< Judges 2 >
1 Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa dìde kúrò láti Gilgali lọ sí Bokimu ó sì wí pé, “Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, èmi sì síwájú yín wá sí ilẹ̀ tí mo ti búra láti fi fún àwọn baba ńlá yín. Èmi sì wí pé, ‘Èmi kì yóò yẹ májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín,
Felméne pedig az Úrnak angyala Gilgálból Bókimba, és monda: Én vezettelek fel titeket Égyiptomból, és hoztalak benneteket erre a földre, a mely felől megesküdtem a ti atyáitoknak, és mondék: Nem bontom fel az én szövetségemet ti veletek soha örökké.
2 ẹ̀yin kò gbọdọ̀ bá àwọn ènìyàn ilẹ̀ yí dá májẹ̀mú àlàáfíà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò wó pẹpẹ ibi ìsin òrìṣà wọn lulẹ̀.’ Síbẹ̀ ẹ̀yin ṣe àìgbọ́ràn sí mi. Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí?
Csakhogy ti se kössetek frigyet ennek a földnek lakosival, rontsátok le az ő oltáraikat; de ti nem hallgattatok az én szómra. Miért cselekedtétek ezt?
3 Ní báyìí, èmi wí fún un yín pé, èmi kì yóò lé àwọn ènìyàn jáde kúrò níwájú yín; ṣùgbọ́n wọn yóò jẹ́ ẹ̀gún ní ìhà yín, àwọn òrìṣà wọn yóò sì jẹ́ ìdánwò fún un yín.”
Annakokáért azt mondom: Nem űzöm el őket előletek, hanem legyenek néktek mint tövisek a ti oldalaitokban, és az ő isteneik legyenek ti néktek tőr gyanánt.
4 Bí angẹli Olúwa sì ti sọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ará Israẹli tan, àwọn ènìyàn náà sì gbé ohùn wọn sókè wọ́n sì sọkún kíkorò,
És lőn, hogy mikor az Úrnak angyala ezeket mondá az Izráel minden fiainak: felemelé a nép az ő szavát és síra.
5 wọ́n sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Bokimu (ibi tí àwọn ènìyàn ti sọkún). Wọ́n sì rú ẹbọ sí Olúwa níbẹ̀.
És elnevezték azt a helyet Bókimnak, és áldozának ott az Úrnak.
6 Lẹ́yìn tí Joṣua ti tú àwọn ènìyàn Israẹli ká, àwọn ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan lọ sí ilẹ̀ tí a fi fún wọn láti lọ gbà á ní ìní wọn.
És elbocsátá Józsué a népet, és elmenének az Izráel fiai, kiki az ő örökségébe, hogy bírják a földet.
7 Àwọn ènìyàn náà sin Olúwa ní gbogbo ìgbà ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
És a nép az Urat szolgálta Józsuénak egész életében, és a véneknek minden napjaiban, a kik hosszú ideig éltek Józsué után, a kik látták az Úrnak minden dolgait, melyeket cselekedett vala Izráellel.
8 Joṣua ọmọ Nuni, ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
És meghalt Józsué, a Nún fia, az Úr szolgája, száztíz esztendős korában.
9 Wọ́n sì sìnkú rẹ̀ sí ààlà ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní Timnati-Hereki ní ilẹ̀ òkè Efraimu ní àríwá òkè Gaaṣi.
És eltemeték őt örökségének határában, Timnat-Héreszben, az Efraim hegyén, északra a Gaas hegyétől.
10 Ní ìgbẹ̀yìn, gbogbo ìran náà sì kú; àwọn ìran tí ó tẹ̀lé wọn kò sì sin Olúwa nítorí wọn kò mọ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò mọ ohun tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
És az az egész nemzetség gyűjteték az ő atyáihoz, és támadott más nemzetség ő utánok, a mely nem ismerte sem az Urat, sem az ő cselekedeteit, melyeket cselekedett Izráellel.
11 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n sì ń sin òrìṣà Baali.
És gonoszul cselekedtek az Izráel fiai az Úrnak szemei előtt, mert a Baáloknak szolgáltak.
12 Wọ́n kọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn sílẹ̀, ẹni tí ó mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n ń tọ àwọn òrìṣà lẹ́yìn, wọ́n sì ń sin àwọn oríṣìíríṣìí òrìṣà àwọn ará ilẹ̀ ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú Olúwa bínú,
És elhagyák az Urat, atyáik Istenét, a ki kihozta őket Égyiptom földéből, és más istenek után jártak, a pogány népek istenei közül, a kik körülöttük voltak, és azok előtt hajtották meg magukat, és haragra ingerelték az Urat.
13 nítorí tí wọ́n kọ̀ Olúwa sílẹ̀ àti nítorí pé wọ́n ń sin Baali àti Aṣtoreti.
És elhagyták az Urat, és szolgáltak Baálnak és Astarótnak.
14 Nínú ìbínú rẹ̀ sí àwọn ọmọ Israẹli Olúwa fi wọ́n lé àwọn akónisìn lọ́wọ́ tí ó kó wọn ní ẹrú, tí ó sì bà wọ́n jẹ́. Ó sì tà wọ́n fún àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká àwọn ẹni tí wọn kò le dúró dè láti kọ ojú ìjà sí.
És felgerjedett az Úrnak haragja Izráel ellen, és adá őket a ragadozók kezébe, és elragadozák őket, és adá őket a körülöttük való ellenségeik kezébe, és még csak megállani sem bírtak ellenségeik előtt.
15 Nígbàkígbà tí àwọn Israẹli bá jáde lọ sí ojú ogun láti jà, ọwọ́ Olúwa sì wúwo ní ara wọn, àwọn ọ̀tá a sì borí wọn, àní gẹ́gẹ́ bí ó ti búra fún wọn. Wọ́n sì wà nínú ìpọ́njú púpọ̀.
A hova csak kivonultak, mindenütt ellenök volt az Úr keze rontásukra, a mint megmondotta volt az Úr, és a mint megesküdt volt az Úr nékik. És igen megnyomorodának.
16 Olúwa sì gbé àwọn onídàájọ́ dìde tí ó gbà wọ́n sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ń kó wọn lẹ́rú.
És támasztott az Úr bírákat, a kik megszabadíták őket szorongatóiknak kezéből.
17 Síbẹ̀síbẹ̀ wọn kò fi etí sí ti àwọn onídàájọ́ wọn, ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àgbèrè, wọ́n ń sin òrìṣà. Wọn kò dàbí àwọn baba wọn, kíákíá ni wọ́n yípadà kúrò lọ́nà tí àwọn baba wọ́n ń tọ̀, ọ̀nà ìgbọ́ràn sí àwọn òfin Olúwa.
De bíráikra sem hallgattak, hanem más istenekkel paráználkodtak, és azoknak hajtották meg magukat, és hamar letértek az útról, a melyen atyáik jártak, kik az Úrnak parancsára hallgattak; ők nem cselekedtek így.
18 Nígbà kí ìgbà tí Olúwa bá gbé onídàájọ́ dìde fún wọn, Olúwa máa ń wà pẹ̀lú onídàájọ́ náà, a sì gbà wọ́n kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn ní ìwọ̀n ìgbà tí onídàájọ́ náà bá wà láààyè nítorí àánú Olúwa wà ní ara wọn, nígbà tí wọ́n bá ké ìrora lábẹ́ àwọn tí ń tẹrí wọn ba, tí sì ń fi ìyà jẹ wọ́n.
Mert mikor bírákat támasztott az Úr nékik, az Úr maga volt a bíróval, és megszabadította őket ellenségeik kezéből a biró egész idejére, mert megindult az Úr panaszaikon, melyeket emeltek elnyomóik és szorongatóik miatt.
19 Ṣùgbọ́n ní kété tí onídàájọ́ bá ti kú, àwọn ènìyàn náà a sì tún padà sí ọ̀nà ìbàjẹ́ àní ju ti àwọn baba wọn lọ, wọn a tẹ̀lé òrìṣà, wọ́n ń sìn wọ́n, wọn a sì foríbalẹ̀ fún wọn, wọ́n kọ̀ láti yàgò kúrò ní ọ̀nà ibi wọn àti agídí ọkàn wọn.
De mihelyt a bíró meghalt, visszatértek, és jobban megromlottak, mint atyáik; más istenek után jártak, azoknak szolgáltak, és azok előtt hajtották meg magukat, föl nem hagytak cselekedeteikkel és nyakas magaviseletökkel.
20 Ìbínú Olúwa yóò sì tún ru sí Israẹli a sì wí pé, “Nítorí tí orílẹ̀-èdè yìí ti yẹ májẹ̀mú tí mo fi lélẹ̀ fún àwọn baba ńlá wọn, tí wọn kò sì fetí sí mi,
Ezért felgerjedett az Úrnak haragja Izráel ellen, és monda: Mivelhogy általhágta ez a nemzetség az én szövetségemet, melyet atyáiknak parancsoltam, és nem hallgatott az én szavamra:
21 Èmi kì yóò lé ọ̀kankan nínú àwọn orílẹ̀-èdè tí Joṣua fi sílẹ̀ nígbà tí ó kú jáde.
Én sem űzök ki többé senkit sem előlük azon pogányok közül, a kiket meghagyott Józsué, a mikor meghalt;
22 Ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀ èmi yóò lo àwọn orílẹ̀-èdè yìí láti fi dán Israẹli wò, láti mọ̀ bóyá wọ́n yóò pa ọ̀nà Olúwa mọ́ àti pé bóyá wọn ó rìn nínú rẹ̀ bí àwọn baba ńlá wọn ti rìn.”
Hanem azok által kísértem Izráelt, ha vajjon megtartják-é az Úrnak útát, járván azon, a miképen megtartották az ő atyáik, avagy nem?
23 Nítorí náà Olúwa fi àwọn orílẹ̀-èdè náà sílẹ̀ ní ilẹ̀ náà kò sì lé wọn jáde, tàbí kí ó jẹ́ kí àwọn Israẹli pa wọ́n run, bẹ́ẹ̀ kò sì fi wọ́n lé Joṣua lọ́wọ́.
Ezért hagyta meg az Úr ezeket a pogányokat, és nem is űzte ki hamar, és nem adta őket Józsué kezébe.