< Judges 7 >

1 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Jerubbaali (èyí ni Gideoni) pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kó ogun jọ lẹ́bàá a orísun Harodi. Àwọn ogun Midiani sì wà ní apá àríwá tí wọ́n ní àfonífojì tí ó wà ní ẹ̀bá òkè More.
Tedy vstav ráno Jerobál, (jenž jest Gedeon), i všecken lid, kterýž byl s ním, položili se při studnici Charod, vojska pak Madianských byla jim na půlnoci před vrchem More v údolí.
2 Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọmọ-ogun tí o kójọ sọ́dọ̀ ti pọ̀jù fún mi láti fi àwọn ogun Midiani lé wọn lọ́wọ́, kí Israẹli má ba à gbé ara rẹ̀ ga sí mi wí pé agbára òun ni ó gbà á là,
I řekl Hospodin Gedeonovi: Příliš mnoho jest lidu s tebou, protož nedám Madianských v ruce jejich, aby se nechlubil Izrael proti mně, řka: Ruka má spomohla mi.
3 sì kéde sí àwọn ènìyàn nísinsin yìí pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbọ̀n, tí ó sì ń bẹ̀rù lè padà sẹ́yìn, kí ó sì kúrò lórí òkè Gileadi.’” Báyìí ni Gideoni ṣe ya àwọn ènìyàn náà. Ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ọkùnrin sì padà sẹ́yìn àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì dúró.
A protož provolej hned, ať slyší lid, a řekni: Kdo jest strašlivý a lekavý, navrať se zase, a odejdi ráno pryč k hoře Galád. I navrátilo se z lidu dvamecítma tisíců, a deset tisíc zůstalo.
4 Olúwa sì tún sọ fún Gideoni pé, “Àwọn ènìyàn yìí sì tún pọ̀jù. Kó wọn lọ sí ibi tí omi wà, èmi yóò sì yọ̀rọ̀ wọn níbẹ̀ fún ọ. Bí mo bá wí pé eléyìí yóò bá ọ lọ yóò lọ, ṣùgbọ́n tí mo bá sọ pé, ‘Eléyìí kò ní bá ọ lọ,’ òun kò gbọdọ̀ lọ.”
Řekl opět Hospodin Gedeonovi: Ještě jest mnoho lidu; kaž jim sstoupiti k vodám, a tam jej tobě zkusím. I bude, že o komžkoli řeknu: Tento půjde s tebou, ten ať s tebou jde, a o komžkoli řeknu tobě: Tento nepůjde s tebou, ten ať nechodí.
5 Gideoni sì kó àwọn ọkùnrin náà lọ sí ibi ìsun omi. Níbẹ̀ ni Olúwa ti wí fún un pé, “Kí ó pín àwọn ènìyàn náà sí ọ̀nà méjì. Ya àwọn tí ó fi ahọ́n wọn lá omi bí ajá kúrò lára àwọn tí ó kúnlẹ̀ láti mu omi pẹ̀lú ọwọ́ wọn.”
I kázal sstoupiti lidu k vodám, a řekl Hospodin k Gedeonovi: Každého, kdož chlemtati bude jazykem svým z vody, jako chlemce pes, postavíš obzvláštně, tolikéž každého, kdož se přisehne na kolena svá ku pití.
6 Ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin ni ó lá omi pẹ̀lú ahọ́n wọn. Gbogbo àwọn ìyókù ni ó kúnlẹ̀ láti mu mi.
I byl počet těch, kteříž chlemtali, rukama svýma k ústům svým vodu nosíce, tři sta mužů, ostatek pak všeho lidu sehnuli se na kolena svá ku pití vody.
7 Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó lá omi ni èmi yóò lò láti gbà yín là àti láti fi ogun Midiani lé yín lọ́wọ́. Jẹ́ kí àwọn tókù padà sí ilé wọn.”
I řekl Hospodin Gedeonovi: Ve třech stech mužů, kteříž chlemtali, vysvobodím vás, a vydám Madianské v ruku tvou, ale ostatek všeho lidu nechť se vrátí, jeden každý k místu svému.
8 Báyìí ni Gideoni ṣe dá àwọn Israẹli tí ó kù padà sí àgọ́ wọn, ṣùgbọ́n ó dá àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin náà dúró. Àwọn wọ̀nyí sì gba gbogbo ohun èlò àti fèrè àwọn tí ó ti padà. Ibùdó ogun àwọn Midiani wà ní àfonífojì ní ìsàlẹ̀. Ibi tí ó wà.
A protož nabral ten lid v ruce své potravy a trouby své; jiné pak muže Izraelské všecky propustil, jednoho každého do stanů jejich, toliko tři sta těch mužů zanechal při sobě. Vojska pak Madianských ležela pod ním v údolí.
9 Ní òru ọjọ́ náà Olúwa sọ fún Gideoni pé, “Dìde, dojú ogun kọ ibùdó ogun àwọn ará Midiani nítorí èmi yóò fi lé ọ lọ́wọ́.
I stalo se, že noci té řekl jemu Hospodin: Vstana, sstup k vojsku, nebo dal jsem je v ruku tvou.
10 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀rù àti kọlù wọ́n bá ń bà ọ́, yọ́ wọ ibùdó wọn lọ kí o mú Pura ìránṣẹ́ rẹ lọ́wọ́
Pakli nesmíš sjíti sám, sejdi s Půrou služebníkem svým do vojska,
11 kí o sì fi ara balẹ̀ gbọ́ ohun tí wọ́n ń sọ nínú ibùdó náà. Lẹ́yìn èyí ọkàn rẹ̀ yóò le láti kọlù ibùdó náà.” Báyìí ni òun àti Pura ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ ẹnu-ọ̀nà ibùdó yìí.
A uslyšíš, co mluviti budou; i posilní se z toho ruce tvé, tak že směle půjdeš proti vojsku tomu. Sstoupil tedy on a Půra služebník jeho k kraji oděnců, kteříž byli v vojště.
12 Àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti gbogbo ènìyàn ìlà-oòrùn tó lọ ní àfonífojì bí eṣú ni wọ́n rí nítorí púpọ̀ wọn. Àwọn ìbákasẹ wọn kò sì lóǹkà, wọ́n sì pọ̀ bí yanrìn inú Òkun.
Madian pak a Amalech i všecken lid východní leželi v údolí, jako kobylky u velikém množství, ani velbloudů jejich počtu nebylo, jako písek, kterýž jest na břehu mořském v nesčíslném množství.
13 Gideoni dé sí àsìkò tí ọkùnrin kan bẹ̀rẹ̀ sí í rọ́ àlá tí ó lá sí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀. Ó ní, “Mo lá àlá kan, nínú àlá náà mo rí àkàrà kan tó ṣe róbótó tí a fi barle ṣe ń yí wọ inú ibùdó àwọn ará Midiani, ó sì kọlu àgọ́ pẹ̀lú agbára ńlá dé bi wí pé àgọ́ náà dojúdé, ó sì ṣubú.”
A když přišel Gedeon, aj, jeden vypravoval bližnímu svému sen, a řekl: Hle, zdálo mi se, že pecen chleba ječmenného valil se do vojska Madianského, a přivaliv se na každý stan, udeřil na něj, až padl, a podvrátil jej svrchu, a tak ležel každý stan.
14 Ọ̀rẹ́ rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Èyí kò le túmọ̀ sí ohun mìíràn ju idà Gideoni ọmọ Joaṣi ará Israẹli lọ: Ọlọ́run ti fi àwọn ará Midiani àti gbogbo ogun ibùdó lé e lọ́wọ́.”
Jemužto odpovídaje bližní jeho, řekl: Není to nic jiného, jediné meč Gedeona syna Joasova, muže Izraelského; dalť jest Bůh v ruku jeho Madianské i všecka tato vojska.
15 Nígbà tí Gideoni gbọ́ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀, ó wólẹ̀ sin Ọlọ́run: lẹ́yìn náà ni ó padà sí ibùdó àwọn ọmọ Israẹli ó sì pè wọ́n pé, “Ẹ dìde! Nítorí pé Olúwa yóò lò yín láti ṣẹ́gun gbogbo ogun Midiani.”
Stalo se pak, že když uslyšel Gedeon vypravování snu i vyložení jeho, poklonil se Bohu, a vrátiv se k vojsku Izraelskému, řekl: Vstaňte, nebo dal Hospodin v ruku vaši vojska Madianská.
16 Nígbà tí ó ti pín àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì sí ọ̀nà mẹ́ta, ó fi fèrè, pẹ̀lú àwọn òfìfo ìkòkò lé ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn lọ́wọ́, iná sì wà nínú àwọn ìkòkò náà.
Rozdělil tedy tři sta mužů na tři houfy, a dal trouby v ruku každému z nich a báně prázdné, a v prostředku těch bání byly pochodně.
17 Ó sọ fún wọn pé, “Ẹ máa wò mí, kí ẹ sì máa ṣe ohun tí mo bá ṣe. Nígbà tí mo bá dé igun ibùdó wọn ẹ ṣe ohun tí mo bá ṣe.
I řekl jim: Jakž na mně uzříte, tak učiníte; nebo hle, já vejdu na kraj vojska, a jakž já tehdáž budu dělati, tak uděláte.
18 Nígbà tí èmi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi bá fun fèrè wa, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin náà ni gbogbo igun ibùdó tí ẹ̀ bá wà kí ẹ fun àwọn fèrè yín kí ẹ sì hó pé, ‘Fún Olúwa àti fún Gideoni.’”
Nebo troubiti budu já v troubu i všickni, jenž se mnou budou, tehdy vy také troubiti budete v trouby vůkol všeho vojska, a řeknete: Meč Hospodinův a Gedeonův.
19 Gideoni àti àwọn ọgọ́rùn-ún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ dé òpin ibùdó àwọn ará Midiani ní nǹkan bí agogo méjìlá padà. Wọ́n fun fèrè wọn, wọ́n sì tún fọ́ àwọn ìkòkò tí ó wà ní ọwọ́ mọ́lẹ̀.
Všel tedy Gedeon a sto mužů, kteříž s ním byli, na kraj vojska při začátku bdění prostředního, jen že byli proměnili stráž; i troubili v trouby, a roztřískali báně, kteréž měli v rukou svých.
20 Àwọn ẹgbẹ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta fun fèrè wọn, wọ́n tún fọ́ àwọn ìkòkò wọn mọ́lẹ̀. Wọ́n mú àwọn fìtílà iná wọn ní ọwọ́ òsì wọn àti fèrè tí wọ́n ń fun ní ọwọ́ ọ̀tún wọn. Wọ́n pariwo hé è pé, “Idà kan fún Olúwa àti fún Gideoni!”
Tedy ti tři houfové troubili v trouby, rozstřískavše báně, a drželi v ruce své levé pochodně, v pravé pak ruce své trouby, aby troubili, i křičeli: Meč Hospodinův a Gedeonův.
21 Nígbà tí ọkùnrin kọ̀ọ̀kan dúró ní ipò rẹ̀ yí ibùdó àwọn Midiani ká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun Midiani ń sá káàkiri, wọ́n ń pariwo bí wọ́n ṣe ń sálọ.
A postavili se každý na místě svém vůkol ležení; i zděšena jsou všecka vojska, a křičíce, utíkali.
22 Nígbà tí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì fun fèrè wọn, Olúwa sì yí ojú idà ọkùnrin kọ̀ọ̀kan padà sí ẹnìkejì rẹ̀ àti sí gbogbo ogun wọn. Àwọn ọmọ-ogun sì sá títí dé Beti-Sitta ní ọ̀nà Serera títí lọ dé ìpínlẹ̀ Abeli-Mehola ní ẹ̀bá Tabbati.
Když pak troubilo v trouby těch tři sta mužů, obrátil Hospodin meč jednoho proti druhému, a to po všem ležení. Utíkalo tedy vojsko až k Betseta do Zererat, a až ku pomezí Abelmehula u Tebat.
23 Gbogbo àwọn ọmọ-ogun Israẹli láti ẹ̀yà Naftali, Aṣeri àti gbogbo Manase ni Gideoni ránṣẹ́ si, wọ́n wá wọ́n sì lé àwọn ará Midiani.
Shromáždivše se pak muži Izraelští z Neftalím a z Asser a ze všeho pokolení Manassesova, honili Madianské.
24 Gideoni tún ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè Efraimu wí pé, “Ẹ jáde wá bá àwọn ará Midiani jà, kí ẹ tètè gba àwọn omi Jordani títí dé Beti-Bara kí wọ́n tó dé bẹ̀.” Báyìí ni a ṣe pe gbogbo ọkùnrin ológun Efraimu jáde tí wọ́n sì gba gbogbo àwọn à bá wọ odò Jordani títí dé Beti-Bara.
I rozeslal Gedeon posly na všecky hory Efraimské, řka: Vyjděte v cestu Madianským, a zastupte jim vody až k Betabaře a Jordánu. Tedy shromáždivše se všickni muži Efraim, zastoupili vody až k Betabaře a Jordánu.
25 Wọ́n mú méjì nínú àwọn olórí àwọn ará Midiani, àwọn náà ni Orebu àti Seebu. Wọ́n pa Horebu nínú àpáta Orebu, wọ́n sì pa Seebu níbi tí àwọn ènìyàn ti mọ̀ fún wáìnì tí a ń pè ní ìfúntí Seebu. Wọ́n lé àwọn ará Midiani, nígbà tí wọ́n gbé orí Orebu àti Seebu tọ Gideoni wá ẹni tí ó wà ní apá kejì Jordani.
A chytili dvé knížat Madianských, Goréba a Zéba. I zabili Goréba na skále Goréb a Zéba zabili v lisu Zéb, a honili Madianské, hlavu pak Gorébovu a Zébovu přinesli k Gedeonovi za Jordán.

< Judges 7 >