< Judges 3 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa fi sílẹ̀ láti dán àwọn ìran tuntun ní Israẹli wò, àwọn ìran tí kò ì tí ì ní ìrírí ogun àwọn ará Kenaani.
A ovo su narodi koje ostavi Gospod da njima kuša Izrailja, sve one koji ne znahu za ratove Hananske,
2 (Ó ṣe èyí láti fi kọ́ àwọn ìran Israẹli tí kò rí ogun rí níbí a ti ṣe ń jagun).
Da bi barem natražje sinova Izrailjevijeh znalo i razumjelo što je rat, barem oni koji od prije nijesu znali:
3 Àwọn ìjòyè ìlú Filistini márààrún, gbogbo àwọn ará Kenaani, àwọn ará Sidoni, àti àwọn ará Hifi tí ń gbé ní àwọn òkè Lebanoni bẹ̀rẹ̀ láti òkè Baali-Hermoni títí dé Lebo-Hamati.
Pet kneževina Filistejskih, i svi Hananeji i Sidonci i Jeveji, koji življahu na gori Livanu od gore Val-Ermona do Emata.
4 A fi àwọn ènìyàn náà sílẹ̀ láti dán àwọn Israẹli wò bóyá wọn yóò gbọ́rọ̀ sí àwọn òfin Olúwa, èyí tí ó ti fi fún àwọn baba wọn láti ipasẹ̀ Mose.
Ti narodi ostaše da se Izrailj njima kuša, da se vidi hoæe li slušati zapovijesti Gospodnje, koje je zapovjedio ocima njihovijem preko Mojsija.
5 Àwọn ọmọ Israẹli gbé láàrín àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti àwọn ará Amori, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi.
I življahu sinovi Izrailjevi usred Hananeja i Heteja i Amoreja i Ferezeja i Jeveja i Jevuseja.
6 Dípò kí wọ́n run àwọn ènìyàn wọ̀nyí, Israẹli ń fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n sì ń fi àwọn ọmọbìnrin Israẹli fún àwọn ará ilẹ̀ náà ní aya, wọ́n sì ń sin àwọn òrìṣà wọn.
I ženjahu se kæerima njihovijem i udavahu kæeri svoje za sinove njihove, i služahu bogovima njihovijem.
7 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe èyí tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń sin Baali àti Aṣerah.
I èinjahu sinovi Izrailjevi što je zlo pred Gospodom, i zaboraviše Gospoda Boga svojega i služahu Valima i lugovima.
8 Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ kí Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu-Naharaimu bá wọn jà kí ó sì ṣẹ́gun wọn, Israẹli sì ṣe ẹrú rẹ̀ fún ọdún mẹ́jọ.
Zato se razgnjevi Gospod na Izrailja, i dade ih u ruke Husan-Risatajimu caru Mesopotamskom; i služiše sinovi Izrailjevi Husan-Risatajimu osam godina.
9 Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli kígbe sí Olúwa, Òun gbé olùgbàlà kan dìde fún wọn, ẹni náà ni Otnieli ọmọ Kenasi àbúrò Kalebu tí ó jẹ́ ọkùnrin, ẹni tí ó gbà wọ́n sílẹ̀.
Potom vapiše sinovi Izrailjevi ka Gospodu, i podiže Gospod izbavitelja sinovima Izrailjevijem da ih izbavi, Gotonila sina Kenezova, mlaðega brata Halevova,
10 Ẹ̀mí Olúwa bà lé e, òun sì ṣe ìdájọ́ Israẹli, ó sì síwájú wọn lọ sí ogun. Olúwa sì fi Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu lé Otnieli lọ́wọ́, ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ sì borí Kuṣani-Riṣataimu.
I bijaše na njemu duh Gospodnji, i suðaše Izrailju; i izide na vojsku, i predade mu Gospod u ruke Husan-Risatajima cara Mesopotamskoga; i ruka njegova nadjaèa Husan-Risatajima.
11 Ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún títí tí Otnieli ọmọ Kenasi sì kú.
I zemlja bi mirna èetrdeset godina. Potom umrije Gotonilo sin Kenezov.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sì tún padà sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn, wọ́n sì ṣe èyí tí ó burú ní iwájú Olúwa, fún ìdí iṣẹ́ búburú yìí, Olúwa fún Egloni, ọba àwọn Moabu ní agbára ní orí Israẹli.
A sinovi Izrailjevi stadoše opet èiniti što je zlo pred Gospodom; a Gospod ukrijepi Eglona cara Moavskoga na Izrailja, jer èinjahu što je zlo pred Gospodom.
13 Pẹ̀lú ìfi ọwọ́ ṣowọ́pọ̀ ogun àwọn Ammoni àti àwọn ọmọ-ogun Amaleki ní Egloni gbógun ti àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì gba ìlú Ọ̀pẹ tí i se Jeriko.
Jer skupi k sebi sinove Amonove i Amalike, i izašavši pobi Izrailja, i osvojiše grad palmov.
14 Àwọn ọmọ Israẹli sì sin Egloni ọba Moabu fún ọdún méjìdínlógún.
I sinovi Izrailjevi služiše Eglonu caru Moavskom osamnaest godina.
15 Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli tún ké pe Olúwa, Olúwa rán olùgbàlà kan sí wọn, Ehudu ẹni tí ń lo ọwọ́ òsì, ọmọ Gera ti ẹ̀yà Benjamini. Àwọn ọmọ Israẹli fi ẹ̀bùn rán sí Egloni ọba Moabu.
Potom vapiše sinovi Izrailjevi ka Gospodu; i Gospod im podiže izbavitelja Aoda sina Gire sina Venijaminova, èovjeka koji bijaše ljevak. I poslaše sinovi Izrailjevi po njemu dar Eglonu caru Moavskom.
16 Ehudu sì rọ idà kan olójú méjì, ìgbọ̀nwọ́ kan ní gígùn; òun sì sán an ní abẹ́ aṣọ rẹ̀ ní itan rẹ̀ ọ̀tún.
A Aod naèini sebi maè s obje strane oštar, od lakta u dužinu; i pripasa ga pod haljine svoje uz desnu bedricu.
17 Ó sì mú ọrẹ náà wá fún Egloni ọba Moabu, Egloni ẹni tí ó sanra púpọ̀.
I odnese dar Eglonu caru Moavskom; a Eglon bješe èovjek vrlo debeo.
18 Lẹ́yìn tí Ehudu ti fi ẹ̀bùn náà fún ọba tan, ó rán àwọn tí ó kó ẹrú náà wá lọ sí ọ̀nà wọn.
I kad predade dar, otpusti ljude koji su nosili dar.
19 Ṣùgbọ́n nígbà tí òun fúnra rẹ̀ dé ibi ère fínfín tí ó wà létí Gilgali, ó padà sí Egloni, ó sì wí pé, “Ọba, mo ní ọ̀rọ̀ àṣírí láti bá ọ sọ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ dákẹ́!” Gbogbo àwọn tí ń ṣọ sì jáde síta kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Pa sam vrativ se od likova kamenijeh, koji bijahu kod Galgala, reèe: imam, care, neku tajnu da ti kažem. A on reèe: muèi! I otidoše od njega svi koji stajahu pred njim.
20 Ehudu lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ níbi tí ó ti jókòó ní iyàrá ìtura rẹ̀, Ehudu sì wí fún un pé, “Mo ní ọ̀rọ̀ kan fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.” Bí ọba sì ti dìde ní orí ìtẹ́ rẹ̀,
A Aod pristupi k njemu; a on sjeðaše sam u ljetnoj sobi; pa reèe Aod: rijeè Božiju imam da ti kažem. Tada on usta s prijestola.
21 Ehudu fi ọwọ́ òsì rẹ̀ yọ idà láti ibi itan ọ̀tún rẹ̀ ó sì fi gún ọba nínú ikùn rẹ̀.
A Aod poteže lijevom rukom svojom i uze maè od desne bedrice, i satjera mu ga u trbuh,
22 Àti idà àti èèkù rẹ̀ sì wọlé ó sì yọ ní ẹ̀yìn rẹ̀. Ehudu kò yọ idà náà, ọ̀rá sì bo idà náà.
I držak uðe za maèem, i salo se sklopi za maèem, te ne može izvuæi maèa iz trbuha; i izide neèist.
23 Ehudu ti àwọn ìlẹ̀kùn ní àtì-sínú òun sì bá yàrá òkè jáde, ó sì sálọ.
Potom izide Aod iz sobe, i zatvori vrata za sobom i zakljuèa.
24 Lẹ́yìn tí ó ti lọ àwọn ìránṣẹ́ ọba dé, ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ìlẹ̀kùn yàrá òkè ní títì, wọ́n rò pé, “Bóyá ó wà ní ilé ìyàgbẹ́ ní yàrá nínú ilé.”
A kad on otide, doðoše sluge, i pogledaše, a to vrata od sobe zakljuèana, pa rekoše: valjada ide napolje u klijeti do ljetne sobe.
25 Nígbà tí wọ́n dúró dé ibi pé ó jẹ́ ìyanu fún wọn, wọ́n mú kọ́kọ́rọ́, wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn. Níbẹ̀ ni wọ́n ti rí Olúwa wọn tí ó ti ṣubú, ó sì ti kú.
I veæ im se dosadi èekati a vrata se od sobe ne otvoraju, te uzeše kljuè i otvoriše, a gle, gospodar im leži na zemlji mrtav.
26 Nígbà tí wọ́n dúró tí wọn sì ń retí, Ehudu ti sálọ. Ó ti gba ibi tí wọ́n ti ń gbẹ́ òkúta lére, ó sì sálọ sí Seira.
A Aod dokle se oni zabaviše pobježe i proðe likove kamene, i uteèe u Seirot.
27 Nígbà tí ó dé ibẹ̀, ó fọn ìpè ní orí òkè Efraimu, àwọn ọmọ Israẹli sì ba sọ̀kalẹ̀ lọ láti òkè náà wá, òun sì wà níwájú wọn.
I kad doðe, zatrubi u trubu u gori Jefremovoj; i sidoše s njim sinovi Izrailjevi s gore, a on naprijed.
28 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa tẹ̀lé mi, nítorí Olúwa ti fi Moabu ọ̀tá yín lé yín lọ́wọ́.” Wọ́n sì tẹ̀lé e, wọ́n sì gba ìwọdò Jordani tí ó lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọn ò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kọjá.
Pa im reèe: hajdete za mnom, jer Gospod predade vam u ruke neprijatelje vaše Moavce. I sidoše za njim, i uzeše Moavcima brodove Jordanske, i ne dadijahu nikome prijeæi.
29 Ní báyìí, wọ́n ti pa tó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ará Moabu tí wọ́n jẹ́ alágbára àti onígboyà ènìyàn, kò sí ènìyàn tí ó sálà.
I tada pobiše Moavce, oko deset tisuæa ljudi, sve bogate i hrabre, i nijedan ne uteèe.
30 Ní ọjọ́ náà ni Israẹli ṣẹ́gun àwọn ará Moabu, ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ọgọ́rin ọdún.
Tako u taj dan potpadoše Moavci pod ruku Izrailjevu; i zemlja bi mirna osamdeset godina.
31 Lẹ́yìn Ehudu, ni Ṣamgari ọmọ Anati ẹni tí ó pa ẹgbẹ̀ta Filistini pẹ̀lú ọ̀pá tí a fi ń da akọ màlúù, òun pẹ̀lú sì gba Israẹli kúrò nínú ìpọ́njú.
A poslije njega nasta Samegar sin Anatov, i pobi šest stotina Filisteja ostanom volujskim, i izbavi i on Izrailja.

< Judges 3 >