< Judges 18 >

1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ẹ̀yà Dani ń wá ilẹ̀ tiwọn, níbi tí wọn yóò máa gbé, nítorí pé títí di àkókò náà wọn kò ì tí ì pín ogún ilẹ̀ fún wọn ní ìní láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Xu künlǝrdǝ Israilda ⱨeq padixaⱨ bolmidi; xundaⱪla xu künlǝrdǝ Danlarning ⱪǝbilisi ɵzlirigǝ olturaⱪlixix üqün jay izdǝwatⱪanidi, qünki xu küngiqǝ ular Israil ⱪǝbililiri arisida qǝk taxlinip bekitilgǝn miras zeminƣa erixmigǝnidi.
2 Nítorí náà àwọn ẹ̀yà Dani rán àwọn jagunjagun márùn-ún lọ láti Sora àti Eṣtaoli láti yọ́ ilẹ̀ náà wò àti láti rìn ín wò. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe ojú fún gbogbo àwọn ẹ̀yà wọn. Wọ́n wí fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ rin ilẹ̀ náà ká, kí ẹ sì wò ó fínní fínní.” Àwọn ọkùnrin náà wọ àwọn ìlú tí ó wà ní agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika, níbi tí wọ́n sùn ní òru náà.
Xuning bilǝn Danlar pütkül jǝmǝtidin Zoreaⱨ wǝ Əxtaolda olturuxluⱪ bǝx palwanni zeminni qarlap kelixkǝ ǝwǝtti wǝ ularƣa tapilap: — Silǝr berip zeminni qarlap kelinglar, dedi. Ular sǝpǝr ⱪilip Əfraim taƣliⱪ yurtiƣa kelip Mikaⱨning ɵyigǝ qüxüp u yǝrdǝ ⱪondi.
3 Nígbà tí wọ́n súnmọ́ tòsí ilé e Mika, wọ́n dá ohùn ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà mọ̀, torí náà wọ́n yípadà, wọ́n sì wọ inú ilé náà lọ wọ́n sì bi í pé, “Tá ni ó mú ọ wa sí ibi? Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí? Èéṣe tí o fi wà ní ibí?”
Ular Mikaⱨning ɵyining yenida turƣinida Lawiy yigitning awazini tonup, uning ⱪexiƣa kirip uningdin: — Seni kim bu jayƣa elip kǝldi? Bu yǝrdǝ nemǝ ix ⱪilisǝn? Bu jayda nemigǝ erixting? — dǝp soridi.
4 Ó sọ ohun tí Mika ti ṣe fún un, ó fi kún un fún wọn pé, “Ó gbà mí sí iṣẹ́, èmi sì ni àlùfáà rẹ̀.”
U ularƣa jawabǝn: — Mikaⱨ manga mundaⱪ-mundaⱪ ⱪilip, meni yallap ɵzigǝ kaⱨin ⱪildi, dedi.
5 Wọ́n wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ béèrè ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí àwa lè mọ̀ bí ìrìnàjò wa yóò yọrí sí rere.”
Buni anglap ular uningƣa: — Undaⱪ bolsa bizning mangƣan sǝpirimizning onguxluⱪ bolidiƣan-bolmaydiƣanliⱪini bilmikimiz üqün, Hudadin sorap bǝrgin, — dedi.
6 Àlùfáà náà dá wọn lóhùn pé, “Ẹ máa lọ ní àlàáfíà. Ìrìnàjò yín tí ẹ̀yin ń rìn bá ojúrere Olúwa pàdé.”
Kaⱨin ularƣa: — Hatirjǝm beriweringlar. Mangƣan yolunglar Pǝrwǝrdigarning aldididur, — dedi.
7 Àwọn ọkùnrin márààrún náà kúrò, wọ́n sì wá sí Laiṣi, níbi tí wọ́n ti rí i pé àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ ní ààbò, bí àwọn ará Sidoni, láìsí ìfòyà àti ní ìpamọ́. Ní ìgbà tí ilẹ̀ wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, wọ́n ní ọrọ̀ púpọ̀. Ibùgbé wọn tún jìnnà sí ti àwọn ará Sidoni, wọn kò fi ohunkóhun bá ẹnikẹ́ni dàpọ̀.
Xuning bilǝn bu bǝx adǝm qiⱪip, Laix degǝn jayƣa yetip kǝldi. Ular u yǝrdiki hǝlⱪning tinq-aman yaxawatⱪinini, turmuxining Zidoniylarning ɵrp-adǝtliri boyiqǝ ikǝnlikini, hatirjǝmlik wǝ raⱨǝt iqidǝ turuwatⱪinini kɵrdi; xu zeminda ularni har ⱪilƣuqi ⱨeqⱪandaⱪ ⱨoⱪuⱪdar yoⱪ idi; ular Zidoniylardin yiraⱪta turatti, xundaⱪla baxⱪilar bilǝnmu ⱨeqⱪandaⱪ bardi-kǝldi ⱪilixmaytti.
8 Nígbà tí wọ́n padà sí Sora àti Eṣtaoli, àwọn arákùnrin wọn bi wọ́n léèrè pé, “Báwo ni ibi tí ẹ lọ ti rí? Kí ni ìròyìn tí ẹ mú wá?”
[Bǝx palwan] Zoreaⱨ wǝ Əxtaolƣa ɵz ⱪerindaxlirining ⱪexiƣa ⱪaytip kǝldi. Ⱪerindaxliri ulardin: — Nemǝ hǝwǝr elip kǝldinglar? — dǝp soridi.
9 Wọ́n dáhùn pé, “Ẹ dìde ẹ jẹ́ kí a lọ kọlù wọ́n! A wá rí i pé ilẹ̀ náà dára gidigidi. Ṣé ẹ̀yin ó sì jókòó láìsí nǹkan nípa rẹ̀? Ẹ má ṣe lọ́ra láti lọ síbẹ̀ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà.
Ular jawabǝn: — Biz ⱪopup ularƣa ⱨujum ⱪilayli! Qünki biz xu zeminni qarlap kǝlduⱪ, mana, u intayin yahxi bir yurt ikǝn. Əmdi nemixⱪa ⱪimir ⱪilmay jim olturisilǝr? Əmdi dǝrⱨal berip, u yurtni elixⱪa ǝzmǝnglǝrni ǝzmǝnglar, berip ⱨujum ⱪilip zeminni igilǝnglar.
10 Nígbà tí ẹ̀yin bá dé ibẹ̀, ẹ yóò rí àwọn ènìyàn tí ọkàn wọn balẹ̀ àti ilẹ̀ tí ó tẹ́jú tí Ọlọ́run ti fi fún yín, ilẹ̀ tí kò ṣe aláìní nǹkan kan.”
U yǝrgǝ barƣininglarda silǝr tinq-aman turuwatⱪan bir hǝlⱪni, ⱨǝr ǝtrapiƣa sozulƣan kǝng-azadǝ bir zeminni kɵrisilǝr! Huda u yǝrni silǝrning ⱪolunglarƣa tapxurƣandur. U yurtta yǝr yüzidǝ tepilidiƣan barliⱪ nǝrsilǝrdin ⱨeqbiri kǝm ǝmǝs, dedi.
11 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó múra ogun láti ìran Dani, jáde lọ láti Sora àti Eṣtaoli ní mímú ra láti jagun.
Xuning bilǝn Danlarning jǝmǝtidin altǝ yüz adǝm jǝnggǝ ⱪorallinip, Zoreaⱨ wǝ Əxtaoldin qiⱪip mangdi.
12 Wọ́n sì jáde lọ, ní ojú ọ̀nà wọn, wọ́n tẹ̀dó ogun sí ẹ̀bá Kiriati-Jearimu ní Juda. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń gbé ìwọ̀-oòrùn Kiriati-Jearimu ni Mahane-Dani títí di òní yìí.
Ular Yǝⱨuda yurtidiki Kiriat-Yearim degǝn jayƣa berip, qedir tikti (xunga bu jay taki bügüngiqǝ «Danning lǝxkǝrgaⱨi» dǝp atalmaⱪta; u Kiriat-Yearimning arⱪa tǝripigǝ jaylaxⱪanidi).
13 Láti ibẹ̀ wọ́n kọjá lọ sí àwọn ìlú agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika.
Andin ular u yǝrdin Əfraim taƣliⱪ rayoniƣa berip, Mikaⱨning ɵyigǝ yetip kǝldi.
14 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin márùn-ún tí ó lọ yọ́ ilẹ̀ Laiṣi wò sọ fún àwọn arákùnrin wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ọ̀kan nínú àwọn ilé yìí ní ẹ̀wù efodu, àwọn yòókù ní òrìṣà, ère gbígbẹ́ àti ère dídà? Ẹ mọ ohun tí ó yẹ kí ẹ ṣe báyìí.”
Laix yurtiƣa qarlax üqün barƣan bǝx kixi ɵz ⱪerindaxliriƣa: — Bilǝmsilǝr? Bu ɵydǝ bir ǝfod toni, birnǝqqǝ tǝrafim butliri, bir oyma mǝbud wǝ ⱪuyma mǝbud bardur! Əmdi ⱪandaⱪ ⱪilixinglar kerǝklikini oylixinglar! — dedi.
15 Wọ́n sì yà sí ibẹ̀, wọ́n sì wọ ilé ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà, sí ilé Mika, wọ́n sì béèrè àlàáfíà rẹ̀.
Ular burulup Lawiy yigitning ɵyigǝ (Mikaⱨⱪa tǝwǝ ɵygǝ) kirip uningdin ⱨal soridi.
16 Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin ará Dani náà tí ó hámọ́ra ogun, dúró ní àbáwọlé ẹnu odi.
Dan ⱪǝbilisidin bolƣan jǝng ⱪorallirini kɵtürgǝn altǝ yüz kixi dǝrwaza aldida turup turdi.
17 Àwọn ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n lọ yọ́ ilẹ̀ náà wò wọlé lọ wọ́n sì kó ère gbígbẹ́ náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé àti ère dídà náà nígbà tí àlùfáà náà àti àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó hámọ́ra ogun dúró ní à bá wọ ẹnu odi náà.
U zeminni qarlaxⱪa barƣan bǝx adǝm [buthaniƣa] kirip, oyma but, ǝfod toni, tǝrafim butliri wǝ ⱪuyma butni elip qiⱪti. Kaⱨin jǝng ⱪorallirini kɵtürgǝn altǝ yüz kixi bilǝn billǝ dǝrwazida turatti.
18 Nígbà tí àwọn ọkùnrin yìí wọ ilé e Mika lọ tí wọ́n sì kó ère fínfín náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère dídà náà, àlùfáà náà béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Kí ni ẹ̀yin ń ṣe?”
Bu bǝx adǝm Mikaⱨning ɵyigǝ kirip oyma but, ǝfod tonini, tǝrafim butliri wǝ ⱪuyma butni elip qiⱪⱪanda kaⱨin ulardin: — Bu nemǝ ⱪilƣininglar?! — dǝp soridi.
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Dákẹ́! Ma sọ nǹkan kan, tẹ̀lé wa kí o sì di baba àti àlùfáà wa. Kò ha sàn fún ọ láti máa ṣe ìránṣẹ́ ẹ̀yà àti ìdílé kan tí ó wá láti Israẹli bí àlùfáà ju ilé ẹnìkan ṣoṣo lọ?”
Ular uningƣa: — Ün qiⱪarmay, aƣzingni ⱪolung bilǝn etip, biz bilǝn mengip, bizgǝ ⱨǝm ata ⱨǝm kaⱨin bolup bǝrgin. Sening pǝⱪǝt bir adǝmning ɵyidikilǝrgǝ kaⱨin bolƣining yahximu, yaki Israilning bir jǝmǝti bolƣan pütün bir ⱪǝbiligǝ kaⱨin bolƣining yahximu? — dedi.
20 Nígbà náà ni inú àlùfáà náà sì dùn, òun mú efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère fínfín náà, ó sì bá àwọn ènìyàn náà lọ.
Xundaⱪ dewidi, kaⱨinning kɵngli hux bolup, ǝfod, tǝrafim butliri wǝ oyma mǝbudni elip hǝlⱪning arisiƣa kirip turdi.
21 Wọ́n kó àwọn ọmọdé wọn, àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní wọn síwájú, wọ́n yípadà wọ́n sì lọ.
Andin ular burulup, u yǝrdin kǝtti; ular baliliri wǝ qarpaylarni wǝ yük-taⱪlirining ⱨǝmmisini aldida mangduruwǝtkǝnidi.
22 Nígbà tí wọ́n ti rìn jìnnà díẹ̀ sí ilé Mika, àwọn ọkùnrin tí ó wà ní agbègbè Mika kó ara wọn jọ, wọ́n sì lé àwọn ará Dani bá.
Mikaⱨning ɵyidin heli yiraⱪliƣanda Mikaⱨning ɵyining ǝtrapidiki hǝlⱪlǝr yiƣilip, Danlarƣa ⱪoƣlap yetixti.
23 Bí wọ́n ṣe ń pariwo tẹ̀lé wọn lẹ́yìn, àwọn ará Dani yípadà wọ́n sì bi Mika pé, “Kí ló ṣe ọ́ tí o fi pe àwọn ọkùnrin rẹ jáde láti jà?”
Ular Danlarni towlap qaⱪirdi, Danlar burulup Mikaⱨⱪa: — Sanga nemǝ boldi, bunqiwila kɵp hǝlⱪni yiƣip kelip nemǝ ⱪilmaⱪqisǝn?! — dedi.
24 Ó dáhùn pé, “Ẹ̀yin kó àwọn ère tí mo ṣe, àti àlùfáà mi lọ. Kí ni ó kù tí mo ní? Báwo ni ẹ̀yin ò ṣe béèrè pé, ‘Kí ló ṣe ọ́?’”
U jawab berip: — Silǝr mǝn yasatⱪan mǝbudlarni kaⱨinim bilǝn ⱪoxup aldinglar, andin kǝttinglar! Manga yǝnǝ nemǝ ⱪaldi?! Xundaⱪ turuⱪluⱪ silǝr tehi: «Sanga nemǝ boldi?» — dǝwatisilǝrƣu! — dedi.
25 Àwọn ọkùnrin Dani náà dáhùn pé, “Má ṣe bá wa jiyàn, tàbí àwọn oníbìínú fùfù ènìyàn lè kọlù yín, ìwọ àti àwọn ìdílé yóò sì sọ ẹ̀mí yín nù.”
Danlar uningƣa: — Ününgni qiⱪarma, bolmisa aqqiⱪi yaman kixilǝr seni tutuwelip, seni wǝ ailǝngdikilǝrni janliridin juda ⱪilmisun, yǝnǝ, — dedi.
26 Àwọn ọkùnrin Dani náà sì bá ọ̀nà wọn lọ. Nígbà tí Mika rí í pé wọ́n lágbára púpọ̀ fún òun, ó sì padà sí ilé rẹ̀.
Bularni dǝp Danlar ɵz yoliƣa mangdi; Mikaⱨ ularning ɵzidin küqlük ikǝnlikini kɵrüp, yenip ɵz ɵyigǝ kǝtti.
27 Wọ́n sì kó àwọn ohun tí Mika ti ṣe àti àlùfáà rẹ̀, wọ́n sì kọjá lọ sí Laiṣi, ní ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó ní ìbàlẹ̀ ọkàn tí wọ́n sì wà ní àlàáfíà. Wọ́n fi ojú idà kọlù wọ́n, wọ́n sì jó ìlú wọn run.
Ular Mikaⱨ yasatⱪuzƣan nǝrsilǝr wǝ uning kaⱨinini elip, Laixⱪa ⱨujum ⱪildi; u yǝrdiki hǝlⱪ tinq-aman wǝ hatirjǝm turuwatⱪanidi; ular ularni ⱪiliqlap ⱪirip, xǝⱨǝrni otta kɵydürüwǝtti.
28 Kò sì sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀ nítorí pé ibi tí wọ́n ń gbé jìnà sí àwọn ará Sidoni, wọn kò sì ní àṣepọ̀ pẹ̀lú ẹnikẹ́ni. Ìlú náà wà ní inú àfonífojì lẹ́bàá a Beti-Rehobu. Àwọn ará Dani sì tún ìlú náà kọ́, wọ́n sì ń gbé inú rẹ̀.
Xǝⱨǝrni ⱪutⱪuzƣudǝk ⱨeq adǝm qiⱪimidi; qünki bu xǝⱨǝr Zidondin yiraⱪta idi, hǝlⱪi ⱨeqkim bilǝn bardi-kǝldi ⱪilixmaytti. Xǝⱨǝr Bǝyt-Rǝⱨobning yenidiki jilƣida idi. Danlar xǝⱨǝrni ⱪaytidin ⱪurup, olturaⱪlaxti.
29 Wọ́n sọ orúkọ ìlú náà ní Dani gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba ńlá wọn Dani, ẹni tí wọ́n bí fún Israẹli: bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Laiṣi ni orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí.
Ular bu xǝⱨǝrgǝ Israilning oƣulliridin bolƣan, ɵz atisi Danning ismini ⱪoyup Dan dǝp atidi. Ilgiri u xǝⱨǝrning nami Laix idi.
30 Àwọn ọmọ Dani sì gbé àwọn ère kalẹ̀ fún ara wọn níbẹ̀; Jonatani ọmọ Gerṣomu, ọmọ Mose, àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni àlùfáà fún àwọn ẹ̀yà Dani títí di àkókò tí a kó ilẹ̀ náà ní ìgbèkùn.
Danlar xu yǝrdǝ bu oyma butni ɵzlirigǝ tiklidi; Musaning oƣli Gǝrxomning ǝwladi Yonatan wǝ uning oƣulliri bolsa xu zeminning hǝlⱪi sürgün boluxⱪa elip ketilgǝn küngiqǝ Danlarning ⱪǝbilisigǝ kaⱨin bolup turƣanidi.
31 Wọ́n tẹ̀síwájú láti lo àwọn ère tí Mika ṣe, ní gbogbo àkókò tí ilé Ọlọ́run wà ní Ṣilo.
Hudaning ɵyi Xiloⱨda turƣan barliⱪ waⱪitlarda, Danlar ɵzliri üqün tikligǝn, Mikaⱨ yasatⱪuzƣan oyma mǝbud [Danda] turƣuzuldi.

< Judges 18 >