< Judges 7 >

1 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Jerubbaali (èyí ni Gideoni) pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kó ogun jọ lẹ́bàá a orísun Harodi. Àwọn ogun Midiani sì wà ní apá àríwá tí wọ́n ní àfonífojì tí ó wà ní ẹ̀bá òkè More.
Då stod JerubBaal, det är Gideon, bittida upp, och allt folket, som med honom var, och lägrade sig vid den brunnen Harod, så att han hade de Midianiters här norrut, bakföre det berget More i dalenom.
2 Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọmọ-ogun tí o kójọ sọ́dọ̀ ti pọ̀jù fún mi láti fi àwọn ogun Midiani lé wọn lọ́wọ́, kí Israẹli má ba à gbé ara rẹ̀ ga sí mi wí pé agbára òun ni ó gbà á là,
Och Herren sade till Gideon: Folket, som med dig är, är allt för mycket. Om jag gåfve Midian i deras händer, måtte Israels barn berömma sig emot mig, och säga: Min hand hafver frälst mig.
3 sì kéde sí àwọn ènìyàn nísinsin yìí pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbọ̀n, tí ó sì ń bẹ̀rù lè padà sẹ́yìn, kí ó sì kúrò lórí òkè Gileadi.’” Báyìí ni Gideoni ṣe ya àwọn ènìyàn náà. Ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ọkùnrin sì padà sẹ́yìn àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì dúró.
Så låt nu utropa för folkets öron, och säga: Den som rädder är och förfärad, han vände om, och skynde sig af berget Gilead. Då vände folket tillbaka, tu och tjugu tusend, så att icke utan tiotusend blefvo qvara.
4 Olúwa sì tún sọ fún Gideoni pé, “Àwọn ènìyàn yìí sì tún pọ̀jù. Kó wọn lọ sí ibi tí omi wà, èmi yóò sì yọ̀rọ̀ wọn níbẹ̀ fún ọ. Bí mo bá wí pé eléyìí yóò bá ọ lọ yóò lọ, ṣùgbọ́n tí mo bá sọ pé, ‘Eléyìí kò ní bá ọ lọ,’ òun kò gbọdọ̀ lọ.”
Och Herren sade till Gideon: Detta folket är ännu för mycket; haf dem neder till vattnet, der vill jag pröfva dig dem; och om hvilken jag säger dig, att han skall draga med dig, han skall draga med dig; och om hvilken jag säger, att han icke skall draga med dig, han skall icke draga.
5 Gideoni sì kó àwọn ọkùnrin náà lọ sí ibi ìsun omi. Níbẹ̀ ni Olúwa ti wí fún un pé, “Kí ó pín àwọn ènìyàn náà sí ọ̀nà méjì. Ya àwọn tí ó fi ahọ́n wọn lá omi bí ajá kúrò lára àwọn tí ó kúnlẹ̀ láti mu omi pẹ̀lú ọwọ́ wọn.”
Och han hade folket neder till vattnet. Och Herren sade till Gideon: Hvilken som läppjar vattnet med sine tungo, såsom en hund läppjar, honom ställ afsides; desslikes dem som på sin knä nederfalla till att dricka.
6 Ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin ni ó lá omi pẹ̀lú ahọ́n wọn. Gbogbo àwọn ìyókù ni ó kúnlẹ̀ láti mu mi.
Då var deras tal, som med munnen läppjat hade utu handene, trehundrade män; allt det andra folket hade fallit på knä och druckit.
7 Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó lá omi ni èmi yóò lò láti gbà yín là àti láti fi ogun Midiani lé yín lọ́wọ́. Jẹ́ kí àwọn tókù padà sí ilé wọn.”
Och Herren sade till Gideon: Med de trehundrade män, som läppjat hafva, vill jag frälsa eder, och gifva de Midianiter i dina händer; men det andra folket låt alltsammans gå hem till sitt.
8 Báyìí ni Gideoni ṣe dá àwọn Israẹli tí ó kù padà sí àgọ́ wọn, ṣùgbọ́n ó dá àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin náà dúró. Àwọn wọ̀nyí sì gba gbogbo ohun èlò àti fèrè àwọn tí ó ti padà. Ibùdó ogun àwọn Midiani wà ní àfonífojì ní ìsàlẹ̀. Ibi tí ó wà.
Och de togo spisning för folket med sig, och sina basuner; men de andra Israeliter lät han alla gå hvar och en i sina hyddo; men han stärkte sig med de trehundrade män; och de Midianiters här låg nedanför honom i dalenom.
9 Ní òru ọjọ́ náà Olúwa sọ fún Gideoni pé, “Dìde, dojú ogun kọ ibùdó ogun àwọn ará Midiani nítorí èmi yóò fi lé ọ lọ́wọ́.
Och Herren sade till honom i samma natt: Statt upp, och gack neder till lägret; ty jag hafver gifvit dem i dina händer.
10 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀rù àti kọlù wọ́n bá ń bà ọ́, yọ́ wọ ibùdó wọn lọ kí o mú Pura ìránṣẹ́ rẹ lọ́wọ́
Om du fruktar dig att gå ditneder, så låt din dräng Pura gå ned med dig till lägret;
11 kí o sì fi ara balẹ̀ gbọ́ ohun tí wọ́n ń sọ nínú ibùdó náà. Lẹ́yìn èyí ọkàn rẹ̀ yóò le láti kọlù ibùdó náà.” Báyìí ni òun àti Pura ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ ẹnu-ọ̀nà ibùdó yìí.
Att du må få höra hvad de tala; sedan skall du med magt draga neder till lägret. Så gick Gideon med sin dräng Pura neder till det rummet på lägret, der vakten var.
12 Àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti gbogbo ènìyàn ìlà-oòrùn tó lọ ní àfonífojì bí eṣú ni wọ́n rí nítorí púpọ̀ wọn. Àwọn ìbákasẹ wọn kò sì lóǹkà, wọ́n sì pọ̀ bí yanrìn inú Òkun.
Men de Midianiter och de Amalekiter, och alle österländningarna, hade lägrat sig i dalenom, såsom en hop gräshoppor; och deras cameler stodo icke till att räkna, så månge voro de, såsom sanden på hafsens strand.
13 Gideoni dé sí àsìkò tí ọkùnrin kan bẹ̀rẹ̀ sí í rọ́ àlá tí ó lá sí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀. Ó ní, “Mo lá àlá kan, nínú àlá náà mo rí àkàrà kan tó ṣe róbótó tí a fi barle ṣe ń yí wọ inú ibùdó àwọn ará Midiani, ó sì kọlu àgọ́ pẹ̀lú agbára ńlá dé bi wí pé àgọ́ náà dojúdé, ó sì ṣubú.”
Då nu Gideon kom, si, då förtäljde en för dem andra en dröm, och sade: Mig tyckte, att ett bjuggbröd, på glöd bakadt, välte sig intill de Midianiters lägre, och då det kom till tjället, slog det det, och kastade det neder, och vände upp ned uppå thy, så att tjället låg.
14 Ọ̀rẹ́ rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Èyí kò le túmọ̀ sí ohun mìíràn ju idà Gideoni ọmọ Joaṣi ará Israẹli lọ: Ọlọ́run ti fi àwọn ará Midiani àti gbogbo ogun ibùdó lé e lọ́wọ́.”
Då svarade den andre: Det är icke annat än Gideons svärd, Joas sons, den Israelitens; Gud hafver gifvit de Midianiter i hans händer med hela hären.
15 Nígbà tí Gideoni gbọ́ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀, ó wólẹ̀ sin Ọlọ́run: lẹ́yìn náà ni ó padà sí ibùdó àwọn ọmọ Israẹli ó sì pè wọ́n pé, “Ẹ dìde! Nítorí pé Olúwa yóò lò yín láti ṣẹ́gun gbogbo ogun Midiani.”
Då Gideon nu hörde förtäljas sådana dröm, och hans utläggning, tillbad han, och kom igen i Israels här, och sade: Upp, ty Herren hafver gifvit de Midianiters här uti edra händer.
16 Nígbà tí ó ti pín àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì sí ọ̀nà mẹ́ta, ó fi fèrè, pẹ̀lú àwọn òfìfo ìkòkò lé ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn lọ́wọ́, iná sì wà nínú àwọn ìkòkò náà.
Och han skifte de trehundrade män i tre delar, och fick hvarjom och enom en basun i sina hand, och tomma krukor, och lampor deruti;
17 Ó sọ fún wọn pé, “Ẹ máa wò mí, kí ẹ sì máa ṣe ohun tí mo bá ṣe. Nígbà tí mo bá dé igun ibùdó wọn ẹ ṣe ohun tí mo bá ṣe.
Och sade till dem: Ser på mig, och görer ock så; si, när jag kommer intill hären, såsom jag gör, så görer ock med.
18 Nígbà tí èmi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi bá fun fèrè wa, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin náà ni gbogbo igun ibùdó tí ẹ̀ bá wà kí ẹ fun àwọn fèrè yín kí ẹ sì hó pé, ‘Fún Olúwa àti fún Gideoni.’”
Såsom jag blås i basunen, och alle de som med mig äro, så skolen ock I blåsa i basunen omkring hela hären, och säga: Herren och Gideon.
19 Gideoni àti àwọn ọgọ́rùn-ún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ dé òpin ibùdó àwọn ará Midiani ní nǹkan bí agogo méjìlá padà. Wọ́n fun fèrè wọn, wọ́n sì tún fọ́ àwọn ìkòkò tí ó wà ní ọwọ́ mọ́lẹ̀.
Så kom Gideon, och hundrade män med honom, till det yttersta på hären, till första väktarena, som der skickade voro och väckte dem upp, och blåste med basunerna, och slogo sönder krukorna i sina händer.
20 Àwọn ẹgbẹ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta fun fèrè wọn, wọ́n tún fọ́ àwọn ìkòkò wọn mọ́lẹ̀. Wọ́n mú àwọn fìtílà iná wọn ní ọwọ́ òsì wọn àti fèrè tí wọ́n ń fun ní ọwọ́ ọ̀tún wọn. Wọ́n pariwo hé è pé, “Idà kan fún Olúwa àti fún Gideoni!”
Och så blåste då alle tre hoparna med basunerna, och slogo sönder krukorna; men lamporna höllo de i deras venstra hand, och basunen i deras högra hand, och blåste och ropade: Herrans och Gideons svärd.
21 Nígbà tí ọkùnrin kọ̀ọ̀kan dúró ní ipò rẹ̀ yí ibùdó àwọn Midiani ká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun Midiani ń sá káàkiri, wọ́n ń pariwo bí wọ́n ṣe ń sálọ.
Och hvar och en stod på sitt rum, omkring hären. Då begynte hela hären att löpa, ropa och fly.
22 Nígbà tí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì fun fèrè wọn, Olúwa sì yí ojú idà ọkùnrin kọ̀ọ̀kan padà sí ẹnìkejì rẹ̀ àti sí gbogbo ogun wọn. Àwọn ọmọ-ogun sì sá títí dé Beti-Sitta ní ọ̀nà Serera títí lọ dé ìpínlẹ̀ Abeli-Mehola ní ẹ̀bá Tabbati.
Och som de trehundrade män blåste i basunerna, gjorde Herren så, att hvars och ens svärd i hela härenom var emot den andra; och hären flydde allt intill BethSittaZereratha, allt intill gränsona åt den slättene Mehola vid Tabbath.
23 Gbogbo àwọn ọmọ-ogun Israẹli láti ẹ̀yà Naftali, Aṣeri àti gbogbo Manase ni Gideoni ránṣẹ́ si, wọ́n wá wọ́n sì lé àwọn ará Midiani.
Och de Israels män af Naphthali, af Asser, och af hela Manasse, skriade, och jagade efter de Midianiter.
24 Gideoni tún ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè Efraimu wí pé, “Ẹ jáde wá bá àwọn ará Midiani jà, kí ẹ tètè gba àwọn omi Jordani títí dé Beti-Bara kí wọ́n tó dé bẹ̀.” Báyìí ni a ṣe pe gbogbo ọkùnrin ológun Efraimu jáde tí wọ́n sì gba gbogbo àwọn à bá wọ odò Jordani títí dé Beti-Bara.
Och Gideon sände bådskap på hela berget Ephraim, och lät säga dem: Kommer neder emot de Midianiter, och kommer förr än de till vattnet, intill BethBara och Jordan. Så ropade alle de som af Ephraim voro, och kommo förr än de till vattnet, intill BethBara och Jordan.
25 Wọ́n mú méjì nínú àwọn olórí àwọn ará Midiani, àwọn náà ni Orebu àti Seebu. Wọ́n pa Horebu nínú àpáta Orebu, wọ́n sì pa Seebu níbi tí àwọn ènìyàn ti mọ̀ fún wáìnì tí a ń pè ní ìfúntí Seebu. Wọ́n lé àwọn ará Midiani, nígbà tí wọ́n gbé orí Orebu àti Seebu tọ Gideoni wá ẹni tí ó wà ní apá kejì Jordani.
Och de fingo fatt på två de Midianiters Förstar, Oreb och Seeb; och dråpo Oreb på det hälleberget Oreb, och Seeb i Seebs press; och jagade de Midianiter; och båro Orebs och Seebs hufvud till Gideon öfver Jordan.

< Judges 7 >