< Judges 3 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa fi sílẹ̀ láti dán àwọn ìran tuntun ní Israẹli wò, àwọn ìran tí kò ì tí ì ní ìrírí ogun àwọn ará Kenaani.
Voici les nations que l'Éternel laissa pour mettre Israël à l'épreuve par elles, tous ceux qui n'avaient pas connu toutes les guerres de Canaan,
2 (Ó ṣe èyí láti fi kọ́ àwọn ìran Israẹli tí kò rí ogun rí níbí a ti ṣe ń jagun).
afin que les générations des enfants d'Israël le sachent, pour leur apprendre la guerre, du moins à ceux qui ne l'avaient pas connue auparavant:
3 Àwọn ìjòyè ìlú Filistini márààrún, gbogbo àwọn ará Kenaani, àwọn ará Sidoni, àti àwọn ará Hifi tí ń gbé ní àwọn òkè Lebanoni bẹ̀rẹ̀ láti òkè Baali-Hermoni títí dé Lebo-Hamati.
les cinq princes des Philistins, tous les Cananéens, les Sidoniens et les Héviens qui habitaient la montagne du Liban, depuis la montagne de Baal Hermon jusqu'à l'entrée de Hamath.
4 A fi àwọn ènìyàn náà sílẹ̀ láti dán àwọn Israẹli wò bóyá wọn yóò gbọ́rọ̀ sí àwọn òfin Olúwa, èyí tí ó ti fi fún àwọn baba wọn láti ipasẹ̀ Mose.
On les laissa pour éprouver Israël par eux, afin de savoir s'ils écouteraient les commandements de l'Éternel, qu'il avait prescrits à leurs pères par Moïse.
5 Àwọn ọmọ Israẹli gbé láàrín àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti àwọn ará Amori, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi.
Les enfants d'Israël habitaient parmi les Cananéens, les Hittites, les Amorites, les Perizzites, les Hivvites et les Jébusites.
6 Dípò kí wọ́n run àwọn ènìyàn wọ̀nyí, Israẹli ń fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n sì ń fi àwọn ọmọbìnrin Israẹli fún àwọn ará ilẹ̀ náà ní aya, wọ́n sì ń sin àwọn òrìṣà wọn.
Ils prirent leurs filles pour femmes, donnèrent leurs propres filles à leurs fils et servirent leurs dieux.
7 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe èyí tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń sin Baali àti Aṣerah.
Les enfants d'Israël firent ce qui est mal aux yeux de l'Éternel, ils oublièrent l'Éternel, leur Dieu, et servirent les Baals et les Ashéroths.
8 Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ kí Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu-Naharaimu bá wọn jà kí ó sì ṣẹ́gun wọn, Israẹli sì ṣe ẹrú rẹ̀ fún ọdún mẹ́jọ.
La colère de l'Éternel s'enflamma contre Israël, et il les vendit entre les mains de Cushan Rishathaim, roi de Mésopotamie; les enfants d'Israël furent au service de Cushan Rishathaim pendant huit ans.
9 Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli kígbe sí Olúwa, Òun gbé olùgbàlà kan dìde fún wọn, ẹni náà ni Otnieli ọmọ Kenasi àbúrò Kalebu tí ó jẹ́ ọkùnrin, ẹni tí ó gbà wọ́n sílẹ̀.
Lorsque les enfants d'Israël crièrent à l'Éternel, l'Éternel suscita aux enfants d'Israël un sauveur qui les sauva, Othniel, fils de Kenaz, frère cadet de Caleb.
10 Ẹ̀mí Olúwa bà lé e, òun sì ṣe ìdájọ́ Israẹli, ó sì síwájú wọn lọ sí ogun. Olúwa sì fi Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu lé Otnieli lọ́wọ́, ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ sì borí Kuṣani-Riṣataimu.
L'Esprit de Yahvé descendit sur lui, et il jugea Israël. Il partit en guerre, et Yahvé livra entre ses mains Cushan Rishathaim, roi de Mésopotamie. Sa main l'emporta sur Cushan Rishathaim.
11 Ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún títí tí Otnieli ọmọ Kenasi sì kú.
Le pays fut en repos pendant quarante ans, puis Othniel, fils de Kenaz, mourut.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sì tún padà sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn, wọ́n sì ṣe èyí tí ó burú ní iwájú Olúwa, fún ìdí iṣẹ́ búburú yìí, Olúwa fún Egloni, ọba àwọn Moabu ní agbára ní orí Israẹli.
Les enfants d'Israël firent encore ce qui est mal aux yeux de l'Éternel, et l'Éternel fortifia Églon, roi de Moab, contre Israël, parce qu'ils avaient fait ce qui est mal aux yeux de l'Éternel.
13 Pẹ̀lú ìfi ọwọ́ ṣowọ́pọ̀ ogun àwọn Ammoni àti àwọn ọmọ-ogun Amaleki ní Egloni gbógun ti àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì gba ìlú Ọ̀pẹ tí i se Jeriko.
Il rassembla à lui les fils d'Ammon et d'Amalek, et il alla frapper Israël, et ils possédèrent la ville des palmiers.
14 Àwọn ọmọ Israẹli sì sin Egloni ọba Moabu fún ọdún méjìdínlógún.
Les enfants d'Israël servirent Églon, roi de Moab, pendant dix-huit ans.
15 Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli tún ké pe Olúwa, Olúwa rán olùgbàlà kan sí wọn, Ehudu ẹni tí ń lo ọwọ́ òsì, ọmọ Gera ti ẹ̀yà Benjamini. Àwọn ọmọ Israẹli fi ẹ̀bùn rán sí Egloni ọba Moabu.
Mais lorsque les enfants d'Israël crièrent à Yahvé, Yahvé leur suscita un sauveur: Ehud, fils de Gera, le Benjamite, un gaucher. Les enfants d'Israël envoyèrent par lui un tribut à Eglon, roi de Moab.
16 Ehudu sì rọ idà kan olójú méjì, ìgbọ̀nwọ́ kan ní gígùn; òun sì sán an ní abẹ́ aṣọ rẹ̀ ní itan rẹ̀ ọ̀tún.
Ehud se fabriqua une épée à deux tranchants, longue d'une coudée, qu'il porta sous ses vêtements, sur sa cuisse droite.
17 Ó sì mú ọrẹ náà wá fún Egloni ọba Moabu, Egloni ẹni tí ó sanra púpọ̀.
Il offrit le tribut à Églon, roi de Moab. Or Églon était un homme très gras.
18 Lẹ́yìn tí Ehudu ti fi ẹ̀bùn náà fún ọba tan, ó rán àwọn tí ó kó ẹrú náà wá lọ sí ọ̀nà wọn.
Quand Ehud eut fini d'offrir le tribut, il renvoya les gens qui portaient le tribut.
19 Ṣùgbọ́n nígbà tí òun fúnra rẹ̀ dé ibi ère fínfín tí ó wà létí Gilgali, ó padà sí Egloni, ó sì wí pé, “Ọba, mo ní ọ̀rọ̀ àṣírí láti bá ọ sọ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ dákẹ́!” Gbogbo àwọn tí ń ṣọ sì jáde síta kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Mais lui-même s'éloigna des idoles de pierre qui se trouvaient près de Gilgal et dit: « J'ai un message secret pour toi, ô roi. » Le roi dit: « Tais-toi! » Tous ceux qui se tenaient près de lui le quittèrent.
20 Ehudu lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ níbi tí ó ti jókòó ní iyàrá ìtura rẹ̀, Ehudu sì wí fún un pé, “Mo ní ọ̀rọ̀ kan fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.” Bí ọba sì ti dìde ní orí ìtẹ́ rẹ̀,
Ehud vint le trouver, et il était assis seul dans la chambre haute et fraîche. Ehud dit: « J'ai un message de Dieu pour toi. » Il se leva de son siège.
21 Ehudu fi ọwọ́ òsì rẹ̀ yọ idà láti ibi itan ọ̀tún rẹ̀ ó sì fi gún ọba nínú ikùn rẹ̀.
Ehud étendit sa main gauche, prit l'épée de sa cuisse droite et se la planta dans le corps.
22 Àti idà àti èèkù rẹ̀ sì wọlé ó sì yọ ní ẹ̀yìn rẹ̀. Ehudu kò yọ idà náà, ọ̀rá sì bo idà náà.
La poignée entra aussi après la lame; et la graisse se referma sur la lame, car il n'avait pas retiré l'épée de son corps; et elle sortit par derrière.
23 Ehudu ti àwọn ìlẹ̀kùn ní àtì-sínú òun sì bá yàrá òkè jáde, ó sì sálọ.
Ehud sortit sur le portique, ferma sur lui les portes de la chambre haute et les verrouilla.
24 Lẹ́yìn tí ó ti lọ àwọn ìránṣẹ́ ọba dé, ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ìlẹ̀kùn yàrá òkè ní títì, wọ́n rò pé, “Bóyá ó wà ní ilé ìyàgbẹ́ ní yàrá nínú ilé.”
Après qu'il fut parti, ses serviteurs vinrent et virent que les portes de la chambre haute étaient fermées. Ils dirent: « Il est sûrement en train de se couvrir les pieds dans la chambre haute. »
25 Nígbà tí wọ́n dúró dé ibi pé ó jẹ́ ìyanu fún wọn, wọ́n mú kọ́kọ́rọ́, wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn. Níbẹ̀ ni wọ́n ti rí Olúwa wọn tí ó ti ṣubú, ó sì ti kú.
Ils attendirent jusqu'à ce qu'ils aient honte; et voici qu'il n'ouvrait pas les portes de la chambre haute. Ils prirent donc la clé et les ouvrirent, et voici que leur seigneur était tombé mort sur le sol.
26 Nígbà tí wọ́n dúró tí wọn sì ń retí, Ehudu ti sálọ. Ó ti gba ibi tí wọ́n ti ń gbẹ́ òkúta lére, ó sì sálọ sí Seira.
Ehud s'échappa pendant qu'ils attendaient, passa au-delà des idoles de pierre et se sauva à Seirah.
27 Nígbà tí ó dé ibẹ̀, ó fọn ìpè ní orí òkè Efraimu, àwọn ọmọ Israẹli sì ba sọ̀kalẹ̀ lọ láti òkè náà wá, òun sì wà níwájú wọn.
Lorsqu'il fut arrivé, il sonna de la trompette dans la montagne d'Ephraïm; les enfants d'Israël descendirent avec lui de la montagne, et il les conduisit.
28 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa tẹ̀lé mi, nítorí Olúwa ti fi Moabu ọ̀tá yín lé yín lọ́wọ́.” Wọ́n sì tẹ̀lé e, wọ́n sì gba ìwọdò Jordani tí ó lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọn ò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kọjá.
Il leur dit: « Suivez-moi, car Yahvé a livré entre vos mains les Moabites, vos ennemis. » Ils le suivirent et prirent les gués du Jourdain contre les Moabites, et ne permirent à aucun homme de passer.
29 Ní báyìí, wọ́n ti pa tó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ará Moabu tí wọ́n jẹ́ alágbára àti onígboyà ènìyàn, kò sí ènìyàn tí ó sálà.
Ils frappèrent en ce temps-là environ dix mille hommes de Moab, tous les hommes forts et tous les hommes valeureux. Aucun homme n'échappa.
30 Ní ọjọ́ náà ni Israẹli ṣẹ́gun àwọn ará Moabu, ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ọgọ́rin ọdún.
Moab fut donc soumis en ce jour sous la main d'Israël. Et le pays fut en repos pendant quatre-vingts ans.
31 Lẹ́yìn Ehudu, ni Ṣamgari ọmọ Anati ẹni tí ó pa ẹgbẹ̀ta Filistini pẹ̀lú ọ̀pá tí a fi ń da akọ màlúù, òun pẹ̀lú sì gba Israẹli kúrò nínú ìpọ́njú.
Après lui, Shamgar, fils d'Anath, frappa six cents hommes des Philistins avec un aiguillon à bœuf. Il sauva aussi Israël.

< Judges 3 >