< Judges 3 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa fi sílẹ̀ láti dán àwọn ìran tuntun ní Israẹli wò, àwọn ìran tí kò ì tí ì ní ìrírí ogun àwọn ará Kenaani.
Și acestea sunt națiunile pe care le-a lăsat DOMNUL, ca prin ele să încerce pe Israel, pe toți cei care nu cunoscuseră toate războaiele Canaanului;
2 (Ó ṣe èyí láti fi kọ́ àwọn ìran Israẹli tí kò rí ogun rí níbí a ti ṣe ń jagun).
Numai pentru ca generațiile copiilor lui Israel să cunoască, pentru a-i învăța războiul, cel puțin cei care nu știuseră nimic de el,
3 Àwọn ìjòyè ìlú Filistini márààrún, gbogbo àwọn ará Kenaani, àwọn ará Sidoni, àti àwọn ará Hifi tí ń gbé ní àwọn òkè Lebanoni bẹ̀rẹ̀ láti òkè Baali-Hermoni títí dé Lebo-Hamati.
Adică, cei cinci domni ai filistenilor și toți canaaniții și sidonienii și hiviții care au locuit pe muntele Liban, de la muntele Baal-Hermon până la intrarea în Hamat.
4 A fi àwọn ènìyàn náà sílẹ̀ láti dán àwọn Israẹli wò bóyá wọn yóò gbọ́rọ̀ sí àwọn òfin Olúwa, èyí tí ó ti fi fún àwọn baba wọn láti ipasẹ̀ Mose.
Și ele erau pentru a încerca pe Israel prin ele, ca să cunoască dacă vor da ascultare poruncilor DOMNULUI, pe care el le-a poruncit părinților lor prin mâna lui Moise.
5 Àwọn ọmọ Israẹli gbé láàrín àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti àwọn ará Amori, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi.
Și copiii lui Israel au locuit printre canaaniți, hitiți și amoriți și periziți și hiviți și iebusiți:
6 Dípò kí wọ́n run àwọn ènìyàn wọ̀nyí, Israẹli ń fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n sì ń fi àwọn ọmọbìnrin Israẹli fún àwọn ará ilẹ̀ náà ní aya, wọ́n sì ń sin àwọn òrìṣà wọn.
Și au luat pe fiicele lor de soții și au dat pe fiicele lor fiilor lor și au servit dumnezeilor lor.
7 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe èyí tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń sin Baali àti Aṣerah.
Și copiii lui Israel au făcut ce este rău în ochii DOMNULUI și au uitat pe DOMNUL Dumnezeul lor și au servit Baalilor și dumbrăvilor.
8 Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ kí Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu-Naharaimu bá wọn jà kí ó sì ṣẹ́gun wọn, Israẹli sì ṣe ẹrú rẹ̀ fún ọdún mẹ́jọ.
De aceea mânia DOMNULUI s-a aprins împotriva lui Israel și i-a vândut în mâna lui Cușan-Rișeataim, împăratul Mesopotamiei; și copiii lui Israel au servit lui Cușan-Rișeataim opt ani.
9 Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli kígbe sí Olúwa, Òun gbé olùgbàlà kan dìde fún wọn, ẹni náà ni Otnieli ọmọ Kenasi àbúrò Kalebu tí ó jẹ́ ọkùnrin, ẹni tí ó gbà wọ́n sílẹ̀.
Și când copiii lui Israel au strigat către DOMNUL, DOMNUL a ridicat copiilor lui Israel un eliberator, care i-a eliberat, pe Otniel, fiul lui Chenaz, fratele mai mic al lui Caleb.
10 Ẹ̀mí Olúwa bà lé e, òun sì ṣe ìdájọ́ Israẹli, ó sì síwájú wọn lọ sí ogun. Olúwa sì fi Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu lé Otnieli lọ́wọ́, ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ sì borí Kuṣani-Riṣataimu.
Și Duhul DOMNULUI a fost peste el și el a judecat pe Israel și a ieșit la război; și DOMNUL a dat în mâna lui pe Cușan-Rișeataim, împăratul Mesopotamiei; și mâna lui a învins împotriva lui Cușan-Rișeataim.
11 Ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún títí tí Otnieli ọmọ Kenasi sì kú.
Și țara a avut odihnă patruzeci de ani. Și Otniel, fiul lui Chenaz, a murit.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sì tún padà sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn, wọ́n sì ṣe èyí tí ó burú ní iwájú Olúwa, fún ìdí iṣẹ́ búburú yìí, Olúwa fún Egloni, ọba àwọn Moabu ní agbára ní orí Israẹli.
Și copiii lui Israel au făcut din nou ce este rău în ochii DOMNULUI; și DOMNUL a întărit pe Eglon, împăratul Moabului, împotriva lui Israel, pentru că ei făcuseră ce este rău în ochii DOMNULUI.
13 Pẹ̀lú ìfi ọwọ́ ṣowọ́pọ̀ ogun àwọn Ammoni àti àwọn ọmọ-ogun Amaleki ní Egloni gbógun ti àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì gba ìlú Ọ̀pẹ tí i se Jeriko.
Și el a adunat la sine pe copiii lui Amon și ai lui Amalec și a mers și a lovit pe Israel și au stăpânit cetatea palmierilor.
14 Àwọn ọmọ Israẹli sì sin Egloni ọba Moabu fún ọdún méjìdínlógún.
Astfel copiii lui Israel au servit lui Eglon, împăratul Moabului, optsprezece ani.
15 Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli tún ké pe Olúwa, Olúwa rán olùgbàlà kan sí wọn, Ehudu ẹni tí ń lo ọwọ́ òsì, ọmọ Gera ti ẹ̀yà Benjamini. Àwọn ọmọ Israẹli fi ẹ̀bùn rán sí Egloni ọba Moabu.
Dar când copiii lui Israel au strigat către DOMNUL, DOMNUL le-a ridicat un eliberator, pe Ehud, fiul lui Ghera, un beniamit, un bărbat stângaci; și prin el, copiii lui Israel au trimis un dar lui Eglon, împăratul Moabului.
16 Ehudu sì rọ idà kan olójú méjì, ìgbọ̀nwọ́ kan ní gígùn; òun sì sán an ní abẹ́ aṣọ rẹ̀ ní itan rẹ̀ ọ̀tún.
Dar Ehud și-a făcut un pumnal cu două tăișuri, lung de un cot; și l-a încins sub haina sa la coapsa lui dreaptă.
17 Ó sì mú ọrẹ náà wá fún Egloni ọba Moabu, Egloni ẹni tí ó sanra púpọ̀.
Și el a adus darul la Eglon, împăratul Moabului; și Eglon era un om foarte gras.
18 Lẹ́yìn tí Ehudu ti fi ẹ̀bùn náà fún ọba tan, ó rán àwọn tí ó kó ẹrú náà wá lọ sí ọ̀nà wọn.
Și când a terminat de oferit darul, el a dat drumul oamenilor care purtaseră darul.
19 Ṣùgbọ́n nígbà tí òun fúnra rẹ̀ dé ibi ère fínfín tí ó wà létí Gilgali, ó padà sí Egloni, ó sì wí pé, “Ọba, mo ní ọ̀rọ̀ àṣírí láti bá ọ sọ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ dákẹ́!” Gbogbo àwọn tí ń ṣọ sì jáde síta kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Dar el singur s-a întors de la carierele care erau lângă Ghilgal și a spus: Am o vorbă tainică pentru tine, împărate, care a spus: Tăcere. Și toți care stăteau în picioare lângă el au ieșit de la el.
20 Ehudu lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ níbi tí ó ti jókòó ní iyàrá ìtura rẹ̀, Ehudu sì wí fún un pé, “Mo ní ọ̀rọ̀ kan fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.” Bí ọba sì ti dìde ní orí ìtẹ́ rẹ̀,
Și Ehud a venit la el și el ședea într-un salon de vară, pe care îl avea numai pentru el. Și Ehud a spus: Am un mesaj de la Dumnezeu pentru tine. Și el s-a ridicat de pe scaun.
21 Ehudu fi ọwọ́ òsì rẹ̀ yọ idà láti ibi itan ọ̀tún rẹ̀ ó sì fi gún ọba nínú ikùn rẹ̀.
Și Ehud și-a întins mâna stângă și a luat pumnalul de la coapsa dreaptă și l-a înfipt în pântecele lui;
22 Àti idà àti èèkù rẹ̀ sì wọlé ó sì yọ ní ẹ̀yìn rẹ̀. Ehudu kò yọ idà náà, ọ̀rá sì bo idà náà.
Și mânerul de asemenea a intrat după lamă; și grăsimea s-a închis peste lamă, astfel încât nu a putut trage pumnalul din pântecele lui, și mizeria a ieșit din el.
23 Ehudu ti àwọn ìlẹ̀kùn ní àtì-sínú òun sì bá yàrá òkè jáde, ó sì sálọ.
Atunci Ehud a ieșit prin portic și a închis după el ușile salonului de vară și le-a încuiat.
24 Lẹ́yìn tí ó ti lọ àwọn ìránṣẹ́ ọba dé, ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ìlẹ̀kùn yàrá òkè ní títì, wọ́n rò pé, “Bóyá ó wà ní ilé ìyàgbẹ́ ní yàrá nínú ilé.”
După ce a ieșit, au venit servitorii lui; și când au văzut că, iată, ușile salonului de vară erau încuiate, au spus: Cu siguranță își acoperă picioarele în salonul său de vară.
25 Nígbà tí wọ́n dúró dé ibi pé ó jẹ́ ìyanu fún wọn, wọ́n mú kọ́kọ́rọ́, wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn. Níbẹ̀ ni wọ́n ti rí Olúwa wọn tí ó ti ṣubú, ó sì ti kú.
Și au așteptat până când s-au rușinat; și, iată, el nu deschidea ușile salonului; de aceea au luat o cheie și le-au deschis; și, iată, domnul lor era căzut jos mort pe pământ.
26 Nígbà tí wọ́n dúró tí wọn sì ń retí, Ehudu ti sálọ. Ó ti gba ibi tí wọ́n ti ń gbẹ́ òkúta lére, ó sì sálọ sí Seira.
Și Ehud a scăpat pe când întârziau ei și a trecut de cariere și a scăpat la Seira.
27 Nígbà tí ó dé ibẹ̀, ó fọn ìpè ní orí òkè Efraimu, àwọn ọmọ Israẹli sì ba sọ̀kalẹ̀ lọ láti òkè náà wá, òun sì wà níwájú wọn.
Și s-a întâmplat, când a venit, că a sunat din trâmbiță în muntele lui Efraim și copiii lui Israel au coborât cu el din munte, și el a coborât înaintea lor.
28 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa tẹ̀lé mi, nítorí Olúwa ti fi Moabu ọ̀tá yín lé yín lọ́wọ́.” Wọ́n sì tẹ̀lé e, wọ́n sì gba ìwọdò Jordani tí ó lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọn ò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kọjá.
Și le-a spus: Urmați-mă, pentru că DOMNUL a dat în mâna voastră pe dușmanii voștri, pe moabiți. Și au coborât după el și au luat vadurile Iordanului, spre Moab, și nu au permis nimănui să treacă.
29 Ní báyìí, wọ́n ti pa tó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ará Moabu tí wọ́n jẹ́ alágbára àti onígboyà ènìyàn, kò sí ènìyàn tí ó sálà.
Și în timpul acela au ucis din Moab cam zece mii de oameni, toți voinici și toți bărbați de valoare, și nu a scăpat niciunul.
30 Ní ọjọ́ náà ni Israẹli ṣẹ́gun àwọn ará Moabu, ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ọgọ́rin ọdún.
Astfel, în ziua aceea, Moab a fost înfrânt sub mâna lui Israel. Și țara a avut odihnă optzeci de ani.
31 Lẹ́yìn Ehudu, ni Ṣamgari ọmọ Anati ẹni tí ó pa ẹgbẹ̀ta Filistini pẹ̀lú ọ̀pá tí a fi ń da akọ màlúù, òun pẹ̀lú sì gba Israẹli kúrò nínú ìpọ́njú.
Și după el a fost Șamgar, fiul lui Anat, care a ucis, dintre filisteni, șase sute de oameni cu o țepușă pentru boi, și el de asemenea a eliberat pe Israel.

< Judges 3 >