< Judges 6 >

1 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
بار دیگر قوم اسرائیل نسبت به خداوند گناه ورزیدند و خداوند نیز آنها را مدت هفت سال به دست قوم مدیان گرفتار نمود.
2 Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
مدیانی‌ها چنان بیرحم بودند که اسرائیلی‌ها از ترس آنها به کوهستانها می‌گریختند و به غارها پناه می‌بردند.
3 Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
وقتی اسرائیلی‌ها بذر خود را می‌کاشتند، مدیانیان و عمالیقی‌ها و قبایل همسایه هجوم می‌آوردند و محصولات آنها را تا شهر غزه نابود و پایمال می‌نمودند. آنها گوسفندان و گاوان و الاغهای ایشان را غارت می‌کردند و آذوقه‌ای برای آنها باقی نمی‌گذاشتند.
4 Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
5 Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
دشمنان مهاجم با گله‌ها، خیمه‌ها و شترانشان آنقدر زیاد بودند که نمی‌شد آنها را شمرد. آنها مانند مور و ملخ هجوم می‌آوردند و تمام مزارع را از بین می‌بردند.
6 Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
اسرائیلی‌ها از دست مدیانی‌ها به تنگ آمدند و نزد خداوند فریاد برآوردند تا به ایشان کمک کند.
7 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
8 Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
خداوند، خدای اسرائیل توسط یک نبی که نزد آنها فرستاد چنین فرمود: «من شما را از بردگی در مصر رهانیدم،
9 Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
و از دست مصری‌ها و همهٔ کسانی که به شما ظلم می‌کردند نجات دادم و دشمنانتان را از پیش روی شما رانده، سرزمین ایشان را به شما دادم.
10 Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
به شما گفتم که من خداوند، خدای شما هستم و شما نباید خدایان اموری‌ها را که در اطرافتان سکونت دارند عبادت کنید. ولی شما به من گوش ندادید.»
11 Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
روزی فرشتهٔ خداوند آمده، زیر درخت بلوطی که در عفره در مزرعهٔ یوآش ابیعزری بود نشست. جدعون پسر یوآش مخفیانه و دور از چشم مدیانی‌ها در چرخشت انگور، با دست گندم می‌کوبید
12 Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
که فرشتهٔ خداوند بر او ظاهر شده، گفت: «ای مرد شجاع، خداوند با توست!»
13 Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
جدعون جواب داد: «ای سرورم، اگر خداوند با ماست، چرا این همه بر ما ظلم می‌شود؟ پس آن همه معجزاتی که اجدادمان برای ما تعریف می‌کردند کجاست؟ مگر خداوند اجداد ما را از مصر بیرون نیاورد؟ پس چرا حالا ما را ترک نموده و در چنگ مدیانی‌ها رها ساخته است؟»
14 Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
آنگاه خداوند رو به وی نموده گفت: «با همین قدرتی که داری برو و اسرائیلی‌ها را از دست مدیانیان نجات ده. من هستم که تو را می‌فرستم!»
15 Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
اما جدعون در جواب گفت: «ای خداوند، من چطور می‌توانم اسرائیل را نجات دهم؟ در بین تمام خاندانهای قبیلهٔ منسی، خاندان من از همه حقیرتر است و من هم کوچکترین فرزند پدرم هستم.»
16 Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
خداوند به او گفت: «ولی بدان که من با تو خواهم بود و مدیانی‌ها را به آسانی شکست خواهی داد!»
17 Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
جدعون پاسخ داد: «اگر تو که با من سخن می‌گویی واقعاً خود خداوند هستی و با من خواهی بود، پس با نشانه‌ای این را ثابت کن.
18 Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
خواهش می‌کنم همین‌جا بمان تا من بروم و هدیه‌ای برایت بیاورم.» او گفت: «من همین‌جا می‌مانم تا تو برگردی.»
19 Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
جدعون به خانه شتافت و بزغاله‌ای سر برید و گوشت آن را پخت و با ده کیلوگرم آرد، چند نان فطیر درست کرد. سپس گوشت را در سبدی گذاشت و آب گوشت را در کاسه‌ای ریخت و آن را نزد فرشته که زیر درخت بلوط نشسته بود آورده، پیش وی نهاد.
20 Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
فرشته به او گفت: «گوشت و نان را روی آن صخره بگذار و آب گوشت را روی آن بریز.» وقتی که جدعون دستورهای وی را انجام داد،
21 Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
فرشته با نوک عصای خود گوشت و نان را لمس نمود، و آتش از صخره برآمده، گوشت و نان را بلعید! همان وقت فرشته ناپدید شد!
22 Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
وقتی جدعون فهمید که او در حقیقت فرشتهٔ خداوند بود، از ترس فریاد زده، گفت: «آه ای خداوند! من فرشتهٔ تو را روبرو دیدم!»
23 Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
خداوند به وی فرمود: «آرام باش! نترس، تو نخواهی مرد!»
24 Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
جدعون در آنجا مذبحی برای خداوند ساخت و آن را یهوه شالوم (یعنی «خداوند آرامش است») نامید. (این مذبح هنوز در ملک عفره که متعلق به خاندان ابیعزر است، باقیست.)
25 Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
همان شب خداوند به جدعون گفت: «یکی از گاوهای قوی پدر خود را بگیر و مذبح بت بعل را که در خانهٔ پدرت هست به آن ببند و آن را واژگون کن و بت چوبی اشیره را هم که کنار مذبح است بشکن.
26 Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
به جای آن مذبحی برای یهوه خدایت روی این تپه بساز و سنگهای آن را به دقت کار بگذار. آنگاه گاو را به عنوان قربانی سوختنی به خداوند تقدیم کن و چوب بت اشیره را برای آتش مذبح به کار ببر.»
27 Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
پس جدعون ده نفر از نوکران خود را برداشت و آنچه را که خداوند به او دستور داده بود، انجام داد. اما او از ترس خاندان پدرش و سایر مردم شهر، این کار را در شب انجام داد.
28 Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
صبح روز بعد، وقتی مردم از خواب بیدار شدند، دیدند مذبح بت بعل خراب شده و اثری از اشیره نیست. آنها مذبح دیگری که آثار قربانی روی آن بود، دیدند.
29 Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
مردم از یکدیگر می‌پرسیدند: «چه کسی این کار را کرده است؟» وقتی خوب تحقیق کردند، فهمیدند که کار جدعون پسر یوآش است.
30 Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
پس با عصبانیت به یوآش گفتند: «پسر خود را بیرون بیاور! او باید به خاطر خراب کردن مذبح بعل و قطع کردن ستون اشیره کشته شود.»
31 Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
اما یوآش به همهٔ کسانی که بر ضد او برخاسته بودند گفت: «آیا بعل محتاج کمک شماست؟ این توهین به اوست! شما هستید که باید به خاطر توهین به بعل کشته شوید! اگر بعل واقعاً خداست بگذارید خودش از کسی که مذبحش را خراب کرده است انتقام بگیرد.»
32 Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
از آن پس جدعون، یَرُبعل (یعنی «بگذارید بعل از خودش دفاع کند») نامیده شد، زیرا یوآش گفت: «بگذارید بعل از خودش دفاع کند، زیرا مذبحی که خراب شده متعلق به بعل است.»
33 Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
بعد از این واقعه، تمام مدیانی‌ها، عمالیقی‌ها و سایر قبایل همسایه با هم متحد شدند تا با اسرائیلی‌ها بجنگند. آنها از رود اردن گذشته، در درهٔ یزرعیل اردو زدند.
34 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
در این موقع روح خداوند بر جدعون قرار گرفت و او شیپور را نواخت و مردان خاندان ابیعزر نزد او جمع شدند.
35 Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
همچنین قاصدانی نزد قبایل منسی، اشیر، زبولون و نفتالی فرستاد و آنها نیز آمدند و به او ملحق شدند.
36 Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
آنگاه جدعون به خدا چنین گفت: «اگر همان‌طور که وعده فرمودی، واقعاً قوم اسرائیل را به‌وسیلهٔ من نجات خواهی داد،
37 kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
به این طریق آن را به من ثابت کن: من مقداری پشم در خرمنگاه می‌گذارم. اگر فردا صبح فقط روی پشم شبنم نشسته باشد ولی زمین، خشک باشد، آنگاه مطمئن می‌شوم که قوم اسرائیل را به‌وسیلۀ من نجات خواهی داد.»
38 Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
و چنین شد. صبح زود که جدعون از خواب برخاست و پشم را فشرد به مقدار یک کاسه آب از آن خارج شد!
39 Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
آنگاه جدعون به خدا گفت: «غضب تو بر من افروخته نشود. اجازه بده فقط یک بار دیگر امتحان کنم. این دفعه بگذار پشم خشک بماند و زمین اطراف آن از شبنم تر شود!»
40 Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.
خداوند چنین کرد. آن شب زمین اطراف را شبنم پوشانید اما پشم خشک بود!

< Judges 6 >