< Judges 2 >

1 Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa dìde kúrò láti Gilgali lọ sí Bokimu ó sì wí pé, “Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, èmi sì síwájú yín wá sí ilẹ̀ tí mo ti búra láti fi fún àwọn baba ńlá yín. Èmi sì wí pé, ‘Èmi kì yóò yẹ májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín,
І прийшов Ангол Господній з Ґілґалу до Бохіму, та й сказав: „Я вивів вас із Єгипту до того кра́ю, що присягнув був вашим батька́м. І сказав Я: не зламаю Свого заповіту з вами повіки!
2 ẹ̀yin kò gbọdọ̀ bá àwọn ènìyàn ilẹ̀ yí dá májẹ̀mú àlàáfíà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò wó pẹpẹ ibi ìsin òrìṣà wọn lulẹ̀.’ Síbẹ̀ ẹ̀yin ṣe àìgbọ́ràn sí mi. Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí?
А ви не складете заповіту з ме́шканцями цього краю, їхні же́ртівники порозбиваєте, — та не слухали ви Мого голосу. Що́ це ви зробили?
3 Ní báyìí, èmi wí fún un yín pé, èmi kì yóò lé àwọn ènìyàn jáde kúrò níwájú yín; ṣùgbọ́n wọn yóò jẹ́ ẹ̀gún ní ìhà yín, àwọn òrìṣà wọn yóò sì jẹ́ ìdánwò fún un yín.”
І Я теж сказав: Не прожену́ їх від вас, і вони стануть вам те́рням у боки, а їхні боги стануть вам па́сткою“.
4 Bí angẹli Olúwa sì ti sọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ará Israẹli tan, àwọn ènìyàn náà sì gbé ohùn wọn sókè wọ́n sì sọkún kíkorò,
І сталося, як Ангол Господній говорив ці слова́ до всіх Ізраїлевих синів, то народ підніс свій голос, та й заплакав.
5 wọ́n sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Bokimu (ibi tí àwọn ènìyàn ti sọkún). Wọ́n sì rú ẹbọ sí Olúwa níbẹ̀.
І назвали ім'я́ того місця: Бохім, і прино́сили там жертви Господе́ві.
6 Lẹ́yìn tí Joṣua ti tú àwọn ènìyàn Israẹli ká, àwọn ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan lọ sí ilẹ̀ tí a fi fún wọn láti lọ gbà á ní ìní wọn.
А Ісус відпустив наро́д, і Ізраїлеві сини розійшлися кожен до свого спа́дку, щоб посісти той край.
7 Àwọn ènìyàn náà sin Olúwa ní gbogbo ìgbà ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
І служив народ Господе́ві по всі дні Ісуса та по всі дні ста́рших, які продовжили дні свої по Ісусі, що бачили всякий великий чин Господа, якого зробив Він Ізра́їлеві.
8 Joṣua ọmọ Nuni, ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
І вмер Ісус, син Навинів, раб Господній, віку ста й десяти літ.
9 Wọ́n sì sìnkú rẹ̀ sí ààlà ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní Timnati-Hereki ní ilẹ̀ òkè Efraimu ní àríwá òkè Gaaṣi.
І поховали його в ме́жах спа́дщини його, у Тімнат-Хересі, в Єфремових гора́х, на пі́вніч від гори Ґааш.
10 Ní ìgbẹ̀yìn, gbogbo ìran náà sì kú; àwọn ìran tí ó tẹ̀lé wọn kò sì sin Olúwa nítorí wọn kò mọ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò mọ ohun tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
І також усе це покоління було прилучене до батьків своїх, а по них настало інше покоління, що не знало Господа, а також тих діл, які чинив Він Ізраїлеві.
11 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n sì ń sin òrìṣà Baali.
І Ізраїлеві сини чинили зло в Господніх оча́х, і служили Ваалам.
12 Wọ́n kọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn sílẹ̀, ẹni tí ó mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n ń tọ àwọn òrìṣà lẹ́yìn, wọ́n sì ń sin àwọn oríṣìíríṣìí òrìṣà àwọn ará ilẹ̀ ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú Olúwa bínú,
І вони покинули Господа, Бога батьків своїх, що вивів їх із єгипетського кра́ю, та й пішли за іншими бога́ми, за бога́ми тих народів, що були в їхніх око́лицях, і вклонялися їм, і гніви́ли Господа.
13 nítorí tí wọ́n kọ̀ Olúwa sílẹ̀ àti nítorí pé wọ́n ń sin Baali àti Aṣtoreti.
І покинули вони Господа, та й служили Ваа́лові та Аста́ртам.
14 Nínú ìbínú rẹ̀ sí àwọn ọmọ Israẹli Olúwa fi wọ́n lé àwọn akónisìn lọ́wọ́ tí ó kó wọn ní ẹrú, tí ó sì bà wọ́n jẹ́. Ó sì tà wọ́n fún àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká àwọn ẹni tí wọn kò le dúró dè láti kọ ojú ìjà sí.
І запала́в Господній гнів на Ізраїля, і Він дав їх у руку грабіжників, — і вони їх грабува́ли. І Він передав їх у руку навко́лишніх їхніх ворогів, і вони не могли вже встояти перед своїми ворогами.
15 Nígbàkígbà tí àwọn Israẹli bá jáde lọ sí ojú ogun láti jà, ọwọ́ Olúwa sì wúwo ní ara wọn, àwọn ọ̀tá a sì borí wọn, àní gẹ́gẹ́ bí ó ti búra fún wọn. Wọ́n sì wà nínú ìpọ́njú púpọ̀.
У всьому, де вони ходили, Господня рука була проти них на зло, як говорив був Господь, і як заприсягнув їм Господь. І Він дуже їх тиснув.
16 Olúwa sì gbé àwọn onídàájọ́ dìde tí ó gbà wọ́n sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ń kó wọn lẹ́rú.
І поставив Господь су́ддів, і вони рятували їх від руки їхніх грабіжників.
17 Síbẹ̀síbẹ̀ wọn kò fi etí sí ti àwọn onídàájọ́ wọn, ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àgbèrè, wọ́n ń sin òrìṣà. Wọn kò dàbí àwọn baba wọn, kíákíá ni wọ́n yípadà kúrò lọ́nà tí àwọn baba wọ́n ń tọ̀, ọ̀nà ìgbọ́ràn sí àwọn òfin Olúwa.
Та вони не слухалися також своїх суддів, бо блудили за іншими богами, і вклонялися їм. Вони скоро відхиля́лися з тієї дороги, якою йшли їхні батьки, щоб слухатися Господніх нака́зів. Вони так не робили!
18 Nígbà kí ìgbà tí Olúwa bá gbé onídàájọ́ dìde fún wọn, Olúwa máa ń wà pẹ̀lú onídàájọ́ náà, a sì gbà wọ́n kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn ní ìwọ̀n ìgbà tí onídàájọ́ náà bá wà láààyè nítorí àánú Olúwa wà ní ara wọn, nígbà tí wọ́n bá ké ìrora lábẹ́ àwọn tí ń tẹrí wọn ba, tí sì ń fi ìyà jẹ wọ́n.
А коли Господь ставив їм суддів, то Господь був із суддею, і рятував їх із руки їхніх ворогів по всі дні того судді́, бо Господь жалував їх через їхній сто́гін через тих, що їх переслідували та гноби́ли їх.
19 Ṣùgbọ́n ní kété tí onídàájọ́ bá ti kú, àwọn ènìyàn náà a sì tún padà sí ọ̀nà ìbàjẹ́ àní ju ti àwọn baba wọn lọ, wọn a tẹ̀lé òrìṣà, wọ́n ń sìn wọ́n, wọn a sì foríbalẹ̀ fún wọn, wọ́n kọ̀ láti yàgò kúrò ní ọ̀nà ibi wọn àti agídí ọkàn wọn.
І бувало, як умирав той суддя, вони зно́ву псувалися більше від своїх батьків, щоб іти за іншими богами, щоб їм служити та щоб їм вклонятися, і вони не кидали чи́нів своїх та своєї неслухня́ної дороги.
20 Ìbínú Olúwa yóò sì tún ru sí Israẹli a sì wí pé, “Nítorí tí orílẹ̀-èdè yìí ti yẹ májẹ̀mú tí mo fi lélẹ̀ fún àwọn baba ńlá wọn, tí wọn kò sì fetí sí mi,
І запалився Господній гнів на Ізраїля, і Він сказав: „За те, що люд цей переступив Мого заповіта, що Я наказав був їхнім батькам, і не слухалися Мого голосу,
21 Èmi kì yóò lé ọ̀kankan nínú àwọn orílẹ̀-èdè tí Joṣua fi sílẹ̀ nígbà tí ó kú jáde.
тож Я більше не виганятиму перед ними нікого з тих народів, що Ісус позоставив, умира́ючи,
22 Ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀ èmi yóò lo àwọn orílẹ̀-èdè yìí láti fi dán Israẹli wò, láti mọ̀ bóyá wọ́n yóò pa ọ̀nà Olúwa mọ́ àti pé bóyá wọn ó rìn nínú rẹ̀ bí àwọn baba ńlá wọn ti rìn.”
щоб ви́пробувати ними Ізраїля, — чи держатимуться вони Господньої дороги, щоб нею ходити, як держалися їхні батьки, чи ні.
23 Nítorí náà Olúwa fi àwọn orílẹ̀-èdè náà sílẹ̀ ní ilẹ̀ náà kò sì lé wọn jáde, tàbí kí ó jẹ́ kí àwọn Israẹli pa wọ́n run, bẹ́ẹ̀ kò sì fi wọ́n lé Joṣua lọ́wọ́.
І Господь позоставив тих людей, щоб їх скоро не виганяти, і не дав їх у руку Ісусову.

< Judges 2 >