< Judges 4 >
1 Lẹ́yìn ikú Ehudu, àwọn ènìyàn Israẹli sì tún ṣẹ̀, wọ́n ṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa.
И приложиша сынове Израилевы сотворити злое пред Господем: и Аод умре.
2 Nítorí náà Olúwa jẹ́ kí Jabini, ọba àwọn Kenaani, ẹni tí ó jẹ ọba ní Hasori, ṣẹ́gun wọn. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Sisera ẹni tí ń gbé Haroseti-Hagoyimu.
И отдаде их Господь в руку Иавина царя Ханаанска, иже царствова во Асоре. И воевода силы его Сисара, и той живяше во Арисофе языков.
3 Nítorí tí ó ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ ogun irin, ó sì ń pọ́n Israẹli lójú gidigidi fún ogún ọdún, Israẹli ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́.
И возопиша сынове Израилевы ко Господу, яко девять сот колесниц железных бяше ему: и той озлоби Израиля зело лет двадесять.
4 Debora, wòlíì obìnrin, aya Lapidoti ni olórí àti aṣíwájú àwọn ará Israẹli ní àsìkò náà.
И Деввора, жена пророчица, жена Лафидофова, сия судяше Израилю в то время:
5 Òun a máa jókòó ṣe ìdájọ́ ní abẹ́ igi ọ̀pẹ tí a sọ orúkọ rẹ̀ ní ọ̀pẹ Debora láàrín Rama àti Beteli ní ilẹ̀ òkè Efraimu, àwọn ará Israẹli a sì máa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti yanjú èdè-àìyedè tí wọ́n bá ní sí ara wọn, tàbí láti gbọ́ ohùn Olúwa láti ẹnu rẹ̀.
и сия живяше под Фиником Деввора между Рамою и между Вефилем, в горе Ефремли: и восхождаху сынове Израилевы к ней тамо на суд.
6 Ní ọjọ́ kan, ó ránṣẹ́ pe Baraki ọmọ Abinoamu, ẹni tí ń gbé ní Kedeṣi ní ilẹ̀ Naftali, ó sì wí fún un pé, “Olúwa, Ọlọ́run Israẹli pa á ní àṣẹ fún un pé, ‘Kí ó kó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn akọni ọkùnrin jọ láti ẹ̀yà Naftali àti ẹ̀yà Sebuluni bí ẹgbẹ́ ogun, kí o sì síwájú wọn lọ sí òkè Tabori.
И посла Деввора, и призва Варака сына Авинеемля из Кедеса Неффалимова, и рече к нему: не заповеда ли тебе Господь Бог Израилев? И пойдеши в гору Фавор, и поймеши с собою десять тысящ мужей от сынов Неффалимлих и от сынов Завулоних:
7 Èmi yóò sì fa Sisera olórí ogun Jabini, pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun rẹ àti àwọn ogun rẹ, sí odò Kiṣoni èmi yóò sì fi lé ọ lọ́wọ́ ìwọ yóò sì ṣẹ́gun wọn níbẹ̀.’”
и приведу к тебе в водотечь Кисонь Сисару воеводу силы Иавини, и колесницы его, и множество (вой) его, и предам его в руки твоя.
8 Baraki sì dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ tí ìwọ ó bá bá mi lọ, ṣùgbọ́n tí ìwọ kì yóò bá bá mi lọ, èmi kì yóò lọ.”
И рече к ней Варак: аще пойдеши со мною, пойду, и аще не пойдеши со мною, не пойду: яко не вем дне, в оньже благоустроит Господь Ангела со мною.
9 Debora dá a lóhùn pé, “ó dára, èmi yóò bá ọ lọ. Ṣùgbọ́n ọlá ìṣẹ́gun tí o ń lọ yìí kò ní jẹ́ tìrẹ, nítorí Olúwa yóò fi Sisera lé obìnrin lọ́wọ́,” báyìí Debora bá Baraki lọ sí Kedeṣi.
И рече Деввора к нему: идущи пойду с тобою: обаче веждь, яко не будет тебе слава на пути, в оньже ты идеши: понеже в руку женску предаст Господь Сисару. И воста Деввора и пойде с Вараком до Кадиса.
10 Nígbà tí Baraki pe ẹ̀yà Sebuluni àti ẹ̀yà Naftali sí Kedeṣi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá akíkanjú ọkùnrin ogun tẹ̀lé e, Debora pẹ̀lú bá wọn lọ.
И воззва Варак Завулона и Неффалима до Кадиса, и поидоша вслед его десять тысящ мужей, и иде с ним Деввора.
11 Ǹjẹ́ Heberi ọmọ Keni, ti ya ara rẹ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Keni, àní àwọn ọmọ Hobabu, àna Mose, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ títí dé ibi igi óákù Saananimu, tí ó wà ni agbègbè Kedeṣi.
И Хавер Киней отлучися от Кены и от сынов Иовава, ужика Моисеова: и потче кущу свою под дубом Почивающих, иже есть при Кедесе.
12 Nígbà tí a sọ fún Sisera pé Baraki ọmọ Abinoamu ti kó ogun jọ sí òkè Tabori,
И возвестиша Сисаре, яко взыде Варак сын Авинеемль на гору Фавор.
13 Sisera kó gbogbo kẹ̀kẹ́ ogun irin rẹ̀ tí ṣe ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, láti Haroseti tí àwọn orílẹ̀-èdè wá sí odò Kiṣoni.
И созва Сисара вся колесницы своя, девять сот колесниц железных, и вся люди иже с ним, от Арисофа языков в водотечь Кисонь.
14 Debora sì wí fún Baraki pé, “Lọ! Lónìí ni Olúwa fi Sisera lé ọ lọ́wọ́, Olúwa ti lọ síwájú rẹ.” Baraki sì síwájú, àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì tẹ̀lé e lẹ́yìn, wọ́n sì kọjá sí òkè Tabori.
И рече Деввора к Вараку: востани, яко сей день, в оньже предаде Господь Сисару в руку твою, зане Господь изыдет пред тобою. И сниде Варак с горы Фавор, и десять тысящ мужей вслед его.
15 Olúwa sì mú ìdàrúdàpọ̀ wá sí àárín ogun Sisera, Olúwa sì fi ojú idà ṣẹ́gun Sisera àti àwọn oníkẹ̀kẹ́ ogun àti ọmọ-ogun orí ilẹ̀ ní iwájú Baraki. Sisera sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì fi ẹsẹ̀ sálọ.
И сотре Господь Сисару и вся колесницы его и весь полк его острием меча пред Вараком. И сниде Сисара с колесницы своея и побеже ногами своими.
16 Baraki àti àwọn ogun rẹ̀ sì lé àwọn ọ̀tá náà, àwọn ọmọ-ogun orílẹ̀ àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun wọn títí dé Haroseti ti àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo ogun Sisera sì ti ojú idà ṣubú, kò sí ọ̀kan tí ó lè sálà tàbí tí ó wà láààyè.
И Варак гоняй вслед колесниц его и вслед полка, даже до Дубравы языков. И паде весь полк Сисарин острием меча: не остася ни един.
17 Ṣùgbọ́n Sisera ti fi ẹsẹ̀ sálọ sí àgọ́ Jaeli aya Heberi ẹ̀yà Keni: nítorí ìbá dá ọ̀rẹ́ àlàáfíà wà láàrín Jabini ọba Hasori àti ìdílé Heberi ti ẹ̀yà Keni.
И Сисара убеже ногами своими в кущу Иаили, жены Хавера Кинеева: яко мир бяше между Иавином царем Асорским и между домом Хавера Кинеева.
18 Jaeli sì jáde síta láti pàdé Sisera, ó sì wí fún un pé, “Wọlé sínú àgọ́ mi, Olúwa mi, wọlé wá má ṣe bẹ̀rù nítorí pé ààbò ń bẹ fún ọ.” Ó sì yà sínú àgọ́ rẹ̀, ó sì fi aṣọ bò ó.
И изыде Иаиль во сретение Сисаре и рече к нему: уклонися, господине мой, уклонися ко мне, не бойся. И уклонися к ней в кущу: и покры его одеждею своею.
19 Sisera wí pé, “Òrùngbẹ ń gbẹ́ mí, jọ̀wọ́ fún mi ní omi mu.” Ó sì ṣí awọ wàrà kan, ó sì fún un mu ó sì tún daṣọ bò ó padà.
И рече Сисара к ней: напой мя мало воды, яко возжаждах. И отреши мех млечный, и напои его, и покры его.
20 Sisera sọ fún Jaeli pé, “Kí ó dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, àti pé bí ẹnikẹ́ni bá béèrè bóyá òun wà níbẹ̀ kí ó sọ pé, ‘Kò sí ẹnìkankan ní ibẹ̀.’”
И рече к ней Сисара: стани во дверех кущи, и будет аще кто приидет к тебе, и вопросит тя, и речет: есть ли зде муж? И речеши: несть.
21 Ṣùgbọ́n Jaeli ìyàwó Heberi mú ìṣó àgọ́ tí ó mú àti òòlù ní ọwọ́ rẹ̀, ó sì yọ́ wọ inú ibi tí ó sùn, nígbà tí ó ti sùn fọnfọn, nígbà náà ni ó kan ìṣó náà mọ́ òkè ìpéǹpéjú rẹ̀, ó sì wọlé ṣinṣin, ó sì kú.
И взя Иаиль, жена Хаверова, кол кущный, и взя млат в руку свою, и вниде к нему тихо, и водрузи кол во скрании его, и пронзе до земли: и сей утруждся спаше, и издше.
22 Nígbà tí Baraki dé bí ó ti ń lépa Sisera, Jaeli láti pàdé rẹ̀, wá, èmi yóò fi ẹni tí ìwọ ń wá hàn ọ́, báyìí ni ó tẹ̀lé e wọ inú àgọ́ lọ, kíyèsi Sisera dùbúlẹ̀ síbẹ̀ pẹ̀lú ìṣó àgọ́ ní agbárí rẹ̀ tí a ti kàn mọ́lẹ̀ ṣinṣin tí ó sì ti kú.
И се, Варак гоняй Сисару. И изыде Иаиль во сретение ему и рече ему: прииди, и покажу тебе мужа, егоже ты ищеши. И вниде к ней, и се, Сисара лежаше мертв, и кол во скрании его.
23 Ní ọjọ́ náà ni Ọlọ́run ṣẹ́gun Jabini ọba àwọn ará Kenaani ní iwájú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
И покори Господь Бог в той день Иавина царя Ханааня пред сыны Израилевыми:
24 Ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli sì le, ó sì ń lágbára síwájú àti síwájú sí i lára Jabini ọba Kenaani, títí wọ́n fi run òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
и хождаше рука сынов Израилевых ходящи, и ожесточися на Иавина царя Ханаанска, дондеже истребиша его.