< Judges 7 >
1 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Jerubbaali (èyí ni Gideoni) pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kó ogun jọ lẹ́bàá a orísun Harodi. Àwọn ogun Midiani sì wà ní apá àríwá tí wọ́n ní àfonífojì tí ó wà ní ẹ̀bá òkè More.
Rũciinĩ tene, Jerubu-Baali (nĩwe Gideoni) na andũ ake othe nĩmambire hema gĩthima-inĩ kĩa Harodi. Kambĩ ya Amidiani yarĩ mwena wao wa gathigathini kũu gĩtuamba-inĩ, hakuhĩ na karĩma ka More.
2 Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọmọ-ogun tí o kójọ sọ́dọ̀ ti pọ̀jù fún mi láti fi àwọn ogun Midiani lé wọn lọ́wọ́, kí Israẹli má ba à gbé ara rẹ̀ ga sí mi wí pé agbára òun ni ó gbà á là,
Jehova akĩĩra Gideoni atĩrĩ, “Ũrĩ na andũ aingĩ mũno gũkĩra arĩa ngwenda nĩgeetha neane Amidiani moko-inĩ mao. Nĩgeetha Isiraeli matikanjĩtĩĩre atĩ nĩ hinya wao wamahonokia,
3 sì kéde sí àwọn ènìyàn nísinsin yìí pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbọ̀n, tí ó sì ń bẹ̀rù lè padà sẹ́yìn, kí ó sì kúrò lórí òkè Gileadi.’” Báyìí ni Gideoni ṣe ya àwọn ènìyàn náà. Ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ọkùnrin sì padà sẹ́yìn àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì dúró.
Na rĩrĩ, anĩrĩra kũrĩ andũ, ũmeere atĩrĩ, ‘Mũndũ o wothe ũrainaina nĩ guoya no ahũndũke, ehere Kĩrĩma-inĩ kĩa Gileadi.’” Nĩ ũndũ ũcio andũ 22,000 na igĩrĩ makĩehera, magĩtigara 10,000.
4 Olúwa sì tún sọ fún Gideoni pé, “Àwọn ènìyàn yìí sì tún pọ̀jù. Kó wọn lọ sí ibi tí omi wà, èmi yóò sì yọ̀rọ̀ wọn níbẹ̀ fún ọ. Bí mo bá wí pé eléyìí yóò bá ọ lọ yóò lọ, ṣùgbọ́n tí mo bá sọ pé, ‘Eléyìí kò ní bá ọ lọ,’ òun kò gbọdọ̀ lọ.”
No Jehova akĩĩra Gideoni atĩrĩ, “O na rĩu andũ no aingĩ mũno. Maikũrũkie maaĩ-inĩ, na nĩngũgũthuuranĩria andũ acio ho. Ingiuga atĩrĩ, ‘Ũyũ nĩegũthiĩ hamwe nawe,’ ũcio nĩwe ũrĩthiĩ nawe; no ingiuga atĩrĩ, ‘Ũyũ ndegũthiĩ hamwe nawe,’ ũcio ndegũthiĩ nawe.”
5 Gideoni sì kó àwọn ọkùnrin náà lọ sí ibi ìsun omi. Níbẹ̀ ni Olúwa ti wí fún un pé, “Kí ó pín àwọn ènìyàn náà sí ọ̀nà méjì. Ya àwọn tí ó fi ahọ́n wọn lá omi bí ajá kúrò lára àwọn tí ó kúnlẹ̀ láti mu omi pẹ̀lú ọwọ́ wọn.”
Nĩ ũndũ ũcio Gideoni agĩikũrũkia andũ acio maaĩ-inĩ. Marĩ hau Jehova akĩmwĩra atĩrĩ, “Amũrania arĩa mekũnyua maaĩ na rũrĩmĩ ta ũrĩa ngui ĩnyuuaga na arĩa mekũnyua maaĩ na hĩ ciao maturĩtie ndu.”
6 Ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin ni ó lá omi pẹ̀lú ahọ́n wọn. Gbogbo àwọn ìyókù ni ó kúnlẹ̀ láti mu mi.
Andũ magana matatũ makĩnyua maaĩ na hĩ ciao. Acio angĩ othe magĩturia ndu makĩnyua maaĩ.
7 Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó lá omi ni èmi yóò lò láti gbà yín là àti láti fi ogun Midiani lé yín lọ́wọ́. Jẹ́ kí àwọn tókù padà sí ilé wọn.”
Jehova akĩĩra Gideoni atĩrĩ, “Nĩngũmũhonokia na ũndũ wa andũ magana matatũ arĩa manyuire maaĩ na hĩ, neane Amidiani moko-inĩ manyu. Reke andũ acio angĩ othe mathiĩ, o mũndũ ainũke gwake.”
8 Báyìí ni Gideoni ṣe dá àwọn Israẹli tí ó kù padà sí àgọ́ wọn, ṣùgbọ́n ó dá àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin náà dúró. Àwọn wọ̀nyí sì gba gbogbo ohun èlò àti fèrè àwọn tí ó ti padà. Ibùdó ogun àwọn Midiani wà ní àfonífojì ní ìsàlẹ̀. Ibi tí ó wà.
Nĩ ũndũ ũcio Gideoni akĩĩra andũ acio angĩ a Isiraeli macooke hema-inĩ ciao, no agĩtigwo na andũ magana matatũ, arĩa mooire rĩĩgu na tũrumbeta twa acio mainũkire. Na rĩrĩ, kambĩ ya Amidiani yarĩ mũhuro wake o kũu kĩanda-inĩ.
9 Ní òru ọjọ́ náà Olúwa sọ fún Gideoni pé, “Dìde, dojú ogun kọ ibùdó ogun àwọn ará Midiani nítorí èmi yóò fi lé ọ lọ́wọ́.
Ũtukũ ũcio Jehova akĩĩra Gideoni atĩrĩ, “Ũkĩra, ũikũrũke ũtharĩkĩre kambĩ ĩyo ya Amidiani, tondũ nĩndĩmĩneanĩte moko-inĩ maku.
10 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀rù àti kọlù wọ́n bá ń bà ọ́, yọ́ wọ ibùdó wọn lọ kí o mú Pura ìránṣẹ́ rẹ lọ́wọ́
No angĩkorwo nĩũgwĩtigĩra gũtharĩkĩra-rĩ, gĩikũrũke kambĩ-inĩ mũrĩ na Pura ndungata yaku,
11 kí o sì fi ara balẹ̀ gbọ́ ohun tí wọ́n ń sọ nínú ibùdó náà. Lẹ́yìn èyí ọkàn rẹ̀ yóò le láti kọlù ibùdó náà.” Báyìí ni òun àti Pura ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ ẹnu-ọ̀nà ibùdó yìí.
na ũthikĩrĩrie ũrĩa maroiga. Thuutha ũcio nĩũkũgĩa na hinya wa gũtharĩkĩra kambĩ ĩyo.” Nĩ ũndũ ũcio Gideoni na Pura ndungata yake magĩikũrũka nginya tũnyũmba-inĩ twa arangĩri a kambĩ ĩyo.
12 Àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti gbogbo ènìyàn ìlà-oòrùn tó lọ ní àfonífojì bí eṣú ni wọ́n rí nítorí púpọ̀ wọn. Àwọn ìbákasẹ wọn kò sì lóǹkà, wọ́n sì pọ̀ bí yanrìn inú Òkun.
Nao Amidiani, na Aamaleki na andũ othe a mwena wa irathĩro maikarĩte kĩanda kĩu maingĩhĩte ta ngigĩ. Ngamĩĩra ciao itingĩatarĩkire nĩ ũndũ ciarĩ nyingĩ ta mũthanga wa hũgũrũrũ-inĩ cia iria ũrĩa ũtangĩtarĩka.
13 Gideoni dé sí àsìkò tí ọkùnrin kan bẹ̀rẹ̀ sí í rọ́ àlá tí ó lá sí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀. Ó ní, “Mo lá àlá kan, nínú àlá náà mo rí àkàrà kan tó ṣe róbótó tí a fi barle ṣe ń yí wọ inú ibùdó àwọn ará Midiani, ó sì kọlu àgọ́ pẹ̀lú agbára ńlá dé bi wí pé àgọ́ náà dojúdé, ó sì ṣubú.”
Gideoni aakinyire ho o hĩndĩ ĩrĩa mũndũ ũmwe eeraga mũratawe ũhoro wa kĩroto gĩake. Nake oigaga atĩrĩ, “Ndootete kĩroto ngoona mũgate wa cairi wa gĩthiũrũrĩ ũũkĩte ũkagwĩra kambĩ ya Amidiani. Ũragũthire hema na hinya mũnene mũno, nginya hema ĩrangʼaũka, ĩragũa.”
14 Ọ̀rẹ́ rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Èyí kò le túmọ̀ sí ohun mìíràn ju idà Gideoni ọmọ Joaṣi ará Israẹli lọ: Ọlọ́run ti fi àwọn ará Midiani àti gbogbo ogun ibùdó lé e lọ́wọ́.”
Mũrata wake akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ũyũ ti ũndũ ũngĩ tiga rũhiũ rwa Gideoni mũrũ wa Joashu, ũrĩa Mũisiraeli. Ngai nĩaneanĩte Amidiani na kambĩ yao yothe moko-inĩ make.”
15 Nígbà tí Gideoni gbọ́ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀, ó wólẹ̀ sin Ọlọ́run: lẹ́yìn náà ni ó padà sí ibùdó àwọn ọmọ Israẹli ó sì pè wọ́n pé, “Ẹ dìde! Nítorí pé Olúwa yóò lò yín láti ṣẹ́gun gbogbo ogun Midiani.”
Rĩrĩa Gideoni aiguire ũhoro wa kĩroto kĩu na ũtaũri wakĩo, akĩhooya Ngai. Agĩcooka nginya kambĩ-inĩ ya Isiraeli akĩmeeta akĩmeera atĩrĩ, “Ũkĩrai! Jehova nĩaneanĩte kambĩ ya Amidiani moko-inĩ manyu.”
16 Nígbà tí ó ti pín àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì sí ọ̀nà mẹ́ta, ó fi fèrè, pẹ̀lú àwọn òfìfo ìkòkò lé ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn lọ́wọ́, iná sì wà nínú àwọn ìkòkò náà.
Akĩgayania andũ acio magana matatũ ikundi ithatũ, akĩmanengera othe o mũndũ karumbeta na nyũngũ theri, ĩrĩ na kĩmũrĩ thĩinĩ.
17 Ó sọ fún wọn pé, “Ẹ máa wò mí, kí ẹ sì máa ṣe ohun tí mo bá ṣe. Nígbà tí mo bá dé igun ibùdó wọn ẹ ṣe ohun tí mo bá ṣe.
Nake akĩmeera atĩrĩ, “Ndoraai. Mwĩke o ũrĩa ngwĩka. Hĩndĩ ĩrĩa ndĩrĩkinya mũthia-inĩ wa kambĩ, mwĩke o ũrĩa ndĩrĩka.
18 Nígbà tí èmi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi bá fun fèrè wa, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin náà ni gbogbo igun ibùdó tí ẹ̀ bá wà kí ẹ fun àwọn fèrè yín kí ẹ sì hó pé, ‘Fún Olúwa àti fún Gideoni.’”
Hĩndĩ ĩrĩa niĩ na arĩa othe ndĩ nao tũrĩhuha tũrumbeta twitũ, hĩndĩ ĩyo inyuothe mũthiũrũrũkĩirie kambĩ mũhuhe twanyu na mwanĩrĩre atĩrĩ, ‘Nĩ ũndũ wa Jehova o na wa Gideoni.’”
19 Gideoni àti àwọn ọgọ́rùn-ún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ dé òpin ibùdó àwọn ará Midiani ní nǹkan bí agogo méjìlá padà. Wọ́n fun fèrè wọn, wọ́n sì tún fọ́ àwọn ìkòkò tí ó wà ní ọwọ́ mọ́lẹ̀.
Gideoni na andũ acio igana rĩmwe arĩa maarĩ nake magĩkinya mũthia wa kambĩ o kĩambĩrĩria-inĩ kĩa ũtukũ gatagatĩ, thuutha hanini wa gũcenjania arangĩri. Makĩhuha tũrumbeta twao na makĩũraga nyũngũ iria ciarĩ moko-inĩ mao.
20 Àwọn ẹgbẹ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta fun fèrè wọn, wọ́n tún fọ́ àwọn ìkòkò wọn mọ́lẹ̀. Wọ́n mú àwọn fìtílà iná wọn ní ọwọ́ òsì wọn àti fèrè tí wọ́n ń fun ní ọwọ́ ọ̀tún wọn. Wọ́n pariwo hé è pé, “Idà kan fún Olúwa àti fún Gideoni!”
Ikundi icio ithatũ ikĩhuha tũrumbeta, na ikĩũraga nyũngũ. Maanyiitĩte imũrĩ na moko mao ma ũmotho, na makanyiita tũrumbeta twao twa kũhuha na moko mao ma ũrĩo, nao makĩanĩrĩra atĩrĩ, “Rũhiũ rwa njora rwa Jehova na rwa Gideoni!”
21 Nígbà tí ọkùnrin kọ̀ọ̀kan dúró ní ipò rẹ̀ yí ibùdó àwọn Midiani ká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun Midiani ń sá káàkiri, wọ́n ń pariwo bí wọ́n ṣe ń sálọ.
Na rĩrĩa o mũndũ aarũgamire handũ hake gũthiũrũrũkĩria kambĩ-rĩ, Amidiani othe magĩtengʼera, magĩkayaga morĩte.
22 Nígbà tí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì fun fèrè wọn, Olúwa sì yí ojú idà ọkùnrin kọ̀ọ̀kan padà sí ẹnìkejì rẹ̀ àti sí gbogbo ogun wọn. Àwọn ọmọ-ogun sì sá títí dé Beti-Sitta ní ọ̀nà Serera títí lọ dé ìpínlẹ̀ Abeli-Mehola ní ẹ̀bá Tabbati.
Hĩndĩ ĩrĩa tũrumbeta tũu magana matatũ twahuhirwo, Jehova agĩtũma andũ arĩa maarĩ kambĩ-inĩ yothe mahũũrane na hiũ ciao cia njora mũndũ na mũndũ ũrĩa ũngĩ. Nayo mbũtũ ĩyo yothe ĩkĩũrĩra Bethi-Shita ĩrorete Zerera o nginya mũhaka-inĩ wa Abeli-Mehola gũkuhĩ na Tabathu.
23 Gbogbo àwọn ọmọ-ogun Israẹli láti ẹ̀yà Naftali, Aṣeri àti gbogbo Manase ni Gideoni ránṣẹ́ si, wọ́n wá wọ́n sì lé àwọn ará Midiani.
Andũ a Isiraeli kuuma Nafitali, na Asheri na Manase guothe nĩmetirwo nao magĩtengʼeria Amidiani.
24 Gideoni tún ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè Efraimu wí pé, “Ẹ jáde wá bá àwọn ará Midiani jà, kí ẹ tètè gba àwọn omi Jordani títí dé Beti-Bara kí wọ́n tó dé bẹ̀.” Báyìí ni a ṣe pe gbogbo ọkùnrin ológun Efraimu jáde tí wọ́n sì gba gbogbo àwọn à bá wọ odò Jordani títí dé Beti-Bara.
Nake Gideoni agĩtũmana bũrũri wothe ũrĩa wa irĩma wa Efiraimu, akiuga atĩrĩ, “Ikũrũkai mũhũũrane na Amidiani na mwĩnyiitĩre maaĩ ma Jorodani mbere yao o nginya Bethi-Bara.” Nĩ ũndũ ũcio andũ othe a Efiraimu nĩmetirwo, na makĩĩnyiitĩra maaĩ ma Rũũĩ rwa Jorodani o nginya Bethi-Bara.
25 Wọ́n mú méjì nínú àwọn olórí àwọn ará Midiani, àwọn náà ni Orebu àti Seebu. Wọ́n pa Horebu nínú àpáta Orebu, wọ́n sì pa Seebu níbi tí àwọn ènìyàn ti mọ̀ fún wáìnì tí a ń pè ní ìfúntí Seebu. Wọ́n lé àwọn ará Midiani, nígbà tí wọ́n gbé orí Orebu àti Seebu tọ Gideoni wá ẹni tí ó wà ní apá kejì Jordani.
O na ningĩ nĩmanyiitire atongoria eerĩ a Midiani, nĩo Orebu na Zeebu. Nao makĩũragĩra Orebu ihiga-inĩ rĩa Orebu, nake Zeebu makĩmũũragĩra kĩhihĩro-inĩ kĩa ndibei kĩa Zeebu. Nao magĩthingatana na Amidiani, na magĩtwara mĩtwe ya Orebu na Zeebu kũrĩ Gideoni, ũrĩa warĩ mũrĩmo ũrĩa ũngĩ wa Rũũĩ rwa Jorodani.