< Judges 4 >

1 Lẹ́yìn ikú Ehudu, àwọn ènìyàn Israẹli sì tún ṣẹ̀, wọ́n ṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa.
And the sones of Israel addiden to do yuel in the `siyt of the Lord, aftir the deeth of Aioth.
2 Nítorí náà Olúwa jẹ́ kí Jabini, ọba àwọn Kenaani, ẹni tí ó jẹ ọba ní Hasori, ṣẹ́gun wọn. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Sisera ẹni tí ń gbé Haroseti-Hagoyimu.
And the Lord bitook hem in to the hondis of Jabyn, kyng of Canaan, that regnede in Asor; and he hadde a duyk of his oost, Sisara bi name; and he dwellide in Aroseth of hethene men.
3 Nítorí tí ó ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ ogun irin, ó sì ń pọ́n Israẹli lójú gidigidi fún ogún ọdún, Israẹli ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́.
And the sones of Israel crieden to the Lord; for he hadde nyn hundrid yrone charis, keruynge as sithis, and twenti yeer he oppresside hem greetli.
4 Debora, wòlíì obìnrin, aya Lapidoti ni olórí àti aṣíwájú àwọn ará Israẹli ní àsìkò náà.
Forsothe Delbora was a prophetesse, the wijf of Lapidoth, which Delbora demyde the puple in that tyme;
5 Òun a máa jókòó ṣe ìdájọ́ ní abẹ́ igi ọ̀pẹ tí a sọ orúkọ rẹ̀ ní ọ̀pẹ Debora láàrín Rama àti Beteli ní ilẹ̀ òkè Efraimu, àwọn ará Israẹli a sì máa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti yanjú èdè-àìyedè tí wọ́n bá ní sí ara wọn, tàbí láti gbọ́ ohùn Olúwa láti ẹnu rẹ̀.
and sche sat vndur a palm tree, that was clepid bi her name, bitwixe Rama and Bethel, in the hil of Effraym; and the sones of Israel stieden to hir at ech dom.
6 Ní ọjọ́ kan, ó ránṣẹ́ pe Baraki ọmọ Abinoamu, ẹni tí ń gbé ní Kedeṣi ní ilẹ̀ Naftali, ó sì wí fún un pé, “Olúwa, Ọlọ́run Israẹli pa á ní àṣẹ fún un pé, ‘Kí ó kó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn akọni ọkùnrin jọ láti ẹ̀yà Naftali àti ẹ̀yà Sebuluni bí ẹgbẹ́ ogun, kí o sì síwájú wọn lọ sí òkè Tabori.
And sche sente, and clepide Barach, the sone of Abynoen, of Cedes of Neptalym, and sche seide to hym, The Lord God of Israel comaundide to thee, Go thou, and lede an oost in to the hil of Thabor, and thou schalt take with thee ten thousande `of fiyteris of the sones of Neptalym and of the sones of Zabulon.
7 Èmi yóò sì fa Sisera olórí ogun Jabini, pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun rẹ àti àwọn ogun rẹ, sí odò Kiṣoni èmi yóò sì fi lé ọ lọ́wọ́ ìwọ yóò sì ṣẹ́gun wọn níbẹ̀.’”
Sotheli Y schal brynge to thee, in the place of the stronde of Cison, Sisara, prince of `the oost of Jabyn, and his charis, and al the multitude; and Y schal bitake hem in thin hond.
8 Baraki sì dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ tí ìwọ ó bá bá mi lọ, ṣùgbọ́n tí ìwọ kì yóò bá bá mi lọ, èmi kì yóò lọ.”
And Barach seide to hir, If thou comest with me, Y schal go; if thou nylt come with me, Y schal not go.
9 Debora dá a lóhùn pé, “ó dára, èmi yóò bá ọ lọ. Ṣùgbọ́n ọlá ìṣẹ́gun tí o ń lọ yìí kò ní jẹ́ tìrẹ, nítorí Olúwa yóò fi Sisera lé obìnrin lọ́wọ́,” báyìí Debora bá Baraki lọ sí Kedeṣi.
And sche seyde to hym, Sotheli Y schal go with thee; but in this tyme the victorie schal not be arettide to thee; for Sisara schal be bitakun in the hond of a womman. Therfor Delbora roos, and yede with Barach in to Cedes.
10 Nígbà tí Baraki pe ẹ̀yà Sebuluni àti ẹ̀yà Naftali sí Kedeṣi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá akíkanjú ọkùnrin ogun tẹ̀lé e, Debora pẹ̀lú bá wọn lọ.
And whanne Zabulon and Neptalym weren clepid, he stiede with ten thousynde of fiyteris, and hadde Delbora in his felouschipe.
11 Ǹjẹ́ Heberi ọmọ Keni, ti ya ara rẹ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Keni, àní àwọn ọmọ Hobabu, àna Mose, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ títí dé ibi igi óákù Saananimu, tí ó wà ni agbègbè Kedeṣi.
Forsothe Aber of Cyneth hadde departid sum tyme fro othere Cyneys hise britheren, sones of Obab, `alie of Moises; and he hadde set forth tabernaclis `til to the valei, which is clepid Sennym, and was bisidis Cedes.
12 Nígbà tí a sọ fún Sisera pé Baraki ọmọ Abinoamu ti kó ogun jọ sí òkè Tabori,
And it was teld to Sisara, that Barach, sone of Abynoen, hadde stiede in to the hil of Thabor.
13 Sisera kó gbogbo kẹ̀kẹ́ ogun irin rẹ̀ tí ṣe ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, láti Haroseti tí àwọn orílẹ̀-èdè wá sí odò Kiṣoni.
And he gaderide nyn hundrid yronne charis, keruynge as sithis, and al the oost fro Aroseth of hethene men to the stronde of Cison.
14 Debora sì wí fún Baraki pé, “Lọ! Lónìí ni Olúwa fi Sisera lé ọ lọ́wọ́, Olúwa ti lọ síwájú rẹ.” Baraki sì síwájú, àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì tẹ̀lé e lẹ́yìn, wọ́n sì kọjá sí òkè Tabori.
And Delbora seide to Barach, Rise thou, for this is the day, in which the Lord bitook Sisara in to thin hondis; lo! the Lord is thi ledere. And so Barach cam doun fro the hil of Thabor, and ten thousynde of fyyteris with hym.
15 Olúwa sì mú ìdàrúdàpọ̀ wá sí àárín ogun Sisera, Olúwa sì fi ojú idà ṣẹ́gun Sisera àti àwọn oníkẹ̀kẹ́ ogun àti ọmọ-ogun orí ilẹ̀ ní iwájú Baraki. Sisera sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì fi ẹsẹ̀ sálọ.
And the Lord made aferd Sisara, and alle `the charis of hym, and al the multitude, bi the scharpnesse of swerd, at the siyt of Barach, in so myche that Sisara lippide doun of the chare, and fledde `a foote.
16 Baraki àti àwọn ogun rẹ̀ sì lé àwọn ọ̀tá náà, àwọn ọmọ-ogun orílẹ̀ àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun wọn títí dé Haroseti ti àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo ogun Sisera sì ti ojú idà ṣubú, kò sí ọ̀kan tí ó lè sálà tàbí tí ó wà láààyè.
And Barach pursuede the charis fleynge and the oost `til to Aroseth of hethene men; and al the multitude of enemyes felde doun `til to deeth.
17 Ṣùgbọ́n Sisera ti fi ẹsẹ̀ sálọ sí àgọ́ Jaeli aya Heberi ẹ̀yà Keni: nítorí ìbá dá ọ̀rẹ́ àlàáfíà wà láàrín Jabini ọba Hasori àti ìdílé Heberi ti ẹ̀yà Keni.
Sotheli Sisara fledde, and cam to the tente of Jahel, the wijf of Aber Cyney; forsothe pees waas bitwixe Jabyn, kyng of Asor, and bitwixe the hows of Aber Cyney.
18 Jaeli sì jáde síta láti pàdé Sisera, ó sì wí fún un pé, “Wọlé sínú àgọ́ mi, Olúwa mi, wọlé wá má ṣe bẹ̀rù nítorí pé ààbò ń bẹ fún ọ.” Ó sì yà sínú àgọ́ rẹ̀, ó sì fi aṣọ bò ó.
Therfor Jahel yede out in to the comyng of Sisara, and seide to hym, My lord, entre thou to me, entre thou to me; drede thou not. And he entride in to `the tabernacle of hir, and was hilid of hir with a mentil.
19 Sisera wí pé, “Òrùngbẹ ń gbẹ́ mí, jọ̀wọ́ fún mi ní omi mu.” Ó sì ṣí awọ wàrà kan, ó sì fún un mu ó sì tún daṣọ bò ó padà.
And he seide to hir, Y biseche, yyue `thou to me a litil of watir, for Y thirste greetli. And sche openyde a `botel of mylk, and yaf to hym to drynke, and hilide hym.
20 Sisera sọ fún Jaeli pé, “Kí ó dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, àti pé bí ẹnikẹ́ni bá béèrè bóyá òun wà níbẹ̀ kí ó sọ pé, ‘Kò sí ẹnìkankan ní ibẹ̀.’”
And Sisara seide to hir, Stonde thou bifor the dore of the tabernacle, and whanne ony man cometh, and axith thee, and seith, Whether ony man is here? thou schalt answere, No man is here.
21 Ṣùgbọ́n Jaeli ìyàwó Heberi mú ìṣó àgọ́ tí ó mú àti òòlù ní ọwọ́ rẹ̀, ó sì yọ́ wọ inú ibi tí ó sùn, nígbà tí ó ti sùn fọnfọn, nígbà náà ni ó kan ìṣó náà mọ́ òkè ìpéǹpéjú rẹ̀, ó sì wọlé ṣinṣin, ó sì kú.
And so Jahel, the wijf of Aber, took a nayl of the tabernacle, and sche took also an hamer; and sche entride pryueli, and puttide with silence the nail on the temple of his heed, and sche fastnede the nail smytun with the hamer in to the brayn, `til to the erthe; and he slepte, and diede to gidere, and failide, and was deed.
22 Nígbà tí Baraki dé bí ó ti ń lépa Sisera, Jaeli láti pàdé rẹ̀, wá, èmi yóò fi ẹni tí ìwọ ń wá hàn ọ́, báyìí ni ó tẹ̀lé e wọ inú àgọ́ lọ, kíyèsi Sisera dùbúlẹ̀ síbẹ̀ pẹ̀lú ìṣó àgọ́ ní agbárí rẹ̀ tí a ti kàn mọ́lẹ̀ ṣinṣin tí ó sì ti kú.
And lo! Barach suede Sisara, `and cam; and Jahel yede out in to his comyng, and seide to hym, Come, and Y schal schewe to thee the man, whom thou sekist. And whanne he hadde entrid to hir, he siy Sisara liggynge deed, and a nail fastnede in to hise templis.
23 Ní ọjọ́ náà ni Ọlọ́run ṣẹ́gun Jabini ọba àwọn ará Kenaani ní iwájú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Therfor in that day God `made low Jabyn, the kyng of Canaan, bifor the sones of Israel;
24 Ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli sì le, ó sì ń lágbára síwájú àti síwájú sí i lára Jabini ọba Kenaani, títí wọ́n fi run òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
whiche encresiden ech dai, and with strong hond oppressiden Jabyn, the kyng of Canaan, til thei diden hym awey.

< Judges 4 >