< Judges 21 >

1 Àwọn ọkùnrin Israẹli ti búra ní Mispa pé, “Kò sí ẹnìkan nínú wa tí yóò fi ọmọ obìnrin rẹ̀ fún ẹ̀yà Benjamini ní ìyàwó.”
Also the sones of Israel sworen in Maspha, and seiden, Noon of vs schal yyue to the sones of Beniamyn a wijf of his douytris.
2 Àwọn ènìyàn náà lọ sí Beteli: ilé Ọlọ́run, níbi tí wọ́n jókòó níwájú Ọlọ́run títí di àṣálẹ́, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún kíkorò.
And `alle camen to the hows of God in Silo, and thei saten in the `siyt of hym `til to euentid, and thei reisiden the vois, and bigunnen to wepe with greet yellyng,
3 Wọ́n sọkún wí pé, “Háà! Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èéṣe tí nǹkan yìí fi ṣẹlẹ̀ sí Israẹli? Èéṣe tí ẹ̀yà kan yóò fi run nínú Israẹli lónìí?”
and seiden, Lord God of Israel, whi is this yuel don in thi puple, that to dai o lynage be takun awey of vs?
4 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì àwọn ènìyàn náà mọ pẹpẹ kan wọ́n sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà.
Sotheli in the tother day thei risiden eerli, and bildyden an auter, and offriden there brent sacrifices and pesible sacrifices, and seiden,
5 Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè wí pé, “Èwo nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti péjọ síwájú Olúwa?” Torí pé wọ́n ti fi ìbúra ńlá búra pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti péjọ níwájú Olúwa ní Mispa pípa ni àwọn yóò pa á.
Who of alle the lynagis of Israel stiede not in to the oost of the Lord? For whanne thei weren in Maspha, thei `hadden bounde hem silf with a greuouse ooth, that thei that failiden schulden be slayn.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì banújẹ́ fún àwọn arákùnrin wọn, àwọn ẹ̀yà Benjamini. Wọ́n wí pé, “A ti ké ẹ̀yà kan kúrò lára Israẹli lónìí.”
And the sones of Israel weren led bi penaunce on her brother Beniamyn, and bigunnen to seie, O lynage of Israel is takun awey;
7 Báwo ni a yóò ṣe rí aya fún àwọn tí ó ṣẹ́kù, nítorí àwa ti fi Olúwa búra láti má fi ọ̀kankan nínú àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya.
wherof schulen thei take wyues? for alle we sworen in comyn, that we schulen not yyue oure douytris to hem.
8 Wọ́n sì béèrè wí pé, “Èwo ni nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mispa?” Wọ́n rí i pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó wa láti Jabesi Gileadi tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà.
Therfor thei seiden, Who is of alle the lynagis of Israel, that stiede not to the Lord in Maspha? And lo! the dwelleris of Jabes of Galaad weren foundun, that thei weren not in the oost.
9 Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkankan láti inú àwọn ará Jabesi Gileadi tí ó wà níbẹ̀.
Also in that tyme, whanne thei weren in Silo, noon of hem was foundun there.
10 Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá mẹ́fà àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gileadi wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
Therfor thei senten ten thousynde strongeste men, and comaundiden to hem, Go ye, and smyte the dwelleris of Jabes of Galaad bi the scharpnesse of swerd, as wel the wyues as `the litle children of hem.
11 Wọ́n ní, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe, ẹ pa gbogbo ọkùnrin àti gbogbo obìnrin tí kì í ṣe wúńdíá.”
And this thing schal be, which ye `owen to kepe, sle ye alle of male kynde, and the wymmen, that knewen men fleischli; reserue ye the virgyns.
12 Wọ́n rí àwọn irinwó ọ̀dọ́bìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí nínú àwọn olùgbé Jabesi Gileadi, wọ́n sì mú wọn lọ sí ibùdó ní Ṣilo àwọn ará Kenaani.
And foure hundrid virgyns, that knewen not the bed of man, weren foundun of Jabes of Galaad; and thei brouyten hem to the castels in Silo, in to the lond of Chanaan.
13 Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ránṣẹ́ àlàáfíà sí àwọn Benjamini ní ihò àpáta Rimoni.
And `thei senten messangeris to the sones of Beniamyn, that weren in the stoon of Remmon; and thei comaundiden to hem, that thei schulden resseyue tho wymmen in pees.
14 Àwọn ẹ̀yà Benjamini náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gileadi. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.
And the sones of Beniamyn camen in that tyme, and the douytris of Jabes of Galaad weren youun to hem to wyues; forsothe thei founden not othere wymmen, whiche thei schulden yyue in lijk maner.
15 Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Benjamini, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
And al Israel sorewide greetly, and dide penaunce on the sleyng of o lynage of Israel.
16 Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Benjamini run?”
And the grettere men in birthe seiden, What schulen we do to the othere men, that han not take wyues? Alle the wymmen in Beniamyn felden doun,
17 Wọ́n sì wí pé, “Àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n là nínú àwọn ẹ̀yà Benjamini ní láti ní ogún àti àrólé, kí ẹ̀yà kan nínú Israẹli má ṣe di píparun kúrò ní orí ilẹ̀.
and it `is to vs to puruey `with greet cure and greet studie, that o lynage be not don awey fro Israel.
18 Àwa kò le fi àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya, nítorí tí àwa ọmọ Israẹli ti ṣe ìbúra yìí pé, ‘Ègún ni fún ẹnikẹ́ni tí ó fi aya fún ẹnikẹ́ni nínú ẹ̀yà Benjamini.’”
We moun not yyue oure douytris to hem, for we ben boundun with an ooth and cursyng, bi which we seiden, Be he cursid that yyueth of hise douytris a wijf to Beniamyn.
19 Wọ́n sì wí pé, “Kíyèsi i ayẹyẹ ọlọ́dọọdún fún Olúwa wà ní Ṣilo ní ìhà àríwá Beteli àti ìhà ìlà-oòrùn òpópó náà tí ó gba Beteli kọjá sí Ṣekemu, àti sí ìhà gúúsù Lebona.”
And thei token a counsel, and seiden, Lo! annyuersarie solempnyte of the Lord is in Silo, whych is set at the north of the citee of Bethel, and at the eest coost of the weie that goith from Bethel to Siccyma, and at the south of the citee of Lebona.
20 Wọ́n sì fi àṣẹ fún àwọn ará Benjamini pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fi ara pamọ́ nínú àwọn ọgbà àjàrà
And thei comaundiden to the sones of Beniamyn, and seiden, Go ye, be ye hid in the vyneris;
21 kí ẹ sì wà ní ìmúrasílẹ̀. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin Ṣilo bá jáde láti lọ darapọ̀ fún ijó, kí ẹ yára jáde láti inú àwọn ọgbà àjàrà wọ̀n-ọn-nì kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbé aya kan nínú àwọn ọmọbìnrin Ṣilo kí ẹ padà sí ilẹ̀ Benjamini.
and whanne ye seen douytris of Silo go forth bi custom to lede daunsis, go ye out of the vyneris sudeynli, and rauysche ye hem, eche man o wijf, and go ye in to the lond of Beniamyn.
22 Nígbà tí àwọn baba wọn tàbí àwọn arákùnrin wọn bá fi ẹjọ́ sùn wá, àwa yóò wí fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe wá ní oore nípa ríràn wọ́n lọ́wọ́, nítorí àwa kò rí aya fún wọn ní àkókò ogun, ẹ̀yin kò sì ní jẹ̀bi, nítorí pé ẹ̀yin kọ́ ni ó fi àwọn ọmọbìnrin yín fún wọn bí aya.’”
And whanne the fadris and britheren of hem schulen come, and bigynne to pleyne and plete ayens you, we schulen seie to hem, Haue ye mercy of hem; for thei rauyschiden not hem bi riyt of fiyteris and ouercomeris, but ye `yauen not to hem preiynge that thei schulden take; and the synne is of youre part.
23 Èyí sì ni ohun tí àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣe. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin náà ń jó lọ́wọ́, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan mú ọmọbìnrin kọ̀ọ̀kan, wọ́n sì gbé e lọ láti di aya rẹ̀. Wọ́n sì padà sí ilẹ̀ ìní wọn, wọ́n sì tún àwọn ìlú náà kọ́, wọ́n sì tẹ̀dó sínú wọn.
And the sones of Beniamyn diden as it was comaundid to hem, and bi her noumbre thei rauyschiden wyues to hem, ech man o wijf, of hem that ledden daunsis. And thei yeden in to her possessioun, and bildiden citees, and dwelliden in tho.
24 Ní àkókò náà, àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ibẹ̀, wọ́n lọ sí ilé àti ẹ̀yà rẹ̀ olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
And the sones of Israel turneden ayen, bi lynagis and meynees, in to her tabernaclis.
25 Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, kò sí ọba ní ilẹ̀ Israẹli; olúkúlùkù sì ń ṣe bí ó ti tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
In tho dayes was no kyng in Israel, but ech man dide this, that semyde ryytful to hym silf.

< Judges 21 >