< Judges 6 >
1 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
Potem synowie Izraela czynili to, co złe w oczach PANA. Wydał ich więc PAN w ręce Midianitów na siedem lat.
2 Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
A ręka Midianitów wzmocniła się nad Izraelem, [tak że] synowie Izraela kopali sobie przed Midianitami kryjówki w górach, jaskinie i warownie.
3 Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
Bywało, że gdy Izrael coś zasiał, przychodzili Midianici, Amalekici i ludzie ze wschodu i najeżdżali go;
4 Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
I rozbijali obóz naprzeciwko niego, i niszczyli plony ziemi aż po granice Gazy. Nie pozostawiali nic na pożywienie Izraelitom – ani owiec, ani wołów, ani osłów.
5 Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
Przybywali bowiem ze swymi stadami i namiotami, a przychodzili jak szarańcza tak licznie, że nie można było zliczyć ich ani ich wielbłądów. Tak wkraczali do ziemi, aby ją spustoszyć.
6 Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
Dlatego Izrael bardzo zubożał z powodu Midianitów i synowie Izraela wołali do PANA.
7 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
A gdy synowie Izraela wołali do PANA z powodu Midianitów;
8 Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
PAN posłał do synów Izraela proroka, który powiedział do nich: Tak mówi PAN, Bóg Izraela: Ja wyprowadziłem was z ziemi Egiptu i wywiodłem was z domu niewoli.
9 Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
I wyrwałem was z rąk Egipcjan oraz z rąk wszystkich, którzy was trapili. Wypędziłem ich przed wami i dałem wam ich ziemię;
10 Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
I powiedziałem wam: Ja jestem PAN, wasz Bóg, nie bójcie się bogów Amorytów, w których ziemi mieszkacie; lecz nie posłuchaliście mego głosu.
11 Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
Wtedy przyszedł Anioł PANA i stanął pod dębem, który stał w Ofra, należącym do Joasza, Abiezerita. A jego syn Gedeon młócił zboże w tłoczni, aby [je] ukryć przed Midianitami.
12 Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
Wówczas ukazał mu się Anioł PANA i powiedział do niego: PAN z tobą, dzielny wojowniku.
13 Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
Gedeon mu odpowiedział: Mój Panie, proszę, jeśli PAN jest z nami, dlaczego przyszło na nas to wszystko? Gdzie są teraz wszystkie jego cuda, o których opowiadali nam nasi ojcowie, mówiąc: Czy PAN nie wyprowadził nas z Egiptu? A teraz PAN nas opuścił i wydał w ręce Midianitów.
14 Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
Wtedy PAN spojrzał na niego i powiedział: Idź w tej swojej mocy, a wybawisz Izraela z rąk Midianitów. Czyż nie ja cię posłałem?
15 Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
[On] zaś powiedział do niego: Mój Panie, proszę, czym wybawię Izraela? Oto moja rodzina jest biedna w Manassesa, a ja [jestem] najmniejszy w domu swego ojca.
16 Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
I PAN powiedział do niego: Ponieważ [ja] będę z tobą, pobijesz Midianitów jak jednego męża.
17 Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
A [on] mu odpowiedział: Jeśli znalazłem łaskę w twoich oczach, daj mi znak, że to ty rozmawiasz ze mną.
18 Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
Nie odchodź stąd, proszę, aż wrócę do ciebie i przyniosę ci swoją ofiarę i położę ją przed tobą. I odpowiedział: Poczekam, aż wrócisz.
19 Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
Gedeon poszedł więc i przyrządził koźlę oraz przaśne chleby z jednej efy mąki. Mięso włożył do kosza, a polewkę mięsną wlał do garnka i przyniósł to do niego pod dąb, i ofiarował.
20 Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
I Anioł Boga powiedział do niego: Weź mięso i przaśne chleby i połóż na tej skale, a polewkę wylej. I tak uczynił.
21 Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
Wtedy Anioł PANA wyciągnął koniec laski, którą miał w ręce, i dotknął mięsa oraz przaśników; i wydobył się ogień ze skały i strawił mięso i przaśne chleby. Potem Anioł PANA zniknął sprzed jego oczu.
22 Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
A gdy Gedeon zrozumiał, że to był Anioł PANA, powiedział: Ach, Panie BOŻE! Widziałem bowiem Anioła PANA twarzą w twarz.
23 Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
I PAN mu powiedział: Pokój z tobą. Nie bój się, nie umrzesz.
24 Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
Dlatego więc Gedeon zbudował tam ołtarz dla PANA i nazwał go: PAN jest pokojem. Do dziś znajduje się [on] w Ofra Abiezerytów.
25 Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
Tej nocy PAN mu powiedział: Weź młodego cielca, który [należy do] twego ojca, [oraz] drugiego cielca siedmioletniego i zburz ołtarz Baala należący do twego ojca, i zetnij gaj, który jest przy nim;
26 Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
A zbuduj ołtarz dla PANA, swego Boga, na szczycie tej skały, na równym miejscu; weź tego drugiego cielca i złóż z niego całopalenie na drwach z gaju, który zetniesz.
27 Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
Wziął więc Gedeon dziesięciu mężczyzn spośród swoich sług i uczynił tak, jak PAN mu rozkazał. A ponieważ bał się domu swego ojca i mieszkańców miasta, nie uczynił tego za dnia, lecz uczynił to w nocy.
28 Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
A gdy mieszkańcy miasta wstali wczesnym rankiem, zobaczyli zburzony ołtarz Baala i ścięty gaj, który był obok niego, i tego drugiego cielca złożonego na całopalenie na zbudowanym ołtarzu.
29 Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
I mówili jeden do drugiego: Któż to uczynił? A gdy się o to pytali i dowiadywali, powiedzieli: Uczynił to Gedeon, syn Joasza.
30 Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
Wtedy mieszkańcy miasta powiedzieli do Joasza: Wyprowadź swego syna, niech umrze, gdyż zburzył ołtarz Baala i ściął gaj, który był przy nim.
31 Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
A Joasz odpowiedział wszystkim, którzy stali dokoła niego: Czy chcecie stawać w obronie Baala? Czy chcecie go wybawić? Kto chciałby go bronić, niech umrze tego ranka. Jeśli jest bogiem, niech sam się spiera o to, że zburzono jego ołtarz.
32 Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
I nazwano go tego dnia Jerubbaal, mówiąc: Niech Baal się spiera z nim, bo zburzył on jego ołtarz.
33 Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
Wtedy wszyscy Midianici i Amalekici oraz ludzie ze wschodu zebrali się razem, przeprawili się [przez Jordan] i rozbili obóz w dolinie Jizreel.
34 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
Lecz Duch PANA ogarnął Gedeona, a on zadął w trąbę i zwołał do siebie dom Abiezera.
35 Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
I wyprawił posłańców do całego [pokolenia] Manassesa, które zebrało się przy nim. Wysłał też posłańców do Aszera, do Zebulona i Neftalego; i wyruszyli im na spotkanie.
36 Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
Wtedy Gedeon powiedział do Boga: Jeśli moją ręką wybawisz Izraela, jak powiedziałeś;
37 kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
To ja położę runo wełny na klepisku. Jeśli rosa spadnie tylko na runo, a cała ziemia [będzie] sucha, wtedy będę wiedział, że moją ręką wybawisz Izraela, jak powiedziałeś.
38 Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
I tak się stało. Gdy wstał nazajutrz, ścisnął runo i wycisnął rosę z runa – pełną czaszę wody.
39 Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
Gedeon powiedział jeszcze do Boga: Niech nie zapłonie twój gniew przeciwko mnie, że przemówię jeszcze raz. Pozwól, proszę, że powtórzę doświadczenie z runem: niech będzie suche tylko [samo] runo, a na całej ziemi niech będzie rosa.
40 Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.
I Bóg tak uczynił tej nocy: samo runo było suche, a na całej ziemi była rosa.