< Judges 3 >
1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa fi sílẹ̀ láti dán àwọn ìran tuntun ní Israẹli wò, àwọn ìran tí kò ì tí ì ní ìrírí ogun àwọn ará Kenaani.
Ezek pedig a pogányok, a kiket meghagyott az Úr, hogy azok által kísértse Izráelt, azokat a kik nem ismerték a Kanaánért való harczokat,
2 (Ó ṣe èyí láti fi kọ́ àwọn ìran Israẹli tí kò rí ogun rí níbí a ti ṣe ń jagun).
Csak azért, hogy az Izráel fiainak nemzetségei megismerjék, hogy tanítsa őket hadakozásra, csak azokat, a kik azelőtt ezt nem tudták:
3 Àwọn ìjòyè ìlú Filistini márààrún, gbogbo àwọn ará Kenaani, àwọn ará Sidoni, àti àwọn ará Hifi tí ń gbé ní àwọn òkè Lebanoni bẹ̀rẹ̀ láti òkè Baali-Hermoni títí dé Lebo-Hamati.
A Filiszteusok öt fejedelemsége, a Kananeusok mindnyájan, és a Sidoniusok, meg a Khivveusok, a kik a Libánon hegyén laknak, a Baálhermon hegyétől fogva Hamath bemeneteléig.
4 A fi àwọn ènìyàn náà sílẹ̀ láti dán àwọn Israẹli wò bóyá wọn yóò gbọ́rọ̀ sí àwọn òfin Olúwa, èyí tí ó ti fi fún àwọn baba wọn láti ipasẹ̀ Mose.
Kik azért hagyattak meg, hogy megkísértse általok az Úr Izráelt, hogy meglássa, vajjon engedelmeskednek-é az Úr parancsolatainak melyeket parancsolt az ő atyáiknak Mózes által?
5 Àwọn ọmọ Israẹli gbé láàrín àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti àwọn ará Amori, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi.
Így az Izráel fiai a Kananeusok, Khitteusok, Emoreusok, Perizeusok, Khivveusok és Jebuzeusok között laktak,
6 Dípò kí wọ́n run àwọn ènìyàn wọ̀nyí, Israẹli ń fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n sì ń fi àwọn ọmọbìnrin Israẹli fún àwọn ará ilẹ̀ náà ní aya, wọ́n sì ń sin àwọn òrìṣà wọn.
És azok leányait vették magoknak feleségül, a saját leányaikat pedig oda adták azok fiainak, és szolgálák azoknak isteneit.
7 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe èyí tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń sin Baali àti Aṣerah.
És gonoszul cselekedtek az Izráel fiai az Úr szemei előtt, és elfelejtkezének az Úrról, az ő Istenökről, és a Baáloknak és Aseráknak szolgáltak.
8 Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ kí Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu-Naharaimu bá wọn jà kí ó sì ṣẹ́gun wọn, Israẹli sì ṣe ẹrú rẹ̀ fún ọdún mẹ́jọ.
Ezért felgerjedett az Úrnak haragja az Izráel ellen, és adá őket Kusán-Risathaimnak, Mesopotámia királyának kezébe, és nyolcz évig szolgáltak az Izráel fiai Kusán-Risathaimnak.
9 Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli kígbe sí Olúwa, Òun gbé olùgbàlà kan dìde fún wọn, ẹni náà ni Otnieli ọmọ Kenasi àbúrò Kalebu tí ó jẹ́ ọkùnrin, ẹni tí ó gbà wọ́n sílẹ̀.
Ekkor az Úrhoz kiáltának az Izráel fiai, és az Úr szabadítót támasztott az Izráel fiainak, aki megszabadítá őket: Othnielt, Kénáz fiát, Káleb öcscsét.
10 Ẹ̀mí Olúwa bà lé e, òun sì ṣe ìdájọ́ Israẹli, ó sì síwájú wọn lọ sí ogun. Olúwa sì fi Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu lé Otnieli lọ́wọ́, ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ sì borí Kuṣani-Riṣataimu.
És az Úrnak lelke vala ő rajta, és biráskodott Izráelben, és a mint kiméne a hadra, az Úr kezébe adta Kusán-Risathaimot, Mesopotámia királyát, és ránehezült keze Kusán-Risathaimra.
11 Ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún títí tí Otnieli ọmọ Kenasi sì kú.
És megnyugovék a föld negyven esztendeig, és meghalt Othniel, a Kénáz fia.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sì tún padà sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn, wọ́n sì ṣe èyí tí ó burú ní iwájú Olúwa, fún ìdí iṣẹ́ búburú yìí, Olúwa fún Egloni, ọba àwọn Moabu ní agbára ní orí Israẹli.
De az Izráel fiai ismét gonoszul cselekedének az Úr szemei előtt, és megerősítette az Úr Eglont, Moáb királyát Izráel ellen, azért, mert gonoszul cselekedtek az Úrnak szemei előtt.
13 Pẹ̀lú ìfi ọwọ́ ṣowọ́pọ̀ ogun àwọn Ammoni àti àwọn ọmọ-ogun Amaleki ní Egloni gbógun ti àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì gba ìlú Ọ̀pẹ tí i se Jeriko.
Ez magához gyűjtötte Ammonnak és Amáleknek fiait, és elment, és megverte Izráelt, és elfoglalták a pálmák városát.
14 Àwọn ọmọ Israẹli sì sin Egloni ọba Moabu fún ọdún méjìdínlógún.
És szolgálák az Izráel fiai Eglont, a Moáb királyát tizennyolcz esztendeig.
15 Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli tún ké pe Olúwa, Olúwa rán olùgbàlà kan sí wọn, Ehudu ẹni tí ń lo ọwọ́ òsì, ọmọ Gera ti ẹ̀yà Benjamini. Àwọn ọmọ Israẹli fi ẹ̀bùn rán sí Egloni ọba Moabu.
Ekkor megint az Úrhoz kiáltottak Izráel fiai, és az Úr szabadítót támasztott nékik: Ehudot, Gérának fiát, ki Jemininek volt a fia, a ki suta volt. És mikor az Izráel fiai ajándékot küldének általa Eglonnak, Moáb királyának,
16 Ehudu sì rọ idà kan olójú méjì, ìgbọ̀nwọ́ kan ní gígùn; òun sì sán an ní abẹ́ aṣọ rẹ̀ ní itan rẹ̀ ọ̀tún.
Ehud szerze magának egy kétélű kardot, egy singnyi hosszút, és azt az ő ruhája alatt a jobb tomporára övezé.
17 Ó sì mú ọrẹ náà wá fún Egloni ọba Moabu, Egloni ẹni tí ó sanra púpọ̀.
És bemutatá az ajándékot Eglonnak, Moáb királyának. Eglon pedig igen kövér ember vala.
18 Lẹ́yìn tí Ehudu ti fi ẹ̀bùn náà fún ọba tan, ó rán àwọn tí ó kó ẹrú náà wá lọ sí ọ̀nà wọn.
És lőn, hogy mikor elvégezé az ajándék bemutatását, elbocsátá az embereket, a kik az ajándékot vitték vala.
19 Ṣùgbọ́n nígbà tí òun fúnra rẹ̀ dé ibi ère fínfín tí ó wà létí Gilgali, ó padà sí Egloni, ó sì wí pé, “Ọba, mo ní ọ̀rọ̀ àṣírí láti bá ọ sọ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ dákẹ́!” Gbogbo àwọn tí ń ṣọ sì jáde síta kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Ő maga pedig visszatért a Gilgál közelében lévő kőbányáktól és monda: Titkos beszédem van veled, óh király! És ez monda: Hallgass! és kimenének előle mindnyájan, kik állanak vala körülötte.
20 Ehudu lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ níbi tí ó ti jókòó ní iyàrá ìtura rẹ̀, Ehudu sì wí fún un pé, “Mo ní ọ̀rọ̀ kan fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.” Bí ọba sì ti dìde ní orí ìtẹ́ rẹ̀,
És Ehud akkor ment be hozzá, mikor épen az ő hűsölő felházában ült magányosan, és monda Ehud néki: Istennek beszéde van nálam te hozzád. És fölkele az a királyi székből.
21 Ehudu fi ọwọ́ òsì rẹ̀ yọ idà láti ibi itan ọ̀tún rẹ̀ ó sì fi gún ọba nínú ikùn rẹ̀.
Akkor kinyújtá Ehud az ő balkezét, és kirántá kardját a jobb tomporáról, és beleüté azt annak hasába.
22 Àti idà àti èèkù rẹ̀ sì wọlé ó sì yọ ní ẹ̀yìn rẹ̀. Ehudu kò yọ idà náà, ọ̀rá sì bo idà náà.
És beméne még a markolatja is a vasa után és berekeszté a háj a fegyver vasát, mert nem vonta ki a kardot annak hasából, sőt átment annak vékonyán.
23 Ehudu ti àwọn ìlẹ̀kùn ní àtì-sínú òun sì bá yàrá òkè jáde, ó sì sálọ.
Általméne pedig Ehud a csarnokon, minekutána bevonta maga után a felház ajtait, és bezárta.
24 Lẹ́yìn tí ó ti lọ àwọn ìránṣẹ́ ọba dé, ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ìlẹ̀kùn yàrá òkè ní títì, wọ́n rò pé, “Bóyá ó wà ní ilé ìyàgbẹ́ ní yàrá nínú ilé.”
A mint ő kiméne, jövének annak szolgái, és láták, hogy ímé a felház ajtai be vannak zárva, és mondának: Bizonyára szükségét végzi a hűsölő kamarájában.
25 Nígbà tí wọ́n dúró dé ibi pé ó jẹ́ ìyanu fún wọn, wọ́n mú kọ́kọ́rọ́, wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn. Níbẹ̀ ni wọ́n ti rí Olúwa wọn tí ó ti ṣubú, ó sì ti kú.
De mikor váltig várakoztak és ímé nem nyitotta meg a felház ajtaját, fogák a kulcsot és megnyiták: és ímé az ő urok ott feküdt a földön halva.
26 Nígbà tí wọ́n dúró tí wọn sì ń retí, Ehudu ti sálọ. Ó ti gba ibi tí wọ́n ti ń gbẹ́ òkúta lére, ó sì sálọ sí Seira.
Ehud pedig elmenekült vala, míg azok késedelmezének, és elhaladván a kőbányák mellett, Szeiráhba futott.
27 Nígbà tí ó dé ibẹ̀, ó fọn ìpè ní orí òkè Efraimu, àwọn ọmọ Israẹli sì ba sọ̀kalẹ̀ lọ láti òkè náà wá, òun sì wà níwájú wọn.
És a mikor oda megérkezett, kürtjébe fújt az Efraim hegyén, és alámenének ő vele az Izráel fiai a hegyről, és ő előttük.
28 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa tẹ̀lé mi, nítorí Olúwa ti fi Moabu ọ̀tá yín lé yín lọ́wọ́.” Wọ́n sì tẹ̀lé e, wọ́n sì gba ìwọdò Jordani tí ó lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọn ò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kọjá.
És monda nékik: Jertek utánam, mert kezetekbe adta az Úr a ti ellenségeteket, Moábot. És levonultak ő utána, és elfoglalák a Jordán réveit, melyek Moáb felé vezettek, és nem engedtek azokon senkit általkelni.
29 Ní báyìí, wọ́n ti pa tó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ará Moabu tí wọ́n jẹ́ alágbára àti onígboyà ènìyàn, kò sí ènìyàn tí ó sálà.
És leöltek a Moábiták közül akkor mintegy tízezer embert, mind erős és vitéz férfiakat, úgy hogy egy sem menekült el.
30 Ní ọjọ́ náà ni Israẹli ṣẹ́gun àwọn ará Moabu, ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ọgọ́rin ọdún.
Így aláztatott meg Moáb abban az időben Izráel keze alatt. És megnyugovék a föld nyolczvan esztendeig.
31 Lẹ́yìn Ehudu, ni Ṣamgari ọmọ Anati ẹni tí ó pa ẹgbẹ̀ta Filistini pẹ̀lú ọ̀pá tí a fi ń da akọ màlúù, òun pẹ̀lú sì gba Israẹli kúrò nínú ìpọ́njú.
Ő utána pedig Sámgár, Anáthnak fia volt bíró, a ki hatszáz Filiszteus férfiút ölt meg egy ökörösztökével, és megszabadítá ő is Izráelt.