< Judges 6 >

1 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
És gonoszul cselekedének az Izráel fiai az Úrnak szemei előtt, azért adá őket az Úr a Midiániták kezébe hét esztendeig.
2 Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
És hatalmat vőn a Midiániták keze az Izráelen, és a Midiánitáktól való féltökben készítették magoknak az Izráel fiai azokat a barlangokat, rejtekhelyeket és erősségeket, a melyek a hegységben vannak.
3 Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
Mert ha vetett Izráel, mindjárt ott termettek a Midiániták, az Amálekiták és a Napkeletnek fiai, és rájok törtek.
4 Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
És táborba szálltak ellenök, és pusztították a földnek termését egész addig, a merre Gázába járnak, és nem hagytak élésre valót Izráelben, sem juhot, sem ökröt, sem szamarat.
5 Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
Mert barmaikkal és sátoraikkal vonultak föl; csapatosan jöttek, mint a sáskák, úgy hogy sem nékik magoknak, sem tevéiknek nem volt száma, és ellepték a földet, hogy elpusztítsák azt.
6 Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
Mikor azért igen megnyomorodott az Izráel a Midiániták miatt, az Úrhoz kiáltának az Izráel fiai.
7 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
Mikor pedig kiáltottak vala az Izráel fiai az Úrhoz Midián miatt:
8 Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
Prófétát külde az Úr az Izráel fiaihoz, és monda nékik: Azt mondja az Úr, Izráel Istene: Én vezettelek fel titeket Égyiptomból, és hoztalak ki titeket a szolgálatnak házából,
9 Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
És én mentettelek meg benneteket az Égyiptombeliek kezéből, és minden nyomorgatóitoknak kezökből, a kiket kiűztem előletek, és néktek adtam az ő földjüket.
10 Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
És mondék néktek: Én, az Úr, vagyok a ti Istenetek; ne féljétek az Emoreusok isteneit, kiknek földén laktok; de ti nem hallgattatok az én szómra.
11 Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
És eljöve az Úrnak angyala, és leüle ama cserfa alatt, a mely Ofrában van, a mely az Abiézer nemzetségéből való Joásé vala, és az ő fia Gedeon épen búzát csépelt a pajtában, hogy megmentse a Midiániták orczája elől.
12 Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
Ekkor megjelenék néki az Úrnak angyala, és monda néki: Az Úr veled, erős férfiú!
13 Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
Gedeon pedig monda néki: Kérlek uram, ha velünk van az Úr, miért ért bennünket mindez? és hol vannak minden ő csoda dolgai, a melyekről beszéltek nékünk atyáink, mondván: Nem az Úr hozott-é fel minket Égyiptomból?! Most pedig elhagyott minket az Úr, és adott a Midiániták kezébe.
14 Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
És az Úr hozzá fordula, és monda: Menj el ezzel a te erőddel, és megszabadítod Izráelt Midián kezéből. Nemde, én küldelek téged?
15 Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
És monda néki: Kérlek uram, miképen szabadítsam én meg Izráelt? Ímé az én nemzetségem a legszegényebb Manasséban, és én vagyok a legkisebb atyámnak házában.
16 Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
És monda néki az Úr: Én leszek veled, és megvered Midiánt, mint egy embert.
17 Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
Ő pedig monda néki: Ha kegyelmet találtam a te szemeid előtt, kérlek, adj nékem valamely jelt, hogy te szólasz én velem.
18 Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
El ne menj kérlek innen, míg vissza nem jövök hozzád, és ki nem hozom az én áldozatomat, és le nem teszem elődbe. Az pedig monda: Én itt leszek, míg visszatérsz.
19 Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
Gedeon pedig elméne, és elkészíte egy kecskegödölyét és egy efa lisztből kovásztalan pogácsákat, és betevé a húst egy kosárba, és a hús levét fazékba, és kivivé hozzá a cserfa alá, és felajánlá néki.
20 Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
És monda néki az Isten angyala: Vegyed a húst és a kovásztalan kenyereket, és rakd erre a kősziklára, és a hús levét öntsd rá. És úgy cselekedék.
21 Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
Ekkor kinyújtá az Úrnak angyala pálczájának végét, mely kezében vala, és megérinté a húst, és a kovásztalan kenyeret; és tűz jött ki a kősziklából, és megemészté a húst és a kovásztalan kenyereket. Az Úrnak angyala pedig eltünt az ő szemei elől.
22 Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
Látván pedig Gedeon, hogy az Úrnak angyala volt az, monda Gedeon: Jaj nékem Uram, Istenem! mert az Úrnak angyalát láttam színről színre!
23 Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
És monda néki az Úr: Békesség néked! ne félj, nem halsz meg!
24 Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
És építe ott Gedeon oltárt az Úrnak, és nevezé azt Jehova-Salomnak (azaz: az Úr a béke), mely mind e mai napig megvan az Abiézer nemzetségének városában, Ofrában.
25 Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
És lőn ugyanazon éjjel, hogy monda az Úr néki: Végy egy tulkot atyádnak ökrei közül, és egy másik tulkot, a mely hét éves, és rontsd le a Baál oltárát, a mely a te atyádé és a berket, a mely a mellett van, vágd ki.
26 Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
És építs oltárt az Úrnak, a te Istenednek, ennek a megerősített helynek tetején alkalmatos helyen, és vedd a második tulkot, és áldozd meg égőáldozatul a berek fájával, a melyet kivágsz.
27 Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
Ekkor Gedeon tíz férfiút vőn maga mellé az ő szolgái közül, és a képen cselekedék, a mint megmondotta vala néki az Úr. De miután félt atyjának háznépétől és a városnak férfiaitól ezt nappal cselekedni, éjszaka tevé meg.
28 Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
Mikor aztán felkeltek reggel a városnak férfiai, íme már össze volt törve a Baál oltára, és levágva a mellette levő berek, és a második tulok égőáldozatul azon az oltáron, a mely építteték.
29 Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
És mondának egyik a másikának: Ki cselekedte ezt? És mikor utána kérdezősködtek és tudakozódtak, azt mondották: Gedeon, a Joás fia cselekedte ezt a dolgot.
30 Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
Akkor mondának a városnak férfiai Joásnak: Add ki fiadat, meg kell halnia, mert lerontotta a Baál oltárát és mert kivágta a berket, a mely mellette volt.
31 Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
Joás pedig monda mindazoknak, a kik körülötte állának: Baálért pereltek ti? Avagy ti oltalmazzátok-é őtet? Valaki perel ő érette, ölettessék meg reggelig. Ha isten ő, hát pereljen ő maga, hogy oltára lerontatott!
32 Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
És azon a napon elnevezték őt Jerubbaálnak, mondván: Pereljen ő vele Baál, mert lerontotta az ő oltárát.
33 Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
És mikor az egész Midián és Amálek és a Napkeletiek egybegyűlének, és általkeltek a Jordánon, és tábort jártak a Jezréel völgyében:
34 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
Az Úrnak lelke megszállotta Gedeont, és megfúván a harsonákat, egybehívá az Abiézer házát, hogy őt kövesse.
35 Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
És követeket külde egész Manasséba, és egybegyűle az is ő utána; és követeket külde Aserbe és Zebulonba és Nafthaliba, és feljövének eleikbe.
36 Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
És monda Gedeon az Istennek: Ha csakugyan az én kezem által akarod megszabadítani Izráelt, a miképen mondottad,
37 kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
Íme egy fürt gyapjat teszek a szérűre, és ha csak maga a gyapjú lesz harmatos, míg az egész föld száraz leénd: erről megtudom, hogy valóban az én kezem által szabadítod meg Izráelt, a mint mondottad.
38 Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
És úgy lőn. Mert mikor másnap reggel felkelt, és megszorítá a gyapjat, harmatot facsart ki a gyapjúból, egy tele csésze vizet.
39 Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
És monda Gedeon az Istennek: Ne gerjedjen fel a te haragod én ellenem, hogy még egyszer szólok. Hadd tegyek kísérletet, kérlek, még egyszer e gyapjúval. Legyen, kérlek, szárazság csak a gyapjún, és harmat az egész földön.
40 Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.
És úgy cselekedék Isten azon az éjszakán, és lőn szárazság csak magán a gyapjún, míg az egész földön harmat lőn.

< Judges 6 >