< Judges 21 >

1 Àwọn ọkùnrin Israẹli ti búra ní Mispa pé, “Kò sí ẹnìkan nínú wa tí yóò fi ọmọ obìnrin rẹ̀ fún ẹ̀yà Benjamini ní ìyàwó.”
Men Israels män hade svurit i Mispa och sagt: "Ingen av oss skall giva sin dotter till hustru åt någon benjaminit."
2 Àwọn ènìyàn náà lọ sí Beteli: ilé Ọlọ́run, níbi tí wọ́n jókòó níwájú Ọlọ́run títí di àṣálẹ́, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún kíkorò.
Och nu kom folket till Betel och stannade där ända till aftonen inför Guds ansikte; och de brusto ut i bitter gråt
3 Wọ́n sọkún wí pé, “Háà! Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èéṣe tí nǹkan yìí fi ṣẹlẹ̀ sí Israẹli? Èéṣe tí ẹ̀yà kan yóò fi run nínú Israẹli lónìí?”
och sade: "Varför, o HERRE, Israels Gud, har sådant fått ske i Israel, att i dag en hel stam fattas i Israel?"
4 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì àwọn ènìyàn náà mọ pẹpẹ kan wọ́n sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà.
Dagen därefter stod folket bittida upp och byggde där ett altare och offrade brännoffer och tackoffer.
5 Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè wí pé, “Èwo nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti péjọ síwájú Olúwa?” Torí pé wọ́n ti fi ìbúra ńlá búra pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti péjọ níwájú Olúwa ní Mispa pípa ni àwọn yóò pa á.
och Israels barn sade: "Finnes någon bland Israels alla stammar, som icke kom upp till HERREN med den övriga församlingen?" Ty man hade svurit en dyr ed, att den som icke komme upp till HERREN i Mispa skulle straffas med döden.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì banújẹ́ fún àwọn arákùnrin wọn, àwọn ẹ̀yà Benjamini. Wọ́n wí pé, “A ti ké ẹ̀yà kan kúrò lára Israẹli lónìí.”
Och Israels barn ömkade sig över sin broder Benjamin och sade: "Nu har en hel stam blivit borthuggen från Israel.
7 Báwo ni a yóò ṣe rí aya fún àwọn tí ó ṣẹ́kù, nítorí àwa ti fi Olúwa búra láti má fi ọ̀kankan nínú àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya.
Vad skola vi göra för dem som äro kvar, så att de kunna få hustrur? Ty själva hava vi ju svurit vid HERREN att icke åt dem giva hustrur av våra döttrar."
8 Wọ́n sì béèrè wí pé, “Èwo ni nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mispa?” Wọ́n rí i pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó wa láti Jabesi Gileadi tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà.
Och då frågade åter: "Finnes bland Israels stammar någon som icke kom upp till HERREN i Mispa?" Och se, från Jabes i Gilead hade ingen kommit till lägret, till församlingen där.
9 Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkankan láti inú àwọn ará Jabesi Gileadi tí ó wà níbẹ̀.
Ty när folket mönstrades, befanns det att ingen av invånarna i Jabes i Gilead var där.
10 Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá mẹ́fà àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gileadi wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
Då sände menigheten dit tolv tusen av de tappraste männen och bjöd dessa och sade: "Gån åstad och slån invånarna i Jabes i Gilead med svärdsegg, också kvinnor och barn.
11 Wọ́n ní, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe, ẹ pa gbogbo ọkùnrin àti gbogbo obìnrin tí kì í ṣe wúńdíá.”
Ja, detta är vad I skolen göra: allt mankön och alla de kvinnor som hava haft med mankön att skaffa skolen I giva till spillo.
12 Wọ́n rí àwọn irinwó ọ̀dọ́bìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí nínú àwọn olùgbé Jabesi Gileadi, wọ́n sì mú wọn lọ sí ibùdó ní Ṣilo àwọn ará Kenaani.
Men bland invånarna i Jabes i Gilead funno de fyra hundra unga kvinnor som voro jungfrur och icke hade haft med män, med mankön, att skaffa. Dessa förde de då till lägret i Silo i Kanaans land.
13 Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ránṣẹ́ àlàáfíà sí àwọn Benjamini ní ihò àpáta Rimoni.
Sedan sände hela menigheten åstad och underhandlade med de benjaminiter som befunno sig på Rimmons klippa, och tillbjöd dem fred.
14 Àwọn ẹ̀yà Benjamini náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gileadi. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.
Så vände nu Benjamin tillbaka; och man gav dem till hustrur de kvinnor från Jabes i Gilead, som man hade låtit leva. Men dessa räckte ingalunda till för dem.
15 Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Benjamini, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Och folket ömkade sig över Benjamin, eftersom HERREN hade gjort en rämna bland Israels stammar.
16 Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Benjamini run?”
Och de äldste i menigheten sade: "Vad skola vi göra med dem som äro kvar, så att de kunna få hustrur? Ty alla kvinnor äro ju utrotade ur Benjamin."
17 Wọ́n sì wí pé, “Àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n là nínú àwọn ẹ̀yà Benjamini ní láti ní ogún àti àrólé, kí ẹ̀yà kan nínú Israẹli má ṣe di píparun kúrò ní orí ilẹ̀.
Och de sade ytterligare: "De undkomna av Benjamin måste få en besittning, så att icke en stam bliver utplånad ur Israel.
18 Àwa kò le fi àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya, nítorí tí àwa ọmọ Israẹli ti ṣe ìbúra yìí pé, ‘Ègún ni fún ẹnikẹ́ni tí ó fi aya fún ẹnikẹ́ni nínú ẹ̀yà Benjamini.’”
Men själva kunna vi icke åt dem giva hustrur av våra döttrar, ty Israels barn hava svurit och sagt: Förbannad vare den som giver en hustru åt Benjamin."
19 Wọ́n sì wí pé, “Kíyèsi i ayẹyẹ ọlọ́dọọdún fún Olúwa wà ní Ṣilo ní ìhà àríwá Beteli àti ìhà ìlà-oòrùn òpópó náà tí ó gba Beteli kọjá sí Ṣekemu, àti sí ìhà gúúsù Lebona.”
Och de sade vidare: "En HERREN högtid plägar ju hållas år efter år i Silo, som ligger norr om Betel, öster om den väg som går från Betel upp till Sikem, och söder om Lebona."
20 Wọ́n sì fi àṣẹ fún àwọn ará Benjamini pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fi ara pamọ́ nínú àwọn ọgbà àjàrà
Och de bjödo Benjamins barn och sade: "Gån åstad och läggen eder i försåt i vingårdarna.
21 kí ẹ sì wà ní ìmúrasílẹ̀. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin Ṣilo bá jáde láti lọ darapọ̀ fún ijó, kí ẹ yára jáde láti inú àwọn ọgbà àjàrà wọ̀n-ọn-nì kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbé aya kan nínú àwọn ọmọbìnrin Ṣilo kí ẹ padà sí ilẹ̀ Benjamini.
När I då fån se Silos döttrar komma ut för att uppföra sina dansar, skolen I komma fram ur vingårdarna, och var och en av eder skall bland Silos döttrar rycka till sig en som kan bliva hans hustru; därefter skolen I begiva eder hem till Benjamins land.
22 Nígbà tí àwọn baba wọn tàbí àwọn arákùnrin wọn bá fi ẹjọ́ sùn wá, àwa yóò wí fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe wá ní oore nípa ríràn wọ́n lọ́wọ́, nítorí àwa kò rí aya fún wọn ní àkókò ogun, ẹ̀yin kò sì ní jẹ̀bi, nítorí pé ẹ̀yin kọ́ ni ó fi àwọn ọmọbìnrin yín fún wọn bí aya.’”
Om sedan deras fäder eller deras bröder komma och beklaga sig för oss, vilja vi säga till dem: 'Förunnen oss dem; ty ingen av oss har tagit sig någon hustru i kriget. I haven ju då icke själva givit dem åt dessa; ty i sådant fall haden I ådragit eder skuld.'"
23 Èyí sì ni ohun tí àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣe. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin náà ń jó lọ́wọ́, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan mú ọmọbìnrin kọ̀ọ̀kan, wọ́n sì gbé e lọ láti di aya rẹ̀. Wọ́n sì padà sí ilẹ̀ ìní wọn, wọ́n sì tún àwọn ìlú náà kọ́, wọ́n sì tẹ̀dó sínú wọn.
Och Benjamins barn gjorde så och skaffade sig hustrur, lika många som de själva voro, bland de dansande kvinnor som de rövade. Sedan begåvo de sig tillbaka till sin arvedel och byggde åter upp städerna och bosatte sig i dem.
24 Ní àkókò náà, àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ibẹ̀, wọ́n lọ sí ilé àti ẹ̀yà rẹ̀ olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
Också de övriga israeliterna begåvo sig bort därifrån, var och en till sin stam och sin släkt, och drogo ut därifrån, var och en till sin arvedel.
25 Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, kò sí ọba ní ilẹ̀ Israẹli; olúkúlùkù sì ń ṣe bí ó ti tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
På den tiden fanns ingen konung i Israel; var och en gjorde vad honom behagade.

< Judges 21 >