< Judges 2 >

1 Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa dìde kúrò láti Gilgali lọ sí Bokimu ó sì wí pé, “Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, èmi sì síwájú yín wá sí ilẹ̀ tí mo ti búra láti fi fún àwọn baba ńlá yín. Èmi sì wí pé, ‘Èmi kì yóò yẹ májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín,
Pǝrwǝrdigarning Pǝrixtisi Gilgaldin Bokimƣa kelip: — Mǝn silǝrni Misirdin qiⱪirip, ata-bowiliringlarƣa ⱪǝsǝm ⱪilip bǝrgǝn zeminƣa elip kelip: «Mǝn silǝr bilǝn ⱪilƣan ǝⱨdǝmni ǝbǝdgiqǝ bikar ⱪilmaymǝn;
2 ẹ̀yin kò gbọdọ̀ bá àwọn ènìyàn ilẹ̀ yí dá májẹ̀mú àlàáfíà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò wó pẹpẹ ibi ìsin òrìṣà wọn lulẹ̀.’ Síbẹ̀ ẹ̀yin ṣe àìgbọ́ràn sí mi. Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí?
Lekin silǝr bu zeminning hǝlⱪi bilǝn ⱨeqⱪandaⱪ ǝⱨdǝ baƣlimanglar, bǝlki ularning ⱪurbangaⱨlirini buzup taxlixinglar kerǝk» — degǝnidim; lekin silǝr Mening awazimƣa ⱪulaⱪ salmidinglar. Bu silǝrning nemǝ ⱪilƣininglar?!
3 Ní báyìí, èmi wí fún un yín pé, èmi kì yóò lé àwọn ènìyàn jáde kúrò níwájú yín; ṣùgbọ́n wọn yóò jẹ́ ẹ̀gún ní ìhà yín, àwọn òrìṣà wọn yóò sì jẹ́ ìdánwò fún un yín.”
Xunga Mǝn [xu qaƣda] silǝrgǝ: «[Xundaⱪ ⱪilsanglar] ularni silǝrning aldinglardin ⱪoƣliwǝtmǝymǝn; ular biⱪininglarƣa yantaⱪ bolup sanjilidu, ularning ilaⱨliri silǝrgǝ tor-tuzaⱪ bolidu» — dǝp agaⱨlandurdum, — dedi.
4 Bí angẹli Olúwa sì ti sọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ará Israẹli tan, àwọn ènìyàn náà sì gbé ohùn wọn sókè wọ́n sì sọkún kíkorò,
Pǝrwǝrdigarning Pǝrixtisi barliⱪ Israillarƣa bularni degǝndǝ, ular ün selip yiƣlap ketixti.
5 wọ́n sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Bokimu (ibi tí àwọn ènìyàn ti sọkún). Wọ́n sì rú ẹbọ sí Olúwa níbẹ̀.
Xuning bilǝn bu jayning nami «Bokim» dǝp ⱪoyuldi; ular xu yǝrdǝ Pǝrwǝrdigarƣa atap ⱪurbanliⱪlarni sundi.
6 Lẹ́yìn tí Joṣua ti tú àwọn ènìyàn Israẹli ká, àwọn ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan lọ sí ilẹ̀ tí a fi fún wọn láti lọ gbà á ní ìní wọn.
Yǝxua hǝlⱪni tarⱪitiwetiwidi, Israillar ⱨǝrⱪaysisi ɵzlirigǝ miras ⱪilinƣan zeminni igilǝx üqün ⱪaytip ketixti.
7 Àwọn ènìyàn náà sin Olúwa ní gbogbo ìgbà ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
Yǝxuaning pütkül ⱨayat künliridǝ, xundaⱪla Yǝxuadin keyin ⱪalƣan, Pǝrwǝrdigarning Israil üqün ⱪilƣan ⱨǝmmǝ karamǝt ǝmǝllirini obdan bilgǝn aⱪsaⱪallarning pütkül ⱨayat künliridimu [Israil] hǝlⱪi Pǝrwǝrdigarning ibaditidǝ bolup turdi.
8 Joṣua ọmọ Nuni, ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
Əmdi Nunning oƣli, Pǝrwǝrdigarning ⱪuli Yǝxua bir yüz on yexida wapat boldi.
9 Wọ́n sì sìnkú rẹ̀ sí ààlà ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní Timnati-Hereki ní ilẹ̀ òkè Efraimu ní àríwá òkè Gaaṣi.
Ular uni elip berip, Əfraim taƣliⱪ rayonida, Gaax teƣining ximal tǝripidiki ɵz miras ülüxi bolƣan Timnat-Seraⱨ degǝn jayda dǝpnǝ ⱪildi.
10 Ní ìgbẹ̀yìn, gbogbo ìran náà sì kú; àwọn ìran tí ó tẹ̀lé wọn kò sì sin Olúwa nítorí wọn kò mọ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò mọ ohun tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
Bu dǝwrdikilǝrning ⱨǝmmisi [ɵlüp] ɵz ata-bowiliriƣa ⱪoxulup kǝtti; ulardin keyin Pǝrwǝrdigarnimu tonumaydiƣan, xundaⱪla uning Israil üqün ⱪilƣan ǝmǝllirini bilmigǝn bir dǝwr pǝyda boldi.
11 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n sì ń sin òrìṣà Baali.
Xuningdin tartip Israil Pǝrwǝrdigarning nǝziridǝ rǝzil bolƣanni ⱪilip Baal-butlarning ibaditigǝ kirixti.
12 Wọ́n kọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn sílẹ̀, ẹni tí ó mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n ń tọ àwọn òrìṣà lẹ́yìn, wọ́n sì ń sin àwọn oríṣìíríṣìí òrìṣà àwọn ará ilẹ̀ ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú Olúwa bínú,
Ular ɵzlirini Misir zeminidin qiⱪirip elip kǝlgǝn ata-bowilirining Hudasi Pǝrwǝrdigarni taxlap, ǝtrapidiki taipilǝrning ilaⱨliridin bolƣan yat ilaⱨlarƣa ǝgixip, ularƣa bax urup, Pǝrwǝrdigarning ƣǝzipini ⱪozƣidi.
13 nítorí tí wọ́n kọ̀ Olúwa sílẹ̀ àti nítorí pé wọ́n ń sin Baali àti Aṣtoreti.
Ular Pǝrwǝrdigarni taxlap, Baal wǝ Axǝraⱨlarning ⱪulluⱪiƣa kirixti.
14 Nínú ìbínú rẹ̀ sí àwọn ọmọ Israẹli Olúwa fi wọ́n lé àwọn akónisìn lọ́wọ́ tí ó kó wọn ní ẹrú, tí ó sì bà wọ́n jẹ́. Ó sì tà wọ́n fún àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká àwọn ẹni tí wọn kò le dúró dè láti kọ ojú ìjà sí.
Buning bilǝn Pǝrwǝrdigarning ƣǝzipi Israilƣa tutixip, harab ⱪilinsun dǝp, u ularni talan-taraj ⱪilƣuqilarning ⱪoliƣa taxlap bǝrdi, yǝnǝ ǝtrapidiki düxmǝnlirining ⱪoliƣa tapxurup bǝrdi; xuning bilǝn ular düxmǝnlirining aldida bax kɵtürǝlmidi.
15 Nígbàkígbà tí àwọn Israẹli bá jáde lọ sí ojú ogun láti jà, ọwọ́ Olúwa sì wúwo ní ara wọn, àwọn ọ̀tá a sì borí wọn, àní gẹ́gẹ́ bí ó ti búra fún wọn. Wọ́n sì wà nínú ìpọ́njú púpọ̀.
Ular ⱪǝyǝrgǝ barmisun, Pǝrwǝrdigarning ⱪoli ularni apǝt bilǝn urdi, huddi Pǝrwǝrdigarning deginidǝk, wǝ Pǝrwǝrdigarning ularƣa ⱪǝsǝm ⱪilƣinidǝk, ular tolimu azabliⱪ ⱨalǝtkǝ qüxüp ⱪaldi.
16 Olúwa sì gbé àwọn onídàájọ́ dìde tí ó gbà wọ́n sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ń kó wọn lẹ́rú.
Andin Pǝrwǝrdigar [ularning arisidin] batur ⱨakimlarni turƣuzdi, ular [Israillarni] talan-taraj ⱪilƣuqilarning ⱪolidin ⱪutⱪuzup qiⱪti.
17 Síbẹ̀síbẹ̀ wọn kò fi etí sí ti àwọn onídàájọ́ wọn, ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àgbèrè, wọ́n ń sin òrìṣà. Wọn kò dàbí àwọn baba wọn, kíákíá ni wọ́n yípadà kúrò lọ́nà tí àwọn baba wọ́n ń tọ̀, ọ̀nà ìgbọ́ràn sí àwọn òfin Olúwa.
Xundaⱪtimu, ular ɵz ⱨakimliriƣa ⱪulaⱪ salmidi; ǝksiqǝ ular yat ilaⱨlarƣa ǝgixip buzuⱪluⱪ ⱪilip, ularƣa bax urup qoⱪundi; ata-bowilirining mangƣan yolidin, yǝni Pǝrwǝrdigarning ǝmrlirigǝ itaǝt ⱪilix yolidin tezla qiⱪip kǝtti; ular ⱨeq itaǝt ⱪilmidi.
18 Nígbà kí ìgbà tí Olúwa bá gbé onídàájọ́ dìde fún wọn, Olúwa máa ń wà pẹ̀lú onídàájọ́ náà, a sì gbà wọ́n kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn ní ìwọ̀n ìgbà tí onídàájọ́ náà bá wà láààyè nítorí àánú Olúwa wà ní ara wọn, nígbà tí wọ́n bá ké ìrora lábẹ́ àwọn tí ń tẹrí wọn ba, tí sì ń fi ìyà jẹ wọ́n.
Pǝrwǝrdigar ⱪaqaniki ular üqün batur ⱨakimlarni turƣuzsa, Pǝrwǝrdigar ⱨaman xu batur ⱨakim bilǝn billǝ bolatti, batur ⱨakimning ⱨayat künliridǝ ularni düxmǝnlirining ⱪolidin ⱪutⱪuzup qiⱪatti; qünki ularni harlap ǝzgǝnlǝr tüpǝylidin kɵtürülgǝn aⱨ-zarlarni angliƣan Pǝrwǝrdigar ularƣa iqini aƣritatti.
19 Ṣùgbọ́n ní kété tí onídàájọ́ bá ti kú, àwọn ènìyàn náà a sì tún padà sí ọ̀nà ìbàjẹ́ àní ju ti àwọn baba wọn lọ, wọn a tẹ̀lé òrìṣà, wọ́n ń sìn wọ́n, wọn a sì foríbalẹ̀ fún wọn, wọ́n kọ̀ láti yàgò kúrò ní ọ̀nà ibi wọn àti agídí ọkàn wọn.
Lekin batur ⱨakim ɵlüp ketixi bilǝnla, ular arⱪisiƣa yenip, yat ilaⱨlarƣa ǝgixip, ularning ⱪulluⱪiƣa kirip, ularƣa bax uruxup, ɵzlirini ata-bowiliridinmu ziyadǝ bulƣaytti; ular nǝ xu ⱪilmixliridin tohtimaytti, nǝ ɵz jaⱨil yolidin ⱨeq yanmaytti.
20 Ìbínú Olúwa yóò sì tún ru sí Israẹli a sì wí pé, “Nítorí tí orílẹ̀-èdè yìí ti yẹ májẹ̀mú tí mo fi lélẹ̀ fún àwọn baba ńlá wọn, tí wọn kò sì fetí sí mi,
Xuning bilǝn Pǝrwǝrdigarning ƣǝzipi Israilƣa ⱪattiⱪ tutaxti, U: — «Bu hǝlⱪ Mǝn ularning ata-bowiliriƣa tapiliƣan ǝⱨdǝmni buzup, awazimƣa ⱪulaⱪ salmiƣini üqün,
21 Èmi kì yóò lé ọ̀kankan nínú àwọn orílẹ̀-èdè tí Joṣua fi sílẹ̀ nígbà tí ó kú jáde.
buningdin keyin Mǝn Yǝxua ɵlgǝndǝ bu yurtta ⱪaldurƣan taipilǝrdin ⱨeqbirini ularning aldidin ⱪoƣliwǝtmǝymǝn;
22 Ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀ èmi yóò lo àwọn orílẹ̀-èdè yìí láti fi dán Israẹli wò, láti mọ̀ bóyá wọ́n yóò pa ọ̀nà Olúwa mọ́ àti pé bóyá wọn ó rìn nínú rẹ̀ bí àwọn baba ńlá wọn ti rìn.”
buningdiki mǝⱪsǝt, Mǝn xular arⱪiliⱪ Israilning ularning ata-bowiliri tutⱪandǝk, Mǝn Pǝrwǝrdigarning yolini tutup mangidiƣan-mangmaydiƣanliⱪini sinaymǝn» — dedi.
23 Nítorí náà Olúwa fi àwọn orílẹ̀-èdè náà sílẹ̀ ní ilẹ̀ náà kò sì lé wọn jáde, tàbí kí ó jẹ́ kí àwọn Israẹli pa wọ́n run, bẹ́ẹ̀ kò sì fi wọ́n lé Joṣua lọ́wọ́.
Xuning bilǝn Pǝrwǝrdigar xu taipilǝrni ⱪaldurup, ularni nǝ dǝrⱨalla zeminidin mǝⱨrum ⱪilip ⱪoƣliwǝtmidi nǝ Yǝxuaning ⱪoliƣimu tapxurup bǝrmigǝnidi.

< Judges 2 >