< Judges 7 >
1 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Jerubbaali (èyí ni Gideoni) pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kó ogun jọ lẹ́bàá a orísun Harodi. Àwọn ogun Midiani sì wà ní apá àríwá tí wọ́n ní àfonífojì tí ó wà ní ẹ̀bá òkè More.
Unya si Jerobaal, nga mao si Gedeon, ug ang tanang tawo nga ming-uban kaniya mingsayo pagbangon, ug nagpahaluna tupad sa tuburan sa Harod: ug ang campo sa Madian didto dapit sa amihanan nila, tupad sa bungtod sa More, didto sa walog.
2 Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọmọ-ogun tí o kójọ sọ́dọ̀ ti pọ̀jù fún mi láti fi àwọn ogun Midiani lé wọn lọ́wọ́, kí Israẹli má ba à gbé ara rẹ̀ ga sí mi wí pé agbára òun ni ó gbà á là,
Ug si Jehova miingon kang Gedeon: Ang katawohan nga anaa uban kanimo daghan ra kaayo alang kanako aron sa pagtugyan sa mga Madianhon ngadto sa ilang kamot, tingali unya ang Israel magapagarbo sa ilang kaugalingon batok kanako, nga magaingon: Ang akong kaugalingong kamot maoy nakaluwas kanako.
3 sì kéde sí àwọn ènìyàn nísinsin yìí pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbọ̀n, tí ó sì ń bẹ̀rù lè padà sẹ́yìn, kí ó sì kúrò lórí òkè Gileadi.’” Báyìí ni Gideoni ṣe ya àwọn ènìyàn náà. Ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ọkùnrin sì padà sẹ́yìn àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì dúró.
Busa karon, isangyaw mo sa mga igdulungog sa katawohan, sa pag-ingon. Bisan kinsa ang napun-an sa kahadlok ug nangurog, pumauli siya ug pumahawa gikan sa bukid sa Galaad. Ug may mingpauli sa katawohan nga kaluhaan ug duha ka libo; ug may nahibilin nga napulo ka libo.
4 Olúwa sì tún sọ fún Gideoni pé, “Àwọn ènìyàn yìí sì tún pọ̀jù. Kó wọn lọ sí ibi tí omi wà, èmi yóò sì yọ̀rọ̀ wọn níbẹ̀ fún ọ. Bí mo bá wí pé eléyìí yóò bá ọ lọ yóò lọ, ṣùgbọ́n tí mo bá sọ pé, ‘Eléyìí kò ní bá ọ lọ,’ òun kò gbọdọ̀ lọ.”
Ug si Jehova miingon kang Gedeon: Ang katawohan daghan pa kaayo; dad-a sila ngadto sa tubig, ug sila sulayan ko didto alang kanimo: ug mahitabo nga kinsa kadtong akong igaingon kanimo: Kini makakuyog kanimo, ang mao makauban kanimo: ug tungod kang bisan kinsa ako magaingon kanimo: Kini dili makauban kanimo, ang mao dili makauban kanimo.
5 Gideoni sì kó àwọn ọkùnrin náà lọ sí ibi ìsun omi. Níbẹ̀ ni Olúwa ti wí fún un pé, “Kí ó pín àwọn ènìyàn náà sí ọ̀nà méjì. Ya àwọn tí ó fi ahọ́n wọn lá omi bí ajá kúrò lára àwọn tí ó kúnlẹ̀ láti mu omi pẹ̀lú ọwọ́ wọn.”
Busa iyang gidala ang katawohan ngadto sa tubig: ug si Jehova miingon kang Gedeon: Ang tagsatagsa nga mga magatilap sa tubig sa iyang dila ingon sa pagtilap sa iro, pinigon mo siya; mao usab ang tagsatagsa nga moluhod sa pag-inum.
6 Ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin ni ó lá omi pẹ̀lú ahọ́n wọn. Gbogbo àwọn ìyókù ni ó kúnlẹ̀ láti mu mi.
Ug ang gidaghanon niadtong mga mingtilap, nga nagabutang sa ilang kamot sa ilang baba, may totolo ka gatus ka tawo: apan ang uban sa katawohan nangluhod sa pag-inum sa tubig.
7 Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó lá omi ni èmi yóò lò láti gbà yín là àti láti fi ogun Midiani lé yín lọ́wọ́. Jẹ́ kí àwọn tókù padà sí ilé wọn.”
Ug si Jehova miingon kang Gedeon: Pinaagi niining totolo ka gatus ka tawo nga mingtilap ako magaluwas kanimo, ug magahatag sa mga Madianhon nganha sa imong kamot: ug ang tibook nga katawohan papaulia ang tagsatagsa ka tawo sa iyang kaugalingong dapit.
8 Báyìí ni Gideoni ṣe dá àwọn Israẹli tí ó kù padà sí àgọ́ wọn, ṣùgbọ́n ó dá àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin náà dúró. Àwọn wọ̀nyí sì gba gbogbo ohun èlò àti fèrè àwọn tí ó ti padà. Ibùdó ogun àwọn Midiani wà ní àfonífojì ní ìsàlẹ̀. Ibi tí ó wà.
Busa ang katawohan nanagdala ug mga kalan-on sa ilang kamot, ug ang ilang mga trompeta; ug iyang gipalakaw ang tanang mga tawo sa Israel ang tagsatagsa ngadto sa iyang balong-balong, apan gihawiran ang totolo ka gatus ka tawo: ug ang campo sa Madian didto sa ubos kaniya sa walog.
9 Ní òru ọjọ́ náà Olúwa sọ fún Gideoni pé, “Dìde, dojú ogun kọ ibùdó ogun àwọn ará Midiani nítorí èmi yóò fi lé ọ lọ́wọ́.
Ug nahitabo sa maong gabii nga si Jehova miingon kaniya: Tumindog ka, lumugsong ka ngadto sa campo; kay gihatag ko na kana nganha sa imong kamot.
10 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀rù àti kọlù wọ́n bá ń bà ọ́, yọ́ wọ ibùdó wọn lọ kí o mú Pura ìránṣẹ́ rẹ lọ́wọ́
Apan kong ikaw mahadlok sa paglugsong, umadto ka uban kang Pura nga imong sulogoon ngadto sa campo:
11 kí o sì fi ara balẹ̀ gbọ́ ohun tí wọ́n ń sọ nínú ibùdó náà. Lẹ́yìn èyí ọkàn rẹ̀ yóò le láti kọlù ibùdó náà.” Báyìí ni òun àti Pura ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ ẹnu-ọ̀nà ibùdó yìí.
Ug ikaw makadungog unsay ilang isulti; ug unya ang imong mga kamot magmakusanon sa paglugsong ngadto sa campo. Unya milugsong siya uban kang Pura nga iyang sulogoon ngadto sa kinagawasan gayud nga dapit sa mga tawo nga may hinagiban nga diha sa campo.
12 Àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti gbogbo ènìyàn ìlà-oòrùn tó lọ ní àfonífojì bí eṣú ni wọ́n rí nítorí púpọ̀ wọn. Àwọn ìbákasẹ wọn kò sì lóǹkà, wọ́n sì pọ̀ bí yanrìn inú Òkun.
Ug ang mga Madianhon ug ang Amalecanhon ug ang tanan nga mga anak sa silangan nanagpahaluna sa walog ingon sa mga dulon sa gidaghanon; ug ang ilang mga camello dili maisip ingon sa balas nga anaa sa baybayon sa gidaghanon.
13 Gideoni dé sí àsìkò tí ọkùnrin kan bẹ̀rẹ̀ sí í rọ́ àlá tí ó lá sí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀. Ó ní, “Mo lá àlá kan, nínú àlá náà mo rí àkàrà kan tó ṣe róbótó tí a fi barle ṣe ń yí wọ inú ibùdó àwọn ará Midiani, ó sì kọlu àgọ́ pẹ̀lú agbára ńlá dé bi wí pé àgọ́ náà dojúdé, ó sì ṣubú.”
Ug sa diha nga nahiabut sa Gedeon, ania karon, didtoy usa ka tawo nagasugilon ug usa ka damgo sa iyang kauban, ug siya miingon: Ania karon, ako nagdamgo ug usa ka damgo; ug ania karon, usa ka tinapay sa cebada naligid ngadto sa campo sa Madian, ug nahiabut ngadto sa balong-balong, ug nahibangga kini mao nga ang balong-balong mihapla.
14 Ọ̀rẹ́ rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Èyí kò le túmọ̀ sí ohun mìíràn ju idà Gideoni ọmọ Joaṣi ará Israẹli lọ: Ọlọ́run ti fi àwọn ará Midiani àti gbogbo ogun ibùdó lé e lọ́wọ́.”
Ug ang iyang kauban mitubag ug miingon: Kini dili lain kondili ang espada ni Gedeon ang anak nga lalake ni Joas, usa ka tawo sa Israel: ngadto sa iyang kamot gitugyan sa Dios ang Madian ug ang tanan niyang panon.
15 Nígbà tí Gideoni gbọ́ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀, ó wólẹ̀ sin Ọlọ́run: lẹ́yìn náà ni ó padà sí ibùdó àwọn ọmọ Israẹli ó sì pè wọ́n pé, “Ẹ dìde! Nítorí pé Olúwa yóò lò yín láti ṣẹ́gun gbogbo ogun Midiani.”
Ug nahitabo kini nga sa diha nga si Gedeon nakadungog sa pagsugilon sa damgo ug sa hubad niana, nga siya misimba, ug mibalik siya ngadto sa campo sa Israel, ug miingon: Tumindog kamo kay si Jehova nagtugyan nganha sa inyong kamot sa panon sa Madian.
16 Nígbà tí ó ti pín àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì sí ọ̀nà mẹ́ta, ó fi fèrè, pẹ̀lú àwọn òfìfo ìkòkò lé ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn lọ́wọ́, iná sì wà nínú àwọn ìkòkò náà.
Ug gibahin niya ang totolo ka gatus ka tawo sa totolo ka pundok ug gibutang niya diha sa mga kamot nilang tanan ang mga trompeta, ug mga tibod nga walay sulod lakip ang mga sulo sa sulod sa mga tibod.
17 Ó sọ fún wọn pé, “Ẹ máa wò mí, kí ẹ sì máa ṣe ohun tí mo bá ṣe. Nígbà tí mo bá dé igun ibùdó wọn ẹ ṣe ohun tí mo bá ṣe.
Ug siya miingon kanila: Tan-awa ako ninyo, ug buhaton ninyo ang ingon niini: ug ania karon, kong ako moadto sa kinagawasang dapit sa campo, ug mao kini, nga ingon sa akong buhaton, buhaton usab ninyo.
18 Nígbà tí èmi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi bá fun fèrè wa, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin náà ni gbogbo igun ibùdó tí ẹ̀ bá wà kí ẹ fun àwọn fèrè yín kí ẹ sì hó pé, ‘Fún Olúwa àti fún Gideoni.’”
Kong ako magahuyop sa trompeta, ako ug ang tanan nga mouban kanako, nan huypa usab ninyo ang mga trompeta sa tanang daplin sa campo ug mag-ingon: Alang kang Jehova ug kang Gedeon.
19 Gideoni àti àwọn ọgọ́rùn-ún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ dé òpin ibùdó àwọn ará Midiani ní nǹkan bí agogo méjìlá padà. Wọ́n fun fèrè wọn, wọ́n sì tún fọ́ àwọn ìkòkò tí ó wà ní ọwọ́ mọ́lẹ̀.
Busa si Gedeon, ug ang usa ka gatus ka tawo nga iyang kauban ming-adto sa kinagawasang dapit sa campo sa sinugdan sa pagtukaw sa tungang gabii sa diha nga bag-o pa lamang nga nahaluna ang bantay: ug ilang gihuyop ang mga trompeta, ug gibuak ang mga tibod nga diha sa ilang mga kamot.
20 Àwọn ẹgbẹ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta fun fèrè wọn, wọ́n tún fọ́ àwọn ìkòkò wọn mọ́lẹ̀. Wọ́n mú àwọn fìtílà iná wọn ní ọwọ́ òsì wọn àti fèrè tí wọ́n ń fun ní ọwọ́ ọ̀tún wọn. Wọ́n pariwo hé è pé, “Idà kan fún Olúwa àti fún Gideoni!”
Ug ang totolo ka panon minghuyop sa mga trompeta, ug mingbuak sa mga tibod, ug nagbibit sa mga sulo sa ilang mga kamot nga wala, ug ang mga trompeta sa ilang mga kamot nga too aron sa paghuyop niini; ug sila misinggit: Ang espada ni Jehova ug ni Gedeon.
21 Nígbà tí ọkùnrin kọ̀ọ̀kan dúró ní ipò rẹ̀ yí ibùdó àwọn Midiani ká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun Midiani ń sá káàkiri, wọ́n ń pariwo bí wọ́n ṣe ń sálọ.
Ug sila nanindog ang tagsatagsa ka tawo sa iyang dapit libut sa campo; ug ang tanang panon nanalagan, ug sila naninggit, ug nakapalagiw kanila.
22 Nígbà tí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì fun fèrè wọn, Olúwa sì yí ojú idà ọkùnrin kọ̀ọ̀kan padà sí ẹnìkejì rẹ̀ àti sí gbogbo ogun wọn. Àwọn ọmọ-ogun sì sá títí dé Beti-Sitta ní ọ̀nà Serera títí lọ dé ìpínlẹ̀ Abeli-Mehola ní ẹ̀bá Tabbati.
Ug ilang gihuyop ang totolo ka gatus ka mga trompeta, ug si Jehova nagabutang sa tagsatagsa ka espada sa mga tawo batok sa iyang masigkauban ug batok sa tibook nga panon; ug ang panon mikalagiw hangtud sa Beth-sitta paingon sa Cerera, hangtud sa utlanan sa Abel-mehola tupad sa Tabbat.
23 Gbogbo àwọn ọmọ-ogun Israẹli láti ẹ̀yà Naftali, Aṣeri àti gbogbo Manase ni Gideoni ránṣẹ́ si, wọ́n wá wọ́n sì lé àwọn ará Midiani.
Ug ang mga tawo sa Israel nanag-usa pagtapok gikan sa Nephtali, ug gikan sa Aser, ug gikan sa tibook nga Manases, ug minglutos kang Madian.
24 Gideoni tún ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè Efraimu wí pé, “Ẹ jáde wá bá àwọn ará Midiani jà, kí ẹ tètè gba àwọn omi Jordani títí dé Beti-Bara kí wọ́n tó dé bẹ̀.” Báyìí ni a ṣe pe gbogbo ọkùnrin ológun Efraimu jáde tí wọ́n sì gba gbogbo àwọn à bá wọ odò Jordani títí dé Beti-Bara.
Ug si Gedeon nagpadala ug mga sinugo ngadto sa tibook nga dapit sa kabungtoran sa Ephraim, nga nagaingon: Lumugsong kamo batok sa Madian, ug kuhaa gikan kanila ang mga tubig hangtud sa Beth-bara, bisan pa sa Jordan. Busa ang tanang tawo sa Ephraim naghiusa pagtigum, ug nagkuha sa mga tubig hangtud sa Beth-bara, lakip ang Jordan.
25 Wọ́n mú méjì nínú àwọn olórí àwọn ará Midiani, àwọn náà ni Orebu àti Seebu. Wọ́n pa Horebu nínú àpáta Orebu, wọ́n sì pa Seebu níbi tí àwọn ènìyàn ti mọ̀ fún wáìnì tí a ń pè ní ìfúntí Seebu. Wọ́n lé àwọn ará Midiani, nígbà tí wọ́n gbé orí Orebu àti Seebu tọ Gideoni wá ẹni tí ó wà ní apá kejì Jordani.
Ug nabihag nila ang duha mga principe sa Madian, si Oreb ug si Zeeb; ug ilang gipatay si Oreb didto sa bato sa Oreb, ug si Zeeb ilang gipatay didto sa pulog-anan sa vino sa Zeeb, ug giapas ang Madian; ug ilang gidala ang mga ulo ni Oreb ug ni Zeeb ngadto kang Gedeon unahan sa Jordan.