< Judges 6 >

1 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
Abantwana bakoIsrayeli basebesenza okubi emehlweni eNkosi; iNkosi yasibanikela esandleni sikaMidiyani iminyaka eyisikhombisa.
2 Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
Lesandla sikaMidiyani saba lamandla phezu kukaIsrayeli. Ngenxa kaMidiyani abantwana bakoIsrayeli bazenzela imihume esezintabeni, lembalu, lezinqaba.
3 Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
Kwasekusithi uIsrayeli esehlanyele, enyuka amaMidiyani lamaAmaleki labantwana bempumalanga, benyuka bamelana labo,
4 Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
bamisa inkamba maqondana labo, bachitha izithelo zelizwe, uze ufike eGaza, njalo kabatshiyanga okondlayo koIsrayeli loba imvu loba inkabi loba ubabhemi.
5 Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
Ngoba bona benyuka lezifuyo zabo lamathente abo, bafika njengokugcwala kwentethe ngobunengi, okokuthi bona lamakamela abo babengelanani; basebengena elizweni ukulichitha.
6 Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
UIsrayeli wasesiba ngumyanga kakhulu ngenxa yamaMidiyani, labantwana bakoIsrayeli bakhala eNkosini.
7 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
Kwasekusithi lapho abantwana bakoIsrayeli bekhala eNkosini ngenxa yamaMidiyani,
8 Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
iNkosi yathuma umprofethi kubantwana bakoIsrayeli, owathi kibo: Itsho njalo iNkosi, uNkulunkulu wakoIsrayeli: Mina ngalenyusa lisuka eGibhithe ngalikhupha endlini yobugqili,
9 Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
ngalihluthuna esandleni samaGibhithe, lesandleni sabo bonke abalicindezelayo, ngabaxotsha phambi kwenu, ngalinika ilizwe labo,
10 Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
ngathi kini: NgiyiNkosi uNkulunkulu wenu; lingesabi onkulunkulu bamaAmori elihlala elizweni lawo. Kodwa kalililalelanga ilizwi lami.
11 Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
Kwasekufika ingilosi yeNkosi, yahlala ngaphansi kwesihlahla se-okhi esiseOfira, esasingesikaJowashi umAbiyezeri, lendodana yakhe uGidiyoni yayibhula ingqoloyi esikhamelweni sewayini, ukuze iyifihlele amaMidiyani.
12 Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
Ingilosi yeNkosi yasibonakala kuye, yathi kuye: INkosi ilawe, qhawe elilamandla.
13 Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
UGidiyoni wasesithi kuyo: Hawu Nkosi yami, uba iNkosi ilathi, kungani konke lokhu kusehlele? Kanti zingaphi zonke izimangaliso zayo abasitshela zona obaba besithi: INkosi kayisenyusanga siphuma eGibhithe yini? Kodwa khathesi iNkosi isidelile, yasinikela esandleni samaMidiyani.
14 Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
INkosi yasiphendukela kuye yathi: Hamba ngalamandla akho, ukhulule uIsrayeli esandleni samaMidiyani. Kangikuthumanga yini?
15 Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
Wasesithi kuyo: Hawu Nkosi yami, ngizamkhulula ngani uIsrayeli? Khangela, usendo lwami lungumyanga koManase, njalo ngingomncinyane endlini kababa.
16 Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
INkosi yasisithi kuye: Ngoba ngizakuba lawe, uzawatshaya-ke amaMidiyani njengendodanye.
17 Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
Wasesithi kuyo: Uba khathesi ngithole umusa emehlweni akho, ngenzela isibonakaliso sokuthi nguwe okhuluma lami.
18 Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
Ake ungasuki lapha, ngize ngibuye kuwe, ngikhuphe isipho sami, ngisibeke phambi kwakho. Yasisithi: Mina ngizahlala uze uphenduke.
19 Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
UGidiyoni wasengena, walungisa izinyane lembuzi, lezinkwa ezingelamvubelo nge-efa lempuphu, inyama wayifaka esitsheni, lomhluzi wawufaka embizeni, wakukhuphela kuyo ngaphansi kwesihlahla se-okhi, wakusondeza.
20 Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
Ingilosi kaNkulunkulu yasisithi kuye: Thatha inyama lezinkwa ezingelamvubelo, ukubeke phezu kwalelidwala, ubusuthela umhluzi. Wasesenza njalo.
21 Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
Ingilosi yeNkosi yasiselula isihloko somqwayi owawusesandleni sayo, yathinta inyama lezinkwa ezingelamvubelo; kwasekusenyuka umlilo uphuma edwaleni, wadla inyama lezinkwa ezingelamvubelo. Lengilosi yeNkosi yasuka emehlweni akhe.
22 Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
UGidiyoni wasebona ukuthi yayiyingilosi yeNkosi. UGidiyoni wathi: Maye, Nkosi Jehova! Ngenxa yokuthi ngibone ingilosi yeNkosi ubuso ngobuso.
23 Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
Kodwa iNkosi yathi kuye: Ukuthula kakube kuwe, ungesabi, kawuyikufa.
24 Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
UGidiyoni waseyakhela iNkosi ilathi lapho, walibiza ngokuthi uJehova-shalomi. Kuze kube lamuhla lisesekhona eOfira lamaAbiyezeri.
25 Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
Kwasekusithi ngalobobusuku iNkosi yathi kuye: Thatha ijongosi lenkunzi engekayihlo, ngitsho ijongosi lesibili elileminyaka eyisikhombisa, udilize ilathi likaBhali elingelikayihlo, lesixuku esiphansi kwalo usigamule;
26 Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
wakhele iNkosi uNkulunkulu wakho ilathi phezu kwengqonga yalinqaba, njengokwejwayelekileyo; ubusuthatha ijongosi lesibili, unikele umnikelo wokutshiswa ngenkuni zesixuku ozasigamula.
27 Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
UGidiyoni wasethatha amadoda alitshumi ezincekwini zakhe, wenza njengokutsho kweNkosi kuye; kodwa kwathi ngenxa yokuthi wayesesaba indlu kayise lamadoda omuzi ukukwenza emini, wakwenza ebusuku.
28 Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
Lapho amadoda omuzi evuka ekuseni kakhulu, khangela, ilathi likaBhali lalidiliziwe, lesixuku esasiphansi kwalo sesiganyuliwe, lejongosi lesibili lanikelwa phezu kwelathi elaselakhiwe.
29 Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
Basebesithi omunye komunye: Ngubani owenze loludaba? Nxa sebedingile bebuza bathi: UGidiyoni indodana kaJowashi wenze loludaba.
30 Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
Amadoda omuzi asesithi kuJowashi: Khupha indodana yakho ukuze ife, ngoba idilizile ilathi likaBhali, langoba igamule isixuku esasiphansi kwalo.
31 Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
Kodwa uJowashi wathi kubo bonke ababemi ngakuye: Lina lizamlwela uBhali yini, kumbe lina limsindise? Omlwelayo uzabulawa kusesekuseni. Uba engunkulunkulu, kazilwele, ngoba ilathi lakhe lidiliziwe.
32 Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
Ngakho ngalolosuku wambiza ngokuthi nguJerubali, esithi: UBhali kalwe laye, ngoba ulidilizile ilathi lakhe.
33 Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
Lawo wonke amaMidiyani lamaAmaleki labantwana bempumalanga babuthana ndawonye, bachapha, bamisa inkamba esigodini seJizereyeli.
34 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
LoMoya weNkosi wembesa uGidiyoni; wavuthela uphondo, lamaAbiyezeri abizwa emva kwakhe.
35 Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
Wasethuma izithunywa kuye wonke uManase, labo futhi babizwa emva kwakhe. Wasethuma izithunywa koAsheri lakoZebuluni lakoNafithali; basebesiza ukubahlangabeza.
36 Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
UGidiyoni wasesithi kuNkulunkulu: Uba uzasindisa uIsrayeli ngesandla sami njengokutsho kwakho,
37 kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
khangela, ngizabeka uboya bezimvu obugundiweyo ebaleni lokubhulela; uba amazolo ezakuba phezu koboya obugundiweyo kuphela, lokoma emhlabathini wonke, ngizakwazi-ke ukuthi uzamsindisa uIsrayeli ngesandla sami, njengokutsho kwakho.
38 Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
Kwasekusiba njalo. Lapho evuka ngovivi kusisa, wacindezela uboya obugundiweyo, wakhama amazolo eboyeni obugundiweyo, umganu ogcwele amanzi.
39 Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
UGidiyoni wasesithi kuNkulunkulu: Ulaka lwakho lungangivutheli, ngizakhuluma khathesi kuphela; ake ngihlole khathesi kuphela ngoboya obugundiweyo; ake kube lokoma eboyeni obugundiweyo kuphela, lemhlabathini wonke kakube lamazolo.
40 Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.
UNkulunkulu wasesenza njalo ngalobobusuku; ngoba kwaba lokoma eboyeni obugundiweyo kuphela, kodwa emhlabathini wonke kwaba lamazolo.

< Judges 6 >