< Judges 21 >

1 Àwọn ọkùnrin Israẹli ti búra ní Mispa pé, “Kò sí ẹnìkan nínú wa tí yóò fi ọmọ obìnrin rẹ̀ fún ẹ̀yà Benjamini ní ìyàwó.”
Isala: ili dunu da Misiba moilaiga musa: gilisiliba, ilia da Hina Gode ba: ma: ne, gasa bagade sema hamosu, amane, “Ninia uda mano amo Bediamini dunu da hamedafa lamu.”
2 Àwọn ènìyàn náà lọ sí Beteli: ilé Ọlọ́run, níbi tí wọ́n jókòó níwájú Ọlọ́run títí di àṣálẹ́, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún kíkorò.
Amalalu, ilia da Bedele moilaiga asili, amola Gode ba: ma: ne eso amo ganodini fili, asili daeya ha: giwane didiga: lalu.
3 Wọ́n sọkún wí pé, “Háà! Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èéṣe tí nǹkan yìí fi ṣẹlẹ̀ sí Israẹli? Èéṣe tí ẹ̀yà kan yóò fi run nínú Israẹli lónìí?”
Ilia amane disu, “Isala: ili Hina Gode! Amo hou da abuliba: le doaga: bela: ? Abuliba: le Bediamini fi da Isala: ili sogega gadenenewane fisi dagoi ba: sala: ?”
4 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì àwọn ènìyàn náà mọ pẹpẹ kan wọ́n sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà.
Golale, hahabedafa ilia da gilisili Hahawane Gilisili Olofole gobele salasu amola ohe hodo amo oloda, ilia hamoi, amo da: iya gogo gobele sali.
5 Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè wí pé, “Èwo nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti péjọ síwájú Olúwa?” Torí pé wọ́n ti fi ìbúra ńlá búra pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti péjọ níwájú Olúwa ní Mispa pípa ni àwọn yóò pa á.
Ilia da amane adole ba: i, “Isala: ili fi amo ganodini, sosogo fi afae da Misiba sogega Godema gilisisu amoga hame misibala: ?” (Ilia da musa: gasa bagade sema hamosu. Amo nowa fi da Misiba moilai gilisisu amoga hame misi ganiaba, ilia da amo dunu ili medole legela: loba.)
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì banújẹ́ fún àwọn arákùnrin wọn, àwọn ẹ̀yà Benjamini. Wọ́n wí pé, “A ti ké ẹ̀yà kan kúrò lára Israẹli lónìí.”
Isala: ili dunu da bu ilia olalali Bediamini dunu ilima asigi galu. Ilia da amane sia: i, “Wali eso, Isala: ili fi afadafa da fisi dagoi.
7 Báwo ni a yóò ṣe rí aya fún àwọn tí ó ṣẹ́kù, nítorí àwa ti fi Olúwa búra láti má fi ọ̀kankan nínú àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya.
Ninia da Bediamini dunu esala, amoga uda ima: ne adi hamoma: bela: ? Bai ninia Hina Godema sema bagade hamoi dagoi, amo ninia uda mano ilima hamedafa imunu.”
8 Wọ́n sì béèrè wí pé, “Èwo ni nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mispa?” Wọ́n rí i pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó wa láti Jabesi Gileadi tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà.
Ilia da nowa gilisisu da Misiba gilisisuga hame misi, amo adole ba: loba, dunu da Ya: ibese moilai Gilia: de soge ganodini esalu, amo da hame misi ilia da nabi.
9 Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkankan láti inú àwọn ará Jabesi Gileadi tí ó wà níbẹ̀.
Amola ilia da dadi gagui gilisima: ne dio wele sia: noba, Ya: ibese dunu da hame misi.
10 Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá mẹ́fà àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gileadi wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
Amaiba: le, ilia da 1,200 gasa bagade dunu amo Ya: ibese moilaiga asunasi. Ilia da ilima amane sia: i, “Ya: ibese dunu huluane, uda amola mano medole legema.
11 Wọ́n ní, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe, ẹ pa gbogbo ọkùnrin àti gbogbo obìnrin tí kì í ṣe wúńdíá.”
Dunu huluane, dunu mano amola uda huluane amo da dunuma fi, amo huluane medole legema.”
12 Wọ́n rí àwọn irinwó ọ̀dọ́bìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí nínú àwọn olùgbé Jabesi Gileadi, wọ́n sì mú wọn lọ sí ibùdó ní Ṣilo àwọn ará Kenaani.
Ya: ibese moilai ganodini, ilia da a: fini amola uda mano amo da dunuma hame gilisili golai, 400 agoane ba: i. Ilia da amo Siailou abula moilai Ga: ina: ne soge ganodini, amoga oule misi.
13 Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ránṣẹ́ àlàáfíà sí àwọn Benjamini ní ihò àpáta Rimoni.
Amalalu, Isala: ili gilisisu da Bediamini dunu amo da Limone Gelega esalu, ilima sia: adole iasi. Ilia da gegesu fisili, olofole gousa: su hamoma: ne sia: i.
14 Àwọn ẹ̀yà Benjamini náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gileadi. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.
Bediamini dunu da bu misini, Isala: ili fi eno da Ya: ibese uda mano ilia hame medole legei amo ilima i. Be ilima iabe idi da defele hame ba: i.
15 Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Benjamini, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Hina Gode da Isala: ili fi ilia habelegele fi afadafa, amo da afafai dagoiba: le, ilia da Bediamini dunuma asigi galu.
16 Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Benjamini run?”
Amaiba: le, ilia ouligisu dunu da amane sia: i, “Uda eno da Bediamini fi ganodini hame esala. Ninia da habodane ilia uda lamusa: ilima ima: bela: ?
17 Wọ́n sì wí pé, “Àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n là nínú àwọn ẹ̀yà Benjamini ní láti ní ogún àti àrólé, kí ẹ̀yà kan nínú Israẹli má ṣe di píparun kúrò ní orí ilẹ̀.
Isala: ili da fi fagoyale gala. Afadafa fisimu da hamedei. Bediamini fi esaloma: ne, ninia logo hogoi helemu da defea.
18 Àwa kò le fi àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya, nítorí tí àwa ọmọ Israẹli ti ṣe ìbúra yìí pé, ‘Ègún ni fún ẹnikẹ́ni tí ó fi aya fún ẹnikẹ́ni nínú ẹ̀yà Benjamini.’”
Be ilia da ninia uda mano lamu da hamedei. Bai ninia da sema bagade hamoi. Nowa da ea uda mano Bediamini dunuma iasea, ninia da ema gagabusu aligima: ne ilegei dagoi.”
19 Wọ́n sì wí pé, “Kíyèsi i ayẹyẹ ọlọ́dọọdún fún Olúwa wà ní Ṣilo ní ìhà àríwá Beteli àti ìhà ìlà-oòrùn òpópó náà tí ó gba Beteli kọjá sí Ṣekemu, àti sí ìhà gúúsù Lebona.”
Amalalu, ilia da agoane dawa: i, “Hina Gode Ea Lolo Nasu Siailou moilaiga da gadenesa galebe.” (Siailou da Bedelehemega gagoe (north) gala. E da Lebouna amoga gagoe (south) amola logo amo da Bedele fisili Siegeme doaga: sa amo ea eso mabe la: idiga gala.)
20 Wọ́n sì fi àṣẹ fún àwọn ará Benjamini pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fi ara pamọ́ nínú àwọn ọgbà àjàrà
Ilia da Bediamini dunuma amane sia: i, “Dilia waini efe sogebi amo ganodini wamoaligili, ouesaloma.
21 kí ẹ sì wà ní ìmúrasílẹ̀. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin Ṣilo bá jáde láti lọ darapọ̀ fún ijó, kí ẹ yára jáde láti inú àwọn ọgbà àjàrà wọ̀n-ọn-nì kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbé aya kan nínú àwọn ọmọbìnrin Ṣilo kí ẹ padà sí ilẹ̀ Benjamini.
Siailou a: fini ilia da lolo nasu ganodini gosa: musa: masea, dilia waini efe aligisu fisili, dilia afae afae uda lamusa: ha: giwane gagulaligima. Amola amo uda dilia Bediamini sogega bu oule masa.
22 Nígbà tí àwọn baba wọn tàbí àwọn arákùnrin wọn bá fi ẹjọ́ sùn wá, àwa yóò wí fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe wá ní oore nípa ríràn wọ́n lọ́wọ́, nítorí àwa kò rí aya fún wọn ní àkókò ogun, ẹ̀yin kò sì ní jẹ̀bi, nítorí pé ẹ̀yin kọ́ ni ó fi àwọn ọmọbìnrin yín fún wọn bí aya.’”
Be ilia eda o olalali da dilima sia: ga gegemusa: masea, ilima amane sia: ma, ‘Ninia da amo a: fini ili lamu da defeala: ? Bai ninia da gegesu ganodini amo a: fini hame lai. Amola dilia da amo uda mano ninima udigili hame iba: le, dilia sema hamoi amo hame wadela: lesiba: le, gagabusu aligima: ne dilima hame dialumu.’”
23 Èyí sì ni ohun tí àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣe. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin náà ń jó lọ́wọ́, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan mú ọmọbìnrin kọ̀ọ̀kan, wọ́n sì gbé e lọ láti di aya rẹ̀. Wọ́n sì padà sí ilẹ̀ ìní wọn, wọ́n sì tún àwọn ìlú náà kọ́, wọ́n sì tẹ̀dó sínú wọn.
Bediamini dunu da ilia sia: i defele hamoi. Ilia da afae afae Siailou a: fini amo da siogolalu amo lale, gisawane asi. Ilia da ilia sogega asili, ilia moilai bu gaguli, fi galu.
24 Ní àkókò náà, àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ibẹ̀, wọ́n lọ sí ilé àti ẹ̀yà rẹ̀ olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
Amola Isala: ili fi dunu eno da fisili asili, ilia fi amola sosogo fi da ilia sogedafa amoga buhagi.
25 Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, kò sí ọba ní ilẹ̀ Israẹli; olúkúlùkù sì ń ṣe bí ó ti tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
Amo esoha, Isala: ili soge ganodini da hina bagade dunu hame esalu. Dunu huluane da afae afae hi hanaiga fawane hamosu. Sia: Ama Dagoi

< Judges 21 >