< Judges 20 >

1 Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli láti Dani dé Beerṣeba, àti láti ilẹ̀ Gileadi jáde bí ẹnìkan ṣoṣo wọ́n sì péjọ síwájú Olúwa ni Mispa.
All the Israelis, from Dan [city in the north] to Beersheba [city in the south], and even from [the] Gilead [region on the east side of the Jordan River, heard what had happened. So they] they gathered together at Mizpah, [at the place where they worshiped] Yahweh.
2 Àwọn olórí gbogbo àwọn ènìyàn láti gbogbo ẹ̀yà Israẹli dúró ní ipò wọn ní àpéjọ àwọn ènìyàn Ọlọ́run, ogún ọ̀kẹ́ ọkùnrin ológun ti àwọn àti idà wọn.
The leaders of [eleven of] the tribes of Israel stood in front of the people who gathered there. There were 400,000 men with swords who were there.
3 (Àwọn ẹ̀yà Benjamini gbọ́ wí pé àwọn ọmọ Israẹli yòókù ti gòkè lọ sí Mispa.) Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli wí pé, “Ẹ sọ fún wa báwo ni iṣẹ́ búburú ṣe ṣẹlẹ̀.”
The people of the tribe of Benjamin heard that the other Israelis had gone up to Mizpah, [but none of the men from their tribe went to the meeting there]. The Israelis who had come to Mizpah asked about the evil thing that had happened.
4 Ará Lefi náà, ọkọ obìnrin tí wọ́n pa fèsì pé, “Èmi àti àlè mi wá sí Gibeah ti àwọn ará Benjamini láti sùn di ilẹ̀ mọ́ níbẹ̀.
So the husband of the woman who had been killed replied, “My slave wife and I came to Gibeah [city], wanting to stay there that night.
5 Ṣùgbọ́n ní òru àwọn ọkùnrin Gibeah lépa mi wọ́n sì yí ilé náà po pẹ̀lú èrò láti pa mí. Wọ́n fi ipá bá àlè mi lòpọ̀, òun sì kú.
That evening, the men of Gibeah came to attack me. They surrounded the house [where I was staying] and wanted to [have sex with me and then] kill me. They [raped and] abused my slave wife [all night], and she died.
6 Mo mú àlè mi náà, mo sì gé e sí ekìrí ekìrí, mo sì fi ekìrí kọ̀ọ̀kan ránṣẹ́ sí agbègbè ìní Israẹli kọ̀ọ̀kan, nítorí pé wọ́n ti ṣe ohun tí ó jẹ́ èèwọ̀ àti ohun ìtìjú yìí ní ilẹ̀ Israẹli.
I took her body home and cut it into pieces. Then I sent one piece to each area of Israel, [because I wanted you all to know about] this wicked and disgraceful/shameful thing [that] has been done here in Israel.
7 Nísinsin yìí, gbogbo ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ sọ ìmọ̀ràn yín, kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ yín.”
So now, all you Israeli people, speak, and tell me what you think should be done!”
8 Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì dìde bí ẹnìkan pẹ̀lú gbólóhùn kan wí pé, “Kò sí ẹnikẹ́ni nínú wa tí yóò lọ sí àgọ́ rẹ̀. Rárá o, kò sí ẹyọ ẹnìkan tí yóò padà lọ sí ilé rẹ̀.
All the people stood up, and in unison said, “None of us will go home! Not one of us will return to his house!
9 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ohun tí àwa yóò ṣe sí Gibeah ní yìí. Àwa yóò lọ kọlù ú bí ìbò bá ṣe darí wa.
This is what we must do to [the people of] Gibeah. First, we will (cast lots/throw marked stones) [to determine which group should attack them].
10 A yóò mú ọkùnrin mẹ́wàá nínú ọgọ́rùn-ún nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli àti ọgọ́rùn-ún láti inú ẹgbẹ̀rún kan àti ẹgbẹ̀rún kan láti inú ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá láti máa pèsè oúnjẹ fún àwọn ọmọ-ogun. Yóò sì ṣe nígbà tí àwọn jagunjagun bá dé Gibeah ti àwọn ará Benjamini, wọn yóò fún wọn ní ohun tí ó bá tọ́ sí wọn fún gbogbo ìwà búburú àti ìwà ìtìjú tí wọ́n ṣe yìí ní ilẹ̀ Israẹli.”
We will choose (one tenth/one from every ten) of the men from all the Israeli tribes. Those men will go and find food for the men who will go to attack the people of Gibeah. Then the other men will go to Gibeah to (pay the people back/punish them) for this terrible thing that they have done [here] in Israel.”
11 Báyìí ni gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli parapọ̀ ṣọ̀kan bí ọkùnrin kan ṣoṣo wọ́n sì dìde sí ìlú náà.
And all the Israeli people agreed [that the people of Gibeah should be punished].
12 Àwọn ẹ̀yà Israẹli rán àwọn ọkùnrin sí gbogbo ẹ̀yà Benjamini wí pé, “Kí ni ẹ̀rí sí ìwà búburú yìí tí ó ṣẹlẹ̀ ní àárín yín?
Then the Israeli men sent messengers throughout the tribe of Benjamin. They demanded, “Do you realize that some of your men have done a very evil thing?
13 Nítorí náà ẹ mú àwọn ẹni ibi ti Gibeah yìí wá fún wa, kí àwa lé pa, kí a sì fọ ìṣe búburú yìí mọ́ kúrò ní Israẹli.” Ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Benjamini kò fetí sí ti àwọn arákùnrin wọn ọmọ Israẹli.
Bring those wicked men to us, in order that we can execute them. [By doing that], we will be doing what should be done because of this evil thing that has happened in Israel.” But the [people of the] tribe of Benjamin did not pay attention to their fellow Israelis.
14 Àwọn ẹ̀yà Benjamini sì kó ara wọn jọ láti àwọn ìlú wọn sí Gibeah láti bá àwọn ọmọ Israẹli jà.
The men of the tribe of Benjamin left their cities and gathered at Gibeah to fight the [other] Israelis.
15 Ní ẹsẹ̀kẹsẹ̀ àwọn ará Benjamini kó ẹgbàá mẹ́tàlá àwọn ọmọ-ogun tí ń lọ dájọ́ láti àwọn ìlú wọn, yàtọ̀ sí àwọn ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àṣàyàn ọkùnrin nínú àwọn tí ń gbé Gibeah.
In that one day the men of the tribe of Benjamin recruited 26,000 soldiers who knew how to fight using swords. They also chose/recruited 700 men from Gibeah.
16 Ní àárín àwọn ọmọ-ogun wọ̀nyí ni ó ti ní àwọn ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àṣàyàn ọkùnrin tí wọ́n ń lo ọwọ́ òsì, tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dára dé bi pé wọ́n lè fi kànnàkànnà ba fọ́nrán òwú ní àìtàsé (wọ́n jẹ́ atamọ́tàsé).
From all those soldiers there were 700 men who were left-handed, and each of them could sling a stone at [a target that was very small and as narrow as] a hair, and the stone always hit the target!
17 Àwọn ọkùnrin Israẹli, yàtọ̀ sí àwọn ará Benjamini, ka ogún ọ̀kẹ́ àwọn tí ń fi idà jagun, gbogbo wọn jẹ́ akọni ní ogun jíjà.
There were 400,000 men from the other Israeli tribes who had swords.
18 Àwọn ọmọ Israẹli lọ sí Beteli, wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run. Wọ́n wí pé, “Ta ni nínú wa tí yóò kọ́ kojú àwọn ará Benjamini láti bá wọn jà?” Olúwa dáhùn pé, “Juda ni yóò kọ́ lọ.”
Those other Israelis went up to Bethel and asked God, “Which tribe should be the first to attack the men from the tribe of Benjamin?” Yahweh answered, “[The men from the tribe of] Judah should go first.”
19 Àwọn ọmọ Israẹli dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, wọ́n sì dó ti Gibeah (wọ́n tẹ̀gùn sí ẹ̀bá Gibeah).
The next morning, the Israeli men went and set up their tents near Gibeah.
20 Àwọn ọkùnrin Israẹli jáde lọ láti bá àwọn ará Benjamini jà wọ́n sì dúró ní ipò ogun sí wọn ní Gibeah.
Then they went to fight against [the men from the tribe of] Benjamin, and stood in their positions for fighting a battle, [facing Gibeah].
21 Àwọn ọmọ Benjamini sì jáde láti Gibeah wá wọ́n sì pa àwọn ọmọ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ọkùnrin nínú àwọn ọmọ Israẹli ní ojú ogun ní ọjọ́ náà.
The men of the tribe of Benjamin came out of Gibeah and fought against them, and they killed 22,000 Israeli men on that day.
22 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Israẹli mú ara wọn lọ́kàn le, wọ́n sì tún dúró sí ipò wọn ní ibi tí wọ́n dúró sí ní ọjọ́ àkọ́kọ́.
[Late that afternoon], the [remaining] Israeli men went to the place of worship and cried until the sun set. Then they asked Yahweh, “Should we attack the men of the tribe of Benjamin again, even though they are our fellow Israelis?” Yahweh replied, “Yes, attack them again.” So the Israeli men encouraged each other.
23 Àwọn ọmọ Israẹli sì lọ wọ́n sọkún ní iwájú Olúwa títí oòrùn fi wọ̀, wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa. Wọ́n ni, “Ṣé kí àwa tún gòkè lọ kí a sì bá àwọn ará Benjamini arákùnrin wa jà?” Olúwa dáhùn pé, “Lọ bá wọn jà.”
24 Àwọn ọmọ Israẹli sì tún súnmọ́ tòsí àwọn ará Benjamini ní ọjọ́ kejì.
The next day they again stood in their positions for fighting, just like they had done on the previous day.
25 Ní ọjọ́ yìí nígbà tí ará Benjamini jáde sí wọn láti Gibeah, láti dojúkọ wọn, wọ́n pa ẹgbàá mẹ́sàn ọkùnrin Israẹli, gbogbo wọn jẹ́ jagunjagun tí ń lo idà.
The men of the tribe of Benjamin came out of Gibeah and attacked the Israelis, and killed 18,000 more of their men.
26 Nígbà náà ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli àní gbogbo àwọn ènìyàn, gòkè lọ sí Beteli, níbẹ̀ ni wọ́n jókòó tí wọ́n sì ń sọkún níwájú Olúwa. Wọ́n gbààwẹ̀ ní ọjọ́ náà títí di àṣálẹ́, wọ́n sì rú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà sí Olúwa.
[In the afternoon], all the people of Israel [who had not been killed] again went to Bethel. There they sat down and cried to Yahweh, and they (fasted/abstained from eating food) until it was evening. They brought some offerings which they burned completely [on the altar], and they also brought some offerings to maintain fellowship with Yahweh.
27 Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa. (Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run wà níbẹ̀,
At that time, the Sacred Chest that contained the stone tablets on which were written the Ten Commandments was there at Bethel. A priest named Phinehas, the son of Eleazar and grandson of Aaron, often stood in front of that chest [and talked with Yahweh]. While he stood there on that day, he asked Yahweh, “Shall we go again to fight against our fellow Israelis from the tribe of Benjamin, or shall we stop fighting against them?” Yahweh answered, “Go again tomorrow, because tomorrow I will enable you to defeat them.”
28 Finehasi ọmọ Eleasari ọmọ Aaroni, ní ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ ní iwájú rẹ̀.) wọ́n béèrè pé, “Ṣe àwa tún le lọ sí ogun pẹ̀lú Benjamini arákùnrin wa tàbí kí a má lọ?” Olúwa dáhùn pé, “Ẹ lọ nítorí ní ọ̀la ni èmi yóò fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.”
29 Àwọn ọmọ Israẹli sì yàn àwọn ènìyàn tí ó sá pamọ́ yí Gibeah ká.
So [the next day, 10,000 of] the Israeli men (set up ambushes/went to hide) [in the fields] around Gibeah.
30 Wọ́n jáde tọ àwọn ọmọ Benjamini lọ ní ọjọ́ kẹta wọ́n sì dúró ní ipò wọn, wọ́n sì dìde ogun sí Gibeah bí wọ́n ti ṣe tẹ́lẹ̀ rí.
The [other] Israeli men went and stood in their positions for fighting a battle just like they had done on the previous days.
31 Àwọn ọmọ Benjamini sì jáde láti pàdé wọn, àwọn ọmọ Israẹli sì tàn wọ́n jáde kúrò ní ìlú náà. Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣẹ́gun àwọn ọmọ Israẹli bí i ti àtijọ́ dé bi pé wọ́n pa bí ọgbọ̀n ọkùnrin ní pápá àti ní àwọn òpópó náà—àwọn ọ̀nà tí ó lọ sí Beteli àti èkejì sí Gibeah.
When the men of the tribe of Benjamin came out of the city to fight against them, the Israeli men retreated away from the city, and the men of the tribe of Benjamin pursued them. The men of the tribe of Benjamin killed many Israelis, like they had done before. They killed about 30 Israelis. They killed some in the fields, and they killed some on the road that went to Bethel and on the road that went to Gibeah.
32 Nígbà tí àwọn Benjamini ń wí pé, “Àwa ti ń ṣẹ́gun wọn bí i ti ìṣáájú,” àwọn ọmọ Israẹli ń wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sá kí a lè fà wọ́n kúrò ní ìlú sí ojú òpópó náà.”
The men of the tribe of Benjamin said, “We are defeating them like we did before!” But then Israeli men did what they had planned. The main group of Israeli men retreated a short distance from the city, to [trick] the men of Gibeah and cause them to pursue the Israeli men along the roads outside the city.
33 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli dìde kúrò ní ipò wọn, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Baali-Tamari, àwọn ọmọ-ogun Israẹli tí wọ́n sá pamọ́ sínú igbó jáde kúrò níbi tí wọ́n wà ní ìwọ̀-oòrùn Gibeah.
The main group of Israeli men left their positions and retreated, and then they stood in their battle positions again at a place named Baal-Tamar.
34 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn àṣàyàn ológun àwọn ọmọ Israẹli gbógun ti Gibeah láti iwájú ogun náà le gidigidi dé bí i pé àwọn ẹ̀yà Benjamini kò funra pé ìparun wà nítòsí.
Then [while the men of Gibeah were running out of the city toward them], the other 10,000 Israelis came out from the places where they had been hiding, west of Gibeah. They were men who had come from all parts of Israel. There was a very big battle. But the men of the tribe of Benjamin did not know that they were about to suffer a disastrous defeat.
35 Olúwa ṣẹ́gun Benjamini níwájú àwọn ọmọ Israẹli, ní ọjọ́ náà àwọn ọmọ Israẹli pa ẹgbàá méjìlá ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ọkùnrin Benjamini, gbogbo wọn fi idà dìhámọ́ra ogun.
Yahweh enabled the Israeli men to defeat the men of the tribe of Benjamin. They killed 25,000 of them, even though they all were using swords. [This is what happened]:
36 Àwọn ẹ̀yà Benjamini sì rí pé wọ́n ti ṣẹ́gun àwọn. Àwọn ọkùnrin Israẹli fàsẹ́yìn níwájú àwọn ẹ̀yà Benjamini nítorí pé wọ́n fọkàn tán àwọn tí ó wà ní ibùba ní ẹ̀bá Gibeah.
The main group of Israeli men arranged with the men who would be hiding that they should send up a smoke signal to enable the main group of soldiers to know when they should attack. Then the main group of Israeli men retreated for a short distance, because they knew that the other Israeli men who had been hiding on the other side of Gibeah would attack the people of the tribe of Benjamin by surprise. So [after the main group of Israeli men retreated a little distance], the men who had been hiding rushed out and ran into Gibeah and used their swords to kill everyone in the city. [Then they started to burn the buildings].
37 Àwọn ọkùnrin tí wọ́n lúgọ yára jáde wọ́n sì tètè wọ Gibeah, wọ́n fọ́nká wọ́n sì fi idà pa gbogbo àwọn tí ó wà nínú ìlú náà.
38 Àwọn ọkùnrin Israẹli àti àwọn tí o ba ní ibùba sínú igbó ti fún ara wọn ní àmì pé, kí àwọn tí ó ba ní ibùba fi èéfín ṣe ìkùùkuu ńlá láti inú ìlú náà,
39 nígbà náà ni àwọn ọkùnrin Israẹli yípadà, wọ́n sá gun. Àwọn ọmọ Benjamini sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ṣẹ́gun àti ní pípa àwọn ọkùnrin Israẹli tí ó to ọgbọ̀n, wọ́n sì wí pé, “Àwa ń ṣẹ́gun wọn bí ìgbà ìjà àkọ́kọ́.”
By that time, the men of the tribe of Benjamin said, “We are winning the battle, as we did before!”
40 Ṣùgbọ́n nígbà tí ìkùùkuu èéfín bẹ̀rẹ̀ sí ní rú sókè láti inú ìlú náà wá, àwọn ẹ̀yà Benjamini yípadà wọ́n sì rí èéfín gbogbo ìlú náà ń gòkè sí ojú ọ̀run.
But then smoke [from the burning buildings] began to rise up from the city. The men of the tribe of Benjamin turned around and saw that the whole city was burning.
41 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yípadà sí wọn, ẹ̀rù gidigidi sì ba àwọn ará Benjamini nítorí pé wọ́n mọ̀ pé àwọn wà nínú ewu.
Then the main group of Israeli men [also saw the smoke, and they knew that the smoke signaled that they should] turn around and begin to attack. The men of the tribe of Benjamin were very afraid, because they realized that they were about to suffer a disastrous defeat.
42 Wọ́n sì sá níwájú àwọn ọmọ Israẹli sí apá àṣálẹ́, ṣùgbọ́n wọn kò le sálà kúrò lọ́wọ́ ogun náà. Àwọn ọkùnrin Israẹli tí ó jáde láti inú àwọn ìlú wọn wá pa wọ́n run níbẹ̀.
So the men of the tribe of Benjamin tried to run away toward the desert to escape from the Israeli men, but they were not able to escape, because the Israeli men who had burned the two cities came out of those cities and killed many of them.
43 Wọ́n yí àwọn ẹ̀yà Benjamini ká, wọ́n lépa wọn, wọ́n sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìrọ̀rùn ní ibi ìsinmi wọn ní agbègbè ìlà-oòrùn Gibeah.
They surrounded [some of] the men of the tribe of Benjamin, and pursued the others to the area east of Gibeah.
44 Ẹgbàá mẹ́sàn àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣubú, gbogbo wọn jẹ́ akọni jagunjagun.
They killed 18,000 strong soldiers of the tribe of Benjamin.
45 Bí wọ́n ṣe síjú padà tí wọ́n sì ń sálọ sí apá ijù lọ sí ọ̀nà àpáta Rimoni ni àwọn ọmọ Israẹli pa ẹgbẹ̀rún márùn-ún ọkùnrin ní àwọn òpópónà. Wọ́n lépa àwọn ẹ̀yà Benjamini títí dé Gidomu, wọ́n sì tún bi ẹgbẹ̀rún méjì ọkùnrin ṣubú.
Then the rest of the men of the tribe of Benjamin realized that they had been defeated. They ran toward the desert to Rimmon Rock, but the Israeli men killed 5,000 more men of the tribe of Benjamin along the roads. They pursued the rest of them to Gidom, and they killed 2,000 more men of the tribe of Benjamin there.
46 Ní ọjọ́ náà ẹgbàá méjìlá ó lé ẹgbẹ̀rún jagunjagun Benjamini tí ń fi idà jagun ní ó ṣubú, gbogbo wọn jẹ́ akọni ológun.
Altogether, there were 25,000 men of the tribe of Benjamin who were killed, all of whom had swords.
47 Ṣùgbọ́n ẹgbẹ̀ta ọkùnrin yípadà wọ́n sì sá nínú ààlà lọ sí àpáta Rimoni, níbi tí wọ́n wà fún oṣù mẹ́rin.
But 600 men of the tribe of Benjamin ran to Rimmon Rock in the desert. They stayed there for four months.
48 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì padà sí àwọn ìlú Benjamini wọn sì fi idà pa gbogbo ohun tí ó wà nínú àwọn ìlú wọn àti àwọn ẹran àti gbogbo ohun tí wọn ba níbẹ̀. Gbogbo ìlú tí wọ́n bá ní ojú ọ̀nà ni wọ́n fi iná sun.
Then the Israeli men went back to the land belonging to the tribe of Benjamin, and killed the people in every city. They also killed all the animals, and destroyed everything else that they found there. And they burned all the cities that they came to.

< Judges 20 >