< Judges 6 >

1 Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
Forsothe the sones of Israel diden yuel in the `siyt of the Lord, and he bitook hem in the hond of Madian seuene yeer.
2 Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
And thei weren oppressid of hem greetly; and `thei maden dichis, and dennes to hem silf in hillis, and strongeste places to fiyte ayen.
3 Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
And whanne Israel hadde sowe, Madian stiede, and Amalech, and othere of the `naciouns of the eest;
4 Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
and thei settiden tentis at the sones of Israel, and wastiden alle thingis `as tho weren in eerbis, ethir grene corn, `til to the entryng of Gaza, and outirli thei leften not in Israel ony thing perteynynge to lijf, not scheep, not oxun, not assis.
5 Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
For thei and alle her flockis camen with her tabernaclis, and at the licnesse of locustus thei filliden alle thingis, and a multitude of men and of camels was with out noumbre, and wastiden what euer thing thei touchiden.
6 Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
And Israel was `maad low greetli in the siyt of Madian.
7 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
And Israel criede to the Lord, `and axyde help ayens Madianytis; and he sente to hem a man,
8 Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
a profete, and he spak, The Lord God of Israel seith these thingis, Y made you to stie fro Egipt, and Y ledde you out of the hows of seruage,
9 Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
and Y delyueride you fro the hond of Egipcians, and of alle enemyes that turmentiden you; and Y castide hem out at youre entryng, and Y yaf to you `the lond of hem;
10 Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
and Y seide, Y am `youre Lord God; drede ye not the goddis of Ammorreis, in whose lond ye dwellen; and ye nolden here my vois.
11 Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
Forsothe an aungel of the Lord cam, and sat undur an ook, that was in Effra, and perteynede to Joas, fadir of the meinee of Ezri. And whanne Gedeon, `his sone, threischide out, and purgide wheetis in a pressour,
12 Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
that he schulde fle Madian, an aungel of the Lord apperide to hym, and seide, The Lord be with thee, thou strongeste of men.
13 Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
And Gedeon seide to hym, My lord, Y biseche, if the Lord is with vs, whi therfor han alle these yuels take vs? Where ben the merueils of hym, whiche oure fadris telden, and seiden, The Lord ledde vs out of Egipt? `Now forsothe he hath forsake vs, and hath bitake vs in the hond of Madian.
14 Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
And the Lord bihelde to hym, and seide, Go thou in this strengthe of thee, and thou schalt delyuere Israel fro the hond of Madian; wite thou, that Y sente thee.
15 Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
Which Gedeon answeride, and seide, My lord, Y biseche, in what thing schal Y delyuere Israel? Lo! my meynee is the loweste in Manasses, and Y am the leeste in the hows of my fadir.
16 Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
And the Lord seide to hym, Y schal be with thee, and thou schalt smyte Madian as o man.
17 Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
And Gedeon seide, If Y haue foundun grace bifor thee, yyue to me a signe, that thou, that spekist to me, art sente of Goddis part;
18 Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
go thou not `awei fro hennus, til Y turne ayen to thee, and brynge sacrifice, and offre to thee. Whiche answeride, Y schal abide thi comyng.
19 Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
And so Gedeon entride, and sethide a kide, and took therf looues of a buyschel of mell, and fleischis in a panyere; and he sente the broth of fleischis in a pot, and bar alle thingis vndur an ook, and offride to hym.
20 Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
To whom the aungel of the Lord seide, Take thou the fleischis, and therf looues, and putte on that stoon, and schede the broth aboue. And whanne he hadde do so,
21 Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
the aungel of the Lord helde forth the `ende of the yerde which he helde in the hond, and he touchide the fleischis, and the therf looues; and fier stiede fro the stoon, and wastide the fleischis, and therf looues. Forsothe the aungel of the Lord vanyschide fro hise iyen.
22 Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
And Gedeon siy that he was `an aungel of the Lord, and seide, Lord God, alas to me, for Y siy the aungel of the Lord face to face.
23 Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
And the Lord seide to hym, Pees be with thee; drede thou not, thou schalt not die.
24 Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
Therfor Gedeon bildide there an auter to the Lord, and he clepide it the Pees of the Lord, `til in to present dai. And whanne he was yit in Effra, which is of the meynee of Ezri, the Lord seide to hym in that nyyt,
25 Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
Take thou `the bole of thy fadir, and anothir bole of seuene yeer, and thou schalt distrie the auter of Baal, which is thi fadris, and kitte thou doun the wode, which is aboute the auter;
26 Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
and thou schalt bilde an auter to thi Lord God in the hiynesse of this stoon, on which thou puttidist sacrifice bifore; and thou schalt take the secounde bole, and thou schalt offre brent sacrifice on the heep of trees, whiche thou kittidist doun of the wode.
27 Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
Therfore Gedeon took ten men of hise seruauntis, and dide as the Lord comaundide to hym. Sotheli Gedeon dredde the hows of his fadir, and the men of that citee, and nolde do bi dai, but fillide alle thingis bi nyyt.
28 Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
And whanne men of that citee hadde rise eerly, thei sien the auter of Baal distried, and the wode kit doun, and the tothir bole put on the auter, that was bildid thanne.
29 Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
And thei seiden togidere, Who hath do this? And whanne thei enqueriden the doer of the deed, it was seid, Gedeon, the sone of Joas, dide alle these thingis.
30 Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
And thei seiden to Joas, Brynge forth thi sone hidur, that he die, for he distriede the auter of Baal, and kittide doun the wode.
31 Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
To whiche he answeride, Whether ye ben the venieris of Baal, that ye fiyte for hym? he that is aduersarie of hym, die, bifor that the `liyt of the morew dai come; if he is God, venge he hym silf of hym that castide doun his auter.
32 Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
Fro that dai Gedeon was clepid Gerobaal, for Joas hadde seid, Baal take veniaunce of hym that castide doun his auter.
33 Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
Therfor al Madian, and Amalech, and the puplis of the eest weren gadirid to gidere, and passiden Jordan, and settiden tentis in the valey of Jezrael.
34 Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
Forsothe the spirit of the Lord clothide Gedeon; `and he sownede with a clarioun, and clepide to gidere the hows of Abiezer, that it schulde sue hym.
35 Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
And he sente messangeris in to al Manasses, and he suede Gedeon; and he sente othere messangeris in to Aser, and Zabulon, and Neptalym, whiche camen to hym.
36 Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
And Gedeon seide to the Lord, If thou makist saaf Israel bi myn hond, as thou hast spoke,
37 kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
Y schal putte this flees of wolle in the corn floor; if dew is in the flees aloone, and drynesse is in al the erthe, Y schal wite, that thou schalt delyuere Israel bi myn hond, as thou hast spoke.
38 Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
And it was don so. And he roos bi nyyt, and whanne the flees was wrongun out, he fillide a pot with deew;
39 Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
and he seide eft to the Lord, Thi strong veniaunce be not wrooth ayens me, if Y asaie, `that is, axe a signe, yit onys, and seke a signe in the flees; Y preye, that the flees aloone be drie, and al the erthe be moist with deew.
40 Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.
And the Lord dide in that nyyt, as Gedeon axide; and drynesse was in the flees aloone, and deew was in al the erthe.

< Judges 6 >