< Judges 21 >
1 Àwọn ọkùnrin Israẹli ti búra ní Mispa pé, “Kò sí ẹnìkan nínú wa tí yóò fi ọmọ obìnrin rẹ̀ fún ẹ̀yà Benjamini ní ìyàwó.”
Agora os homens de Israel haviam jurado em Mizpah, dizendo: “Nenhum de nós dará sua filha a Benjamin como esposa”.
2 Àwọn ènìyàn náà lọ sí Beteli: ilé Ọlọ́run, níbi tí wọ́n jókòó níwájú Ọlọ́run títí di àṣálẹ́, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún kíkorò.
O povo veio a Betel e sentou-se lá até a noite diante de Deus, e levantou a voz, e chorou severamente.
3 Wọ́n sọkún wí pé, “Háà! Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èéṣe tí nǹkan yìí fi ṣẹlẹ̀ sí Israẹli? Èéṣe tí ẹ̀yà kan yóò fi run nínú Israẹli lónìí?”
Eles disseram: “Yahweh, o Deus de Israel, por que isso aconteceu em Israel, que deveria faltar uma tribo em Israel hoje?
4 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì àwọn ènìyàn náà mọ pẹpẹ kan wọ́n sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà.
No dia seguinte, o povo levantou-se cedo e construiu ali um altar, e ofereceu holocaustos e ofertas de paz.
5 Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè wí pé, “Èwo nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti péjọ síwájú Olúwa?” Torí pé wọ́n ti fi ìbúra ńlá búra pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti péjọ níwájú Olúwa ní Mispa pípa ni àwọn yóò pa á.
As crianças de Israel disseram: “Quem está lá entre todas as tribos de Israel que não subiram à assembléia para Yahweh? Pois tinham feito um grande juramento a respeito daquele que não subiu a Iavé a Mizpá, dizendo: “Ele certamente será morto”.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì banújẹ́ fún àwọn arákùnrin wọn, àwọn ẹ̀yà Benjamini. Wọ́n wí pé, “A ti ké ẹ̀yà kan kúrò lára Israẹli lónìí.”
Os filhos de Israel choraram por Benjamim, seu irmão, e disseram: “Há uma tribo isolada de Israel hoje.
7 Báwo ni a yóò ṣe rí aya fún àwọn tí ó ṣẹ́kù, nítorí àwa ti fi Olúwa búra láti má fi ọ̀kankan nínú àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya.
Como forneceremos esposas para aqueles que permanecerem, já que juramos por Javé que não as daremos de nossas filhas às esposas”?
8 Wọ́n sì béèrè wí pé, “Èwo ni nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mispa?” Wọ́n rí i pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó wa láti Jabesi Gileadi tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà.
Eles disseram: “Qual é a das tribos de Israel que não chegaram a Iavé para Mizpá?”. Eis que ninguém veio de Jabesh Gilead ao acampamento para a assembléia.
9 Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkankan láti inú àwọn ará Jabesi Gileadi tí ó wà níbẹ̀.
Pois quando o povo foi contado, eis que não havia lá nenhum dos habitantes de Jabesh Gilead.
10 Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá mẹ́fà àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gileadi wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
A congregação enviou doze mil dos homens mais corajosos para lá, e ordenou-lhes, dizendo: “Ide e golpeai os habitantes de Jabesh Gilead com o fio da espada, com as mulheres e os pequenos”.
11 Wọ́n ní, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe, ẹ pa gbogbo ọkùnrin àti gbogbo obìnrin tí kì í ṣe wúńdíá.”
Isto é o que você deve fazer: destruirá totalmente todo homem e toda mulher que se deitou com um homem”.
12 Wọ́n rí àwọn irinwó ọ̀dọ́bìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí nínú àwọn olùgbé Jabesi Gileadi, wọ́n sì mú wọn lọ sí ibùdó ní Ṣilo àwọn ará Kenaani.
Encontraram entre os habitantes de Jabesh Gilead quatrocentos jovens virgens que não tinham conhecido o homem deitado com ele; e os trouxeram para o acampamento em Shiloh, que fica na terra de Canaã.
13 Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ránṣẹ́ àlàáfíà sí àwọn Benjamini ní ihò àpáta Rimoni.
A congregação inteira enviou e falou às crianças de Benjamin que estavam na rocha de Rimmon, e lhes proclamou a paz.
14 Àwọn ẹ̀yà Benjamini náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gileadi. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.
Benjamin voltou naquela época; e eles lhes deram as mulheres que haviam salvo vivas das mulheres de Jabesh Gilead. Ainda não havia o suficiente para elas.
15 Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Benjamini, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
O povo se entristeceu por Benjamin, porque Yahweh havia feito uma brecha nas tribos de Israel.
16 Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Benjamini run?”
Então os anciãos da congregação disseram: “Como forneceremos esposas para os que permanecem, uma vez que as mulheres são destruídas fora de Benjamim”?
17 Wọ́n sì wí pé, “Àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n là nínú àwọn ẹ̀yà Benjamini ní láti ní ogún àti àrólé, kí ẹ̀yà kan nínú Israẹli má ṣe di píparun kúrò ní orí ilẹ̀.
Eles disseram: “Deve haver uma herança para aqueles que escaparam de Benjamim, que uma tribo não seja apagada de Israel”.
18 Àwa kò le fi àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya, nítorí tí àwa ọmọ Israẹli ti ṣe ìbúra yìí pé, ‘Ègún ni fún ẹnikẹ́ni tí ó fi aya fún ẹnikẹ́ni nínú ẹ̀yà Benjamini.’”
However, não podemos dar-lhes esposas de nossas filhas, pois os filhos de Israel haviam jurado, dizendo: “Maldito seja aquele que dá uma esposa a Benjamim”.
19 Wọ́n sì wí pé, “Kíyèsi i ayẹyẹ ọlọ́dọọdún fún Olúwa wà ní Ṣilo ní ìhà àríwá Beteli àti ìhà ìlà-oòrùn òpópó náà tí ó gba Beteli kọjá sí Ṣekemu, àti sí ìhà gúúsù Lebona.”
Eles disseram: “Eis que há uma festa de Yahweh de ano a ano em Shiloh, que fica ao norte de Betel, no lado leste da rodovia que sobe de Betel a Shechem, e no sul de Lebonah”.
20 Wọ́n sì fi àṣẹ fún àwọn ará Benjamini pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fi ara pamọ́ nínú àwọn ọgbà àjàrà
Eles comandaram as crianças de Benjamin, dizendo: “Vá e espere nos vinhedos,
21 kí ẹ sì wà ní ìmúrasílẹ̀. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin Ṣilo bá jáde láti lọ darapọ̀ fún ijó, kí ẹ yára jáde láti inú àwọn ọgbà àjàrà wọ̀n-ọn-nì kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbé aya kan nínú àwọn ọmọbìnrin Ṣilo kí ẹ padà sí ilẹ̀ Benjamini.
e veja, e veja, se as filhas de Shiloh saírem para dançar nas danças, então saia dos vinhedos, e cada homem pegue sua esposa das filhas de Shiloh, e vá para a terra de Benjamin.
22 Nígbà tí àwọn baba wọn tàbí àwọn arákùnrin wọn bá fi ẹjọ́ sùn wá, àwa yóò wí fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe wá ní oore nípa ríràn wọ́n lọ́wọ́, nítorí àwa kò rí aya fún wọn ní àkókò ogun, ẹ̀yin kò sì ní jẹ̀bi, nítorí pé ẹ̀yin kọ́ ni ó fi àwọn ọmọbìnrin yín fún wọn bí aya.’”
Será, quando seus pais ou seus irmãos vierem reclamar conosco, que lhes diremos: 'Conceda-lhes graciosamente, porque não tomamos para cada homem sua esposa em batalha, nem vocês as deram a eles; caso contrário, agora seriam culpados'”.
23 Èyí sì ni ohun tí àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣe. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin náà ń jó lọ́wọ́, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan mú ọmọbìnrin kọ̀ọ̀kan, wọ́n sì gbé e lọ láti di aya rẹ̀. Wọ́n sì padà sí ilẹ̀ ìní wọn, wọ́n sì tún àwọn ìlú náà kọ́, wọ́n sì tẹ̀dó sínú wọn.
Os filhos de Benjamin o fizeram, e levaram esposas para si, de acordo com seu número, daqueles que dançaram, que carregaram. Foram e voltaram à sua herança, construíram as cidades e viveram nelas.
24 Ní àkókò náà, àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ibẹ̀, wọ́n lọ sí ilé àti ẹ̀yà rẹ̀ olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
Os filhos de Israel partiram de lá naquela época, cada homem para sua tribo e para sua família, e cada um deles saiu de lá para sua própria herança.
25 Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, kò sí ọba ní ilẹ̀ Israẹli; olúkúlùkù sì ń ṣe bí ó ti tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
Naquela época, não havia rei em Israel. Cada um fazia o que era certo aos seus próprios olhos.