< Judges 7 >
1 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Jerubbaali (èyí ni Gideoni) pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kó ogun jọ lẹ́bàá a orísun Harodi. Àwọn ogun Midiani sì wà ní apá àríwá tí wọ́n ní àfonífojì tí ó wà ní ẹ̀bá òkè More.
Wstał tedy bardzo rano Jerobaal, który jest Giedeon, i wszystek lud, który był z nim, i położyli się obozem u źródła Harod, a obóz Madyjański był im na północy od pagórka More w dolinie.
2 Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọmọ-ogun tí o kójọ sọ́dọ̀ ti pọ̀jù fún mi láti fi àwọn ogun Midiani lé wọn lọ́wọ́, kí Israẹli má ba à gbé ara rẹ̀ ga sí mi wí pé agbára òun ni ó gbà á là,
I rzekł Pan do Giedeona: Wielki jest lud z tobą; przetoż nie dam Madyjanitów w ręce ich, by się snać nie chlubił przeciw mnie Izrael, mówiąc: Ręka moja wybawiła mię.
3 sì kéde sí àwọn ènìyàn nísinsin yìí pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbọ̀n, tí ó sì ń bẹ̀rù lè padà sẹ́yìn, kí ó sì kúrò lórí òkè Gileadi.’” Báyìí ni Gideoni ṣe ya àwọn ènìyàn náà. Ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ọkùnrin sì padà sẹ́yìn àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì dúró.
A tak zawołaj teraz, aby słyszał lud, mówiąc: Kto jest lękliwym i bojaźliwym, niech się wróci, a rano niechaj idzie precz ku górze Galaad. Tedy się wróciło z ludu dwadzieścia i dwa tysiące, a dziesięć tysięcy ich zostało.
4 Olúwa sì tún sọ fún Gideoni pé, “Àwọn ènìyàn yìí sì tún pọ̀jù. Kó wọn lọ sí ibi tí omi wà, èmi yóò sì yọ̀rọ̀ wọn níbẹ̀ fún ọ. Bí mo bá wí pé eléyìí yóò bá ọ lọ yóò lọ, ṣùgbọ́n tí mo bá sọ pé, ‘Eléyìí kò ní bá ọ lọ,’ òun kò gbọdọ̀ lọ.”
I rzekł Pan do Giedeona: Jeszcze lud wielki. Zaprowadź ich do wody, a tam go doświadczę; albowiem o kim ci powiem: Ten niech idzie z tobą, ten pójdzie z tobą, a o kimcikolwiek powiem: Ten niech nie chodzi z tobą, ten nie pójdzie.
5 Gideoni sì kó àwọn ọkùnrin náà lọ sí ibi ìsun omi. Níbẹ̀ ni Olúwa ti wí fún un pé, “Kí ó pín àwọn ènìyàn náà sí ọ̀nà méjì. Ya àwọn tí ó fi ahọ́n wọn lá omi bí ajá kúrò lára àwọn tí ó kúnlẹ̀ láti mu omi pẹ̀lú ọwọ́ wọn.”
Tedy zaprowadził lud do wód; i rzekł Pan do Giedeona: Każdego, który łeptać będzie językiem swoim wodę, jako pies łepce, postawisz go osobno; także każdego, który uklęknie na kolana swoje, aby pił, stanie osobno.
6 Ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin ni ó lá omi pẹ̀lú ahọ́n wọn. Gbogbo àwọn ìyókù ni ó kúnlẹ̀ láti mu mi.
I była liczba tych, którzy chwytali ręką swoją do ust swoich wodę, trzy sta mężów; a wszystek inny lud uklęknąwszy na kolana swoje, pił wodę.
7 Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó lá omi ni èmi yóò lò láti gbà yín là àti láti fi ogun Midiani lé yín lọ́wọ́. Jẹ́ kí àwọn tókù padà sí ilé wọn.”
Tedy rzekł Pan do Giedeona: Przez tych trzy sta mężów, którzy łeptali wodę, wybawię was, a podam Madyjanity w ręce twoje, a inny wszystek lud, każdy niech idzie na miejsce swoje.
8 Báyìí ni Gideoni ṣe dá àwọn Israẹli tí ó kù padà sí àgọ́ wọn, ṣùgbọ́n ó dá àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin náà dúró. Àwọn wọ̀nyí sì gba gbogbo ohun èlò àti fèrè àwọn tí ó ti padà. Ibùdó ogun àwọn Midiani wà ní àfonífojì ní ìsàlẹ̀. Ibi tí ó wà.
A tak on lud wziął żywności z sobą, i trąby swe; a inne wszystkie męże Izraelskie rozpuścił każdego do namiotu swego, trzy sta tylko mężów zostawiwszy; a obóz Madyjański był pod nim w dolinie.
9 Ní òru ọjọ́ náà Olúwa sọ fún Gideoni pé, “Dìde, dojú ogun kọ ibùdó ogun àwọn ará Midiani nítorí èmi yóò fi lé ọ lọ́wọ́.
I stało się onej nocy, że rzekł do niego Pan. Wstań, znijdź do obozu, bom go dał w ręce twoje;
10 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀rù àti kọlù wọ́n bá ń bà ọ́, yọ́ wọ ibùdó wọn lọ kí o mú Pura ìránṣẹ́ rẹ lọ́wọ́
A jeźli się ty sam iść boisz, znijdźże z Farą, sługą twoim, do obozu.
11 kí o sì fi ara balẹ̀ gbọ́ ohun tí wọ́n ń sọ nínú ibùdó náà. Lẹ́yìn èyí ọkàn rẹ̀ yóò le láti kọlù ibùdó náà.” Báyìí ni òun àti Pura ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ ẹnu-ọ̀nà ibùdó yìí.
I usłyszysz, co będą mówić; a potem posilą się ręce twoje, i pociągniesz na obóz. A tak szedł on sam, i Fara, sługa jego, aż na koniec zbrojnego ludu, który był w obozie.
12 Àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti gbogbo ènìyàn ìlà-oòrùn tó lọ ní àfonífojì bí eṣú ni wọ́n rí nítorí púpọ̀ wọn. Àwọn ìbákasẹ wọn kò sì lóǹkà, wọ́n sì pọ̀ bí yanrìn inú Òkun.
A Madyjanitowie i Amalekitowie, i wszystek lud od wschodu słońca leżeli w dolinie, jako szarańcza przemnóstwo, i wielbłądów ich nie było liczby, jako piasek, który jest na brzegu morskim niezliczony.
13 Gideoni dé sí àsìkò tí ọkùnrin kan bẹ̀rẹ̀ sí í rọ́ àlá tí ó lá sí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀. Ó ní, “Mo lá àlá kan, nínú àlá náà mo rí àkàrà kan tó ṣe róbótó tí a fi barle ṣe ń yí wọ inú ibùdó àwọn ará Midiani, ó sì kọlu àgọ́ pẹ̀lú agbára ńlá dé bi wí pé àgọ́ náà dojúdé, ó sì ṣubú.”
Tam gdy przyszedł Giedeon, oto, niektóry powiadał towarzyszowi swemu sen, i rzekł: Oto śnił mi się sen, a zdało mi się, że bochen chleba jęczmiennego toczył się do obozu Madyjańskiego, i przytoczył się aż do namiotu, i uderzył weń, aż poległ, i wywrócił go z wierzchu, i upadł namiot.
14 Ọ̀rẹ́ rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Èyí kò le túmọ̀ sí ohun mìíràn ju idà Gideoni ọmọ Joaṣi ará Israẹli lọ: Ọlọ́run ti fi àwọn ará Midiani àti gbogbo ogun ibùdó lé e lọ́wọ́.”
Któremu odpowiedział towarzysz, jego i rzekł: Nic to nie jest innego, jedno miecz Giedeona, syna Joasowego, męża Izraelskiego; dał Bóg w rękę jego Madyjanity ze wszystkim obozem.
15 Nígbà tí Gideoni gbọ́ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀, ó wólẹ̀ sin Ọlọ́run: lẹ́yìn náà ni ó padà sí ibùdó àwọn ọmọ Israẹli ó sì pè wọ́n pé, “Ẹ dìde! Nítorí pé Olúwa yóò lò yín láti ṣẹ́gun gbogbo ogun Midiani.”
I stało się, gdy usłyszał Giedeon powieść snu onego, i wykład jego, podziękował Bogu, a wróciwszy się do obozu Izraelskiego, rzekł: Wstańcie; albowiem dał Pan w ręce wasze obóz Madyjański.
16 Nígbà tí ó ti pín àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì sí ọ̀nà mẹ́ta, ó fi fèrè, pẹ̀lú àwọn òfìfo ìkòkò lé ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn lọ́wọ́, iná sì wà nínú àwọn ìkòkò náà.
Rozdzielił tedy one trzy sta mężów na trzy hufce, a dał trąby w ręce każdemu z nich, i dzbany czcze, i pochodnie w pośrodek dzbanów
17 Ó sọ fún wọn pé, “Ẹ máa wò mí, kí ẹ sì máa ṣe ohun tí mo bá ṣe. Nígbà tí mo bá dé igun ibùdó wọn ẹ ṣe ohun tí mo bá ṣe.
I rzekł do nich: Co ujrzycie, że ja czynię, toż czyńcie; bo oto ja wnijdę w przodek obozu, a co ja czynić będę, toż wy czyńcie.
18 Nígbà tí èmi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi bá fun fèrè wa, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin náà ni gbogbo igun ibùdó tí ẹ̀ bá wà kí ẹ fun àwọn fèrè yín kí ẹ sì hó pé, ‘Fún Olúwa àti fún Gideoni.’”
Gdy zatrąbię w trąbę, ja i wszyscy, którzy są ze mną, tedy wy też zatrąbicie w trąby około wszystkiego obozu, i będziecie mówili: Miecz Pański i Giedeonów.
19 Gideoni àti àwọn ọgọ́rùn-ún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ dé òpin ibùdó àwọn ará Midiani ní nǹkan bí agogo méjìlá padà. Wọ́n fun fèrè wọn, wọ́n sì tún fọ́ àwọn ìkòkò tí ó wà ní ọwọ́ mọ́lẹ̀.
A tak szedł Giedeon, i sto mężów, którzy z nim byli, w przodek obozu, gdy się zaczęła średnia straż; zaraz skoro przemieniono straż i trąbili w trąby, a potłukli dzbany, które w rękach swych mieli.
20 Àwọn ẹgbẹ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta fun fèrè wọn, wọ́n tún fọ́ àwọn ìkòkò wọn mọ́lẹ̀. Wọ́n mú àwọn fìtílà iná wọn ní ọwọ́ òsì wọn àti fèrè tí wọ́n ń fun ní ọwọ́ ọ̀tún wọn. Wọ́n pariwo hé è pé, “Idà kan fún Olúwa àti fún Gideoni!”
Zatrąbiły też one trzy hufy w trąby, i potłukły dzbany; a wziąwszy w lewą rękę swoję pochodnie, a w prawą rękę swoję trąby, aby trąbili, wołali: Miecz Pański i Giedeonów.
21 Nígbà tí ọkùnrin kọ̀ọ̀kan dúró ní ipò rẹ̀ yí ibùdó àwọn Midiani ká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun Midiani ń sá káàkiri, wọ́n ń pariwo bí wọ́n ṣe ń sálọ.
I stanęli każdy na miejscu swojem koło obozu, a strwożył się wszystek obóz, i krzycząc uciekali.
22 Nígbà tí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì fun fèrè wọn, Olúwa sì yí ojú idà ọkùnrin kọ̀ọ̀kan padà sí ẹnìkejì rẹ̀ àti sí gbogbo ogun wọn. Àwọn ọmọ-ogun sì sá títí dé Beti-Sitta ní ọ̀nà Serera títí lọ dé ìpínlẹ̀ Abeli-Mehola ní ẹ̀bá Tabbati.
Gdy tedy trąbili oni trzy sta mężów w trąby, obrócił Pan miecz jednego przeciw drugiemu we wszystkim obozie; a tak uciekło wojsko aż do Betseta w Sererat, aż do granicy Abelmehola w Tabbat.
23 Gbogbo àwọn ọmọ-ogun Israẹli láti ẹ̀yà Naftali, Aṣeri àti gbogbo Manase ni Gideoni ránṣẹ́ si, wọ́n wá wọ́n sì lé àwọn ará Midiani.
A zebrawszy się mężowie Izraelscy z Neftalim, i z Aser, i ze wszystkiego pokolenia Manasesowego, gonili Madyjańczyki.
24 Gideoni tún ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè Efraimu wí pé, “Ẹ jáde wá bá àwọn ará Midiani jà, kí ẹ tètè gba àwọn omi Jordani títí dé Beti-Bara kí wọ́n tó dé bẹ̀.” Báyìí ni a ṣe pe gbogbo ọkùnrin ológun Efraimu jáde tí wọ́n sì gba gbogbo àwọn à bá wọ odò Jordani títí dé Beti-Bara.
Zatem posły rozesłał Giedeon na wszystkę górę Efraimską, mówiąc: Zabiegajcie Madyjanitom, a ubieżcie przed nimi wody aż do Betabara, i do Jordanu. Zebrali się tedy wszyscy mężowie z Efraima, i ubieżeli wody aż do Betabara i do Jordanu.
25 Wọ́n mú méjì nínú àwọn olórí àwọn ará Midiani, àwọn náà ni Orebu àti Seebu. Wọ́n pa Horebu nínú àpáta Orebu, wọ́n sì pa Seebu níbi tí àwọn ènìyàn ti mọ̀ fún wáìnì tí a ń pè ní ìfúntí Seebu. Wọ́n lé àwọn ará Midiani, nígbà tí wọ́n gbé orí Orebu àti Seebu tọ Gideoni wá ẹni tí ó wà ní apá kejì Jordani.
Przytem pojmali dwoje książąt Madyjańskich, Oreba i Zeba; a zabili Oreba na skale Oreb, a Zeba zabili u prasy Zeb, i gonili Madyjanity, a głowę Oreba i Zeba przynieśli do Giedeona za Jordan.