< Judges 5 >

1 Nígbà náà ni Debora àti Baraki ọmọ Abinoamu kọ orin ní ọjọ́ náà wí pé,
Tad Debora un Baraks, Abinoama, dēls, tai dienā dziedāja un sacīja:
2 “Nítorí bí àwọn olórí ti síwájú ní Israẹli, nítorí bi àwọn ènìyàn ti fi tọkàntọkàn wa, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa!
Ka Israēla varenie spēcīgi rādījušies, ka ļaudis labprātīgi cēlušies, teiciet To Kungu!
3 “Ẹ gbọ́ ẹ̀yin ọba! Ẹ fetí yín sílẹ̀ ẹ̀yin ọmọ-aládé! Èmi yóò kọrin sí Olúwa, èmi yóò kọrin ìyìn sí Olúwa: Ọlọ́run Israẹli.
Klausāties, ķēniņi, ņemiet vērā, lielie kungi! Tam Kungam es dziedāšu, Tam Kungam, Israēla Dievam, es dziedāšu dziesmas.
4 “Olúwa nígbà tí o jáde kúrò ní Seiri, nígbà tí ìwọ ń yan jáde wá láti pápá Edomu, ilẹ̀ mì tìtì, àwọn ọ̀run sì kán sílẹ̀, àní àwọsánmọ̀ pẹ̀lú kàn omi sílẹ̀.
Kungs, kad Tu izgāji no Seīra un atnāci no Edoma lauka, tad zeme drebēja, un debesis pilēja, un padebeši pilēja ar ūdeni.
5 Àwọn òkè ńlá wárìrì ní iwájú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Sinai ní iwájú Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
Kalni izkusa Tā Kunga priekšā, pats Sinaī Tā Kunga, Israēla Dieva, priekšā.
6 “Ní ọjọ́ Ṣamgari ọmọ Anati, ní ọjọ́ Jaeli, àwọn ọ̀nà òpópó dá; àwọn arìnrìn-àjò sì ń gba ọ̀nà ìkọ̀kọ̀.
Zamgara, Anata dēla, dienās, Jaēles dienās, ceļi bija klusi, un ceļa ļaudis gāja aplinkus.
7 Àwọn olórí tán ní Israẹli, wọ́n tán, títí èmi Debora fi dìde bí ìyá ní Israẹli.
Klusi bija ciemi iekš Israēla, tie bija klusi, kamēr es, Debora, cēlos, kamēr es cēlos, māte iekš Israēla.
8 Wọ́n ti yan ọlọ́run tuntun, nígbà náà ni ogun wà ní ibodè a ha rí asà tàbí ọ̀kọ̀ kan láàrín ọ̀kẹ́ méjì ní Israẹli bí.
Jaunus dievus izredzējās, tad radās karš vārtos. Vai gan redzēja bruņas, vai šķēpus pie četrdesmit tūkstošiem iekš Israēla?
9 Àyà mi fà sí àwọn aláṣẹ Israẹli àwọn tí wọ́n yọ̀ǹda ara wọn tinútinú láàrín àwọn ènìyàn. Ẹ fi ìbùkún fún Olúwa!
Mana sirds pieder Israēla valdniekiem, tiem ļaudīm, kas labprātīgi cēlušies. Teiciet To Kungu!
10 “Ẹ kéde rẹ̀: ẹ̀yin tí ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ funfun, ẹ̀yin tí ń jókòó lórí ẹní dáradára, àti ẹ̀yin tí ó ń rìn ní ọ̀nà. Ní ọ̀nà jíjìn sí
Kas jājat uz baltām ēzelienēm, kas sēžat uz audumiem, kas staigājat pa ceļu, dziedājiet!
11 ariwo àwọn tafàtafà, ní ibi tí a gbé ń fa omi. Níbẹ̀ ni wọ́n gbé ń sọ ti iṣẹ́ òdodo Olúwa, àní iṣẹ́ òdodo ìjọba rẹ̀ ní Israẹli. “Nígbà náà ni àwọn ènìyàn Olúwa sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibodè.
Kur strēlnieku balss skanēja pie ūdens akām, tur slavē Tā Kunga taisnos darbus, tos taisnos darbus pie Viņa ciemiem iekš Israēla. Tad Tā Kunga ļaudis pārgāja savos vārtos.
12 ‘Jí, jí, Debora! Jí, jí, kọ orin dìde! Dìde ìwọ Baraki! Kó àwọn ìgbèkùn rẹ ní ìgbèkùn ìwọ ọmọ Abinoamu.’
Modies, modies, Debora! modies, modies, dziedi dziesmu! Celies, Barak, un ved savus gūstītos, Abinoama dēls.
13 “Nígbà náà ni àwọn tókù sọ̀kalẹ̀ àwọn ọlọ́lá lọ; àwọn ènìyàn Olúwa tọ̀ mí wá pẹ̀lú àwọn alágbára.
Tad nonāca atlikums no tiem tautas vareniem; Tas Kungs nonāca man līdz starp tiem spēcīgiem.
14 Àwọn kan jáde wá láti Efraimu, àwọn tí gbòǹgbò wọn wà ní Amaleki; Benjamini wà pẹ̀lú àwọn tí ó tẹ̀lé ọ. Láti Makiri ni àwọn aláṣẹ ti sọ̀kalẹ̀ wá, láti Sebuluni ni àwọn ẹni tí ń mú ọ̀pá oyè lọ́wọ́.
No Efraīma tie, kam sakne ir iekš Amaleka, aiz tevis Benjamins starp taviem ļaudīm; no Mahira valdnieki nāca un no Zebulona, kas tur (nes) vadoņa zizli.
15 Àwọn ọmọ-aládé Isakari wá pẹ̀lú Debora; bí Isakari ti ṣe olóòtítọ́ sí Baraki, wọ́n fi ẹsẹ̀ súré tẹ̀lé wọn lọ sí àfonífojì náà. Ní ipadò Reubeni ni ìgbèrò púpọ̀ wà.
Un Īsašara virsnieki bija ar Deboru, un Īsašars tā kā Baraks, lejā nesti savām kājām. Pie Rūbena upēm bija lieli sirds padomi.
16 Èéṣe tí ìwọ fi dúró pẹ́ láàrín agbo àgùntàn láti máa gbọ́ fèrè olùṣọ́-àgùntàn? Ní ipadò Reubeni ni ìgbèrò púpọ̀ wà.
Kāpēc tu paliki pie laidariem, klausīties stabules pie ganāmiem pulkiem? Pie Rūbena upēm bija lieli sirds spriedumi.
17 Gileadi dúró ní òkè odò Jordani. Èéṣe tí Dani fi dúró nínú ọkọ̀ ojú omi? Aṣeri jókòó ní etí bèbè Òkun, ó sì ń gbé èbúté rẹ̀.
Gileāds palika viņpus Jardānes, un kāpēc Dans mīt pie laivām? Ašers sēž jūrmalā un paliek savos līčos.
18 Àwọn ènìyàn Sebuluni fi ẹ̀mí wọn wéwu ikú; bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ènìyàn Naftali ní ibi gíga pápá.
Zebulons, tā ir tauta, kas savu dvēseli nodod nāvē, un Naftalus arīdzan augstos klajumos.
19 “Àwọn ọba wá, wọ́n sì jà; àwọn ọba Kenaani jà ní Taanaki ní etí odo Megido, ṣùgbọ́n wọn kò sì gba èrè owó.
Ķēniņi nāca, tie karoja, tad Kanaāna ķēniņi karoja pie Taānakas, pie Meģidus ūdeņiem; naudas peļņu tie nedabūja.
20 Àwọn ìràwọ̀ já láti ojú ọ̀run wá láti inú ipa ọ̀nà wọn ni wọ́n bá Sisera jà.
No debesīm karoja, zvaigznes no saviem ceļiem karoja pret Siseru.
21 Odò Kiṣoni gbá wọn lọ, odò ìgbàanì, odò Kiṣoni. Máa yan lọ, ìwọ ọkàn mi, nínú agbára!
Ķizonas upe viņus aizrāva, tā veclaiku upe, Ķizonas upe. Celies, mana dvēsele, ar spēku!
22 Nígbà náà ni pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin ki ilẹ̀, nítorí eré sísá, eré sísá àwọn alágbára wọn.
Rībēt rībēja apakš zirgu kājām, jājot, viņu vareniem jājot.
23 ‘Ẹ fi Merosi bú,’ ni angẹli Olúwa wí. ‘Ẹ fi àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ìbú kíkorò, nítorí wọn kò wá sí ìrànlọ́wọ́ Olúwa, láti dojúkọ àwọn alágbára.’
Lādiet Merosu, saka Tā Kunga eņģelis, lādiet lādēdami viņa iedzīvotājus, tāpēc ka tie nav nākuši palīgā Tam Kungam, palīgā Tam Kungam ar stiprajiem.
24 “Ìbùkún ni fún Jaeli, aya Heberi ará Keni ju àwọn obìnrin lọ, ìbùkún ni fún un ju àwọn obìnrin tí ń gbé nínú àgọ́.
Svētīta pār sievām lai ir Jaēle, Hebera, tā Kenieša, sieva, svētīta pār sievām teltīs.
25 Ó béèrè omi, ó fún un ní wàrà; ó mú òrí-àmọ́ tọ̀ ọ́ wá nínú àwo iyebíye tí ó yẹ fún àwọn ọlọ́lá.
Ūdeni tas prasīja, tā deva pienu; dārgā kausā tā atnesa kreimu(krējumu).
26 Ó na ọwọ́ rẹ̀ mú ìṣó àgọ́, ó fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ mú òòlù awọ gbẹ́nàgbẹ́nà, òòlù náà ni ó sì fi lu Sisera, ó gbá a mọ́ ọn ní orí, ó sì gun, ó sì kàn ẹ̀bátí rẹ̀ mọ́lẹ̀ ṣinṣin.
Savu roku tā izstiepa pēc naglas, un savu labo roku pēc strādnieku vesera, un sita Siseram, sašķēla viņa galvu, satrieca un izurba viņa deniņus.
27 Ní ẹsẹ̀ rẹ̀ ó wólẹ̀, ó ṣubú; ó dùbúlẹ̀. Ó wólẹ̀ ní ẹsẹ̀ rẹ̀, ó ṣubú níbi tí ó gbé ń wólẹ̀; níbẹ̀ náà ni ó ṣubú kú sí.
Apakš viņas kājām tas locījās, krita zemē, gulēja; apakš viņas kājām tas locījās, krita; tur, kur locījās, tas gāzās un bija pagalam.
28 “Ìyá Sisera yọjú láti ojú fèrèsé, ó sì kígbe, ó kígbe ní ojú fèrèsé ọlọ́nà pé, ‘Èéṣe tí kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ fi pẹ́ bẹ́ẹ̀ láti dé? Èéṣe tí ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ fi dúró lẹ́yìn?’
Pa logu skatījās Siserus māte un kliedza caur skadriņiem: kāpēc viņa rati kavējās, ka tie nenāk? Kāpēc viņa zirgu soļi tik lēni?
29 Àwọn amòye obìnrin rẹ̀ dá a lóhùn; àní òun náà pẹ̀lú ti dá ara rẹ̀ lóhùn pé,
Tās gudrās no viņas cienīgām tai atbild, un arī (viņa) pati tā atbild uz saviem vārdiem:
30 ‘Wọn kò ha ń wa kiri, wọn kò ha ti pín ìkógun bi: ọmọbìnrin kan tàbí méjì fún ọkùnrin kan, fún Sisera ìkógun aṣọ aláràbarà, ìkógun aṣọ aláràbarà àti ọlọ́nà, àwọn aṣọ ọlọ́nà iyebíye fún ọrùn mi, gbogbo èyí tí a kó ní ogun?’
“Vai tad tie neatradīs un neizdalīs laupījumu, vienu, divas sievietes uz vīra galvu, raibas drēbes Siserum par laupījumu, raibas rakstītas drēbes par laupījumu, raibu drēbi, divas rakstītas raibas drēbes ap kaklu laupītajām.
31 “Bẹ́ẹ̀ ni kí ó jẹ́ kí gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kí ó ṣègbé Olúwa! Ṣùgbọ́n jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ọ ràn bí oòrùn, nígbà tí ó bá yọ nínú agbára rẹ̀.” Ilẹ̀ náà sì sinmi ní ogójì ọdún.
Tā lai, Kungs, iet bojā visi Tavi ienaidnieki! Bet kas Viņu mīļo, lai ir, tā kā saule uzlec savā spēkā.” - Un tai zemei bija miers četrdesmit gadus.

< Judges 5 >