< Judges 3 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa fi sílẹ̀ láti dán àwọn ìran tuntun ní Israẹli wò, àwọn ìran tí kò ì tí ì ní ìrírí ogun àwọn ará Kenaani.
Or ce sont ici les nations que l'Eternel laissa pour éprouver par elles Israël, [savoir] tous ceux qui n'avaient point eu connaissance de toutes les guerres de Canaan;
2 (Ó ṣe èyí láti fi kọ́ àwọn ìran Israẹli tí kò rí ogun rí níbí a ti ṣe ń jagun).
Afin qu'au moins les générations des enfants d'Israël sussent et apprissent ce que c'est que la guerre; au moins ceux qui auparavant n'en avaient rien connu.
3 Àwọn ìjòyè ìlú Filistini márààrún, gbogbo àwọn ará Kenaani, àwọn ará Sidoni, àti àwọn ará Hifi tí ń gbé ní àwọn òkè Lebanoni bẹ̀rẹ̀ láti òkè Baali-Hermoni títí dé Lebo-Hamati.
[Ces nations donc furent] les cinq Gouvernements des Philistins, et tous les Cananéens, les Sidoniens, et les Héviens, qui habitaient en la montagne du Liban, depuis la montagne de Bahal-hermon, jusqu'à l'entrée de Hamath.
4 A fi àwọn ènìyàn náà sílẹ̀ láti dán àwọn Israẹli wò bóyá wọn yóò gbọ́rọ̀ sí àwọn òfin Olúwa, èyí tí ó ti fi fún àwọn baba wọn láti ipasẹ̀ Mose.
[Ces nations], dis-je, servirent à éprouver Israël, pour voir s'ils obéiraient aux commandements de l'Eternel, lesquels il avait donnés à leurs pères par le moyen de Moïse.
5 Àwọn ọmọ Israẹli gbé láàrín àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti àwọn ará Amori, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi.
Ainsi les enfants d'Israël habitèrent parmi les Cananéens, les Héthiens, les Amorrhéens, les Phérésiens, les Héviens, et les Jébusiens.
6 Dípò kí wọ́n run àwọn ènìyàn wọ̀nyí, Israẹli ń fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n sì ń fi àwọn ọmọbìnrin Israẹli fún àwọn ará ilẹ̀ náà ní aya, wọ́n sì ń sin àwọn òrìṣà wọn.
Et ils prirent leurs filles pour femmes, et ils donnèrent leurs filles à leurs fils, et servirent leurs dieux.
7 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe èyí tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń sin Baali àti Aṣerah.
Les enfants d'Israël firent donc ce qui déplaît à l'Eternel; ils oublièrent l'Eternel leur Dieu, et servirent les Bahalins, et les bocages.
8 Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ kí Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu-Naharaimu bá wọn jà kí ó sì ṣẹ́gun wọn, Israẹli sì ṣe ẹrú rẹ̀ fún ọdún mẹ́jọ.
C'est pourquoi la colère de l'Eternel s'enflamma contre Israël, et il les vendit en la main de Cusan-rischathajim, Roi de Mésopotamie. Et les enfants d'Israël furent asservis à Cusan-rischathajim huit ans.
9 Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli kígbe sí Olúwa, Òun gbé olùgbàlà kan dìde fún wọn, ẹni náà ni Otnieli ọmọ Kenasi àbúrò Kalebu tí ó jẹ́ ọkùnrin, ẹni tí ó gbà wọ́n sílẹ̀.
Puis les enfants d'Israël crièrent à l'Eternel, et l'Eternel leur suscita un Libérateur qui les délivra, [savoir] Hothniël, fils de Kénas, frère puîné de Caleb.
10 Ẹ̀mí Olúwa bà lé e, òun sì ṣe ìdájọ́ Israẹli, ó sì síwájú wọn lọ sí ogun. Olúwa sì fi Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu lé Otnieli lọ́wọ́, ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ sì borí Kuṣani-Riṣataimu.
Et l'Esprit de l'Eternel fut sur lui, et il jugea Israël, et sortit en bataille, et l'Eternel livra entre ses mains Cusan-rischathajim, Roi d'Aram; et sa main fut fortifiée contre Cusan-rischathajim.
11 Ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún títí tí Otnieli ọmọ Kenasi sì kú.
Et le pays fut en repos quarante ans. Puis Hothniel, fils de Kénas, mourut.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sì tún padà sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn, wọ́n sì ṣe èyí tí ó burú ní iwájú Olúwa, fún ìdí iṣẹ́ búburú yìí, Olúwa fún Egloni, ọba àwọn Moabu ní agbára ní orí Israẹli.
Et les enfants d'Israël se mirent encore à faire ce qui déplaît à l'Eternel; et l'Eternel fortifia Héglon, Roi de Moab, contre Israël, parce qu'ils avaient fait ce qui déplaît à l'Eternel.
13 Pẹ̀lú ìfi ọwọ́ ṣowọ́pọ̀ ogun àwọn Ammoni àti àwọn ọmọ-ogun Amaleki ní Egloni gbógun ti àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì gba ìlú Ọ̀pẹ tí i se Jeriko.
Et [Héglon] assembla auprès de lui les enfants d'Hammon et d'Hamalec, et il alla, et frappa Israël, et ils s'emparèrent de la ville des palmes.
14 Àwọn ọmọ Israẹli sì sin Egloni ọba Moabu fún ọdún méjìdínlógún.
Et les enfants d'Israël furent asservis à Héglon, Roi de Moab, dix-huit ans.
15 Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli tún ké pe Olúwa, Olúwa rán olùgbàlà kan sí wọn, Ehudu ẹni tí ń lo ọwọ́ òsì, ọmọ Gera ti ẹ̀yà Benjamini. Àwọn ọmọ Israẹli fi ẹ̀bùn rán sí Egloni ọba Moabu.
Puis les enfants d'Israël crièrent à l'Eternel, et l'Eternel leur suscita un Libérateur, [savoir] Ehud, fils de Guéra Benjamite, duquel la main droite était serrée. Et les enfants d'Israël envoyèrent par lui un présent à Héglon, Roi de Moab.
16 Ehudu sì rọ idà kan olójú méjì, ìgbọ̀nwọ́ kan ní gígùn; òun sì sán an ní abẹ́ aṣọ rẹ̀ ní itan rẹ̀ ọ̀tún.
Or Ehud s'était fait une épée à deux tranchants, de la longueur d'une coudée, qu'il avait ceinte sous ses vêtements sur sa cuisse droite.
17 Ó sì mú ọrẹ náà wá fún Egloni ọba Moabu, Egloni ẹni tí ó sanra púpọ̀.
Et il présenta le don à Héglon, Roi de Moab; et Héglon était un homme fort gras.
18 Lẹ́yìn tí Ehudu ti fi ẹ̀bùn náà fún ọba tan, ó rán àwọn tí ó kó ẹrú náà wá lọ sí ọ̀nà wọn.
Or il arriva que quand il eut achevé de présenter le don, il reconduisit le peuple qui avait apporté le don.
19 Ṣùgbọ́n nígbà tí òun fúnra rẹ̀ dé ibi ère fínfín tí ó wà létí Gilgali, ó padà sí Egloni, ó sì wí pé, “Ọba, mo ní ọ̀rọ̀ àṣírí láti bá ọ sọ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ dákẹ́!” Gbogbo àwọn tí ń ṣọ sì jáde síta kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Mais [Ehud] s'en étant retourné depuis les carrières de pierre, qui [étaient] vers Guilgal, il dit: Ô Roi! j'ai à te dire quelque chose en secret. Et il lui répondit: Tais-toi, et tous ceux qui étaient auprès de lui, sortirent de là.
20 Ehudu lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ níbi tí ó ti jókòó ní iyàrá ìtura rẹ̀, Ehudu sì wí fún un pé, “Mo ní ọ̀rọ̀ kan fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.” Bí ọba sì ti dìde ní orí ìtẹ́ rẹ̀,
Et Ehud s'approchant de lui, qui était assis seul dans sa chambre d'Eté, il lui dit: J'ai un mot à te dire de la part de Dieu. Alors [le Roi] se leva du trône.
21 Ehudu fi ọwọ́ òsì rẹ̀ yọ idà láti ibi itan ọ̀tún rẹ̀ ó sì fi gún ọba nínú ikùn rẹ̀.
Et Ehud avançant sa main gauche, prit l'épée de dessus sa cuisse droite, et la lui enfonça dans le ventre;
22 Àti idà àti èèkù rẹ̀ sì wọlé ó sì yọ ní ẹ̀yìn rẹ̀. Ehudu kò yọ idà náà, ọ̀rá sì bo idà náà.
Et la poignée entra après la lame, et la graisse serra tellement la lame, qu'il ne pouvait tirer l'épée du ventre; et il en sortit de la fiente.
23 Ehudu ti àwọn ìlẹ̀kùn ní àtì-sínú òun sì bá yàrá òkè jáde, ó sì sálọ.
Après cela Ehud sortit par le porche, fermant après soi les portes de la chambre, laquelle il ferma à la clef.
24 Lẹ́yìn tí ó ti lọ àwọn ìránṣẹ́ ọba dé, ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ìlẹ̀kùn yàrá òkè ní títì, wọ́n rò pé, “Bóyá ó wà ní ilé ìyàgbẹ́ ní yàrá nínú ilé.”
Ainsi il sortit; et les serviteurs d'Héglon vinrent, et regardèrent, et voilà, les portes de la chambre étaient fermées à la clef; et ils dirent: Sans doute il est à ses affaires dans sa chambre d'Eté.
25 Nígbà tí wọ́n dúró dé ibi pé ó jẹ́ ìyanu fún wọn, wọ́n mú kọ́kọ́rọ́, wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn. Níbẹ̀ ni wọ́n ti rí Olúwa wọn tí ó ti ṣubú, ó sì ti kú.
Et ils attendirent tant qu'ils en furent honteux; et voyant qu'il n'ouvrait point les portes de la chambre, ils prirent la clef, et l'ouvrirent; et voici, leur Seigneur était étendu mort à terre.
26 Nígbà tí wọ́n dúró tí wọn sì ń retí, Ehudu ti sálọ. Ó ti gba ibi tí wọ́n ti ń gbẹ́ òkúta lére, ó sì sálọ sí Seira.
Mais Ehud échappa tandis qu'ils s'amusaient, et passa les carrières de pierre, et se sauva à Séhira.
27 Nígbà tí ó dé ibẹ̀, ó fọn ìpè ní orí òkè Efraimu, àwọn ọmọ Israẹli sì ba sọ̀kalẹ̀ lọ láti òkè náà wá, òun sì wà níwájú wọn.
Et quand il y fut entré, il sonna de la trompette en la montagne d'Ephraïm, et les enfants d'Israël descendirent avec lui en la montagne; et il marchait devant eux.
28 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa tẹ̀lé mi, nítorí Olúwa ti fi Moabu ọ̀tá yín lé yín lọ́wọ́.” Wọ́n sì tẹ̀lé e, wọ́n sì gba ìwọdò Jordani tí ó lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọn ò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kọjá.
Et il leur dit: Suivez-moi, car l'Eternel a livré entre vos mains les Moabites vos ennemis. Ainsi ils descendirent après lui, et se saisissant des passages du Jourdain contre les Moabites, ils ne laissèrent passer personne.
29 Ní báyìí, wọ́n ti pa tó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ará Moabu tí wọ́n jẹ́ alágbára àti onígboyà ènìyàn, kò sí ènìyàn tí ó sálà.
Et en ce temps-là ils frappèrent des Moabites environ dix mille hommes, tous en bon état, et tous vaillants, et il n'en échappa aucun.
30 Ní ọjọ́ náà ni Israẹli ṣẹ́gun àwọn ará Moabu, ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ọgọ́rin ọdún.
En ce jour-là donc Moab fut humilié sous la main d'Israël; et le pays fut en repos quatre-vingts ans.
31 Lẹ́yìn Ehudu, ni Ṣamgari ọmọ Anati ẹni tí ó pa ẹgbẹ̀ta Filistini pẹ̀lú ọ̀pá tí a fi ń da akọ màlúù, òun pẹ̀lú sì gba Israẹli kúrò nínú ìpọ́njú.
Et après lui fut [en sa place] Samgar, fils d'Hanath, qui frappa six cents Philistins avec un aiguillon à bœufs, et qui délivra Israël.

< Judges 3 >