< Judges 21 >

1 Àwọn ọkùnrin Israẹli ti búra ní Mispa pé, “Kò sí ẹnìkan nínú wa tí yóò fi ọmọ obìnrin rẹ̀ fún ẹ̀yà Benjamini ní ìyàwó.”
Andũ acio a Isiraeli nĩmehĩtĩte mwĩhĩtwa marĩ kũu Mizipa makoiga atĩrĩ, “Gũtirĩ o na ũmwe witũ ũkaaneana mũirĩtu wake ahikio nĩ Mũbenjamini.”
2 Àwọn ènìyàn náà lọ sí Beteli: ilé Ọlọ́run, níbi tí wọ́n jókòó níwájú Ọlọ́run títí di àṣálẹ́, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún kíkorò.
Andũ acio nĩmathiire Betheli, kũrĩa maikarire mbere ya Ngai o nginya hwaĩ-inĩ, makĩanĩrĩra na mũgambo makĩrĩra na kĩgirĩko kĩnene.
3 Wọ́n sọkún wí pé, “Háà! Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èéṣe tí nǹkan yìí fi ṣẹlẹ̀ sí Israẹli? Èéṣe tí ẹ̀yà kan yóò fi run nínú Israẹli lónìí?”
Nao makiuga atĩrĩ, “Hĩ! Jehova Ngai wa Isiraeli, nĩ kĩĩ gĩtũmĩte ũndũ ũyũ woneke Isiraeli? Nĩ kĩĩ gĩgũtũma mũhĩrĩga ũmwe ũkorwo ũtarĩ ho thĩinĩ wa Isiraeli ũmũthĩ?”
4 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì àwọn ènìyàn náà mọ pẹpẹ kan wọ́n sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà.
Mũthenya ũyũ ũngĩ rũciinĩ tene andũ magĩaka kĩgongona na makĩruta maruta ma njino o na maruta ma ũiguano.
5 Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè wí pé, “Èwo nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti péjọ síwájú Olúwa?” Torí pé wọ́n ti fi ìbúra ńlá búra pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti péjọ níwájú Olúwa ní Mispa pípa ni àwọn yóò pa á.
Hĩndĩ ĩyo andũ a Isiraeli makĩũria atĩrĩ, “Mĩhĩrĩga-inĩ yothe ya Isiraeli-rĩ, nũũ ũtokĩte kũngana haha mbere ya Jehova?” Nĩgũkorwo nĩmeehĩtĩte mwĩhĩtwa mũrũmu atĩ ũrĩa ũkwaga gũũka kĩũngano mbere ya Jehova kũu Mizipa ti-itherũ nĩagĩrĩire kũũragwo.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì banújẹ́ fún àwọn arákùnrin wọn, àwọn ẹ̀yà Benjamini. Wọ́n wí pé, “A ti ké ẹ̀yà kan kúrò lára Israẹli lónìí.”
Na rĩrĩ, andũ a Isiraeli magĩcakaya nĩ ũndũ wa ariũ a ithe wao, andũ a Benjamini, na makiuga atĩrĩ, “Ũmũthĩ mũhĩrĩga ũmwe nĩmweherie kuuma Isiraeli.
7 Báwo ni a yóò ṣe rí aya fún àwọn tí ó ṣẹ́kù, nítorí àwa ti fi Olúwa búra láti má fi ọ̀kankan nínú àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya.
Tũngĩhota atĩa kuonera arĩa matigarĩte atumia, kuona atĩ nĩtwĩhĩtĩte mwĩhĩtwa mbere ya Jehova atĩ tũtikaamahe airĩtu aitũ mamahikie?”
8 Wọ́n sì béèrè wí pé, “Èwo ni nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mispa?” Wọ́n rí i pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó wa láti Jabesi Gileadi tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà.
Magĩcooka makĩũria atĩrĩ, “Nĩ mũhĩrĩga ũrĩkũ wa Isiraeli ũtokĩte kĩũngano-inĩ mbere ya Jehova kũu Mizipa?” Nao makĩmenya atĩ gũtirĩ mũndũ o na ũmwe kuuma Jabeshi-Gileadi wokĩte kambĩ-inĩ ĩyo nĩ ũndũ wa kĩũngano kĩu.
9 Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkankan láti inú àwọn ará Jabesi Gileadi tí ó wà níbẹ̀.
Tondũ rĩrĩa maatarire andũ, nĩmamenyire atĩ gũtirĩ mũndũ o na ũmwe kuuma Jabeshi-Gileadi warĩ kuo.
10 Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá mẹ́fà àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gileadi wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
Nĩ ũndũ ũcio kĩũngano kĩu gĩgĩtũma andũ a kũrũa 12,000 marĩ na mawatho mathiĩ nginya Jabeshi-Gileadi na moorage arĩa maatũũraga kuo na rũhiũ rwa njora, gwata atumia na ciana.
11 Wọ́n ní, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe, ẹ pa gbogbo ọkùnrin àti gbogbo obìnrin tí kì í ṣe wúńdíá.”
Nao makiuga atĩrĩ, “Ũũ nĩguo mũgwĩka, ũragai mũndũ mũrũme o wothe na mũndũ-wa-nja o wothe ũrĩa ũtarĩ gathirange.”
12 Wọ́n rí àwọn irinwó ọ̀dọ́bìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí nínú àwọn olùgbé Jabesi Gileadi, wọ́n sì mú wọn lọ sí ibùdó ní Ṣilo àwọn ará Kenaani.
Nao magĩkora gatagatĩ-inĩ ka andũ arĩa maatũũraga kũu Jabeshi-Gileadi airĩtu magana mana arĩa mataakomete na mũndũ mũrũme, makĩmatwara kambĩ ĩrĩa yarĩ Shilo kũu Kaanani.
13 Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ránṣẹ́ àlàáfíà sí àwọn Benjamini ní ihò àpáta Rimoni.
Ningĩ kĩũngano gĩothe gĩgĩtũma ihooya rĩa thayũ kũrĩ andũ a Benjamini o hau rwaro-inĩ rwa ihiga rĩa Rimoni.
14 Àwọn ẹ̀yà Benjamini náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gileadi. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.
Nĩ ũndũ ũcio andũ a Benjamini makĩhũndũka ihinda o rĩu na makĩheo andũ-a-nja a Jabeshi-Gileadi arĩa matooragĩtwo. No matingĩamaiganire.
15 Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Benjamini, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Nao andũ magĩcakaĩra andũ a Benjamini, tondũ Jehova nĩatũmire hagĩe na ithenya mĩhĩrĩga-inĩ ya Isiraeli.
16 Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Benjamini run?”
Nao athuuri arĩa akũrũ a kĩũngano makiuga atĩrĩ, “Tondũ andũ-a-nja a Benjamini nĩaniine-rĩ, tũkuonera arũme arĩa matigaire atumia kũ?”
17 Wọ́n sì wí pé, “Àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n là nínú àwọn ẹ̀yà Benjamini ní láti ní ogún àti àrólé, kí ẹ̀yà kan nínú Israẹli má ṣe di píparun kúrò ní orí ilẹ̀.
Makiuga atĩrĩ, “Abenjamini arĩa maahonokire no nginya magĩe na a kũmagaya, nĩguo gũtikagĩe mũhĩrĩga o na ũmwe wa Isiraeli ũkũniinũkio.
18 Àwa kò le fi àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya, nítorí tí àwa ọmọ Israẹli ti ṣe ìbúra yìí pé, ‘Ègún ni fún ẹnikẹ́ni tí ó fi aya fún ẹnikẹ́ni nínú ẹ̀yà Benjamini.’”
Tũtingĩmahe airĩtu aitũ matuĩke atumia ao, nĩgũkorwo ithuĩ andũ a Isiraeli nĩtwehĩtire mwĩhĩtwa ũyũ: ‘Kũrumwo-rĩ, nĩ mũndũ ũrĩa ũngĩhe Mũbenjamini mũtumia.’
19 Wọ́n sì wí pé, “Kíyèsi i ayẹyẹ ọlọ́dọọdún fún Olúwa wà ní Ṣilo ní ìhà àríwá Beteli àti ìhà ìlà-oòrùn òpópó náà tí ó gba Beteli kọjá sí Ṣekemu, àti sí ìhà gúúsù Lebona.”
No rĩrĩ, nĩkũgĩaga gĩathĩ kĩa Jehova o mwaka kũu Shilo, mwena wa gathigathini wa Betheli, na mwena wa irathĩro wa njĩra ĩrĩa ĩthiiaga kuuma Betheli nginya Shekemu, na mwena wa gũthini wa Lebona.”
20 Wọ́n sì fi àṣẹ fún àwọn ará Benjamini pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fi ara pamọ́ nínú àwọn ọgbà àjàrà
Nĩ ũndũ ũcio magĩatha andũ a Benjamini, makĩmeera atĩrĩ, “Thiĩi mwĩhithe kũu mĩgũnda-inĩ ya mĩthabibũ
21 kí ẹ sì wà ní ìmúrasílẹ̀. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin Ṣilo bá jáde láti lọ darapọ̀ fún ijó, kí ẹ yára jáde láti inú àwọn ọgbà àjàrà wọ̀n-ọn-nì kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbé aya kan nínú àwọn ọmọbìnrin Ṣilo kí ẹ padà sí ilẹ̀ Benjamini.
na mũikare mũkĩroraga. Rĩrĩa airĩtu a Shilo mariumĩra meturanĩre na arĩa angĩ rwĩmbo-inĩ-rĩ, mũguthũke kuuma mĩgũnda-inĩ ya mĩthabibũ, na o mũndũ ehurĩrie mũtumia kuuma kũrĩ airĩtu acio a Shilo, na mũthiĩ bũrũri wa Benjamini.
22 Nígbà tí àwọn baba wọn tàbí àwọn arákùnrin wọn bá fi ẹjọ́ sùn wá, àwa yóò wí fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe wá ní oore nípa ríràn wọ́n lọ́wọ́, nítorí àwa kò rí aya fún wọn ní àkókò ogun, ẹ̀yin kò sì ní jẹ̀bi, nítorí pé ẹ̀yin kọ́ ni ó fi àwọn ọmọbìnrin yín fún wọn bí aya.’”
Rĩrĩa maithe mao kana ariũ a maithe mao magaatũrehera thitango, tũkaameera atĩrĩ, ‘Twĩkei wega na kũmateithia, tondũ tũtiamooneire atumia hĩndĩ ya mbaara, no inyuĩ mũtirĩ na mahĩtia, tondũ mũtiamaheire airĩtu anyu.’”
23 Èyí sì ni ohun tí àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣe. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin náà ń jó lọ́wọ́, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan mú ọmọbìnrin kọ̀ọ̀kan, wọ́n sì gbé e lọ láti di aya rẹ̀. Wọ́n sì padà sí ilẹ̀ ìní wọn, wọ́n sì tún àwọn ìlú náà kọ́, wọ́n sì tẹ̀dó sínú wọn.
Ũguo nĩguo andũ a Benjamini meekire. O rĩrĩa airĩtu maainaga-rĩ, o mũndũ akĩnyiita ũmwe, na akĩmũkuua agatuĩke mũtumia wake. Hĩndĩ ĩyo magĩcooka kũrĩ igai rĩao, magĩaka matũũra mao rĩngĩ, na magĩtũũra kuo.
24 Ní àkókò náà, àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ibẹ̀, wọ́n lọ sí ilé àti ẹ̀yà rẹ̀ olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
Na ihinda rĩu andũ a Isiraeli makiuma kũndũ kũu, makĩinũka mũciĩ kũrĩ mĩhĩrĩga yao na nyũmba ciao, o mũndũ kũrĩ igai rĩake.
25 Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, kò sí ọba ní ilẹ̀ Israẹli; olúkúlùkù sì ń ṣe bí ó ti tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
Matukũ-inĩ macio Isiraeli gũtiarĩ na mũthamaki; o mũndũ ekaga ũrĩa oonaga kwagĩrĩire.

< Judges 21 >