< Judges 5 >

1 Nígbà náà ni Debora àti Baraki ọmọ Abinoamu kọ orin ní ọjọ́ náà wí pé,
Mũthenya ũcio Debora na Baraka mũrũ wa Abinoamu makĩina rwĩmbo rũrũ:
2 “Nítorí bí àwọn olórí ti síwájú ní Israẹli, nítorí bi àwọn ènìyàn ti fi tọkàntọkàn wa, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa!
“Rĩrĩa anene a Isiraeli maatongoria, rĩrĩa andũ meheana meyendeire-rĩ, goocai Jehova!
3 “Ẹ gbọ́ ẹ̀yin ọba! Ẹ fetí yín sílẹ̀ ẹ̀yin ọmọ-aládé! Èmi yóò kọrin sí Olúwa, èmi yóò kọrin ìyìn sí Olúwa: Ọlọ́run Israẹli.
“Iguai ũhoro ũyũ, inyuĩ athamaki! Thikĩrĩriai, inyuĩ aathani! Nĩngũinĩra Jehova, nĩngũina; nĩngũtungĩra Jehova rwĩmbo, o we Ngai wa Isiraeli.
4 “Olúwa nígbà tí o jáde kúrò ní Seiri, nígbà tí ìwọ ń yan jáde wá láti pápá Edomu, ilẹ̀ mì tìtì, àwọn ọ̀run sì kán sílẹ̀, àní àwọsánmọ̀ pẹ̀lú kàn omi sílẹ̀.
“Rĩrĩa Wee Jehova woimire Seiru, rĩrĩa woimire bũrũri wa Edomu, thĩ nĩyainainire, igũrũ rĩkiura, namo matu magĩita maaĩ.
5 Àwọn òkè ńlá wárìrì ní iwájú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Sinai ní iwájú Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
Irĩma nĩciathingithire mbere ya Jehova, o we Ngai wa Sinai, ikĩinaina mbere ya Jehova, Ngai wa Isiraeli.
6 “Ní ọjọ́ Ṣamgari ọmọ Anati, ní ọjọ́ Jaeli, àwọn ọ̀nà òpópó dá; àwọn arìnrìn-àjò sì ń gba ọ̀nà ìkọ̀kọ̀.
“Matukũ-inĩ ma Shamigari mũrũ wa Anathu, o na matukũ-inĩ ma Jaeli, njĩra nĩciagĩte andũ a kũgerera; agendi maageraga tũcĩra twa mĩkĩra.
7 Àwọn olórí tán ní Israẹli, wọ́n tán, títí èmi Debora fi dìde bí ìyá ní Israẹli.
Tũtũũra tũkĩaga andũ kũu Isiraeli, tũkĩaga andũ, o nginya rĩrĩa niĩ, Debora, ndaarahũkire, ngĩarahũka ngĩtuĩka ta nyina wa Isiraeli.
8 Wọ́n ti yan ọlọ́run tuntun, nígbà náà ni ogun wà ní ibodè a ha rí asà tàbí ọ̀kọ̀ kan láàrín ọ̀kẹ́ méjì ní Israẹli bí.
Hĩndĩ ĩrĩa maathuurire ngai ngʼeni, mbaara nĩyokire o ihingo-inĩ cia itũũra inene, na gũtionekire ngo kana itimũ harĩ andũ 40,000 kũu Isiraeli.
9 Àyà mi fà sí àwọn aláṣẹ Israẹli àwọn tí wọ́n yọ̀ǹda ara wọn tinútinú láàrín àwọn ènìyàn. Ẹ fi ìbùkún fún Olúwa!
Ngoro yakwa ĩrĩ hamwe na anene a Isiraeli, o hamwe na andũ arĩa merutĩire na kwĩyendera gatagatĩ-inĩ ka andũ. Goocai Jehova.
10 “Ẹ kéde rẹ̀: ẹ̀yin tí ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ funfun, ẹ̀yin tí ń jókòó lórí ẹní dáradára, àti ẹ̀yin tí ó ń rìn ní ọ̀nà. Ní ọ̀nà jíjìn sí
“Inyuĩ mũhaicaga ndigiri njerũ, mũikarĩire matandĩko manyu, na inyuĩ mũthiiaga na njĩra, cũraniai,
11 ariwo àwọn tafàtafà, ní ibi tí a gbé ń fa omi. Níbẹ̀ ni wọ́n gbé ń sọ ti iṣẹ́ òdodo Olúwa, àní iṣẹ́ òdodo ìjọba rẹ̀ ní Israẹli. “Nígbà náà ni àwọn ènìyàn Olúwa sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibodè.
kũrĩ na mĩgambo ya aini itahĩro-inĩ rĩa maaĩ. Mainaga ciĩko cia ũthingu cia Jehova, ciĩko cia ũthingu cia njamba ciake kũu Isiraeli. “Ningĩ andũ a Jehova magĩikũrũka nginya ihingo-inĩ cia itũũra inene.
12 ‘Jí, jí, Debora! Jí, jí, kọ orin dìde! Dìde ìwọ Baraki! Kó àwọn ìgbèkùn rẹ ní ìgbèkùn ìwọ ọmọ Abinoamu.’
‘Wee Debora, ũkĩra! Ĩ ndũgĩũkĩre! Ũkĩra, ũkĩra, ũkũye rwĩmbo! Arahũka wee Baraka! Wee mũrũ wa Abinoamu-rĩ, wĩnyiitĩre mĩgwate yaku.’
13 “Nígbà náà ni àwọn tókù sọ̀kalẹ̀ àwọn ọlọ́lá lọ; àwọn ènìyàn Olúwa tọ̀ mí wá pẹ̀lú àwọn alágbára.
“Ningĩ andũ arĩa maatigaire, magĩikũrũka kũrĩ andũ arĩa maarĩ igweta; andũ a Jehova magĩũka kũrĩ niĩ hamwe na andũ arĩa maarĩ hinya.
14 Àwọn kan jáde wá láti Efraimu, àwọn tí gbòǹgbò wọn wà ní Amaleki; Benjamini wà pẹ̀lú àwọn tí ó tẹ̀lé ọ. Láti Makiri ni àwọn aláṣẹ ti sọ̀kalẹ̀ wá, láti Sebuluni ni àwọn ẹni tí ń mú ọ̀pá oyè lọ́wọ́.
Amwe mookire kuuma Efiraimu, arĩa iruka ciao ciarĩ kũu Amaleki; Benjamini aarĩ hamwe na andũ arĩa maakũrũmĩrĩire. Anene a ita cia mbaara nĩmaikũrũkire kuuma Makiru, nakuo Zebuluni gũkiuma arĩa maanyiitaga rũthanju rwa mũnene wa mbũtũ cia ita.
15 Àwọn ọmọ-aládé Isakari wá pẹ̀lú Debora; bí Isakari ti ṣe olóòtítọ́ sí Baraki, wọ́n fi ẹsẹ̀ súré tẹ̀lé wọn lọ sí àfonífojì náà. Ní ipadò Reubeni ni ìgbèrò púpọ̀ wà.
Anene a Isakaru maarĩ hamwe na Debora; Ĩĩ-ni, Isakaru maarĩ na Baraka, mamumĩte thuutha na ihenya o nginya kĩanda-inĩ. Ngʼongo-inĩ cia Rubeni nĩ kwarĩ na ũhoro mũnene wa gwĩcookera.
16 Èéṣe tí ìwọ fi dúró pẹ́ láàrín agbo àgùntàn láti máa gbọ́ fèrè olùṣọ́-àgùntàn? Ní ipadò Reubeni ni ìgbèrò púpọ̀ wà.
Nĩ kĩĩ gĩatũmire mũikare mĩaki-inĩ mũiguage mahiũ makĩhuhĩrwo mĩrũri? Ngʼongo-inĩ cia Rubeni nĩ kwarĩ ũhoro mũnene wa gwĩcookera.
17 Gileadi dúró ní òkè odò Jordani. Èéṣe tí Dani fi dúró nínú ọkọ̀ ojú omi? Aṣeri jókòó ní etí bèbè Òkun, ó sì ń gbé èbúté rẹ̀.
Gileadi aikarire o kũu mũrĩmo wa Rũũĩ rwa Jorodani. Nake Dani-rĩ, nĩ kĩĩ gĩagĩtũmire atiindage marikabu-inĩ? Asheri aikarire o kũu ndwere-inĩ cia iria, agĩikara icukĩro-inĩ ciake cia marikabu.
18 Àwọn ènìyàn Sebuluni fi ẹ̀mí wọn wéwu ikú; bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ènìyàn Naftali ní ibi gíga pápá.
Andũ a Zebuluni nĩmetwarĩrĩire ũgwati-inĩ wa gĩkuũ; o nake Nafitali agĩĩka o ũguo kũu gũtũũgĩru werũ-inĩ.
19 “Àwọn ọba wá, wọ́n sì jà; àwọn ọba Kenaani jà ní Taanaki ní etí odo Megido, ṣùgbọ́n wọn kò sì gba èrè owó.
“Athamaki magĩũka, makĩrũa; athamaki a Kaanani makĩrũĩra kũu Taanaka, gũkuhĩ na maaĩ ma Megido, no matiakuuire betha, o na kana ndaho.
20 Àwọn ìràwọ̀ já láti ojú ọ̀run wá láti inú ipa ọ̀nà wọn ni wọ́n bá Sisera jà.
Kũu igũrũ njata nĩciarũire, o kũu njĩra-inĩ ciacio ikĩrũa mbaara na Sisera.
21 Odò Kiṣoni gbá wọn lọ, odò ìgbàanì, odò Kiṣoni. Máa yan lọ, ìwọ ọkàn mi, nínú agbára!
Rũũĩ rwa Kishoni nĩ rwamathereririe, rũu rũũĩ rwa tene, Rũũĩ rwa Kishoni. Wee ngoro yakwa wĩtware, na ũgĩe na hinya!
22 Nígbà náà ni pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin ki ilẹ̀, nítorí eré sísá, eré sísá àwọn alágbára wọn.
Ningĩ mahũngũ ma mbarathi makĩrumia thĩ, itengʼerete, mbarathi ciake irĩ hinya igathiĩ itengʼerete.
23 ‘Ẹ fi Merosi bú,’ ni angẹli Olúwa wí. ‘Ẹ fi àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ìbú kíkorò, nítorí wọn kò wá sí ìrànlọ́wọ́ Olúwa, láti dojúkọ àwọn alágbára.’
Nake mũraika wa Jehova akiuga atĩrĩ, ‘Merozu ĩrogwatwo nĩ kĩrumi. Arĩa matũũraga kuo marogwatwo nĩ kĩrumi kĩrĩa kĩũru, nĩ ũndũ matiokire gũteithia Jehova, gũteithia Jehova kũrũa na arĩa marĩ hinya.’
24 “Ìbùkún ni fún Jaeli, aya Heberi ará Keni ju àwọn obìnrin lọ, ìbùkún ni fún un ju àwọn obìnrin tí ń gbé nínú àgọ́.
“Jaeli mũtumia wa Heberi ũrĩa Mũkeni, arorathimwo gũkĩra atumia arĩa angĩ, o we mũrathime mũno harĩ atumia arĩa matũũraga hema-inĩ.
25 Ó béèrè omi, ó fún un ní wàrà; ó mú òrí-àmọ́ tọ̀ ọ́ wá nínú àwo iyebíye tí ó yẹ fún àwọn ọlọ́lá.
Sisera aamũhoire maaĩ, nake akĩmũhe iria; akĩmũrehera iria imata na mbakũri ĩngĩnyuĩrwo nĩ andũ arĩa me igweta.
26 Ó na ọwọ́ rẹ̀ mú ìṣó àgọ́, ó fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ mú òòlù awọ gbẹ́nàgbẹ́nà, òòlù náà ni ó sì fi lu Sisera, ó gbá a mọ́ ọn ní orí, ó sì gun, ó sì kàn ẹ̀bátí rẹ̀ mọ́lẹ̀ ṣinṣin.
Aatambũrũkirie guoko gwake akĩoya higĩ ya hema, akĩnyiita nyondo ya bundi na guoko kwa ũrĩo. Akĩringa Sisera, akĩmũhehenja mũtwe, akĩmũtheeca na agĩthethera thikĩrĩrio yake.
27 Ní ẹsẹ̀ rẹ̀ ó wólẹ̀, ó ṣubú; ó dùbúlẹ̀. Ó wólẹ̀ ní ẹsẹ̀ rẹ̀, ó ṣubú níbi tí ó gbé ń wólẹ̀; níbẹ̀ náà ni ó ṣubú kú sí.
Akĩinama magũrũ-inĩ make, akĩgũa; agĩkoma hau. Akĩinama magũrũ-inĩ make, akĩgũa; o hau ainamire, no ho aagũire arĩ mũkuũ.
28 “Ìyá Sisera yọjú láti ojú fèrèsé, ó sì kígbe, ó kígbe ní ojú fèrèsé ọlọ́nà pé, ‘Èéṣe tí kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ fi pẹ́ bẹ́ẹ̀ láti dé? Èéṣe tí ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ fi dúró lẹ́yìn?’
“Nyina wa Sisera agĩcũthĩrĩria na ndirica; akĩanĩrĩra arĩ gatirica-inĩ kau, akiuga atĩrĩ, ‘Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte ngaari yake ya ita ĩikare ũguo ĩtookĩte? inegene rĩa magũrũ ma ngaari cia ita-rĩ, rĩcereirwo kũ?’
29 Àwọn amòye obìnrin rẹ̀ dá a lóhùn; àní òun náà pẹ̀lú ti dá ara rẹ̀ lóhùn pé,
Atumia ake arĩa oogĩ mũno makamũcookagĩria; o nake agecookagĩria na ngoro yake atĩrĩ,
30 ‘Wọn kò ha ń wa kiri, wọn kò ha ti pín ìkógun bi: ọmọbìnrin kan tàbí méjì fún ọkùnrin kan, fún Sisera ìkógun aṣọ aláràbarà, ìkógun aṣọ aláràbarà àti ọlọ́nà, àwọn aṣọ ọlọ́nà iyebíye fún ọrùn mi, gbogbo èyí tí a kó ní ogun?’
‘Githĩ ti gwetha mareetha na makagayana indo cia ndaho: mũirĩtu ũmwe kana eerĩ harĩ o mũndũ, na nguo cia marangi maingĩ itahĩirwo Sisera, nguo cia marangi maingĩ iria ngʼemie, nguo iria ngʼemie mũno cia ngingo yakwa, icio ciothe nĩ cia gũtahwo?’
31 “Bẹ́ẹ̀ ni kí ó jẹ́ kí gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kí ó ṣègbé Olúwa! Ṣùgbọ́n jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ọ ràn bí oòrùn, nígbà tí ó bá yọ nínú agbára rẹ̀.” Ilẹ̀ náà sì sinmi ní ogójì ọdún.
“Nĩ ũndũ ũcio thũ ciaku iroothira, Wee Jehova! No arĩa makwendete-rĩ, marotuĩka ta riũa rĩkĩratha rĩrĩ na hinya warĩo.” Naguo bũrũri ũcio ũkĩgĩa na thayũ ihinda rĩa mĩaka mĩrongo ĩna.

< Judges 5 >