< Judges 3 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa fi sílẹ̀ láti dán àwọn ìran tuntun ní Israẹli wò, àwọn ìran tí kò ì tí ì ní ìrírí ogun àwọn ará Kenaani.
Šie nu ir tie pagāni, ko Tas Kungs atstāja, ka Viņš caur tiem Israēli kārdinātu, kas nekā nezināja no Kanaāna kariem;
2 (Ó ṣe èyí láti fi kọ́ àwọn ìran Israẹli tí kò rí ogun rí níbí a ti ṣe ń jagun).
Lai Israēla bērnu pēcnākamie zinātu un mācītos karu, tie, kas no tā vēl nekā nezināja.
3 Àwọn ìjòyè ìlú Filistini márààrún, gbogbo àwọn ará Kenaani, àwọn ará Sidoni, àti àwọn ará Hifi tí ń gbé ní àwọn òkè Lebanoni bẹ̀rẹ̀ láti òkè Baali-Hermoni títí dé Lebo-Hamati.
Pieci Fīlistu valdnieki un visi Kanaānieši un Sidonieši un Hivieši, kas dzīvoja Lībanus kalnos, un no BaālErmona kalna līdz Hamatai.
4 A fi àwọn ènìyàn náà sílẹ̀ láti dán àwọn Israẹli wò bóyá wọn yóò gbọ́rọ̀ sí àwọn òfin Olúwa, èyí tí ó ti fi fún àwọn baba wọn láti ipasẹ̀ Mose.
Šie tad bija, lai Israēls caur tiem tiktu kārdināts, ka taptu zināms, vai tie klausīs Tā Kunga baušļiem, ko Viņš viņu tēviem bija pavēlējis caur Mozu.
5 Àwọn ọmọ Israẹli gbé láàrín àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti àwọn ará Amori, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi.
Un Israēla bērni dzīvoja vidū starp Kanaāniešiem, Hetiešiem un Amoriešiem un Fereziešiem un Hiviešiem un Jebusiešiem.
6 Dípò kí wọ́n run àwọn ènìyàn wọ̀nyí, Israẹli ń fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n sì ń fi àwọn ọmọbìnrin Israẹli fún àwọn ará ilẹ̀ náà ní aya, wọ́n sì ń sin àwọn òrìṣà wọn.
Un tie sev ņēma viņu meitas par sievām un deva savas meitas viņu dēliem un kalpoja viņu dieviem,
7 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe èyí tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń sin Baali àti Aṣerah.
Un Israēla bērni darīja, kas Tam Kungam nepatika, un aizmirsa To Kungu, savu Dievu, un kalpoja Baāliem un Astartēm.
8 Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ kí Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu-Naharaimu bá wọn jà kí ó sì ṣẹ́gun wọn, Israẹli sì ṣe ẹrú rẹ̀ fún ọdún mẹ́jọ.
Tad Tā Kunga bardzība iedegās pret Israēli un Viņš tos pārdeva Kuzan Rizataīma, Mezopotamijas ķēniņa, rokā, un Israēla bērni kalpoja Kuzan Rizataīmam astoņus gadus.
9 Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli kígbe sí Olúwa, Òun gbé olùgbàlà kan dìde fún wọn, ẹni náà ni Otnieli ọmọ Kenasi àbúrò Kalebu tí ó jẹ́ ọkùnrin, ẹni tí ó gbà wọ́n sílẹ̀.
Tad Israēla bērni brēca uz To Kungu, un Tas Kungs Israēla bērniem cēla pestītāju, kas tos izpestīja, Otniēli, Ķenasa, Kāleba jaunākā brāļa, dēlu.
10 Ẹ̀mí Olúwa bà lé e, òun sì ṣe ìdájọ́ Israẹli, ó sì síwájú wọn lọ sí ogun. Olúwa sì fi Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu lé Otnieli lọ́wọ́, ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ sì borí Kuṣani-Riṣataimu.
Un Tā Kunga Gars bija uz viņu, un viņš bija par soģi Israēlim un izgāja karā, un Tas Kungs deva viņa rokā Kuzan Rizataīmu, Mezopotamijas ķēniņu, un viņa roka bija stipra pār Kuzan Rizataīmu.
11 Ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún títí tí Otnieli ọmọ Kenasi sì kú.
Tad zemei bija miers četrdesmit gadus, un Otniēls, Ķenasa dēls, nomira.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sì tún padà sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn, wọ́n sì ṣe èyí tí ó burú ní iwájú Olúwa, fún ìdí iṣẹ́ búburú yìí, Olúwa fún Egloni, ọba àwọn Moabu ní agbára ní orí Israẹli.
Bet Israēla bērni joprojām darīja, kas Tam Kungam nepatika. Tad Tas Kungs stiprināja Eglonu, Moaba ķēniņu, pret Israēli, tāpēc, ka tie darīja, kas Tam Kungam nepatika.
13 Pẹ̀lú ìfi ọwọ́ ṣowọ́pọ̀ ogun àwọn Ammoni àti àwọn ọmọ-ogun Amaleki ní Egloni gbógun ti àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì gba ìlú Ọ̀pẹ tí i se Jeriko.
Un viņš sapulcēja pie sevis Amona bērnus un Amaleku, un cēlās un kāva Israēli, un tie ieņēma to palmu pilsētu.
14 Àwọn ọmọ Israẹli sì sin Egloni ọba Moabu fún ọdún méjìdínlógún.
Un Israēla bērni kalpoja Eglonam, Moaba ķēniņam, astoņpadsmit gadus.
15 Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli tún ké pe Olúwa, Olúwa rán olùgbàlà kan sí wọn, Ehudu ẹni tí ń lo ọwọ́ òsì, ọmọ Gera ti ẹ̀yà Benjamini. Àwọn ọmọ Israẹli fi ẹ̀bùn rán sí Egloni ọba Moabu.
Tad Israēla bērni brēca uz To Kungu, un Tas Kungs tiem cēla par pestītāju Eūdu, Ģerus dēlu, no Benjamina cilts; tas bija kreilis, un Israēla bērni caur viņu sūtīja dāvanu Eglonam, Moaba ķēniņam.
16 Ehudu sì rọ idà kan olójú méjì, ìgbọ̀nwọ́ kan ní gígùn; òun sì sán an ní abẹ́ aṣọ rẹ̀ ní itan rẹ̀ ọ̀tún.
Un Eūds taisīja sev abējās pusēs griezīgu zobenu, olekts garumā, un to apjoza apakš savām drēbēm pie savas labās ciskas.
17 Ó sì mú ọrẹ náà wá fún Egloni ọba Moabu, Egloni ẹni tí ó sanra púpọ̀.
Un viņš Eglonam, Moaba ķēniņam, nonesa dāvanas, un Eglons bija ļoti resns vīrs.
18 Lẹ́yìn tí Ehudu ti fi ẹ̀bùn náà fún ọba tan, ó rán àwọn tí ó kó ẹrú náà wá lọ sí ọ̀nà wọn.
Un kad viņš to dāvanu bija nodevis, tad viņš tos ļaudis atlaida, kas to dāvanu bija nesuši.
19 Ṣùgbọ́n nígbà tí òun fúnra rẹ̀ dé ibi ère fínfín tí ó wà létí Gilgali, ó padà sí Egloni, ó sì wí pé, “Ọba, mo ní ọ̀rọ̀ àṣírí láti bá ọ sọ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ dákẹ́!” Gbogbo àwọn tí ń ṣọ sì jáde síta kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Bet viņš griezās atpakaļ no tiem elku stabiem, kas bija Gilgalā un sacīja: man viens noslēpums tev jāsaka, ķēniņ. Un tas sacīja: klusu! Tad visi izgāja ārā, kas ap viņu stāvēja.
20 Ehudu lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ níbi tí ó ti jókòó ní iyàrá ìtura rẹ̀, Ehudu sì wí fún un pé, “Mo ní ọ̀rọ̀ kan fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.” Bí ọba sì ti dìde ní orí ìtẹ́ rẹ̀,
Un Eūds pie viņa pienāca; bet viņš sēdēja kādā dzestrā kambarī, kas bija viņam vienam. Tad Eūds sacīja: man ir Dieva vārds uz tevi. Tad viņš cēlās no tā krēsla.
21 Ehudu fi ọwọ́ òsì rẹ̀ yọ idà láti ibi itan ọ̀tún rẹ̀ ó sì fi gún ọba nínú ikùn rẹ̀.
Un Eūds izstiepa savu kreiso roku un ņēma to zobenu no savas labās ciskas un to viņam iedūra vēderā,
22 Àti idà àti èèkù rẹ̀ sì wọlé ó sì yọ ní ẹ̀yìn rẹ̀. Ehudu kò yọ idà náà, ọ̀rá sì bo idà náà.
Ka gan asmens, gan spals iegāja, un tie tauki to asmeni apklāja, jo viņš to zobenu no viņa vēdera neizvilka, un tas izgāja pakaļā cauri.
23 Ehudu ti àwọn ìlẹ̀kùn ní àtì-sínú òun sì bá yàrá òkè jáde, ó sì sálọ.
Tad Eūds izgāja ārā un aizslēdza tā kambara durvis aiz sevis un tās aizšāva.
24 Lẹ́yìn tí ó ti lọ àwọn ìránṣẹ́ ọba dé, ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ìlẹ̀kùn yàrá òkè ní títì, wọ́n rò pé, “Bóyá ó wà ní ilé ìyàgbẹ́ ní yàrá nínú ilé.”
Kad tas nu bija izgājis, tad viņa kalpi nāca, un redzēja, un lūk, kambara durvis bija aizslēgtas. Un tie sacīja: viņš gan savas kājas apklāj tai dzestrā kambarī.
25 Nígbà tí wọ́n dúró dé ibi pé ó jẹ́ ìyanu fún wọn, wọ́n mú kọ́kọ́rọ́, wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn. Níbẹ̀ ni wọ́n ti rí Olúwa wọn tí ó ti ṣubú, ó sì ti kú.
Kad tie nu gaidīja tik ilgi, ka paši kaunējās, un redzi, viņš tā kambara durvis neatdarīja, tad viņi ņēma atslēgu un atslēdza, un redzi, viņu kungs gulēja pie zemes nomiris.
26 Nígbà tí wọ́n dúró tí wọn sì ń retí, Ehudu ti sálọ. Ó ti gba ibi tí wọ́n ti ń gbẹ́ òkúta lére, ó sì sálọ sí Seira.
Un Eūds izmuka, kamēr tie gaidīja, jo viņš gāja gar tiem elku stabiem un aizmuka uz Seīratu.
27 Nígbà tí ó dé ibẹ̀, ó fọn ìpè ní orí òkè Efraimu, àwọn ọmọ Israẹli sì ba sọ̀kalẹ̀ lọ láti òkè náà wá, òun sì wà níwájú wọn.
Un kad viņš tur nonāca, tad viņš pūta trumetē uz Efraīma kalniem, un Israēla bērni nogāja ar viņu no tiem kalniem un viņš pats viņu priekšā.
28 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa tẹ̀lé mi, nítorí Olúwa ti fi Moabu ọ̀tá yín lé yín lọ́wọ́.” Wọ́n sì tẹ̀lé e, wọ́n sì gba ìwọdò Jordani tí ó lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọn ò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kọjá.
Un viņš uz tiem sacīja: steidzaties man pakaļ, jo Tas Kungs devis jūsu rokā jūsu ienaidniekus, tos Moabiešus. Un tie nogāja viņam pakaļ un uzņēma Jardānes pārejamo vietu, kas pret Moabu, un nevienu nelaida pāri.
29 Ní báyìí, wọ́n ti pa tó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ará Moabu tí wọ́n jẹ́ alágbára àti onígboyà ènìyàn, kò sí ènìyàn tí ó sálà.
Un tie kāva no Moabiešiem tanī laikā kādus desmit tūkstoš vīrus, visus brangus un visus stiprus, ka neviens neizspruka.
30 Ní ọjọ́ náà ni Israẹli ṣẹ́gun àwọn ará Moabu, ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ọgọ́rin ọdún.
Tad Moabs tai dienā tapa pazemots apakš Israēla bērnu rokas, un zemei bija miers astoņdesmit gadus.
31 Lẹ́yìn Ehudu, ni Ṣamgari ọmọ Anati ẹni tí ó pa ẹgbẹ̀ta Filistini pẹ̀lú ọ̀pá tí a fi ń da akọ màlúù, òun pẹ̀lú sì gba Israẹli kúrò nínú ìpọ́njú.
Un pēc viņa bija Zamgars, Anata dēls, tas kāva no Fīlistiem sešsimt vīrus ar vēršu dzenamo. Tā viņš arīdzan Israēli izpestīja.

< Judges 3 >