< Judges 20 >
1 Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli láti Dani dé Beerṣeba, àti láti ilẹ̀ Gileadi jáde bí ẹnìkan ṣoṣo wọ́n sì péjọ síwájú Olúwa ni Mispa.
Wtedy wyszli wszyscy synowie Izraela i zebrało się całe zgromadzenie jednomyślnie od Dan aż do Beer-Szeby i do ziemi Gilead do PANA w Mispie.
2 Àwọn olórí gbogbo àwọn ènìyàn láti gbogbo ẹ̀yà Israẹli dúró ní ipò wọn ní àpéjọ àwọn ènìyàn Ọlọ́run, ogún ọ̀kẹ́ ọkùnrin ológun ti àwọn àti idà wọn.
I przywódcy całego ludu, wszystkich pokoleń Izraela, stanęli w zgromadzeniu ludu Bożego: czterysta tysięcy pieszych dobywających miecz.
3 (Àwọn ẹ̀yà Benjamini gbọ́ wí pé àwọn ọmọ Israẹli yòókù ti gòkè lọ sí Mispa.) Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli wí pé, “Ẹ sọ fún wa báwo ni iṣẹ́ búburú ṣe ṣẹlẹ̀.”
I synowie Beniamina usłyszeli, że synowie Izraela zebrali się w Mispie. Wtedy synowie Izraela powiedzieli: Powiedzcie, jak doszło do tej niegodziwości?
4 Ará Lefi náà, ọkọ obìnrin tí wọ́n pa fèsì pé, “Èmi àti àlè mi wá sí Gibeah ti àwọn ará Benjamini láti sùn di ilẹ̀ mọ́ níbẹ̀.
I ten Lewita, mąż zabitej kobiety, odpowiedział: Przybyłem wraz z moją nałożnicą do Gibea, która należy do Beniamina, aby tam przenocować.
5 Ṣùgbọ́n ní òru àwọn ọkùnrin Gibeah lépa mi wọ́n sì yí ilé náà po pẹ̀lú èrò láti pa mí. Wọ́n fi ipá bá àlè mi lòpọ̀, òun sì kú.
I mężczyźni z Gibea powstali przeciwko mnie i w nocy otoczyli dom, zamierzając mnie zabić, a moją nałożnicę tak gwałcili, aż umarła.
6 Mo mú àlè mi náà, mo sì gé e sí ekìrí ekìrí, mo sì fi ekìrí kọ̀ọ̀kan ránṣẹ́ sí agbègbè ìní Israẹli kọ̀ọ̀kan, nítorí pé wọ́n ti ṣe ohun tí ó jẹ́ èèwọ̀ àti ohun ìtìjú yìí ní ilẹ̀ Israẹli.
Wziąłem więc swoją nałożnicę, rozciąłem ją na części i rozesłałem ją do wszystkich krain dziedzictwa Izraela. Dopuszczono się bowiem w Izraelu haniebnego i sprośnego czynu.
7 Nísinsin yìí, gbogbo ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ sọ ìmọ̀ràn yín, kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ yín.”
Oto wy wszyscy jesteście synami Izraela, rozważcie to między sobą i radźcie o tym.
8 Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì dìde bí ẹnìkan pẹ̀lú gbólóhùn kan wí pé, “Kò sí ẹnikẹ́ni nínú wa tí yóò lọ sí àgọ́ rẹ̀. Rárá o, kò sí ẹyọ ẹnìkan tí yóò padà lọ sí ilé rẹ̀.
I powstał cały lud jednomyślnie, mówiąc: Nikt z nas nie pójdzie do swego namiotu ani nie odejdzie do swego domu.
9 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ohun tí àwa yóò ṣe sí Gibeah ní yìí. Àwa yóò lọ kọlù ú bí ìbò bá ṣe darí wa.
Ale teraz tak uczynimy miastu Gibea: Wyruszymy przeciwko niemu według losu.
10 A yóò mú ọkùnrin mẹ́wàá nínú ọgọ́rùn-ún nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli àti ọgọ́rùn-ún láti inú ẹgbẹ̀rún kan àti ẹgbẹ̀rún kan láti inú ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá láti máa pèsè oúnjẹ fún àwọn ọmọ-ogun. Yóò sì ṣe nígbà tí àwọn jagunjagun bá dé Gibeah ti àwọn ará Benjamini, wọn yóò fún wọn ní ohun tí ó bá tọ́ sí wọn fún gbogbo ìwà búburú àti ìwà ìtìjú tí wọ́n ṣe yìí ní ilẹ̀ Israẹli.”
Z każdego pokolenia Izraela weźmiemy po dziesięciu mężczyzn ze stu, stu z tysiąca i tysiąc z dziesięciu tysięcy, żeby dostarczali żywność dla ludu, który wyruszy do Gibea Beniamina, by pomścić wszelką sprośność, której się dopuszczono w Izraelu.
11 Báyìí ni gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli parapọ̀ ṣọ̀kan bí ọkùnrin kan ṣoṣo wọ́n sì dìde sí ìlú náà.
Zebrał się więc cały lud Izraela przeciwko miastu, zżyty ze sobą jak jeden mąż.
12 Àwọn ẹ̀yà Israẹli rán àwọn ọkùnrin sí gbogbo ẹ̀yà Benjamini wí pé, “Kí ni ẹ̀rí sí ìwà búburú yìí tí ó ṣẹlẹ̀ ní àárín yín?
Potem pokolenia Izraela wysłały mężczyzn do wszystkich domów synów Beniamina, mówiąc: Co to za niegodziwość popełniono wśród was?
13 Nítorí náà ẹ mú àwọn ẹni ibi ti Gibeah yìí wá fún wa, kí àwa lé pa, kí a sì fọ ìṣe búburú yìí mọ́ kúrò ní Israẹli.” Ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Benjamini kò fetí sí ti àwọn arákùnrin wọn ọmọ Israẹli.
Wydajcie więc teraz tych mężczyzn, synów Beliala, którzy są w Gibea, abyśmy ich pozabijali i usunęli zło z Izraela. Lecz synowie Beniamina nie chcieli słuchać głosu swoich braci, synów Izraela.
14 Àwọn ẹ̀yà Benjamini sì kó ara wọn jọ láti àwọn ìlú wọn sí Gibeah láti bá àwọn ọmọ Israẹli jà.
Co więcej, zebrali się synowie Beniamina z [innych] miast w Gibea, aby walczyć z synami Izraela.
15 Ní ẹsẹ̀kẹsẹ̀ àwọn ará Benjamini kó ẹgbàá mẹ́tàlá àwọn ọmọ-ogun tí ń lọ dájọ́ láti àwọn ìlú wọn, yàtọ̀ sí àwọn ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àṣàyàn ọkùnrin nínú àwọn tí ń gbé Gibeah.
I tego dnia naliczono synów Beniamina z [ich] miast dwadzieścia sześć tysięcy mężczyzn dobywających miecz, oprócz mieszkańców Gibea, których naliczono siedmiuset doborowych mężczyzn.
16 Ní àárín àwọn ọmọ-ogun wọ̀nyí ni ó ti ní àwọn ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àṣàyàn ọkùnrin tí wọ́n ń lo ọwọ́ òsì, tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dára dé bi pé wọ́n lè fi kànnàkànnà ba fọ́nrán òwú ní àìtàsé (wọ́n jẹ́ atamọ́tàsé).
Wśród całego ludu było siedmiuset doborowych mężczyzn, leworęcznych, a każdy z nich [potrafił] ciskać z procy kamieniem do włosa i nie chybiał.
17 Àwọn ọkùnrin Israẹli, yàtọ̀ sí àwọn ará Benjamini, ka ogún ọ̀kẹ́ àwọn tí ń fi idà jagun, gbogbo wọn jẹ́ akọni ní ogun jíjà.
Izraelitów zaś naliczono, oprócz [synów] Beniamina, czterysta tysięcy mężczyzn dobywających miecz, wszyscy byli wojownikami.
18 Àwọn ọmọ Israẹli lọ sí Beteli, wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run. Wọ́n wí pé, “Ta ni nínú wa tí yóò kọ́ kojú àwọn ará Benjamini láti bá wọn jà?” Olúwa dáhùn pé, “Juda ni yóò kọ́ lọ.”
Wtedy synowie Izraela powstali, poszli do domu Bożego i radzili się Boga, mówiąc: Któż z nas ma wyruszyć pierwszy do walki z synami Beniamina? I PAN odpowiedział: Juda [wyruszy] pierwszy.
19 Àwọn ọmọ Israẹli dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, wọ́n sì dó ti Gibeah (wọ́n tẹ̀gùn sí ẹ̀bá Gibeah).
Powstali więc synowie Izraela rano i rozbili obóz naprzeciw Gibea.
20 Àwọn ọkùnrin Israẹli jáde lọ láti bá àwọn ará Benjamini jà wọ́n sì dúró ní ipò ogun sí wọn ní Gibeah.
Potem synowie Izraela wyruszyli do walki z synami Beniamina i ustawili się w szyku bojowym do walki przeciw Gibea.
21 Àwọn ọmọ Benjamini sì jáde láti Gibeah wá wọ́n sì pa àwọn ọmọ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ọkùnrin nínú àwọn ọmọ Israẹli ní ojú ogun ní ọjọ́ náà.
Lecz synowie Beniamina wyszli z Gibea i zabili tego dnia dwadzieścia dwa tysiące mężczyzn z Izraela.
22 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Israẹli mú ara wọn lọ́kàn le, wọ́n sì tún dúró sí ipò wọn ní ibi tí wọ́n dúró sí ní ọjọ́ àkọ́kọ́.
Potem mężczyźni z ludu Izraela pokrzepili się i znowu ustawili się w szyku bojowym do walki na tym miejscu, gdzie ustawili się pierwszego dnia.
23 Àwọn ọmọ Israẹli sì lọ wọ́n sọkún ní iwájú Olúwa títí oòrùn fi wọ̀, wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa. Wọ́n ni, “Ṣé kí àwa tún gòkè lọ kí a sì bá àwọn ará Benjamini arákùnrin wa jà?” Olúwa dáhùn pé, “Lọ bá wọn jà.”
[Najpierw] jednak synowie Izraela poszli i płakali przed PANEM aż do wieczora, i pytali PANA: Czy mamy jeszcze iść i walczyć z synami Beniamina, naszego brata? I PAN odpowiedział: Idźcie przeciwko nim.
24 Àwọn ọmọ Israẹli sì tún súnmọ́ tòsí àwọn ará Benjamini ní ọjọ́ kejì.
I wyruszyli synowie Izraela przeciwko synom Beniamina drugiego dnia.
25 Ní ọjọ́ yìí nígbà tí ará Benjamini jáde sí wọn láti Gibeah, láti dojúkọ wọn, wọ́n pa ẹgbàá mẹ́sàn ọkùnrin Israẹli, gbogbo wọn jẹ́ jagunjagun tí ń lo idà.
Lecz synowie Beniamina wyszli przeciwko nim z Gibea drugiego dnia i znowu zabili osiemnaście tysięcy mężczyzn z synów Izraela, wszystkich mężczyzn dobywających miecz.
26 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli àní gbogbo àwọn ènìyàn, gòkè lọ sí Beteli, níbẹ̀ ni wọ́n jókòó tí wọ́n sì ń sọkún níwájú Olúwa. Wọ́n gbààwẹ̀ ní ọjọ́ náà títí di àṣálẹ́, wọ́n sì rú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà sí Olúwa.
Wtedy wszyscy synowie Izraela i cały lud udali się i przyszli do domu Bożego, i płacząc, trwali tam przed PANEM i pościli w tym dniu aż do wieczora, i składali całopalenia i ofiary pojednawcze przed PANEM.
27 Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa. (Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run wà níbẹ̀,
I synowie Izraela pytali PANA (tam bowiem w tych dniach była arka przymierza Boga;
28 Finehasi ọmọ Eleasari ọmọ Aaroni, ní ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ ní iwájú rẹ̀.) wọ́n béèrè pé, “Ṣe àwa tún le lọ sí ogun pẹ̀lú Benjamini arákùnrin wa tàbí kí a má lọ?” Olúwa dáhùn pé, “Ẹ lọ nítorí ní ọ̀la ni èmi yóò fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.”
A Pinchas, syn Eleazara, syna Aarona, sprawował przy niej służbę w tych dniach): Czy mamy jeszcze wyruszać do walki z synami Beniamina, naszego brata, czy też tego zaniechać? I PAN odpowiedział: Wyruszcie, gdyż jutro wydam ich w wasze ręce.
29 Àwọn ọmọ Israẹli sì yàn àwọn ènìyàn tí ó sá pamọ́ yí Gibeah ká.
Wtedy Izrael przygotował zasadzki zewsząd dokoła Gibea.
30 Wọ́n jáde tọ àwọn ọmọ Benjamini lọ ní ọjọ́ kẹta wọ́n sì dúró ní ipò wọn, wọ́n sì dìde ogun sí Gibeah bí wọ́n ti ṣe tẹ́lẹ̀ rí.
I trzeciego dnia synowie Izraela wyruszyli przeciwko synom Beniamina i ustawili się w szyku bojowym przeciwko Gibea jak za pierwszym i drugim razem.
31 Àwọn ọmọ Benjamini sì jáde láti pàdé wọn, àwọn ọmọ Israẹli sì tàn wọ́n jáde kúrò ní ìlú náà. Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣẹ́gun àwọn ọmọ Israẹli bí i ti àtijọ́ dé bi pé wọ́n pa bí ọgbọ̀n ọkùnrin ní pápá àti ní àwọn òpópó náà—àwọn ọ̀nà tí ó lọ sí Beteli àti èkejì sí Gibeah.
Synowie Beniamina także wyszli przeciwko ludowi i zostali odciągnięci od miasta. Zaczęli bić lud i zabijać jak za pierwszym i drugim razem na drogach, z których jedna prowadziła do Betel, a druga do Gibea na polu, a [zabili] około trzydziestu mężczyzn z Izraela.
32 Nígbà tí àwọn Benjamini ń wí pé, “Àwa ti ń ṣẹ́gun wọn bí i ti ìṣáájú,” àwọn ọmọ Israẹli ń wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sá kí a lè fà wọ́n kúrò ní ìlú sí ojú òpópó náà.”
I synowie Beniamina powiedzieli: Są pobici przez nas jak i poprzednio. Lecz synowie Izraela mówili: Uciekajmy i odciągnijmy ich od miasta aż na drogi.
33 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli dìde kúrò ní ipò wọn, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Baali-Tamari, àwọn ọmọ-ogun Israẹli tí wọ́n sá pamọ́ sínú igbó jáde kúrò níbi tí wọ́n wà ní ìwọ̀-oòrùn Gibeah.
Powstali więc wszyscy mężczyźni Izraela ze swego miejsca i ustawili się w szyku bojowym w Baal-Tamar; tymczasem ci z Izraela, którzy przygotowali zasadzkę, wyszli ze swych miejsc, z łąk Gibea.
34 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn àṣàyàn ológun àwọn ọmọ Israẹli gbógun ti Gibeah láti iwájú ogun náà le gidigidi dé bí i pé àwọn ẹ̀yà Benjamini kò funra pé ìparun wà nítòsí.
A tak wyszło naprzeciw Gibea dziesięć tysięcy doborowych mężczyzn z całego Izraela; była to bitwa zacięta, a tamci nie wiedzieli, że ma ich spotkać nieszczęście.
35 Olúwa ṣẹ́gun Benjamini níwájú àwọn ọmọ Israẹli, ní ọjọ́ náà àwọn ọmọ Israẹli pa ẹgbàá méjìlá ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ọkùnrin Benjamini, gbogbo wọn fi idà dìhámọ́ra ogun.
I PAN pobił Beniamina przed Izraelem i w tym dniu synowie Izraela zabili dwadzieścia pięć tysięcy stu mężczyzn z Beniamina, wszystkich dobywających miecz.
36 Àwọn ẹ̀yà Benjamini sì rí pé wọ́n ti ṣẹ́gun àwọn. Àwọn ọkùnrin Israẹli fàsẹ́yìn níwájú àwọn ẹ̀yà Benjamini nítorí pé wọ́n fọkàn tán àwọn tí ó wà ní ibùba ní ẹ̀bá Gibeah.
Wtedy synowie Beniamina widzieli, że są pobici; mężczyźni Izraela ustępowali bowiem miejsca przed Beniaminem, licząc na zasadzki, które przygotowali naprzeciw Gibea.
37 Àwọn ọkùnrin tí wọ́n lúgọ yára jáde wọ́n sì tètè wọ Gibeah, wọ́n fọ́nká wọ́n sì fi idà pa gbogbo àwọn tí ó wà nínú ìlú náà.
A ci, którzy uczestniczyli w zasadzce, pospieszyli się i uderzyli na Gibea, a następnie pobili ostrzem miecza wszystkich, którzy byli w mieście.
38 Àwọn ọkùnrin Israẹli àti àwọn tí o ba ní ibùba sínú igbó ti fún ara wọn ní àmì pé, kí àwọn tí ó ba ní ibùba fi èéfín ṣe ìkùùkuu ńlá láti inú ìlú náà,
A mężczyźni Izraela mieli umówiony znak z tymi, którzy ukryli się w zasadzce, że ci wypuszczą z miasta wielki dym.
39 nígbà náà ni àwọn ọkùnrin Israẹli yípadà, wọ́n sá gun. Àwọn ọmọ Benjamini sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ṣẹ́gun àti ní pípa àwọn ọkùnrin Israẹli tí ó to ọgbọ̀n, wọ́n sì wí pé, “Àwa ń ṣẹ́gun wọn bí ìgbà ìjà àkọ́kọ́.”
Gdy więc mężczyźni Izraela cofnęli się przed bitwą, synowie Beniamina zaczęli bić i zabili około trzydziestu mężczyzn z Izraela. Mówili bowiem: Na pewno są pobici przed nami, jak i w pierwszej bitwie.
40 Ṣùgbọ́n nígbà tí ìkùùkuu èéfín bẹ̀rẹ̀ sí ní rú sókè láti inú ìlú náà wá, àwọn ẹ̀yà Benjamini yípadà wọ́n sì rí èéfín gbogbo ìlú náà ń gòkè sí ojú ọ̀run.
Ale gdy płomień i dym jak słup zaczęły wznosić się z miasta, wtedy synowie Beniamina obejrzeli się, a oto ogień z miasta wznosił się aż ku niebu.
41 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yípadà sí wọn, ẹ̀rù gidigidi sì ba àwọn ará Benjamini nítorí pé wọ́n mọ̀ pé àwọn wà nínú ewu.
A kiedy mężczyźni Izraela zawrócili, mężowie Beniamina przerazili się, widząc, że spadło na nich nieszczęście.
42 Wọ́n sì sá níwájú àwọn ọmọ Israẹli sí apá àṣálẹ́, ṣùgbọ́n wọn kò le sálà kúrò lọ́wọ́ ogun náà. Àwọn ọkùnrin Israẹli tí ó jáde láti inú àwọn ìlú wọn wá pa wọ́n run níbẹ̀.
I uciekali przed mężczyznami Izraela drogą na pustynię, a wojsko doganiało ich i ci, którzy wybiegli z miast, zabijali ich pośród siebie.
43 Wọ́n yí àwọn ẹ̀yà Benjamini ká, wọ́n lépa wọn, wọ́n sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìrọ̀rùn ní ibi ìsinmi wọn ní agbègbè ìlà-oòrùn Gibeah.
Otoczyli więc Beniamina i gonili ich bez przerwy, a pokonali ich naprzeciw Gibea na wschodzie.
44 Ẹgbàá mẹ́sàn àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣubú, gbogbo wọn jẹ́ akọni jagunjagun.
Poległo wtedy z Beniamina osiemnaście tysięcy mężczyzn, wszyscy byli wojownikami.
45 Bí wọ́n ṣe síjú padà tí wọ́n sì ń sálọ sí apá ijù lọ sí ọ̀nà àpáta Rimoni ni àwọn ọmọ Israẹli pa ẹgbẹ̀rún márùn-ún ọkùnrin ní àwọn òpópónà. Wọ́n lépa àwọn ẹ̀yà Benjamini títí dé Gidomu, wọ́n sì tún bi ẹgbẹ̀rún méjì ọkùnrin ṣubú.
Z tych zaś, którzy zawrócili i uciekali na pustynię, na skałę Rimmon, wyłapali po drogach i zabili pięć tysięcy mężczyzn. Gonili ich aż do Gidom, gdzie zabili dwa tysiące mężczyzn spośród nich.
46 Ní ọjọ́ náà ẹgbàá méjìlá ó lé ẹgbẹ̀rún jagunjagun Benjamini tí ń fi idà jagun ní ó ṣubú, gbogbo wọn jẹ́ akọni ológun.
A tak wszystkich poległych z Beniamina tego dnia było dwadzieścia pięć tysięcy mężczyzn dobywających miecz, wszyscy [byli] wojownikami.
47 Ṣùgbọ́n ẹgbẹ̀ta ọkùnrin yípadà wọ́n sì sá nínú ààlà lọ sí àpáta Rimoni, níbi tí wọ́n wà fún oṣù mẹ́rin.
Tylko sześciuset mężczyzn zawróciło i uciekło na pustynię, na skałę Rimmon, i zostali na skale Rimmon przez cztery miesiące.
48 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì padà sí àwọn ìlú Benjamini wọn sì fi idà pa gbogbo ohun tí ó wà nínú àwọn ìlú wọn àti àwọn ẹran àti gbogbo ohun tí wọn ba níbẹ̀. Gbogbo ìlú tí wọ́n bá ní ojú ọ̀nà ni wọ́n fi iná sun.
Potem mężczyźni Izraela wrócili do synów Beniamina i wybili ich ostrzem miecza w mieście, zarówno ludzi, jak i bydło oraz wszystko, co znaleźli. Spalili ogniem także wszystkie miasta, które pozostały.