli wí fún Gideoni pé, “Jọba lórí wa—ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ pẹ̀lú, nítorí tí ìwọ ti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ará Midiani.”
Тогава израилевите мъже казаха на Гедеона: Владей над нас, и ти, и синът ти, и внукът ти, защото ти ни освободи от ръката на Мадиама.
23 Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Èmi kì yóò jẹ ọba lórí yín, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ mi kì yóò jẹ ọba lórí yín. Olúwa ni yóò jẹ ọba lórí yín.”
А Гедеон каза: Нито аз ще владея над вас, нито синът ми ще владее над вас; Господ ще владее над вас.
24 Gideoni sì wí pé, “Mo ní ẹ̀bẹ̀ kan tí mo fẹ́ bẹ̀ yín kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín fún mi ní yẹtí kọ̀ọ̀kan láti inú ohun ti ó kàn yín láti inú ìkógun.” (Àṣà àwọn ará Iṣmaeli ni láti máa fi yẹtí wúrà sétí.)
Гедеон, обаче, им рече: Едно нещо ще поискам от вас, - да ми дадете всеки обеците от користите си. (Защото неприятелите, понеже бяха исмаиляни, носеха златни обеци).
25 Wọ́n dáhùn pé, “Tayọ̀tayọ̀ ni àwa yóò fi wọ́n sílẹ̀.” Wọ́n tẹ́ aṣọ kan sílẹ̀ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan sì ń sọ yẹtí kọ̀ọ̀kan tí ó kàn wọ́n láti ibi ìkógun síbẹ̀.
И те отговориха: На драго сърце ще ги дадем. И като простряха дреха, всеки хвърляше там обеците от користите си.
26 Ìwọ̀n òrùka wúrà tí ó béèrè fún tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ìwọ̀n ṣékélì, láìka àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àti ohun sísorọ̀ tí ó wà lára ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn àti aṣọ elése àlùkò tí àwọn ọba Midiani ń wọ̀ tàbí àwọn ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
И теглото на златните обеци, които поиска, беше хиляда и седемстотин златни сикли, освен полумесецообразните украшения, огърлията и моравите дрехи, които бяха върху мадиамските царе, и освен веригите, които бяха около вратовете на камилите им.
27 Gideoni fi àwọn wúrà náà ṣe efodu èyí tí ó gbé kalẹ̀ ní Ofira ìlú rẹ̀. Àwọn ọmọ Israẹli sì sọ ara wọn di àgbèrè nípa sínsin-ín ní ibẹ̀. Ó sì di ìdẹ̀kùn fún Gideoni àti ìdílé rẹ̀.
И от тях Гедеон направи ефод, който положи в града си, в Офра; а там целият Израил блудствува след него; и той стана примка на Гедеона и на дома му.
28 Báyìí ni a ṣe tẹrí àwọn ará Midiani ba níwájú àwọn ọmọ Israẹli bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tún gbé orí mọ́. Ní ọjọ́ Gideoni, Israẹli wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún.
Така Мадиам се покори пред израилтяните, и не дигна вече глава. И земята имаше спокойствие четиридесет години в дните на Гедеона.
29 Jerubbaali ọmọ Joaṣi padà lọ láti máa gbé ní ìlú rẹ̀.
Тогава Ероваал, Иоасовият син, отиде и седна в дома си.
30 Àádọ́rin ọmọ ni Gideoni bí, nítorí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìyàwó.
И Гедеон имаше седемдесет сине, родени от самия него, защото имаше много жени.
31 Àlè rẹ̀, tó ń gbé ní Ṣekemu, pàápàá bí ọmọkùnrin kan fún un tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Abimeleki.
Също и наложницата му, която беше в Сихем, му роди син, когото той нарече Авимелех.
32 Gideoni ọmọ Joaṣi kú ní ògbólógbòó ọjọ́ rẹ̀, ó sì pọ̀ ní ọjọ́ orí, wọ́n sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀ ní Ofira ti àwọn ará Abieseri.
И Гедеон, Иоасовият син, умря в честита старост, и биде погребан в гроба на баща си Иоаса, в Офра на авиерците.
33 Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gideoni ni àwọn ará Israẹli ṣe àgbèrè tọ Baali lẹ́yìn, wọ́n fi Baali-Beriti ṣe òrìṣà wọn.
А когато умря Гедеон, израилтяните пак се отвърнаха, и, като блудствуваха след ваалимите, поставиха си Ваалверита за бог.
34 Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.
И израилтяните не си спомниха Господа своя Бог, Който ги бе избавил от ръката на всичките им околни неприятели;
35 Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jerubbaali (èyí ni Gideoni) fún gbogbo oore tí ó ṣe fún wọn.
нито показаха благост към дома на Ероваала (който е Гедеон) съответно на всичките добрини, които той бе сторил на Израиля.