< Judges 7 >

1 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Jerubbaali (èyí ni Gideoni) pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kó ogun jọ lẹ́bàá a orísun Harodi. Àwọn ogun Midiani sì wà ní apá àríwá tí wọ́n ní àfonífojì tí ó wà ní ẹ̀bá òkè More.
Bittida följande morgon drog Jerubbaal, det är Gideon, åstad med allt folket som följde honom, och de lägrade sig vid Harodskällan; han hade då midjaniternas läger norr om sig, från Morehöjden ned i dalen.
2 Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọmọ-ogun tí o kójọ sọ́dọ̀ ti pọ̀jù fún mi láti fi àwọn ogun Midiani lé wọn lọ́wọ́, kí Israẹli má ba à gbé ara rẹ̀ ga sí mi wí pé agbára òun ni ó gbà á là,
Men HERREN sade till Gideon: "Folket som har följt dig är för talrikt för att jag skulle vilja giva Midjan i deras hand; ty Israel kunde då berömma sig mot mig och säga: 'Min egen hand har frälst mig.'
3 sì kéde sí àwọn ènìyàn nísinsin yìí pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbọ̀n, tí ó sì ń bẹ̀rù lè padà sẹ́yìn, kí ó sì kúrò lórí òkè Gileadi.’” Báyìí ni Gideoni ṣe ya àwọn ènìyàn náà. Ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ọkùnrin sì padà sẹ́yìn àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì dúró.
Låt därför nu utropa för folket och säga: Om någon fruktar och är rädd, så må han vända tillbaka hem och skynda bort ifrån Gileads berg." Då vände tjugutvå tusen man av folket tillbaka, så att allenast tio tusen man stannade kvar.
4 Olúwa sì tún sọ fún Gideoni pé, “Àwọn ènìyàn yìí sì tún pọ̀jù. Kó wọn lọ sí ibi tí omi wà, èmi yóò sì yọ̀rọ̀ wọn níbẹ̀ fún ọ. Bí mo bá wí pé eléyìí yóò bá ọ lọ yóò lọ, ṣùgbọ́n tí mo bá sọ pé, ‘Eléyìí kò ní bá ọ lọ,’ òun kò gbọdọ̀ lọ.”
Men HERREN sade till Gideon: "Folket är ännu för talrikt; för dem ned till vattnet, så skall jag där göra ett urval av dem åt dig. Den om vilken jag då säger till dig: 'Denne skall gå med dig', han får gå med dig, men var och en om vilken jag säger till dig: 'Denne skall icke gå med dig', han får icke gå med."
5 Gideoni sì kó àwọn ọkùnrin náà lọ sí ibi ìsun omi. Níbẹ̀ ni Olúwa ti wí fún un pé, “Kí ó pín àwọn ènìyàn náà sí ọ̀nà méjì. Ya àwọn tí ó fi ahọ́n wọn lá omi bí ajá kúrò lára àwọn tí ó kúnlẹ̀ láti mu omi pẹ̀lú ọwọ́ wọn.”
Så förde han då folket ned till vattnet. Och HERREN sade till Gideon: "Alla som läppja av vattnet, såsom hunden gör, dem skall du ställa för sig, och likaså alla som falla ned på knä för att dricka."
6 Ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin ni ó lá omi pẹ̀lú ahọ́n wọn. Gbogbo àwọn ìyókù ni ó kúnlẹ̀ láti mu mi.
Då befanns antalet av dem som hade läppjat av vattnet, genom att med handen föra det till munnen, vara tre hundra man; allt det övriga folket hade fallit ned på knä för att dricka vatten.
7 Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó lá omi ni èmi yóò lò láti gbà yín là àti láti fi ogun Midiani lé yín lọ́wọ́. Jẹ́ kí àwọn tókù padà sí ilé wọn.”
Och HERREN sade till Gideon: "Med de tre hundra män som hava läppjat av vattnet skall jag frälsa eder och giva Midjan i din hand; allt det andra folket må begiva sig hem, var och en till sitt."
8 Báyìí ni Gideoni ṣe dá àwọn Israẹli tí ó kù padà sí àgọ́ wọn, ṣùgbọ́n ó dá àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin náà dúró. Àwọn wọ̀nyí sì gba gbogbo ohun èlò àti fèrè àwọn tí ó ti padà. Ibùdó ogun àwọn Midiani wà ní àfonífojì ní ìsàlẹ̀. Ibi tí ó wà.
Då tog hans folk till sig sitt munförråd och sina basuner, därefter lät han alla de andra israeliterna gå hem, var och en till sin hydda; han behöll allenast de tre hundra männen. Och midjaniternas läger hade han nedanför sig i dalen.
9 Ní òru ọjọ́ náà Olúwa sọ fún Gideoni pé, “Dìde, dojú ogun kọ ibùdó ogun àwọn ará Midiani nítorí èmi yóò fi lé ọ lọ́wọ́.
Och HERREN sade den natten till honom: "Stå upp och drag ned i lägret, ty jag har givit det i din hand.
10 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀rù àti kọlù wọ́n bá ń bà ọ́, yọ́ wọ ibùdó wọn lọ kí o mú Pura ìránṣẹ́ rẹ lọ́wọ́
Men om du fruktar för att draga ditned, så må du gå förut med din tjänare Pura ned till lägret
11 kí o sì fi ara balẹ̀ gbọ́ ohun tí wọ́n ń sọ nínú ibùdó náà. Lẹ́yìn èyí ọkàn rẹ̀ yóò le láti kọlù ibùdó náà.” Báyìí ni òun àti Pura ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ ẹnu-ọ̀nà ibùdó yìí.
och höra efter, vad man där talar; sedan skall du få mod till att draga ditned och bryta in i lägret." Så gick han då med sin tjänare Pura ned till förposterna i lägret.
12 Àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti gbogbo ènìyàn ìlà-oòrùn tó lọ ní àfonífojì bí eṣú ni wọ́n rí nítorí púpọ̀ wọn. Àwọn ìbákasẹ wọn kò sì lóǹkà, wọ́n sì pọ̀ bí yanrìn inú Òkun.
Och midjaniterna, amalekiterna och alla österlänningarna lågo där i dalen, talrika såsom gräshoppor; och deras kameler voro oräkneliga, talrika såsom sanden på havets strand.
13 Gideoni dé sí àsìkò tí ọkùnrin kan bẹ̀rẹ̀ sí í rọ́ àlá tí ó lá sí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀. Ó ní, “Mo lá àlá kan, nínú àlá náà mo rí àkàrà kan tó ṣe róbótó tí a fi barle ṣe ń yí wọ inú ibùdó àwọn ará Midiani, ó sì kọlu àgọ́ pẹ̀lú agbára ńlá dé bi wí pé àgọ́ náà dojúdé, ó sì ṣubú.”
Då nu Gideon kom dit, höll en man just på att förtälja en dröm för en annan. Han sade: "Jag har nyss haft en dröm. Jag tyckte att en kornbrödskaka kom rullande in i midjaniternas läger. Den kom ända fram till tältet och slog emot det, så att det föll, och vände upp och ned på det, och tältet blev så liggande."
14 Ọ̀rẹ́ rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Èyí kò le túmọ̀ sí ohun mìíràn ju idà Gideoni ọmọ Joaṣi ará Israẹli lọ: Ọlọ́run ti fi àwọn ará Midiani àti gbogbo ogun ibùdó lé e lọ́wọ́.”
Då svarade den andre och sade: "Detta betyder intet annat än israeliten Gideons, Joas' sons, svärd; Gud har givit Midjan och hela lägret i hans hand."
15 Nígbà tí Gideoni gbọ́ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀, ó wólẹ̀ sin Ọlọ́run: lẹ́yìn náà ni ó padà sí ibùdó àwọn ọmọ Israẹli ó sì pè wọ́n pé, “Ẹ dìde! Nítorí pé Olúwa yóò lò yín láti ṣẹ́gun gbogbo ogun Midiani.”
När Gideon hörde denna dröm förtäljas och hörde dess uttydning, föll han ned och tillbad. Därefter vände han tillbaka till Israels läger och sade: "Stån upp, ty HERREN har givit midjaniternas läger i eder hand.
16 Nígbà tí ó ti pín àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì sí ọ̀nà mẹ́ta, ó fi fèrè, pẹ̀lú àwọn òfìfo ìkòkò lé ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn lọ́wọ́, iná sì wà nínú àwọn ìkòkò náà.
Och han delade sina tre hundra män i tre hopar och gav allasammans basuner i händerna, så ock tomma krukor, med facklor inne i krukorna.
17 Ó sọ fún wọn pé, “Ẹ máa wò mí, kí ẹ sì máa ṣe ohun tí mo bá ṣe. Nígbà tí mo bá dé igun ibùdó wọn ẹ ṣe ohun tí mo bá ṣe.
Och han sade till dem: "Sen på mig och gören såsom jag; så snart jag har kommit till utkanten av lägret, skolen I göra såsom jag gör.
18 Nígbà tí èmi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi bá fun fèrè wa, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin náà ni gbogbo igun ibùdó tí ẹ̀ bá wà kí ẹ fun àwọn fèrè yín kí ẹ sì hó pé, ‘Fún Olúwa àti fún Gideoni.’”
När nämligen jag och alla som jag har med mig stöta i basunerna, skolen ock I stöta i basunerna runt omkring hela lägret och ropa: 'För HERREN och för Gideon!'"
19 Gideoni àti àwọn ọgọ́rùn-ún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ dé òpin ibùdó àwọn ará Midiani ní nǹkan bí agogo méjìlá padà. Wọ́n fun fèrè wọn, wọ́n sì tún fọ́ àwọn ìkòkò tí ó wà ní ọwọ́ mọ́lẹ̀.
Så kommo nu Gideon och de hundra män, som han hade med sig, till utkanten av lägret, när den mellersta nattväkten ingick; och man hade just ställt ut vakterna. Då stötte de i basunerna och krossade krukorna som de hade i sina händer.
20 Àwọn ẹgbẹ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta fun fèrè wọn, wọ́n tún fọ́ àwọn ìkòkò wọn mọ́lẹ̀. Wọ́n mú àwọn fìtílà iná wọn ní ọwọ́ òsì wọn àti fèrè tí wọ́n ń fun ní ọwọ́ ọ̀tún wọn. Wọ́n pariwo hé è pé, “Idà kan fún Olúwa àti fún Gideoni!”
De tre hoparna stötte i basunerna och slogo sönder krukorna; de fattade med vänstra handen i facklorna och med högra handen i basunerna och stötte i dem; och de ropade: "HERRENS och Gideons svärd!"
21 Nígbà tí ọkùnrin kọ̀ọ̀kan dúró ní ipò rẹ̀ yí ibùdó àwọn Midiani ká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun Midiani ń sá káàkiri, wọ́n ń pariwo bí wọ́n ṣe ń sálọ.
Men de stodo stilla, var och en på sin plats, runt omkring lägret. Då begynte alla i lägret att löpa hit och dit och skria och fly.
22 Nígbà tí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì fun fèrè wọn, Olúwa sì yí ojú idà ọkùnrin kọ̀ọ̀kan padà sí ẹnìkejì rẹ̀ àti sí gbogbo ogun wọn. Àwọn ọmọ-ogun sì sá títí dé Beti-Sitta ní ọ̀nà Serera títí lọ dé ìpínlẹ̀ Abeli-Mehola ní ẹ̀bá Tabbati.
Och när de stötte i de tre hundra basunerna, vände HERREN den enes svärd mot den andre i hela lägret; och de som voro i lägret flydde ända till Bet-Hasitta, åt Serera till, ända till stranden vid Abel-Mehola, förbi Tabbat.
23 Gbogbo àwọn ọmọ-ogun Israẹli láti ẹ̀yà Naftali, Aṣeri àti gbogbo Manase ni Gideoni ránṣẹ́ si, wọ́n wá wọ́n sì lé àwọn ará Midiani.
Och åter församlade sig israeliterna, från Naftali och Aser och från hela Manasse, och förföljde midjaniterna.
24 Gideoni tún ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè Efraimu wí pé, “Ẹ jáde wá bá àwọn ará Midiani jà, kí ẹ tètè gba àwọn omi Jordani títí dé Beti-Bara kí wọ́n tó dé bẹ̀.” Báyìí ni a ṣe pe gbogbo ọkùnrin ológun Efraimu jáde tí wọ́n sì gba gbogbo àwọn à bá wọ odò Jordani títí dé Beti-Bara.
Och Gideon hade sänt omkring budbärare i hela Efraims bergsbygd och låtit säga: "Dragen ned mot Midjan och besätten i deras väg vattendragen ända till Bet-Bara, ävensom Jordan." Så församlade sig alla Efraims män och besatte vattendragen ända till Bet-Bara, ävensom Jordan.
25 Wọ́n mú méjì nínú àwọn olórí àwọn ará Midiani, àwọn náà ni Orebu àti Seebu. Wọ́n pa Horebu nínú àpáta Orebu, wọ́n sì pa Seebu níbi tí àwọn ènìyàn ti mọ̀ fún wáìnì tí a ń pè ní ìfúntí Seebu. Wọ́n lé àwọn ará Midiani, nígbà tí wọ́n gbé orí Orebu àti Seebu tọ Gideoni wá ẹni tí ó wà ní apá kejì Jordani.
Och de togo två midjanitiska hövdingar, Oreb och Seeb, till fånga, och dräpte Oreb vid Orebsklippan, och Seeb dräpte de vid Seebspressen, och förföljde så midjaniterna. Men Orebs och Seebs huvuden förde de över till Gideon på andra sidan Jordan.

< Judges 7 >