< Judges 4 >

1 Lẹ́yìn ikú Ehudu, àwọn ènìyàn Israẹli sì tún ṣẹ̀, wọ́n ṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa.
Thuutha wa Ehudu gũkua-rĩ, andũ a Isiraeli o rĩngĩ magĩĩka maũndũ mooru maitho-inĩ ma Jehova.
2 Nítorí náà Olúwa jẹ́ kí Jabini, ọba àwọn Kenaani, ẹni tí ó jẹ ọba ní Hasori, ṣẹ́gun wọn. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Sisera ẹni tí ń gbé Haroseti-Hagoyimu.
Nĩ ũndũ ũcio Jehova akĩmarekereria moko-inĩ ma Jabini, mũthamaki wa bũrũri wa Kaanani ũrĩa waathanaga kũu Hazoru. Nake mũnene wa mbũtũ ciake cia mbaara eetagwo Sisera, ũrĩa watũũraga kũu Haroshethu-Hagoyimu.
3 Nítorí tí ó ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ ogun irin, ó sì ń pọ́n Israẹli lójú gidigidi fún ogún ọdún, Israẹli ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́.
Jabini aarĩ na ngaari cia ita cia igera magana kenda, na nĩahinyĩrĩirie andũ a Isiraeli atarĩ na tha ihinda rĩa mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ, nao andũ a Isiraeli magĩkaĩra Jehova amateithie.
4 Debora, wòlíì obìnrin, aya Lapidoti ni olórí àti aṣíwájú àwọn ará Israẹli ní àsìkò náà.
Na rĩrĩ, Debora, mũnabii mũndũ-wa-nja, mũtumia wa Lapidothu, nĩwe watongoragia Isiraeli hĩndĩ ĩyo.
5 Òun a máa jókòó ṣe ìdájọ́ ní abẹ́ igi ọ̀pẹ tí a sọ orúkọ rẹ̀ ní ọ̀pẹ Debora láàrín Rama àti Beteli ní ilẹ̀ òkè Efraimu, àwọn ará Israẹli a sì máa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti yanjú èdè-àìyedè tí wọ́n bá ní sí ara wọn, tàbí láti gbọ́ ohùn Olúwa láti ẹnu rẹ̀.
Nake aarĩ na handũ ha gũciirĩra rungu rwa Mũkĩndũ wa Debora, gatagatĩ ka Rama na Betheli kũu bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma wa Efiraimu, nao andũ a Isiraeli maathiiaga harĩ we nĩgeetha amatuithanie maciira.
6 Ní ọjọ́ kan, ó ránṣẹ́ pe Baraki ọmọ Abinoamu, ẹni tí ń gbé ní Kedeṣi ní ilẹ̀ Naftali, ó sì wí fún un pé, “Olúwa, Ọlọ́run Israẹli pa á ní àṣẹ fún un pé, ‘Kí ó kó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn akọni ọkùnrin jọ láti ẹ̀yà Naftali àti ẹ̀yà Sebuluni bí ẹgbẹ́ ogun, kí o sì síwájú wọn lọ sí òkè Tabori.
Debora agĩtũmanĩra Baraka mũrũ wa Abinoamu kuuma Kedeshi ya Nafitali, akĩmwĩra atĩrĩ, “Jehova Ngai wa Isiraeli nĩaragwatha agakwĩra atĩrĩ, ‘Thiĩ, woe andũ 10,000 a kuuma Nafitali na Zebuluni, na ũmatongorie nginya Kĩrĩma-inĩ kĩa Taboru.
7 Èmi yóò sì fa Sisera olórí ogun Jabini, pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun rẹ àti àwọn ogun rẹ, sí odò Kiṣoni èmi yóò sì fi lé ọ lọ́wọ́ ìwọ yóò sì ṣẹ́gun wọn níbẹ̀.’”
Niĩ nĩngũguucĩrĩria Sisera, mũnene wa mbũtũ cia ita cia Jabini, hamwe na ngaari ciake cia ita na thigari ciake nginya rũũĩ-inĩ rwa Kishoni, ndĩmũneane moko-inĩ maku.’”
8 Baraki sì dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ tí ìwọ ó bá bá mi lọ, ṣùgbọ́n tí ìwọ kì yóò bá bá mi lọ, èmi kì yóò lọ.”
Nake Baraka akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩngũthiĩ aakorwo nĩũgũtwarana hamwe na niĩ; no aakorwo ndũgũtwarana hamwe na niĩ-rĩ, o na niĩ ndigũthiĩ.”
9 Debora dá a lóhùn pé, “ó dára, èmi yóò bá ọ lọ. Ṣùgbọ́n ọlá ìṣẹ́gun tí o ń lọ yìí kò ní jẹ́ tìrẹ, nítorí Olúwa yóò fi Sisera lé obìnrin lọ́wọ́,” báyìí Debora bá Baraki lọ sí Kedeṣi.
Nake Debora akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩ wega, nĩngũtwarana nawe. No rĩrĩ, nĩ ũndũ wa ũrĩa ũroya ũhoro ũyũ-rĩ, gĩtĩĩo gĩtigatuĩka gĩaku, nĩgũkorwo Jehova nĩekũneana Sisera moko-inĩ ma mũndũ-wa-nja.” Nĩ ũndũ ũcio Debora agĩtwarana na Baraka nginya Kadeshi,
10 Nígbà tí Baraki pe ẹ̀yà Sebuluni àti ẹ̀yà Naftali sí Kedeṣi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá akíkanjú ọkùnrin ogun tẹ̀lé e, Debora pẹ̀lú bá wọn lọ.
na kũu Baraka agĩĩta andũ a Zebuluni na a Nafitali. Andũ 10,000 makĩmũrũmĩrĩra, o na Debora agĩthiĩ hamwe nake.
11 Ǹjẹ́ Heberi ọmọ Keni, ti ya ara rẹ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Keni, àní àwọn ọmọ Hobabu, àna Mose, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ títí dé ibi igi óákù Saananimu, tí ó wà ni agbègbè Kedeṣi.
Na rĩrĩ, Heberi ũrĩa Mũkeni nĩeyamũrĩte agatigana na Akeni arĩa angĩ a rũciaro rwa Hobabu, mũthoni-we wa Musa, na akaamba hema yake mũtĩ-inĩ ũrĩa mũnene kũu Zaananimu gũkuhĩ na Kadeshi.
12 Nígbà tí a sọ fún Sisera pé Baraki ọmọ Abinoamu ti kó ogun jọ sí òkè Tabori,
Nao andũ makĩhe Sisera ũhoro, atĩ Baraka mũrũ wa Abinoamu nĩambatĩte agakinya Kĩrĩma gĩa Taboru.
13 Sisera kó gbogbo kẹ̀kẹ́ ogun irin rẹ̀ tí ṣe ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, láti Haroseti tí àwọn orílẹ̀-èdè wá sí odò Kiṣoni.
Sisera agĩcookanĩrĩria ngaari ciake cia ita cia igera magana kenda, hamwe na andũ othe arĩa maarĩ hamwe nake, kuuma Haroshethu-Hagoyimu nginya Rũũĩ rwa Kishoni.
14 Debora sì wí fún Baraki pé, “Lọ! Lónìí ni Olúwa fi Sisera lé ọ lọ́wọ́, Olúwa ti lọ síwájú rẹ.” Baraki sì síwájú, àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì tẹ̀lé e lẹ́yìn, wọ́n sì kọjá sí òkè Tabori.
Nake Debora akĩĩra Baraka atĩrĩ, “Thiĩ! Ũyũ nĩguo mũthenya ũrĩa Jehova aneanĩte Sisera moko-inĩ maku. Githĩ Jehova tiwe ũthiĩte arĩ mbere yaku?” Nĩ ũndũ ũcio Baraka agĩikũrũka oimĩte Kĩrĩma-inĩ gĩa Taboru, arũmĩrĩirwo nĩ andũ 10,000.
15 Olúwa sì mú ìdàrúdàpọ̀ wá sí àárín ogun Sisera, Olúwa sì fi ojú idà ṣẹ́gun Sisera àti àwọn oníkẹ̀kẹ́ ogun àti ọmọ-ogun orí ilẹ̀ ní iwájú Baraki. Sisera sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì fi ẹsẹ̀ sálọ.
Rĩrĩa Baraka aamakuhĩrĩirie, Jehova akĩingatithia Sisera hamwe na ngaari ciake cia ita ciothe, na mbũtũ yake yothe, akĩmahũũra na rũhiũ rwa njora, nake Sisera agĩtiganĩria ngaari yake ya ita, akĩũra na magũrũ.
16 Baraki àti àwọn ogun rẹ̀ sì lé àwọn ọ̀tá náà, àwọn ọmọ-ogun orílẹ̀ àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun wọn títí dé Haroseti ti àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo ogun Sisera sì ti ojú idà ṣubú, kò sí ọ̀kan tí ó lè sálà tàbí tí ó wà láààyè.
No Baraka akĩingatithia ngaari icio cia ita o hamwe na mbũtũ cia ita nginya Haroshethu-Hagoyimu. Nacio thigari ciothe cia Sisera ikĩũragwo na rũhiũ rwa njora; na gũtirĩ mũndũ o na ũmwe watigarire.
17 Ṣùgbọ́n Sisera ti fi ẹsẹ̀ sálọ sí àgọ́ Jaeli aya Heberi ẹ̀yà Keni: nítorí ìbá dá ọ̀rẹ́ àlàáfíà wà láàrín Jabini ọba Hasori àti ìdílé Heberi ti ẹ̀yà Keni.
No rĩrĩ, Sisera agĩĩthara na magũrũ, akĩũrĩra hema-inĩ ya Jaeli, mũtumia wa Heberi ũrĩa Mũkeni, nĩ ũndũ kwarĩ na ũrata gatagatĩ-inĩ ka Jabini mũthamaki wa Hazoru na mbarĩ ya Heberi ũcio Mũkeni.
18 Jaeli sì jáde síta láti pàdé Sisera, ó sì wí fún un pé, “Wọlé sínú àgọ́ mi, Olúwa mi, wọlé wá má ṣe bẹ̀rù nítorí pé ààbò ń bẹ fún ọ.” Ó sì yà sínú àgọ́ rẹ̀, ó sì fi aṣọ bò ó.
Jaeli akiumagara agatũnge Sisera, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ũka, mwathi wakwa, toonya thĩinĩ. Ndũgetigĩre.” Nĩ ũndũ ũcio agĩtoonya hema thĩinĩ nake Jaeli akĩmũhumbĩra.
19 Sisera wí pé, “Òrùngbẹ ń gbẹ́ mí, jọ̀wọ́ fún mi ní omi mu.” Ó sì ṣí awọ wàrà kan, ó sì fún un mu ó sì tún daṣọ bò ó padà.
Sisera akiuga atĩrĩ, “Ndĩ mũnyootu, ndagũthaitha he maaĩ nyue.” Jaeli agĩkunũra mbũthũ ya iria, akĩmũhe anyue, agĩcooka akĩmũhumbĩra.
20 Sisera sọ fún Jaeli pé, “Kí ó dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, àti pé bí ẹnikẹ́ni bá béèrè bóyá òun wà níbẹ̀ kí ó sọ pé, ‘Kò sí ẹnìkankan ní ibẹ̀.’”
Sisera akĩmwĩra atĩrĩ, “Rũgama mũrango-inĩ wa hema, na hangĩũka mũndũ akũũrie atĩrĩ, ‘Kũrĩ mũndũ ũrĩ gũkũ?’ uuge atĩrĩ, ‘Aca.’”
21 Ṣùgbọ́n Jaeli ìyàwó Heberi mú ìṣó àgọ́ tí ó mú àti òòlù ní ọwọ́ rẹ̀, ó sì yọ́ wọ inú ibi tí ó sùn, nígbà tí ó ti sùn fọnfọn, nígbà náà ni ó kan ìṣó náà mọ́ òkè ìpéǹpéjú rẹ̀, ó sì wọlé ṣinṣin, ó sì kú.
No Jaeli ũcio mũtumia wa Heberi akĩoya higĩ ya hema na nyondo, agĩthiĩ acemete harĩa Sisera aakomete anogete mũno. Akĩhũũrĩrĩra higĩ ĩyo thikĩrĩrio-inĩ, ĩgĩtũrĩkania nginya igĩtoonyerera thĩ, nake agĩkua.
22 Nígbà tí Baraki dé bí ó ti ń lépa Sisera, Jaeli láti pàdé rẹ̀, wá, èmi yóò fi ẹni tí ìwọ ń wá hàn ọ́, báyìí ni ó tẹ̀lé e wọ inú àgọ́ lọ, kíyèsi Sisera dùbúlẹ̀ síbẹ̀ pẹ̀lú ìṣó àgọ́ ní agbárí rẹ̀ tí a ti kàn mọ́lẹ̀ ṣinṣin tí ó sì ti kú.
Baraka agĩũka aingatithĩtie Sisera, nake Jaeli agĩthiĩ kũmũtũnga. Akĩmwĩra atĩrĩ, “Ũka, nĩngũkuonia mũndũ ũrĩa ũracaria.” Nĩ ũndũ ũcio Baraka agĩtoonya hamwe na Jaeli, na agĩkora Sisera akomete thĩ arĩ mũkuũ nayo higĩ ĩmũtũrĩkanĩtie thikĩrĩrio.
23 Ní ọjọ́ náà ni Ọlọ́run ṣẹ́gun Jabini ọba àwọn ará Kenaani ní iwájú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Mũthenya ũcio-rĩ, nĩguo Ngai aatooririe Jabini, mũthamaki wa andũ a Kaanani, mbere ya andũ a Isiraeli.
24 Ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli sì le, ó sì ń lágbára síwájú àti síwájú sí i lára Jabini ọba Kenaani, títí wọ́n fi run òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
Nakuo guoko kwa andũ a Isiraeli gũgĩkĩrĩrĩria kũgĩa na hinya igũrũ rĩa Jabini, mũthamaki wa andũ a Kaanani, nginya makĩmũniina biũ.

< Judges 4 >