< Judges 18 >
1 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ẹ̀yà Dani ń wá ilẹ̀ tiwọn, níbi tí wọn yóò máa gbé, nítorí pé títí di àkókò náà wọn kò ì tí ì pín ogún ilẹ̀ fún wọn ní ìní láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
O dönemde İsrail'de kral yoktu ve Dan oymağından olanlar yerleşecek yer arıyorlardı. Çünkü İsrail oymakları arasında kendilerine düşen payı henüz almamışlardı.
2 Nítorí náà àwọn ẹ̀yà Dani rán àwọn jagunjagun márùn-ún lọ láti Sora àti Eṣtaoli láti yọ́ ilẹ̀ náà wò àti láti rìn ín wò. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe ojú fún gbogbo àwọn ẹ̀yà wọn. Wọ́n wí fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ rin ilẹ̀ náà ká, kí ẹ sì wò ó fínní fínní.” Àwọn ọkùnrin náà wọ àwọn ìlú tí ó wà ní agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika, níbi tí wọ́n sùn ní òru náà.
Böylece kendi boylarından, Sora ve Eştaol kentlerinden beş cesur savaşçıyı toprakları araştırıp bilgi toplamak üzere yola çıkardılar. Onlara, “Gidin, toprakları araştırın” dediler. Adamlar Efrayim'in dağlık bölgesinde bulunan Mika'nın evine gelip geceyi orada geçirdiler.
3 Nígbà tí wọ́n súnmọ́ tòsí ilé e Mika, wọ́n dá ohùn ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà mọ̀, torí náà wọ́n yípadà, wọ́n sì wọ inú ilé náà lọ wọ́n sì bi í pé, “Tá ni ó mú ọ wa sí ibi? Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí? Èéṣe tí o fi wà ní ibí?”
Mika'nın evinin yanındayken genç Levili'nin sesini tanıdılar. Eve yaklaşarak ona, “Seni buraya kim getirdi? Burada ne yapıyorsun? Burada ne işin var?” diye sordular.
4 Ó sọ ohun tí Mika ti ṣe fún un, ó fi kún un fún wọn pé, “Ó gbà mí sí iṣẹ́, èmi sì ni àlùfáà rẹ̀.”
Levili Mika'nın kendisi için yaptıklarını anlattı. “Bana verdiği ücrete karşılık ona kâhinlik ediyorum” dedi.
5 Wọ́n wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ béèrè ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí àwa lè mọ̀ bí ìrìnàjò wa yóò yọrí sí rere.”
Adamlar, “Lütfen Tanrı'ya danış, bu yolculuğumuz başarılı olacak mı, bilelim” dediler.
6 Àlùfáà náà dá wọn lóhùn pé, “Ẹ máa lọ ní àlàáfíà. Ìrìnàjò yín tí ẹ̀yin ń rìn bá ojúrere Olúwa pàdé.”
Kâhin, “Esenlikle gidin, Tanrı yolculuğunuzu onaylıyor” diye yanıtladı.
7 Àwọn ọkùnrin márààrún náà kúrò, wọ́n sì wá sí Laiṣi, níbi tí wọ́n ti rí i pé àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ ní ààbò, bí àwọn ará Sidoni, láìsí ìfòyà àti ní ìpamọ́. Ní ìgbà tí ilẹ̀ wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, wọ́n ní ọrọ̀ púpọ̀. Ibùgbé wọn tún jìnnà sí ti àwọn ará Sidoni, wọn kò fi ohunkóhun bá ẹnikẹ́ni dàpọ̀.
Böylece beş adam yola çıkıp Layiş'e vardılar. Kent halkının Saydalılar gibi kaygıdan uzak, esenlik ve güvenlik içinde yaşadığını gördüler. Yörede onlara egemen olan, baskı yapan kimse yoktu. Saydalılar'dan uzaktaydılar, başka kimseyle de ilişkileri yoktu.
8 Nígbà tí wọ́n padà sí Sora àti Eṣtaoli, àwọn arákùnrin wọn bi wọ́n léèrè pé, “Báwo ni ibi tí ẹ lọ ti rí? Kí ni ìròyìn tí ẹ mú wá?”
Sonra adamlar Sora ve Eştaol'a, soydaşlarının yanına döndüler. Soydaşları, “Ne öğrendiniz?” diye sordular.
9 Wọ́n dáhùn pé, “Ẹ dìde ẹ jẹ́ kí a lọ kọlù wọ́n! A wá rí i pé ilẹ̀ náà dára gidigidi. Ṣé ẹ̀yin ó sì jókòó láìsí nǹkan nípa rẹ̀? Ẹ má ṣe lọ́ra láti lọ síbẹ̀ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà.
Adamlar, “Haydi, onlara saldıralım” dediler, “Ülkeyi gördük, toprağı çok güzel. Ne duruyorsunuz? Gecikmeden gidip ülkeyi sahiplenin.
10 Nígbà tí ẹ̀yin bá dé ibẹ̀, ẹ yóò rí àwọn ènìyàn tí ọkàn wọn balẹ̀ àti ilẹ̀ tí ó tẹ́jú tí Ọlọ́run ti fi fún yín, ilẹ̀ tí kò ṣe aláìní nǹkan kan.”
Oraya vardığınızda halkın her şeyden habersiz olduğunu göreceksiniz. Tanrı'nın elinize teslim ettiği bu ülke çok geniş; öyle bir yer ki, hiçbir eksiği yok.”
11 Nígbà náà ni ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó múra ogun láti ìran Dani, jáde lọ láti Sora àti Eṣtaoli ní mímú ra láti jagun.
Bunun üzerine Dan oymağından altı yüz kişi silahlarını kuşanıp Sora ve Eştaol'dan yola çıktı.
12 Wọ́n sì jáde lọ, ní ojú ọ̀nà wọn, wọ́n tẹ̀dó ogun sí ẹ̀bá Kiriati-Jearimu ní Juda. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń gbé ìwọ̀-oòrùn Kiriati-Jearimu ni Mahane-Dani títí di òní yìí.
Gidip Yahuda'nın Kiryat-Yearim Kenti yakınında ordugah kurdular. Bu nedenle Kiryat-Yearim'in batısındaki bu yer bugün de Mahane-Dan diye anılıyor.
13 Láti ibẹ̀ wọ́n kọjá lọ sí àwọn ìlú agbègbè òkè Efraimu, wọ́n sì dé ilé Mika.
Buradan Efrayim'in dağlık bölgesine geçip Mika'nın evine gittiler.
14 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin márùn-ún tí ó lọ yọ́ ilẹ̀ Laiṣi wò sọ fún àwọn arákùnrin wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ọ̀kan nínú àwọn ilé yìí ní ẹ̀wù efodu, àwọn yòókù ní òrìṣà, ère gbígbẹ́ àti ère dídà? Ẹ mọ ohun tí ó yẹ kí ẹ ṣe báyìí.”
Layiş yöresini araştırmaya gitmiş olan beş adam soydaşlarına, “Bu evlerden birinde bir efod, özel aile putları, bir oyma, bir de dökme put olduğunu biliyor musunuz?” dediler, “Ne yapacağınıza siz karar verin.”
15 Wọ́n sì yà sí ibẹ̀, wọ́n sì wọ ilé ọ̀dọ́mọkùnrin Lefi náà, sí ilé Mika, wọ́n sì béèrè àlàáfíà rẹ̀.
Bunun üzerine halk genç Levili'nin kaldığı Mika'nın evine yöneldi. Eve girip Levili'ye hal hatır sordular.
16 Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin ará Dani náà tí ó hámọ́ra ogun, dúró ní àbáwọlé ẹnu odi.
Silahlarını kuşanmış altı yüz Danlı dış kapının önüne yığılmıştı.
17 Àwọn ọkùnrin márùn-ún tí wọ́n lọ yọ́ ilẹ̀ náà wò wọlé lọ wọ́n sì kó ère gbígbẹ́ náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé àti ère dídà náà nígbà tí àlùfáà náà àti àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin tí ó hámọ́ra ogun dúró ní à bá wọ ẹnu odi náà.
Yöreyi araştırmış olan beş adam içeri girip efodu, özel putları, oyma ve dökme putları aldılar. Kâhinle silah kuşanmış altı yüz kişiyse dış kapının önünde duruyordu.
18 Nígbà tí àwọn ọkùnrin yìí wọ ilé e Mika lọ tí wọ́n sì kó ère fínfín náà, efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère dídà náà, àlùfáà náà béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Kí ni ẹ̀yin ń ṣe?”
Adamların Mika'nın evine girip efodu, özel putları, oyma ve dökme putları aldığını gören kâhin, “Ne yapıyorsunuz?” diye sordu.
19 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Dákẹ́! Ma sọ nǹkan kan, tẹ̀lé wa kí o sì di baba àti àlùfáà wa. Kò ha sàn fún ọ láti máa ṣe ìránṣẹ́ ẹ̀yà àti ìdílé kan tí ó wá láti Israẹli bí àlùfáà ju ilé ẹnìkan ṣoṣo lọ?”
Adamlar, “Sus, sesini çıkarma” dediler, “Bizimle gel. Bize danışmanlık ve kâhinlik yap. Bir adamın evinde kâhinlik etmek mi iyi, yoksa İsrail'in bir boyuna, bir oymağına kâhinlik etmek mi?”
20 Nígbà náà ni inú àlùfáà náà sì dùn, òun mú efodu náà, àwọn òrìṣà ìdílé mìíràn àti ère fínfín náà, ó sì bá àwọn ènìyàn náà lọ.
Kâhinin yüreği sevinçle doldu. Efodu, özel putları, oyma putu alıp topluluğun ortasında yürümeye başladı.
21 Wọ́n kó àwọn ọmọdé wọn, àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní wọn síwájú, wọ́n yípadà wọ́n sì lọ.
Topluluk çocuklarını, hayvanlarını, değerli eşyalarını alıp yola çıktı.
22 Nígbà tí wọ́n ti rìn jìnnà díẹ̀ sí ilé Mika, àwọn ọkùnrin tí ó wà ní agbègbè Mika kó ara wọn jọ, wọ́n sì lé àwọn ará Dani bá.
Danoğulları Mika'nın evinden biraz uzaklaştıktan sonra, Mika'nın komşuları toplanıp onlara yetiştiler.
23 Bí wọ́n ṣe ń pariwo tẹ̀lé wọn lẹ́yìn, àwọn ará Dani yípadà wọ́n sì bi Mika pé, “Kí ló ṣe ọ́ tí o fi pe àwọn ọkùnrin rẹ jáde láti jà?”
Bağırıp çağırmaya başladılar. Danoğulları dönüp Mika'ya, “Ne oldu, neden adamlarını toplayıp geldin?” dediler.
24 Ó dáhùn pé, “Ẹ̀yin kó àwọn ère tí mo ṣe, àti àlùfáà mi lọ. Kí ni ó kù tí mo ní? Báwo ni ẹ̀yin ò ṣe béèrè pé, ‘Kí ló ṣe ọ́?’”
Mika, “Kâhinimi, yaptırdığım putları alıp gittiniz” dedi, “Bana ne kaldı ki? Bir de, ‘Ne oldu?’ diye soruyorsunuz.”
25 Àwọn ọkùnrin Dani náà dáhùn pé, “Má ṣe bá wa jiyàn, tàbí àwọn oníbìínú fùfù ènìyàn lè kọlù yín, ìwọ àti àwọn ìdílé yóò sì sọ ẹ̀mí yín nù.”
“Kes sesini!” dediler, “Yoksa öfkeli adamlarımız saldırıp seni de, aileni de öldürür.”
26 Àwọn ọkùnrin Dani náà sì bá ọ̀nà wọn lọ. Nígbà tí Mika rí í pé wọ́n lágbára púpọ̀ fún òun, ó sì padà sí ilé rẹ̀.
Sonra yollarına devam ettiler. Mika onların kendisinden daha güçlü olduğunu görünce dönüp evine gitti.
27 Wọ́n sì kó àwọn ohun tí Mika ti ṣe àti àlùfáà rẹ̀, wọ́n sì kọjá lọ sí Laiṣi, ní ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó ní ìbàlẹ̀ ọkàn tí wọ́n sì wà ní àlàáfíà. Wọ́n fi ojú idà kọlù wọ́n, wọ́n sì jó ìlú wọn run.
Danoğulları Mika'nın yaptırdığı putları ve kâhini yanlarına alarak Layiş üzerine yürüdüler. Barışçıl ve her şeyden habersiz olan kent halkını kılıçtan geçirip kenti ateşe verdiler.
28 Kò sì sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀ nítorí pé ibi tí wọ́n ń gbé jìnà sí àwọn ará Sidoni, wọn kò sì ní àṣepọ̀ pẹ̀lú ẹnikẹ́ni. Ìlú náà wà ní inú àfonífojì lẹ́bàá a Beti-Rehobu. Àwọn ará Dani sì tún ìlú náà kọ́, wọ́n sì ń gbé inú rẹ̀.
Beytrehov yakınındaki vadide bulunan Layiş Kenti'nin yardımına gelen olmadı. Çünkü kent Sayda'dan uzaktı, başka bir kentle de ilişkisi yoktu. Danoğulları kenti yeniden inşa ederek oraya yerleştiler.
29 Wọ́n sọ orúkọ ìlú náà ní Dani gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba ńlá wọn Dani, ẹni tí wọ́n bí fún Israẹli: bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Laiṣi ni orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí.
Yakup'un oğlu olan ataları Dan'ın anısına kente Dan adını verdiler. Kentin eski adı Layiş'ti.
30 Àwọn ọmọ Dani sì gbé àwọn ère kalẹ̀ fún ara wọn níbẹ̀; Jonatani ọmọ Gerṣomu, ọmọ Mose, àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni àlùfáà fún àwọn ẹ̀yà Dani títí di àkókò tí a kó ilẹ̀ náà ní ìgbèkùn.
Oyma putu oraya diktiler. Musa oğlu Gerşom oğlu Yonatan ile oğulları sürgüne kadar onlara kâhinlik ettiler.
31 Wọ́n tẹ̀síwájú láti lo àwọn ère tí Mika ṣe, ní gbogbo àkókò tí ilé Ọlọ́run wà ní Ṣilo.
Tanrı'nın Tapınağı Şilo'da olduğu sürece Mika'nın yaptırdığı puta taptılar.