< Judges 19 >
1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì Israẹli kò ní ọba. Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Lefi tí ń gbé ibi tí ó sá pamọ́ nínú àwọn agbègbè òkè Efraimu, mú àlè kan láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda.
Pripetilo se je v tistih dneh, ko ni bilo kralja v Izraelu, da je bil tam nek Lévijevec, [ki je] začasno prebival na pobočju gore Efrájim, ki si je vzel priležnico iz Judovega Betlehema.
2 Ṣùgbọ́n àlè rẹ̀ náà sì ṣe panṣágà sí i, òun fi sílẹ̀, ó sì padà lọ sí ilé baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu ti Juda, ó sì wà ní ibẹ̀ ní ìwọ̀n oṣù mẹ́rin,
Njegova priležnica je zoper njega igrala vlačugo in odšla proč od njega, v hišo svojega očeta v Judovem Betlehemu in bila tam cele štiri mesece.
3 ọkọ rẹ̀ lọ sí ibẹ̀ láti rọ̀ ọ́ pé kí ó padà sí ọ̀dọ̀ òun. Nígbà tí ó ń lọ ó mú ìránṣẹ́ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì lọ́wọ́, obìnrin náà mú un wọ inú ilé baba rẹ̀ lọ, nígbà tí baba obìnrin náà rí i ó fi tayọ̀tayọ̀ gbà á.
Njen soprog je vstal in odšel za njo, da ji prijateljsko govori in da jo ponovno privede. S seboj je imel svojega služabnika in nekaj oslov in privedla ga je v hišo svojega očeta. Ko ga je oče od gospodične zagledal, se je razveselil, da ga je srečal.
4 Àna rẹ̀, baba ọmọbìnrin náà rọ̀ ọ́, ó sì borí rẹ̀ láti dá a dúró fún ìgbà díẹ̀, òun sì dúró fún ọjọ́ mẹ́ta, ó ń jẹ, ó ń mu, ó sì ń sùn níbẹ̀.
Njegov tast, oče od gospodične, ga je zadržal in z njimi je ostal tri dni. Tako so jedli in pili ter tam prenočevali.
5 Ní ọjọ́ kẹrin, wọ́n dìde ní òwúrọ̀ kùtùkùtù òun sì múra láti padà lọ, ṣùgbọ́n baba ọmọbìnrin náà wí fún àna rẹ̀ pé, “Fi ohun jíjẹ díẹ̀ gbé inú ró nígbà náà kí ìwọ máa lọ.”
Pripetilo se je na četrti dan, ko so zgodaj zjutraj vstali, da se je dvignil, da odide. Oče od gospodične pa je svojemu zetu rekel: »Potolaži svoje srce z grižljajem kruha in potem pojdi svojo pot.«
6 Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ jókòó láti jọ jẹun àti láti jọ mu. Lẹ́yìn èyí ni baba ọmọbìnrin wí pé, “Jọ̀wọ́ dúró ní alẹ́ yìí kí o sì gbádùn ara rẹ.”
Oba skupaj sta se usedla, jedla in pila, kajti oče od gospodične je možu rekel: »Privoli, prosim te in ostani vso noč in naj bo tvoje srce veselo.«
7 Nígbà tí ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, baba ìyàwó rẹ̀ rọ̀ ọ́, torí náà ó sùn níbẹ̀ ní alẹ́ ọjọ́ náà.
Ko je mož vstal, da odide, mu je tast prigovarjal, zato je tam ponovno prenočil.
8 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ karùn-ún nígbà tí ó dìde láti lọ, baba ọmọbìnrin wí pé, “Fi oúnjẹ gbé ara ró. Dúró de ọ̀sán!” Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ jọ jẹun.
Vstal je zgodaj zjutraj, peti dan, da odide in oče od gospodične je rekel: »Potolaži svoje srce, prosim te.« Ostala sta do popoldneva in oba sta jedla.
9 Nígbà tí ọkùnrin náà, pẹ̀lú àlè àti ìránṣẹ́ rẹ̀, dìde láti máa lọ, àna rẹ̀, baba ọmọbìnrin náà ní, “Wò ó ilẹ̀ ti ń ṣú lọ, dúró níbí, ọjọ́ ti lọ. Dúró kí o sì gbádùn ara rẹ. Ìwọ lè jí ní àárọ̀ kùtùkùtù ọ̀la kí ìwọ sì máa lọ ilé.”
Ko je mož vstal, da odide, on, njegova priležnica in njegov služabnik, mu je tast, oče od gospodične, rekel: »Glej, sedaj se dan približuje večeru. Prosim te, ostani vso noč. Glej, dan gre h koncu, prenočuj tukaj, da bo tvoje srce lahko veselo in naslednji dan zgodaj pojdi na svojo pot, da boš lahko šel domov.«
10 Ṣùgbọ́n nítorí pé òun kò fẹ́ dúró mọ́ níbẹ̀ ní òru náà ọkùnrin náà kúrò ó sì gba ọ̀nà Jebusi: ọ̀nà Jerusalẹmu pẹ̀lú àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ méjèèjì tí ó fi dì í ní gàárì àti àlè rẹ̀.
Toda mož to noč ni hotel ostati, temveč je vstal, odšel in prišel nasproti Jebúsa, ki je Jeruzalem in tam sta bila z njim dva osedlana osla in tudi njegova priležnica je bila z njim.
11 Nígbà tí wọ́n súnmọ́ Jebusi tí ilẹ̀ ti fẹ́ ṣú tan, ìránṣẹ́ náà sọ fún ọ̀gá rẹ̀ pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a dúró ní ìlú yìí tí í ṣe ti àwọn ará Jebusi kí a sì sùn níbẹ̀.”
In ko so bili pri Jebúsu, je bil dan že davno porabljen in služabnik je rekel svojemu gospodarju: »Pridi, prosim te in obrniva se v to mesto Jebusejcev in prenočiva v njem.«
12 Ọ̀gá rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Rárá o, àwa kì yóò wọ ìlú àwọn àjèjì, àwọn tí olùgbé ibẹ̀ kì í ṣe ọmọ Israẹli, a yóò dé Gibeah.”
Njegov gospodar pa mu je rekel: »Ne bomo zavili vstran, sèm v to mesto tujca, ki ni izmed Izraelovih otrok; prešli bomo do Gíbee.«
13 Ó fi kún un pé, ẹ wá ẹ jẹ́ kí a gbìyànjú kí a dé Gibeah tàbí Rama kí a sùn ní ọ̀kan nínú wọn.
Svojemu služabniku je rekel: »Pridi in približajmo se enemu izmed teh mest, da vso noč prenočimo v Gíbei ali v Rami.«
14 Wọ́n sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn, oòrùn wọ̀ bí wọ́n ti súnmọ́ Gibeah tí ṣe ti àwọn Benjamini.
Šli so naprej svojo pot in sonce je zašlo nad njimi, ko so bili pri Gíbei, ki pripada Benjaminu.
15 Wọ́n yípadà wọ́n lọ sí inú ìlú Gibeah láti wọ̀ síbẹ̀ ní òru náà, wọ́n lọ wọ́n sì jókòó níbi gbọ̀ngàn ìlú náà, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó gbà wọ́n sínú ilé rẹ̀ láti wọ̀ sí.
Obrnili so se tja, da vstopijo in prenočijo v Gíbei. Ko so vstopili, se je usedel na mestno ulico, kajti tam ni bilo nobenega človeka, ki bi jih vzel v svojo hišo, da prenočijo.
16 Ní alẹ́ ọjọ́ náà ọkùnrin arúgbó kan láti àwọn òkè Efraimu, ṣùgbọ́n tí ń gbé ní Gibeah (ibẹ̀ ni àwọn ẹ̀yà Benjamini ń gbé) ń ti ibi iṣẹ́ rẹ̀ bọ̀ láti inú oko.
Glej, zvečer je prišel starec od svojega dela zunaj na polju, ki je bil prav tako z gore Efrájim in je začasno prebival v Gíbei. Toda možje kraja so bili Benjaminovci.
17 Nígbà tí ó wòkè ó rí arìnrìn-àjò náà ní gbọ̀ngàn ìlú náà, ọkùnrin arúgbó yìí bi í léèrè pé, “Níbo ni ò ń lọ? Níbo ni o ti ń bọ̀?”
Ko je povzdignil svoje oči, je na mestni ulici zagledal popotnika in starec je rekel: »Kam greš? In od kod prihajaš?«
18 Ọmọ Lefi náà dá a lóhùn pé, “Bẹtilẹhẹmu ti Juda ni àwa ti ń bọ̀, àwa sì ń lọ sí agbègbè tí ó sá pamọ́ ní àwọn òkè Efraimu níbi ti mo ń gbé. Mo ti lọ sí Bẹtilẹhẹmu ti Juda, èmi sì ń lọ sí ilé Olúwa nísinsin yìí. Kò sí ẹni tí ó gbà mí sí ilé rẹ̀.
Ta mu je odgovoril: »Mi smo prešli iz Judovega Betlehema proti pobočju gore Efrájim. Od tam sem in odšel sem k Judovemu Betlehemu, toda sedaj grem h Gospodovi hiši. Tukaj pa ni nobenega moža, ki bi me sprejel v hišo.
19 Àwa ní koríko àti oúnjẹ tó tó fún àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wa àti oúnjẹ àti wáìnì fún àwa ìránṣẹ́ rẹ—èmi, ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú wa. A ò ṣe aláìní ohun kankan.”
Vendar je tukaj tako slama in krma za naša osla in tukaj je kruh in vino zame in za mojo pomočnico in za mladeniča, ki je s tvojimi služabniki. Tukaj ni potrebe po nobeni stvari.«
20 Ọkùnrin arúgbó náà sì wí pé. “Àlàáfíà fún ọ, bí ó ti wù kí ó rí, èmi yóò pèsè gbogbo ohun tí o nílò, kìkì pé kí ìwọ má ṣe sun ní ìgboro.”
Starec je rekel: »Mir bodi s teboj. Kakorkoli, pusti vse svoje potrebe počivati na meni, samo ne prenočuj na ulici.«
21 Òun sì mú wa sí ilé rẹ̀, ó ń bọ́ àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wẹ ẹsẹ̀ wọn, àwọn àlejò náà jẹ, wọ́n mu.
Tako ga je odvedel v svojo hišo in dal krmo k oslom. Umili so svoja stopala, jedli in pili.
22 Ǹjẹ́ bí wọ́n ti ń ṣe àríyá, kíyèsi i, àwọn ọkùnrin ìlú náà, àwọn ọmọ Beliali kan, yí ilé náà ká, wọ́n sì ń lu ìlẹ̀kùn; wọ́n sì sọ fún baálé ilé náà ọkùnrin arúgbó náà pé, “Mú ọkùnrin tí ó wọ̀ sínú ilé rẹ wá, kí àwa lè mọ̀ ọ́n.”
Torej ko so razveseljevali svoja srca, glej, so možje iz mesta, neki Beliálovi sinovi, naokoli obkrožili hišo in udarjali na vrata ter hišnemu gospodarju, starcu, spregovorili, rekoč: »Privedi moškega, ki je prišel v tvojo hišo, da ga lahko spoznamo.«
23 Ọkùnrin, baálé ilé náà sì jáde tọ̀ wọ́n lọ, ó sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi bẹ̀ yín, ẹ má ṣe hùwà búburú; nítorí tí ọkùnrin yìí ti wọ ilé mi, ẹ má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí.
Mož, hišni gospodar, je odšel ven k njim ter jim rekel: »Ne, moji bratje, ne, prosim vas, ne storite tako zlobno, glede na to, da je ta mož prišel v mojo hišo, ne storite te neumnosti.
24 Kíyèsi i, ọmọbìnrin mi ni èyí, wúńdíá, àti àlè rẹ̀; àwọn ni èmi ó mú jáde wá nísinsin yìí, kí ẹ̀yin tẹ̀ wọ́n lógo, kí ẹ̀yin ṣe sí wọn bí ó ti tọ́ lójú yín: ṣùgbọ́n ọkùnrin yìí ni kí ẹ̀yin má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí sí.”
Glejte, tukaj je moja hči, devica in njegova priležnica. Njiju bom torej privedel ven in ju ponižajte ter z njima storite kar se vam zdi dobro, toda temu možu ne storite tako ogabne stvari.«
25 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà kò fetí sí tirẹ̀. Nítorí náà ọkùnrin náà mú àlè rẹ̀ ó sì tari rẹ̀ jáde sí wọn, wọ́n sì bá a fi ipá lòpọ̀, wọ́n sì fi gbogbo òru náà bá a lòpọ̀, nígbà tí ó di àfẹ̀mọ́júmọ́ wọ́n jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́.
Toda možje mu niso hoteli prisluhniti. Tako je mož vzel svojo priležnico in jo privedel k njim. Spoznali so jo in jo zlorabljali vso noč do jutra. Ko pa se je dan začel svitati, so jo pustili oditi.
26 Nígbà tí ojúmọ́ bẹ̀rẹ̀ sí là obìnrin náà padà lọ sí ilé tí ọ̀gá rẹ̀ wà, ó ṣubú lulẹ̀ lọ́nà, ó sì wà níbẹ̀ títí ó fi di òwúrọ̀.
Potem je ob jutranjem svitanju ženska prišla in padla dol pri vratih moževe hiše, kjer je bil njen gospodar, dokler ni bilo svetlo.
27 Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ jí tí ó sì dìde ní òwúrọ̀ tí ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ilé náà, tí ó sì bọ́ sí òde láti tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò rẹ̀, kíyèsi i àlè rẹ̀ wà ní ṣíṣubú ní iwájú ilé, tí ọwọ́ rẹ̀ sì di òpó ẹnu-ọ̀nà ibẹ̀ mú,
Njen gospodar je zjutraj vstal, odprl vrata hiše in odšel ven, da gre svojo pot. In glej, ženska, njegova priležnica, je bila zvrnjena dol pri hišnih vratih in njene roke so bile na pragu.
28 òun sì wí fún obìnrin náà pé, “Dìde jẹ́ kí a máa bá ọ̀nà wa lọ.” Ṣùgbọ́n òun kò dá a lóhùn. Nígbà náà ni ọkùnrin náà gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì kọjá lọ sí ilé e rẹ̀.
Rekel ji je: »Vstani in pojdimo.« Toda ni se odzvala. Potem jo je mož vzel gor na osla in mož se je dvignil ter se spravil k svojemu kraju.
29 Nígbà tí ó dé ilé, ó mú ọ̀bẹ ó sì gé àlè rẹ̀ ní oríkeríke sí ọ̀nà méjìlá, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí gbogbo agbègbè Israẹli.
Ko je prišel v svojo hišo, je vzel nož in ga položil na svojo priležnico in jo razdelil na dvanajst kosov, skupaj z njenimi kostmi in jo poslal po vseh Izraelovih pokrajinah.
30 Gbogbo ẹni tí ó rí i sì wí pé, “A kò ti rí i, bẹ́ẹ̀ a kò tí ì ṣe irú nǹkan yìí rí, kì í ṣe láti ọjọ́ tí Israẹli ti jáde tí Ejibiti wá títí di òní olónìí. Ẹ rò ó wò, ẹ gbìmọ̀ràn, kí ẹ sọ fún wa ohun tí a yóò ṣe!”
In bilo je tako, da so vsi, ki so to videli, rekli: »Takšnega dejanja ni bilo storjenega niti videnega od dneva, ko so Izraelovi otroci prišli gor iz egiptovske dežele, do današnjega dne. Preudarite o tem, sprejmite nasvet in govorite svojim umom.«