< Judges 2 >

1 Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa dìde kúrò láti Gilgali lọ sí Bokimu ó sì wí pé, “Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, èmi sì síwájú yín wá sí ilẹ̀ tí mo ti búra láti fi fún àwọn baba ńlá yín. Èmi sì wí pé, ‘Èmi kì yóò yẹ májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín,
Na rĩrĩ, mũraika wa Jehova nĩambatire agĩkinya Bokimu oimĩte Giligali, akiuga atĩrĩ, “Niĩ nĩ niĩ ndaamwambatirie ngĩmũruta bũrũri wa Misiri na ngĩmũtongoria nginya bũrũri-inĩ ũrĩa ndeerĩire maithe manyu na mwĩhĩtwa atĩ nĩngamahe. Ngiuga atĩrĩ, ‘Niĩ ndirĩ hĩndĩ ngaathũkia kĩrĩkanĩro giitũ na inyuĩ,
2 ẹ̀yin kò gbọdọ̀ bá àwọn ènìyàn ilẹ̀ yí dá májẹ̀mú àlàáfíà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò wó pẹpẹ ibi ìsin òrìṣà wọn lulẹ̀.’ Síbẹ̀ ẹ̀yin ṣe àìgbọ́ràn sí mi. Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí?
na inyuĩ mũtikanagĩe na kĩrĩkanĩro na andũ a bũrũri ũyũ, no nĩmũkoinanga igongona ciao.’ No inyuĩ mũtiinjathĩkĩire. Mwĩkĩte ũguo nĩkĩ?
3 Ní báyìí, èmi wí fún un yín pé, èmi kì yóò lé àwọn ènìyàn jáde kúrò níwájú yín; ṣùgbọ́n wọn yóò jẹ́ ẹ̀gún ní ìhà yín, àwọn òrìṣà wọn yóò sì jẹ́ ìdánwò fún un yín.”
Nĩ ũndũ ũcio, ndamwĩra atĩrĩ, ndikũmaingata mamweherere; no megũtuĩka ta mĩigua ĩmũtheecage mĩena, nacio ngai ciao ituĩke mũtego harĩ inyuĩ.”
4 Bí angẹli Olúwa sì ti sọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ará Israẹli tan, àwọn ènìyàn náà sì gbé ohùn wọn sókè wọ́n sì sọkún kíkorò,
Rĩrĩa mũraika wa Jehova aarĩkirie kwarĩria andũ a Isiraeli maũndũ macio mothe, andũ makĩrĩra manĩrĩire,
5 wọ́n sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Bokimu (ibi tí àwọn ènìyàn ti sọkún). Wọ́n sì rú ẹbọ sí Olúwa níbẹ̀.
nao magĩĩta handũ hau Bokimu. Nao makĩrutĩra Jehova magongona hau.
6 Lẹ́yìn tí Joṣua ti tú àwọn ènìyàn Israẹli ká, àwọn ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan lọ sí ilẹ̀ tí a fi fún wọn láti lọ gbà á ní ìní wọn.
Thuutha wa Joshua kũrekereria andũ a Isiraeli-rĩ, andũ acio magĩthiĩ kwĩgwatĩra bũrũri, o mũndũ igai rĩake.
7 Àwọn ènìyàn náà sin Olúwa ní gbogbo ìgbà ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
Nao andũ acio magĩtungatĩra Jehova matukũ-inĩ mothe ma Joshua na ma athuuri arĩa maatigirwo marĩ muoyo Joshua akua, arĩa meyoneire maũndũ mothe manene marĩa Jehova eekĩire Isiraeli.
8 Joṣua ọmọ Nuni, ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
Nake Joshua mũrũ wa Nuni, ndungata ya Jehova, aakuire arĩ na ũkũrũ wa mĩaka igana na ikũmi.
9 Wọ́n sì sìnkú rẹ̀ sí ààlà ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní Timnati-Hereki ní ilẹ̀ òkè Efraimu ní àríwá òkè Gaaṣi.
Nao makĩmũthika kũu gĩthaka-inĩ gĩake o kũu Timinathu-Heresi bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma wa Efiraimu, mwena wa gathigathini wa Kĩrĩma kĩa Gaashu.
10 Ní ìgbẹ̀yìn, gbogbo ìran náà sì kú; àwọn ìran tí ó tẹ̀lé wọn kò sì sin Olúwa nítorí wọn kò mọ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò mọ ohun tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
Thuutha wa rũciaro rũu ruothe gũkua, gũkĩgĩa na rũciaro rũngĩ rũtooĩ Jehova kana rũkamenya maũndũ marĩa eekĩire Isiraeli.
11 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n sì ń sin òrìṣà Baali.
Ningĩ andũ a Isiraeli magĩĩka maũndũ mooru maitho-inĩ ma Jehova na magĩtungatĩra ngai cia Baali.
12 Wọ́n kọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn sílẹ̀, ẹni tí ó mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n ń tọ àwọn òrìṣà lẹ́yìn, wọ́n sì ń sin àwọn oríṣìíríṣìí òrìṣà àwọn ará ilẹ̀ ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú Olúwa bínú,
Nao magĩtirika Jehova, Ngai wa maithe mao ũrĩa wamarutĩte bũrũri wa Misiri. Nao makĩrũmĩrĩra na makĩhooya ngai cia mĩthemba mĩingĩ cia andũ arĩa maamarigiicĩirie, magĩtũma Jehova arakare
13 nítorí tí wọ́n kọ̀ Olúwa sílẹ̀ àti nítorí pé wọ́n ń sin Baali àti Aṣtoreti.
tondũ nĩmatirikĩte Jehova, magatungatagĩra Baali na Maashitarothu.
14 Nínú ìbínú rẹ̀ sí àwọn ọmọ Israẹli Olúwa fi wọ́n lé àwọn akónisìn lọ́wọ́ tí ó kó wọn ní ẹrú, tí ó sì bà wọ́n jẹ́. Ó sì tà wọ́n fún àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká àwọn ẹni tí wọn kò le dúró dè láti kọ ojú ìjà sí.
Nake Jehova akĩrakarĩra andũ a Isiraeli, akĩmaneana kũrĩ atharĩkanĩri arĩa maatahire indo ciao. Akĩmarekereria thũ ciao iria ciamathiũrũrũkĩirie, na matiacookire gũciĩtiiria.
15 Nígbàkígbà tí àwọn Israẹli bá jáde lọ sí ojú ogun láti jà, ọwọ́ Olúwa sì wúwo ní ara wọn, àwọn ọ̀tá a sì borí wọn, àní gẹ́gẹ́ bí ó ti búra fún wọn. Wọ́n sì wà nínú ìpọ́njú púpọ̀.
Rĩrĩa rĩothe andũ a Isiraeli maathiiaga kũrũa, guoko kwa Jehova kwamookagĩrĩra magatoorio, o ta ũrĩa eehĩtĩte na mwĩhĩtwa kũrĩ o. Nao makĩnyamarĩka mũno.
16 Olúwa sì gbé àwọn onídàájọ́ dìde tí ó gbà wọ́n sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ń kó wọn lẹ́rú.
Ningĩ Jehova akĩmaarahũrĩra atiirĩrĩri bũrũri arĩa maamahonokirie moko-inĩ ma andũ acio maamatharĩkagĩra.
17 Síbẹ̀síbẹ̀ wọn kò fi etí sí ti àwọn onídàájọ́ wọn, ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àgbèrè, wọ́n ń sin òrìṣà. Wọn kò dàbí àwọn baba wọn, kíákíá ni wọ́n yípadà kúrò lọ́nà tí àwọn baba wọ́n ń tọ̀, ọ̀nà ìgbọ́ràn sí àwọn òfin Olúwa.
No rĩrĩ, o na kũrĩ ũguo, matiigana kũigua atiirĩrĩri bũrũri acio ao, no nĩmahũũrire ũmaraya na ũndũ wa kũhooya ngai ingĩ. Matiigana gwĩka ta maithe mao, no nĩmagarũrũkire narua, magĩtiga gũthiĩ na mĩthiĩre ĩrĩa maithe mao maathiiaga nayo, nĩyo mĩthiĩre ya gwathĩkĩra maathani ma Jehova.
18 Nígbà kí ìgbà tí Olúwa bá gbé onídàájọ́ dìde fún wọn, Olúwa máa ń wà pẹ̀lú onídàájọ́ náà, a sì gbà wọ́n kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn ní ìwọ̀n ìgbà tí onídàájọ́ náà bá wà láààyè nítorí àánú Olúwa wà ní ara wọn, nígbà tí wọ́n bá ké ìrora lábẹ́ àwọn tí ń tẹrí wọn ba, tí sì ń fi ìyà jẹ wọ́n.
Rĩrĩa rĩothe Jehova aamaarahũragĩra mũtiirĩrĩri bũrũri-rĩ, Jehova aakoragwo hamwe na mũtiirĩrĩri bũrũri ũcio, akamahonokagia moko-inĩ ma thũ ciao hĩndĩ ĩrĩa yothe mũtiirĩrĩri bũrũri ũcio aarĩ muoyo; nĩgũkorwo Jehova nĩamaiguagĩra tha nĩ ũndũ wa ũrĩa macaayaga nĩ kũhinyĩrĩrio nĩ arĩa mamanyariiraga.
19 Ṣùgbọ́n ní kété tí onídàájọ́ bá ti kú, àwọn ènìyàn náà a sì tún padà sí ọ̀nà ìbàjẹ́ àní ju ti àwọn baba wọn lọ, wọn a tẹ̀lé òrìṣà, wọ́n ń sìn wọ́n, wọn a sì foríbalẹ̀ fún wọn, wọ́n kọ̀ láti yàgò kúrò ní ọ̀nà ibi wọn àti agídí ọkàn wọn.
No mũtiirĩrĩri bũrũri akua, andũ magacookerera maũndũ mooru makĩria kũrĩ marĩa ma maithe mao, makarũmagĩrĩra ngai ingĩ, magacihooyaga na magacitungatĩra. Makĩrega gũtiga mĩtugo ĩyo yao mĩũru na mĩthiĩre yao ya ũremi.
20 Ìbínú Olúwa yóò sì tún ru sí Israẹli a sì wí pé, “Nítorí tí orílẹ̀-èdè yìí ti yẹ májẹ̀mú tí mo fi lélẹ̀ fún àwọn baba ńlá wọn, tí wọn kò sì fetí sí mi,
Tondũ ũcio, Jehova agĩkĩrakario mũno nĩ andũ a Isiraeli, akiuga atĩrĩ, “Tondũ rũrĩrĩ rũrũ nĩrũthũkĩtie kĩrĩkanĩro kĩrĩa ndaarĩkanĩire na maithe mao ma tene, na nĩ rwagĩte kũnjigua-rĩ,
21 Èmi kì yóò lé ọ̀kankan nínú àwọn orílẹ̀-èdè tí Joṣua fi sílẹ̀ nígbà tí ó kú jáde.
ndigũcooka kũrutũrũra rũrĩrĩ o na rũmwe rwa iria Joshua aatigire kuo agĩkua.
22 Ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀ èmi yóò lo àwọn orílẹ̀-èdè yìí láti fi dán Israẹli wò, láti mọ̀ bóyá wọ́n yóò pa ọ̀nà Olúwa mọ́ àti pé bóyá wọn ó rìn nínú rẹ̀ bí àwọn baba ńlá wọn ti rìn.”
Nĩcio ngũhũthĩra kũgeria andũ a Isiraeli, nĩguo menye kana nĩmekũrũmia mĩthiĩre ya Jehova, na mathiiage nayo o ta ũrĩa maithe mao meekaga.”
23 Nítorí náà Olúwa fi àwọn orílẹ̀-èdè náà sílẹ̀ ní ilẹ̀ náà kò sì lé wọn jáde, tàbí kí ó jẹ́ kí àwọn Israẹli pa wọ́n run, bẹ́ẹ̀ kò sì fi wọ́n lé Joṣua lọ́wọ́.
Jehova nĩetĩkĩririe ndũrĩrĩ icio itigare kuo, na ndaigana gũcirutũrũra o rĩmwe na ũndũ wa gũcineana moko-inĩ ma Joshua.

< Judges 2 >