< Judges 4 >

1 Lẹ́yìn ikú Ehudu, àwọn ènìyàn Israẹli sì tún ṣẹ̀, wọ́n ṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa.
De az Izráel fiai azután is gonoszul cselekedének az Úrnak szemei előtt, mikor Ehud meghalt.
2 Nítorí náà Olúwa jẹ́ kí Jabini, ọba àwọn Kenaani, ẹni tí ó jẹ ọba ní Hasori, ṣẹ́gun wọn. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Sisera ẹni tí ń gbé Haroseti-Hagoyimu.
Azért adá őket az Úr Jábinnak, a Kanaán királyának kezébe, a ki Hásorban uralkodott; seregének vezére pedig Sisera volt. Ez a pogányok városában, Harósethben lakott.
3 Nítorí tí ó ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ ogun irin, ó sì ń pọ́n Israẹli lójú gidigidi fún ogún ọdún, Israẹli ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́.
És kiáltának az Izráel fiai az Úrhoz, mert kilenczszáz vas-szekere volt, és húsz esztendeig zsarnokoskodott az Izráel fiai felett erőszakkal.
4 Debora, wòlíì obìnrin, aya Lapidoti ni olórí àti aṣíwájú àwọn ará Israẹli ní àsìkò náà.
Ebben az időben Debora, a prófétanő, a Lappidoth felesége volt biró Izráelben.
5 Òun a máa jókòó ṣe ìdájọ́ ní abẹ́ igi ọ̀pẹ tí a sọ orúkọ rẹ̀ ní ọ̀pẹ Debora láàrín Rama àti Beteli ní ilẹ̀ òkè Efraimu, àwọn ará Israẹli a sì máa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti yanjú èdè-àìyedè tí wọ́n bá ní sí ara wọn, tàbí láti gbọ́ ohùn Olúwa láti ẹnu rẹ̀.
És ő a Debora-pálmája alatt lakott Ráma és Béthel között, az Efraim hegyén, és ide jöttek fel hozzá az Izráel fiai törvényre.
6 Ní ọjọ́ kan, ó ránṣẹ́ pe Baraki ọmọ Abinoamu, ẹni tí ń gbé ní Kedeṣi ní ilẹ̀ Naftali, ó sì wí fún un pé, “Olúwa, Ọlọ́run Israẹli pa á ní àṣẹ fún un pé, ‘Kí ó kó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn akọni ọkùnrin jọ láti ẹ̀yà Naftali àti ẹ̀yà Sebuluni bí ẹgbẹ́ ogun, kí o sì síwájú wọn lọ sí òkè Tabori.
És elkülde és hivatá Bárákot, az Abinoám fiát, Kedes-Nafthaliból, és monda néki: Avagy nem parancsolta-é meg az Úr, Izráelnek Istene: Menj és vonulj fel a Thábor hegyére, és végy magadhoz tízezer embert a Nafthali és a Zebulon fiai közül?
7 Èmi yóò sì fa Sisera olórí ogun Jabini, pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun rẹ àti àwọn ogun rẹ, sí odò Kiṣoni èmi yóò sì fi lé ọ lọ́wọ́ ìwọ yóò sì ṣẹ́gun wọn níbẹ̀.’”
És te ellened kihozom a Kison patakjához Siserát, Jábin hadvezérét, az ő szekereit és seregét, és kezedbe adom őt.
8 Baraki sì dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ tí ìwọ ó bá bá mi lọ, ṣùgbọ́n tí ìwọ kì yóò bá bá mi lọ, èmi kì yóò lọ.”
És monda néki Bárák: Ha velem jösz, elmegyek; de ha nem jösz el velem, én sem megyek.
9 Debora dá a lóhùn pé, “ó dára, èmi yóò bá ọ lọ. Ṣùgbọ́n ọlá ìṣẹ́gun tí o ń lọ yìí kò ní jẹ́ tìrẹ, nítorí Olúwa yóò fi Sisera lé obìnrin lọ́wọ́,” báyìí Debora bá Baraki lọ sí Kedeṣi.
Ki felele: Elmenvén elmegyek te veled, csakhogy nem a tied lesz a dicsőség az útban, a melyre mégy, mert asszony kezébe adja az Úr Siserát. És felkele Debora, és elméne Bárákkal Kedes felé.
10 Nígbà tí Baraki pe ẹ̀yà Sebuluni àti ẹ̀yà Naftali sí Kedeṣi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá akíkanjú ọkùnrin ogun tẹ̀lé e, Debora pẹ̀lú bá wọn lọ.
Összegyűjté annakokáért Bárák Zebulont és Nafthalit Kedesbe, és elvive magával tízezer embert, és elméne vele Debora is.
11 Ǹjẹ́ Heberi ọmọ Keni, ti ya ara rẹ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Keni, àní àwọn ọmọ Hobabu, àna Mose, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ títí dé ibi igi óákù Saananimu, tí ó wà ni agbègbè Kedeṣi.
A Keneus Héber pedig elvált a Keneusoktól, Hobábnak, a Mózes ipának fiaitól, és sátorát a Saanaim tölgyesénél vonta fel, mely Kedes mellett van.
12 Nígbà tí a sọ fún Sisera pé Baraki ọmọ Abinoamu ti kó ogun jọ sí òkè Tabori,
Hírül vivék pedig Siserának, hogy Bárák, az Abinoám fia felvonult a Thábor hegyére.
13 Sisera kó gbogbo kẹ̀kẹ́ ogun irin rẹ̀ tí ṣe ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, láti Haroseti tí àwọn orílẹ̀-èdè wá sí odò Kiṣoni.
Egybegyűjté azért Sisera minden szekereit, a kilenczszáz vas-szekeret, és egész népét, mely vele volt, a pogányok városából, Harósethből, a Kison patakjához.
14 Debora sì wí fún Baraki pé, “Lọ! Lónìí ni Olúwa fi Sisera lé ọ lọ́wọ́, Olúwa ti lọ síwájú rẹ.” Baraki sì síwájú, àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì tẹ̀lé e lẹ́yìn, wọ́n sì kọjá sí òkè Tabori.
És monda Debora Báráknak: Kelj fel, mert ez a nap az, a melyen kezedbe adja az Úr Siserát! hisz maga az Úr vezet téged! És alájöve Bárák a Thábor hegyéről, és a tízezer ember ő utána.
15 Olúwa sì mú ìdàrúdàpọ̀ wá sí àárín ogun Sisera, Olúwa sì fi ojú idà ṣẹ́gun Sisera àti àwọn oníkẹ̀kẹ́ ogun àti ọmọ-ogun orí ilẹ̀ ní iwájú Baraki. Sisera sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì fi ẹsẹ̀ sálọ.
És megrettenté az Úr Siserát minden szekereivel és egész táborával fegyvernek élivel Bárák előtt, anynyira, hogy Sisera leugrott szekeréről, és gyalog futott.
16 Baraki àti àwọn ogun rẹ̀ sì lé àwọn ọ̀tá náà, àwọn ọmọ-ogun orílẹ̀ àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun wọn títí dé Haroseti ti àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo ogun Sisera sì ti ojú idà ṣubú, kò sí ọ̀kan tí ó lè sálà tàbí tí ó wà láààyè.
Bárák pedig a szekereket és a tábort egész Harósethig, a pogányok városáig űzé, és Siserának egész tábora elhulla fegyvernek éle miatt, még csak egyetlen egy sem maradt meg.
17 Ṣùgbọ́n Sisera ti fi ẹsẹ̀ sálọ sí àgọ́ Jaeli aya Heberi ẹ̀yà Keni: nítorí ìbá dá ọ̀rẹ́ àlàáfíà wà láàrín Jabini ọba Hasori àti ìdílé Heberi ti ẹ̀yà Keni.
Sisera pedig gyalog futott Jáhelnek, a Keneus Héber feleségének sátoráig, mert béke volt Jábin között, Hásor királya között, és a Keneus Héber háznépe között.
18 Jaeli sì jáde síta láti pàdé Sisera, ó sì wí fún un pé, “Wọlé sínú àgọ́ mi, Olúwa mi, wọlé wá má ṣe bẹ̀rù nítorí pé ààbò ń bẹ fún ọ.” Ó sì yà sínú àgọ́ rẹ̀, ó sì fi aṣọ bò ó.
És kiméne Jáhel Sisera elé, és monda néki: Jőjj be Uram, jőjj be hozzám, ne félj! És betére ő hozzá a sátorba, és betakará őt lasnakkal.
19 Sisera wí pé, “Òrùngbẹ ń gbẹ́ mí, jọ̀wọ́ fún mi ní omi mu.” Ó sì ṣí awọ wàrà kan, ó sì fún un mu ó sì tún daṣọ bò ó padà.
Az pedig monda néki: Adj kérlek innom egy kis vizet, mert szomjúhozom. És megnyita ez egy tejes tömlőt, és ada néki inni, és betakará őt.
20 Sisera sọ fún Jaeli pé, “Kí ó dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, àti pé bí ẹnikẹ́ni bá béèrè bóyá òun wà níbẹ̀ kí ó sọ pé, ‘Kò sí ẹnìkankan ní ibẹ̀.’”
És az annakfelette monda néki: Állj a sátor ajtajába, és ha valaki jőne és kérdezne, és ezt mondaná: Van-é itt valaki? mondjad: Nincsen!
21 Ṣùgbọ́n Jaeli ìyàwó Heberi mú ìṣó àgọ́ tí ó mú àti òòlù ní ọwọ́ rẹ̀, ó sì yọ́ wọ inú ibi tí ó sùn, nígbà tí ó ti sùn fọnfọn, nígbà náà ni ó kan ìṣó náà mọ́ òkè ìpéǹpéjú rẹ̀, ó sì wọlé ṣinṣin, ó sì kú.
Ekkor Jáhel, a Héber felesége vevé a sátorszöget, és pőrölyt vőn kezébe, és beméne ő hozzá halkan, és beveré a szöget halántékába, úgy hogy beszegeződék a földbe. Amaz pedig nagy fáradtság miatt mélyen aludt vala, és így meghala.
22 Nígbà tí Baraki dé bí ó ti ń lépa Sisera, Jaeli láti pàdé rẹ̀, wá, èmi yóò fi ẹni tí ìwọ ń wá hàn ọ́, báyìí ni ó tẹ̀lé e wọ inú àgọ́ lọ, kíyèsi Sisera dùbúlẹ̀ síbẹ̀ pẹ̀lú ìṣó àgọ́ ní agbárí rẹ̀ tí a ti kàn mọ́lẹ̀ ṣinṣin tí ó sì ti kú.
És ímé, a mint Bárák űzve keresné Siserát, Jáhel kiméne elébe, és monda néki: Jöszte és megmutatom néked az embert, a kit keressz. És beméne ő hozzá, és ímé Sisera ott feküdt halva, és a szög halántékában.
23 Ní ọjọ́ náà ni Ọlọ́run ṣẹ́gun Jabini ọba àwọn ará Kenaani ní iwájú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Így alázá meg Isten azon a napon Jábint, a Kanaán királyát az Izráel fiai előtt.
24 Ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli sì le, ó sì ń lágbára síwájú àti síwájú sí i lára Jabini ọba Kenaani, títí wọ́n fi run òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
Az Izráel fiainak keze pedig mind jobban ránehezedék Jábinra, a Kanaán királyára, mígnem kiirták Jábint, a Kanaán királyát.

< Judges 4 >