< Judges 4 >

1 Lẹ́yìn ikú Ehudu, àwọn ènìyàn Israẹli sì tún ṣẹ̀, wọ́n ṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa.
A po śmierci Ehuda synowie Izraela znowu czynili to, co złe w oczach PANA.
2 Nítorí náà Olúwa jẹ́ kí Jabini, ọba àwọn Kenaani, ẹni tí ó jẹ ọba ní Hasori, ṣẹ́gun wọn. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Sisera ẹni tí ń gbé Haroseti-Hagoyimu.
I PAN wydał ich w ręce Jabina, króla Kanaanu, który królował w Chasor. Dowódcą jego wojska był Sisera, który mieszkał w pogańskim Charoszet.
3 Nítorí tí ó ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ ogun irin, ó sì ń pọ́n Israẹli lójú gidigidi fún ogún ọdún, Israẹli ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́.
I synowie Izraela wołali do PANA. Miał tamten bowiem dziewięćset żelaznych rydwanów i mocno uciskał synów Izraela przez dwadzieścia lat.
4 Debora, wòlíì obìnrin, aya Lapidoti ni olórí àti aṣíwájú àwọn ará Israẹli ní àsìkò náà.
W tym czasie sądziła Izraela prorokini Debora, żona Lappidota.
5 Òun a máa jókòó ṣe ìdájọ́ ní abẹ́ igi ọ̀pẹ tí a sọ orúkọ rẹ̀ ní ọ̀pẹ Debora láàrín Rama àti Beteli ní ilẹ̀ òkè Efraimu, àwọn ará Israẹli a sì máa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti yanjú èdè-àìyedè tí wọ́n bá ní sí ara wọn, tàbí láti gbọ́ ohùn Olúwa láti ẹnu rẹ̀.
I mieszkała pod palmą Debory, między Rama a Betel, na górze Efraim, a synowie Izraela przychodzili do niej na sąd.
6 Ní ọjọ́ kan, ó ránṣẹ́ pe Baraki ọmọ Abinoamu, ẹni tí ń gbé ní Kedeṣi ní ilẹ̀ Naftali, ó sì wí fún un pé, “Olúwa, Ọlọ́run Israẹli pa á ní àṣẹ fún un pé, ‘Kí ó kó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn akọni ọkùnrin jọ láti ẹ̀yà Naftali àti ẹ̀yà Sebuluni bí ẹgbẹ́ ogun, kí o sì síwájú wọn lọ sí òkè Tabori.
Posłała ona i wezwała Baraka, syna Abinoama, z Kedesz-Neftali, i powiedziała do niego: Czy PAN, Bóg Izraela nie rozkazał: Idź, udaj się na górę Tabor i weź ze sobą dziesięć tysięcy mężczyzn z synów Neftalego i z synów Zebulona?
7 Èmi yóò sì fa Sisera olórí ogun Jabini, pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun rẹ àti àwọn ogun rẹ, sí odò Kiṣoni èmi yóò sì fi lé ọ lọ́wọ́ ìwọ yóò sì ṣẹ́gun wọn níbẹ̀.’”
I przyprowadzę do ciebie, do rzeki Kiszon, Siserę, dowódcę wojska Jabina, jego rydwany i jego liczne oddziały, i wydam go w twoje ręce.
8 Baraki sì dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ tí ìwọ ó bá bá mi lọ, ṣùgbọ́n tí ìwọ kì yóò bá bá mi lọ, èmi kì yóò lọ.”
Barak zaś powiedział do niej: Jeśli pójdziesz ze mną, pójdę, lecz jeśli nie pójdziesz ze mną, nie pójdę.
9 Debora dá a lóhùn pé, “ó dára, èmi yóò bá ọ lọ. Ṣùgbọ́n ọlá ìṣẹ́gun tí o ń lọ yìí kò ní jẹ́ tìrẹ, nítorí Olúwa yóò fi Sisera lé obìnrin lọ́wọ́,” báyìí Debora bá Baraki lọ sí Kedeṣi.
Ona odpowiedziała: Na pewno pójdę z tobą. Nie tobie jednak przypadnie chwała z tej wyprawy, na którą wyruszysz. PAN bowiem wyda Siserę w ręce kobiety. I Debora wstała, i udała się z Barakiem do Kedesz.
10 Nígbà tí Baraki pe ẹ̀yà Sebuluni àti ẹ̀yà Naftali sí Kedeṣi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá akíkanjú ọkùnrin ogun tẹ̀lé e, Debora pẹ̀lú bá wọn lọ.
Wtedy Barak wezwał Zebulona i Neftalego do Kedesz i wyruszył, a za nim dziesięć tysięcy mężczyzn. Szła z nim także Debora.
11 Ǹjẹ́ Heberi ọmọ Keni, ti ya ara rẹ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Keni, àní àwọn ọmọ Hobabu, àna Mose, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ títí dé ibi igi óákù Saananimu, tí ó wà ni agbègbè Kedeṣi.
A Cheber Kenita odłączył się od Kenitów, od synów Chobaba, teścia Mojżesza, i rozbił swój namiot aż do równin w Saananim, które jest przy Kedesz.
12 Nígbà tí a sọ fún Sisera pé Baraki ọmọ Abinoamu ti kó ogun jọ sí òkè Tabori,
I doniesiono Siserze, że Barak, syn Abinoama, wyruszył na górę Tabor.
13 Sisera kó gbogbo kẹ̀kẹ́ ogun irin rẹ̀ tí ṣe ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, láti Haroseti tí àwọn orílẹ̀-èdè wá sí odò Kiṣoni.
Sisera zebrał więc wszystkie swoje rydwany, [to jest] dziewięćset żelaznych rydwanów, oraz cały lud, który z nim był, od pogańskiego Charoszet aż do rzeki Kiszon.
14 Debora sì wí fún Baraki pé, “Lọ! Lónìí ni Olúwa fi Sisera lé ọ lọ́wọ́, Olúwa ti lọ síwájú rẹ.” Baraki sì síwájú, àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì tẹ̀lé e lẹ́yìn, wọ́n sì kọjá sí òkè Tabori.
Wtedy Debora powiedziała do Baraka: Wstań, bo to jest dzień, w którym PAN wyda Siserę w twoje ręce. Czyż PAN nie idzie przed tobą? Barak zszedł więc z góry Tabor, a dziesięć tysięcy mężczyzn [zeszło] za nim.
15 Olúwa sì mú ìdàrúdàpọ̀ wá sí àárín ogun Sisera, Olúwa sì fi ojú idà ṣẹ́gun Sisera àti àwọn oníkẹ̀kẹ́ ogun àti ọmọ-ogun orí ilẹ̀ ní iwájú Baraki. Sisera sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì fi ẹsẹ̀ sálọ.
I PAN rozgromił Siserę, wszystkie wozy oraz całe jego wojsko ostrzem miecza przed Barakiem, tak że Sisera zeskoczył z rydwanu i uciekał pieszo.
16 Baraki àti àwọn ogun rẹ̀ sì lé àwọn ọ̀tá náà, àwọn ọmọ-ogun orílẹ̀ àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun wọn títí dé Haroseti ti àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo ogun Sisera sì ti ojú idà ṣubú, kò sí ọ̀kan tí ó lè sálà tàbí tí ó wà láààyè.
Lecz Barak ścigał rydwany i wojsko aż do pogańskiego Charoszet. I poległo od ostrza miecza całe wojsko Sisery; nie pozostał ani jeden [z jego wojowników].
17 Ṣùgbọ́n Sisera ti fi ẹsẹ̀ sálọ sí àgọ́ Jaeli aya Heberi ẹ̀yà Keni: nítorí ìbá dá ọ̀rẹ́ àlàáfíà wà láàrín Jabini ọba Hasori àti ìdílé Heberi ti ẹ̀yà Keni.
A Sisera uciekł pieszo do namiotu Jael, żony Chebera Kenity, ponieważ panował pokój między Jabinem, królem Chasoru, a domem Chebera Kenity.
18 Jaeli sì jáde síta láti pàdé Sisera, ó sì wí fún un pé, “Wọlé sínú àgọ́ mi, Olúwa mi, wọlé wá má ṣe bẹ̀rù nítorí pé ààbò ń bẹ fún ọ.” Ó sì yà sínú àgọ́ rẹ̀, ó sì fi aṣọ bò ó.
A Jael wyszła naprzeciw Siserze i powiedziała do niego: Wejdź, mój panie, wejdź do mnie, nie bój się. Wszedł więc do niej do namiotu, a [ona] przykryła go kocem.
19 Sisera wí pé, “Òrùngbẹ ń gbẹ́ mí, jọ̀wọ́ fún mi ní omi mu.” Ó sì ṣí awọ wàrà kan, ó sì fún un mu ó sì tún daṣọ bò ó padà.
Wtedy powiedział do niej: Daj mi, proszę, napić się trochę wody, bo jestem spragniony. A ona otworzyła bukłak z mlekiem, dała mu się napić i przykryła go.
20 Sisera sọ fún Jaeli pé, “Kí ó dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, àti pé bí ẹnikẹ́ni bá béèrè bóyá òun wà níbẹ̀ kí ó sọ pé, ‘Kò sí ẹnìkankan ní ibẹ̀.’”
I powiedział do niej: Stój przy wejściu do namiotu, a jeśli ktoś przyjdzie i zapyta cię: Czy jest tu ktoś? – odpowiesz: Nie ma.
21 Ṣùgbọ́n Jaeli ìyàwó Heberi mú ìṣó àgọ́ tí ó mú àti òòlù ní ọwọ́ rẹ̀, ó sì yọ́ wọ inú ibi tí ó sùn, nígbà tí ó ti sùn fọnfọn, nígbà náà ni ó kan ìṣó náà mọ́ òkè ìpéǹpéjú rẹ̀, ó sì wọlé ṣinṣin, ó sì kú.
Potem Jael, żona Chebera, wzięła kołek od namiotu, chwyciła do ręki młot, podeszła do niego po cichu i wbiła kołek w jego skroń, tak że ten utkwił w ziemi, bo on [twardo] spał, gdyż był zmęczony. I w ten sposób umarł.
22 Nígbà tí Baraki dé bí ó ti ń lépa Sisera, Jaeli láti pàdé rẹ̀, wá, èmi yóò fi ẹni tí ìwọ ń wá hàn ọ́, báyìí ni ó tẹ̀lé e wọ inú àgọ́ lọ, kíyèsi Sisera dùbúlẹ̀ síbẹ̀ pẹ̀lú ìṣó àgọ́ ní agbárí rẹ̀ tí a ti kàn mọ́lẹ̀ ṣinṣin tí ó sì ti kú.
Tymczasem Barak ścigał Siserę i Jael wyszła mu naprzeciw, i powiedziała do niego: Chodź, a pokażę ci człowieka, którego szukasz. I wstąpił do niej, a oto Sisera leżał martwy z kołkiem w skroni.
23 Ní ọjọ́ náà ni Ọlọ́run ṣẹ́gun Jabini ọba àwọn ará Kenaani ní iwájú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Tak Bóg tego dnia poniżył przed synami Izraela Jabina, króla Kanaanu.
24 Ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli sì le, ó sì ń lágbára síwájú àti síwájú sí i lára Jabini ọba Kenaani, títí wọ́n fi run òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
I ręka synów Izraela coraz bardziej nacierała na Jabina, króla Kanaanu, i uciskała go, aż zgładzili Jabina, króla Kanaanu.

< Judges 4 >