< Judges 19 >

1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì Israẹli kò ní ọba. Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Lefi tí ń gbé ibi tí ó sá pamọ́ nínú àwọn agbègbè òkè Efraimu, mú àlè kan láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda.
På den tiden, då ännu ingen konung fanns i Israel, bodde en levitisk man längst uppe i Efraims bergsbygd. Denne tog till bihustru åt sig en kvinna från Bet-Lehem i Juda.
2 Ṣùgbọ́n àlè rẹ̀ náà sì ṣe panṣágà sí i, òun fi sílẹ̀, ó sì padà lọ sí ilé baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu ti Juda, ó sì wà ní ibẹ̀ ní ìwọ̀n oṣù mẹ́rin,
Men hans bihustru blev honom otrogen och gick ifrån honom till sin faders hus i Bet-Lehem i Juda; där uppehöll hon sig en tid av fyra månader.
3 ọkọ rẹ̀ lọ sí ibẹ̀ láti rọ̀ ọ́ pé kí ó padà sí ọ̀dọ̀ òun. Nígbà tí ó ń lọ ó mú ìránṣẹ́ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì lọ́wọ́, obìnrin náà mú un wọ inú ilé baba rẹ̀ lọ, nígbà tí baba obìnrin náà rí i ó fi tayọ̀tayọ̀ gbà á.
Då stod hennes man upp och begav sig åstad efter henne, för att tala vänligt med henne och så föra henne tillbaka; och han hade med sig sin tjänare och ett par åsnor. Hon förde honom då in i sin faders hus, och när kvinnans fader fick se honom, gick han glad emot honom.
4 Àna rẹ̀, baba ọmọbìnrin náà rọ̀ ọ́, ó sì borí rẹ̀ láti dá a dúró fún ìgbà díẹ̀, òun sì dúró fún ọjọ́ mẹ́ta, ó ń jẹ, ó ń mu, ó sì ń sùn níbẹ̀.
Och hans svärfader, kvinnans fader, höll honom kvar, så att han stannade hos honom i tre dagar; de åto och drucko och voro där nätterna över.
5 Ní ọjọ́ kẹrin, wọ́n dìde ní òwúrọ̀ kùtùkùtù òun sì múra láti padà lọ, ṣùgbọ́n baba ọmọbìnrin náà wí fún àna rẹ̀ pé, “Fi ohun jíjẹ díẹ̀ gbé inú ró nígbà náà kí ìwọ máa lọ.”
När de nu på fjärde dagen stodo upp bittida om morgonen och han gjorde sig redo att resa, sade kvinnans fader till sin måg: "Vederkvick dig med ett stycke bröd; sedan mån I resa."
6 Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ jókòó láti jọ jẹun àti láti jọ mu. Lẹ́yìn èyí ni baba ọmọbìnrin wí pé, “Jọ̀wọ́ dúró ní alẹ́ yìí kí o sì gbádùn ara rẹ.”
Då satte de sig ned och åto båda tillsammans och drucko. Därefter sade kvinnans fader till mannen: "Beslut dig för att stanna här över natten, och låt ditt hjärta vara glatt."
7 Nígbà tí ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, baba ìyàwó rẹ̀ rọ̀ ọ́, torí náà ó sùn níbẹ̀ ní alẹ́ ọjọ́ náà.
Och när mannen ändå gjorde sig redo att resa, bad hans svärfader honom så enträget, att han ännu en gång stannade kvar där över natten.
8 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ karùn-ún nígbà tí ó dìde láti lọ, baba ọmọbìnrin wí pé, “Fi oúnjẹ gbé ara ró. Dúró de ọ̀sán!” Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ jọ jẹun.
På femte dagen stod han åter upp bittida om morgonen för att resa; då sade kvinnans fader: "Vederkvick dig först, och dröjen så till eftermiddagen." Därefter åto de båda tillsammans.
9 Nígbà tí ọkùnrin náà, pẹ̀lú àlè àti ìránṣẹ́ rẹ̀, dìde láti máa lọ, àna rẹ̀, baba ọmọbìnrin náà ní, “Wò ó ilẹ̀ ti ń ṣú lọ, dúró níbí, ọjọ́ ti lọ. Dúró kí o sì gbádùn ara rẹ. Ìwọ lè jí ní àárọ̀ kùtùkùtù ọ̀la kí ìwọ sì máa lọ ilé.”
När sedan mannen gjorde sig redo att resa med sin bihustru och sin tjänare, sade hans svärfader, kvinnans fader, till honom: "Se, det lider mot aftonen; stannen kvar över natten, dagen nalkas ju sitt slut; ja, stanna kvar här över natten, och låt ditt hjärta vara glatt. Sedan kunnen I i morgon bittida företaga eder färd, så att du får komma hem till din hydda."
10 Ṣùgbọ́n nítorí pé òun kò fẹ́ dúró mọ́ níbẹ̀ ní òru náà ọkùnrin náà kúrò ó sì gba ọ̀nà Jebusi: ọ̀nà Jerusalẹmu pẹ̀lú àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ méjèèjì tí ó fi dì í ní gàárì àti àlè rẹ̀.
Men mannen ville icke stanna över natten, utan gjorde sig redo och reste sin väg, och kom så fram till platsen mitt emot Jebus, det är Jerusalem. Och han hade med sig ett par sadlade åsnor; och hans bihustru följde honom.
11 Nígbà tí wọ́n súnmọ́ Jebusi tí ilẹ̀ ti fẹ́ ṣú tan, ìránṣẹ́ náà sọ fún ọ̀gá rẹ̀ pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a dúró ní ìlú yìí tí í ṣe ti àwọn ará Jebusi kí a sì sùn níbẹ̀.”
Då de nu voro vid Jebus och dagen var långt framliden, sade tjänaren till sin herre: "Kom, låt oss taga in i denna jebuséstad och stanna där över natten."
12 Ọ̀gá rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Rárá o, àwa kì yóò wọ ìlú àwọn àjèjì, àwọn tí olùgbé ibẹ̀ kì í ṣe ọmọ Israẹli, a yóò dé Gibeah.”
Men hans herre svarade honom: "Vi skola icke taga in i en främmande stad, där inga israeliter bo; låt oss draga vidare, fram till Gibea."
13 Ó fi kún un pé, ẹ wá ẹ jẹ́ kí a gbìyànjú kí a dé Gibeah tàbí Rama kí a sùn ní ọ̀kan nínú wọn.
Och han sade ytterligare till sin tjänare: "Kom, låt oss försöka hinna fram till en av orterna här och stanna över natten i Gibea eller Rama."
14 Wọ́n sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn, oòrùn wọ̀ bí wọ́n ti súnmọ́ Gibeah tí ṣe ti àwọn Benjamini.
Så drogo de vidare; och när de voro invid Gibea i Benjamin, gick solen ned.
15 Wọ́n yípadà wọ́n lọ sí inú ìlú Gibeah láti wọ̀ síbẹ̀ ní òru náà, wọ́n lọ wọ́n sì jókòó níbi gbọ̀ngàn ìlú náà, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó gbà wọ́n sínú ilé rẹ̀ láti wọ̀ sí.
Då togo de in där och kommo för att stanna över natten i Gibea. Och när mannen kom ditin, satte han sig på den öppna platsen i staden, men ingen ville taga emot dem i sitt hus över natten.
16 Ní alẹ́ ọjọ́ náà ọkùnrin arúgbó kan láti àwọn òkè Efraimu, ṣùgbọ́n tí ń gbé ní Gibeah (ibẹ̀ ni àwọn ẹ̀yà Benjamini ń gbé) ń ti ibi iṣẹ́ rẹ̀ bọ̀ láti inú oko.
Men då, om aftonen, kom en gammal man från sitt arbete på fältet, och denne man var från Efraims bergsbygd och bodde såsom främling i Gibea; ty folket där på orten voro benjaminiter.
17 Nígbà tí ó wòkè ó rí arìnrìn-àjò náà ní gbọ̀ngàn ìlú náà, ọkùnrin arúgbó yìí bi í léèrè pé, “Níbo ni ò ń lọ? Níbo ni o ti ń bọ̀?”
När denne nu lyfte upp sina ögon, fick han se den vägfarande mannen på den öppna platsen i staden. Då sade den gamle mannen: "Vart skall du resa, och varifrån kommer du?"
18 Ọmọ Lefi náà dá a lóhùn pé, “Bẹtilẹhẹmu ti Juda ni àwa ti ń bọ̀, àwa sì ń lọ sí agbègbè tí ó sá pamọ́ ní àwọn òkè Efraimu níbi ti mo ń gbé. Mo ti lọ sí Bẹtilẹhẹmu ti Juda, èmi sì ń lọ sí ilé Olúwa nísinsin yìí. Kò sí ẹni tí ó gbà mí sí ilé rẹ̀.
Han svarade honom: "Vi äro på genomresa från Bet-Lehem i Juda till den del av Efraims bergsbygd, som ligger längst uppe; därifrån är jag, och jag har gjort en resa till Bet-Lehem i Juda. Nu är jag på väg till HERRENS hus, men ingen vill här taga emot mig i sitt hus.
19 Àwa ní koríko àti oúnjẹ tó tó fún àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wa àti oúnjẹ àti wáìnì fún àwa ìránṣẹ́ rẹ—èmi, ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú wa. A ò ṣe aláìní ohun kankan.”
Jag har både halm och foder åt våra åsnor, så ock bröd och vin åt mig själv och åt din tjänarinna och åt mannen som åtföljer oss, dina tjänare, så att intet fattas oss."
20 Ọkùnrin arúgbó náà sì wí pé. “Àlàáfíà fún ọ, bí ó ti wù kí ó rí, èmi yóò pèsè gbogbo ohun tí o nílò, kìkì pé kí ìwọ má ṣe sun ní ìgboro.”
Då sade den gamle mannen: "Frid vare med dig! Men låt mig få sörja för allt som kan fattas dig. Härute på den öppna platsen må du icke stanna över natten."
21 Òun sì mú wa sí ilé rẹ̀, ó ń bọ́ àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wẹ ẹsẹ̀ wọn, àwọn àlejò náà jẹ, wọ́n mu.
Därefter förde han honom till sitt hus och fodrade åsnorna. Och sedan de hade tvått sina fötter, åto de och drucko.
22 Ǹjẹ́ bí wọ́n ti ń ṣe àríyá, kíyèsi i, àwọn ọkùnrin ìlú náà, àwọn ọmọ Beliali kan, yí ilé náà ká, wọ́n sì ń lu ìlẹ̀kùn; wọ́n sì sọ fún baálé ilé náà ọkùnrin arúgbó náà pé, “Mú ọkùnrin tí ó wọ̀ sínú ilé rẹ wá, kí àwa lè mọ̀ ọ́n.”
Under det att de så gjorde sina hjärtan glada, omringades plötsligt huset av männen i staden, onda män, som bultade på dörren; och de sade till den gamle mannen, som rådde om huset: "För hitut den man som har kommit till ditt hus, så att vi få känna honom."
23 Ọkùnrin, baálé ilé náà sì jáde tọ̀ wọ́n lọ, ó sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi bẹ̀ yín, ẹ má ṣe hùwà búburú; nítorí tí ọkùnrin yìí ti wọ ilé mi, ẹ má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí.
Då gick mannen som rådde om huset ut till dem och sade till dem: "Nej, mina bröder, gören icke så illa. Eftersom nu denne man har kommit in i mitt hus, mån I icke göra en sådan galenskap.
24 Kíyèsi i, ọmọbìnrin mi ni èyí, wúńdíá, àti àlè rẹ̀; àwọn ni èmi ó mú jáde wá nísinsin yìí, kí ẹ̀yin tẹ̀ wọ́n lógo, kí ẹ̀yin ṣe sí wọn bí ó ti tọ́ lójú yín: ṣùgbọ́n ọkùnrin yìí ni kí ẹ̀yin má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí sí.”
Se, jag har en dotter som är jungfru, och han har själv en bihustru. Dem vill jag föra hitut, så kunnen I kränka dem och göra med dem vad I finnen för gott. Men med denne man mån I icke göra någon sådan galenskap.
25 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà kò fetí sí tirẹ̀. Nítorí náà ọkùnrin náà mú àlè rẹ̀ ó sì tari rẹ̀ jáde sí wọn, wọ́n sì bá a fi ipá lòpọ̀, wọ́n sì fi gbogbo òru náà bá a lòpọ̀, nígbà tí ó di àfẹ̀mọ́júmọ́ wọ́n jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́.
Men männen ville icke höra på honom; då tog mannen sin bihustru och förde henne ut till dem. Och de kände henne och hanterade henne skändligt hela natten ända till morgonen; först när morgonrodnaden gick upp, läto de henne gå.
26 Nígbà tí ojúmọ́ bẹ̀rẹ̀ sí là obìnrin náà padà lọ sí ilé tí ọ̀gá rẹ̀ wà, ó ṣubú lulẹ̀ lọ́nà, ó sì wà níbẹ̀ títí ó fi di òwúrọ̀.
Då kom kvinnan mot morgonen och föll ned vid ingången till mannens hus, där hennes herre var, och låg så, till dess det blev dager.
27 Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ jí tí ó sì dìde ní òwúrọ̀ tí ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ilé náà, tí ó sì bọ́ sí òde láti tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò rẹ̀, kíyèsi i àlè rẹ̀ wà ní ṣíṣubú ní iwájú ilé, tí ọwọ́ rẹ̀ sì di òpó ẹnu-ọ̀nà ibẹ̀ mú,
När nu hennes herre stod upp om morgonen och öppnade dörren till huset och gick ut för att fortsätta sin färd, fick han se sin bihustru ligga vid ingången till huset med händerna på tröskeln.
28 òun sì wí fún obìnrin náà pé, “Dìde jẹ́ kí a máa bá ọ̀nà wa lọ.” Ṣùgbọ́n òun kò dá a lóhùn. Nígbà náà ni ọkùnrin náà gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì kọjá lọ sí ilé e rẹ̀.
Han sade till henne: "Stå upp och låt oss gå." Men hon gav intet svar. Då tog han och lade henne på åsnan; sedan gjorde mannen sig redo och reste hem till sitt.
29 Nígbà tí ó dé ilé, ó mú ọ̀bẹ ó sì gé àlè rẹ̀ ní oríkeríke sí ọ̀nà méjìlá, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí gbogbo agbègbè Israẹli.
Men när han hade kommit hem, fattade han en kniv och tog sin bi- hustru och styckade henne, efter benen i hennes kropp, i tolv stycken och sände styckena omkring över hela Israels land.
30 Gbogbo ẹni tí ó rí i sì wí pé, “A kò ti rí i, bẹ́ẹ̀ a kò tí ì ṣe irú nǹkan yìí rí, kì í ṣe láti ọjọ́ tí Israẹli ti jáde tí Ejibiti wá títí di òní olónìí. Ẹ rò ó wò, ẹ gbìmọ̀ràn, kí ẹ sọ fún wa ohun tí a yóò ṣe!”
Och var och en som såg detta sade: "Något sådant har icke hänt eller blivit sett allt ifrån den dag då Israels barn drogo upp ur Egyptens land ända till denna dag. Övervägen detta, rådslån och sägen edert ord."

< Judges 19 >